< Példabeszédek 20 >

1 A bor csúfoló, a részegítő ital háborgó, és valaki abba beletéved, nem bölcs!
Ẹlẹ́yà ni ọtí wáìnì, aláriwo sì ní ọtí líle; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi tànjẹ kò gbọ́n.
2 Mint a fiatal oroszlán ordítása, olyan a királynak rettentése; a ki azt haragra ingerli, vétkezik a maga élete ellen.
Ìbẹ̀rù ọba dàbí kíké e kìnnìún; ẹnikẹ́ni tí ó bá mú un bínú ba ayé ara rẹ̀ jẹ́.
3 Tisztesség az embernek elmaradni a versengéstől; valaki pedig bolond, patvarkodik.
Iyì ni ó jẹ́ fún ènìyàn láti sá fún ìjà, ṣùgbọ́n gbogbo aláìgbọ́n a máa tètè wá ìjà.
4 A hideg miatt nem szánt a rest; aratni akar majd, de nincs mit.
Ọ̀lẹ kì í ṣiṣẹ́ oko nígbà tí ó yẹ, nítorí náà ní àsìkò ìkórè, yóò wá kò sì ní rì nǹkan.
5 Mély víz a férfiúnak elméjében a tanács; mindazáltal a bölcs ember kimeríti azt.
Ète ọkàn ènìyàn dàbí omi jíjìn; ṣùgbọ́n ènìyàn olóye á wá wọn jáde.
6 A legtöbb ember talál valakit, a ki jó hozzá; de hű embert, azt ki találhat?
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni wọ́n máa ń sọ pe àwọn ní ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn, ṣùgbọ́n kò rọrùn láti rí ènìyàn olóòtítọ́.
7 A ki az ő tökéletességében jár, igaz ember; boldogok az ő fiai ő utána!
Olódodo ènìyàn a máa gbé ìgbé ayé àìlábùkù ìbùkún ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
8 A király, ha az ő ítélőszékiben ül, tekintetével minden gonoszt eltávoztat.
Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ rẹ̀ láti ṣe ìdájọ́ yóò fẹ́ gbogbo ibi dànù pẹ̀lú ojú rẹ̀.
9 Ki mondhatná azt: megtisztítottam szívemet, tiszta vagyok az én bűnömtől?
Ta ni ó le è wí pé, “Mo ti ṣe ọkàn mi ní mímọ́, mo mọ́, n kò sì lẹ́ṣẹ̀”?
10 A kétféle font és a kétféle mérték, útálatos az Úrnál egyaránt mind a kettő.
Ìwọ̀n èké àti òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ Olúwa kórìíra méjèèjì.
11 Az ő cselekedetiből ismerteti meg magát még a gyermek is, ha tiszta-é, és ha igaz-é az ő cselekedete.
Kódà a mọ ọmọdé nípa iṣẹ́ rẹ̀ nípa pe bóyá iṣẹ́ rẹ mọ́ tàbí pé ó tọ̀nà.
12 A halló fület és a látó szemet, az Úr teremtette egyaránt mindkettőt.
Etí tí ó ń gbọ́ àti ojú tí ó ń ríran Olúwa ni ó dá méjèèjì.
13 Ne szeresd az álmot, hogy ne légy szegény; nyisd fel a te szemeidet, és megelégszel kenyérrel.
Má ṣe fẹ́ràn oorun, àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò di tálákà. Ma ṣe sùn ìwọ yóò sì ní oúnjẹ láti tún fi tọrọ.
14 Hitvány, hitvány, azt mondja a vevő; de mikor elmegy, akkor dicsekedik.
“Kò dára, kò dára!” ní ẹni tó ra ọjà máa ń wí; nígbà tí ó bá kúrò níbẹ̀ tán, yóò máa yangàn bí òun tí ṣe rí rà sí.
15 Van arany és drágagyöngyök sokasága; de drága szer a tudománynyal teljes ajak.
Wúrà wà, iyùn sì wà rẹpẹtẹ, ṣùgbọ́n, ahọ́n tí ń sọ ìmọ̀ gan an ni ọ̀ṣọ́ iyebíye.
