< Nehemiás 11 >

1 És lakozának a nép fejedelmei Jeruzsálemben, a többi nép pedig sorsot vete, hogy minden tíz emberből vinnének egyet Jeruzsálembe, a szent városba lakóul, a többi kilencz pedig marad a maga városában.
Nísinsin yìí àwọn olórí àwọn ènìyàn tẹ̀dó sí Jerusalẹmu, àwọn ènìyàn tókù sì dìbò láti mú ẹnìkọ̀ọ̀kan jáde nínú àwọn mẹ́wàá mẹ́wàá láti máa gbé ní Jerusalẹmu, ìlú mímọ́, nígbà tí àwọn mẹ́sàn-án tókù yóò dúró sí àwọn ìlú u wọn.
2 És áldá a nép mindazon férfiakat, a kik önkéntesen vállalkozának arra, hogy Jeruzsálemben lakoznak.
Àwọn ènìyàn súre fún gbogbo àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ̀wọ́ ara wọn láti gbé ní Jerusalẹmu.
3 Ezek pedig a tartomány fejei, a kik Jeruzsálemben megtelepedének; de Júda városaiban lakozék kiki az ő örökségében, városaikban: az Izráel, a papok, a Léviták, a Léviták szolgái és Salamon szolgáinak fiai.
Wọ̀nyí ni àwọn olórí agbègbè ìjọba tí wọ́n tẹ̀dó sí Jerusalẹmu (díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ìran àwọn ìránṣẹ́ Solomoni ń gbé àwọn ìlú Juda, olúkúlùkù ń gbé lórí ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní àwọn ìlú náà.
4 Jeruzsálemben azért megtelepedének a Júda