16 Vedd el ruháját, mert kezes lett másért, és az idegenért vedd el zálogát.
Gba abọ́ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àlejò; mú un lọ́wọ́ bí ìbúra bí ó bá ṣe é fún obìnrin onírìnkurìn.
17 Gyönyörűséges az embernek az álnokságnak kenyere; de annakutána betelik az ő szája kavicsokkal.
Oúnjẹ tí a fi ọ̀nà èrú rí máa ń dùn lẹ́nu ènìyàn, ṣùgbọ́n, a yọrí sí ibi ẹnu tí ó kún fún erùpẹ̀.
18 A gondolatok tanácskozással erősek; és bölcs vezetéssel folytass hadakozást.
Pa ètè rẹ mọ́ nípa wíwá ìmọ̀ràn bí o bá ń jagun, gba ìtọ́sọ́nà.
19 Megjelenti a titkot, a ki rágalmazó; tehát a ki fecsegő szájú, azzal ne barátkozzál.
Olófòófó a máa tú àṣírí nítorí náà yẹra fún ènìyàn tí ń rojọ́ púpọ̀.
20 A ki az ő atyját vagy anyját megátkozza, annak kialszik szövétneke a legnagyobb setétségben.
Bí ènìyàn kan bá ṣépè fún baba tàbí ìyá rẹ̀, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ni a ó pa kú nínú òkùnkùn biribiri.
21 A mely örökséget először siettetnek, annak vége meg nem áldatik.
Ogún tí a kójọ kíákíá ní ìbẹ̀rẹ̀ kì yóò ní ìbùkún ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín.
22 Ne mondd: bosszút állok rajta! Várjad az Urat, és megszabadít téged!
Má ṣe wí pé, “N ó sẹ̀san àṣìṣe rẹ yìí fún ọ.” Dúró de Olúwa yóò sì gbà ọ́ là.
23 Útálatos az Úrnál a kétféle súly; és a hamis fontok nem jó dolgok.
Olúwa kórìíra òdínwọ̀n èké. Òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ kò sì tẹ́ ẹ lọ́rùn.
24 Az Úrtól vannak a férfi lépései; az ember pedig mit ért az ő útában?
Olúwa ni ó ń ṣe olùdarí ìgbésẹ̀ ènìyàn. Báwo wá ni òye gbogbo ọ̀nà ènìyàn ṣe le yé ni?
25 Tőr az embernek meggondolatlanul mondani: szent, és a fogadástétel után megfontolni.
Ìdẹ̀kùn ni fún ènìyàn láti ṣe ìlérí kíákíá nígbà tí ó bá sì yá kí ó máa ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wò.
26 Szétszórja a gonoszokat a bölcs király, és fordít reájok kereket.
Ọlọ́gbọ́n ọba tú ènìyàn búburú ká; Ó sì fi òòlọ ìpakà lọ̀ wọ́n.
27 Az Úrtól való szövétnek az embernek lelke, a ki megvizsgálja a szívnek minden rejtekét.
Àtùpà Olúwa ń ṣe àwárí ẹ̀mí ènìyàn a máa ṣàwárí ibi ìkọ̀kọ̀ inú.
28 A kegyelmesség és az igazság megőrzik a királyt, megerősíti irgalmasság által az ő székét.
Ìfẹ́ àti òdodo pa ọba mọ́, nípa ìfẹ́, ìtẹ́ rẹ̀ wà láìléwu.
29 Az ifjaknak ékessége az ő erejök; és a véneknek dísze az ősz haj.
Ògo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ni agbára wọn, ewú orí ni iyì arúgbó.
30 A kékek és a sebek távoztatják el a gonoszt, és a belső részekig ható csapások.
Ìgbájú ìgbámú àti ìfarapa máa ń mú ibi lọ, pàṣán sì máa ń ṣe àfọ̀mọ́ ibi ìkọ̀kọ̀ inú.

< Példabeszédek 20 >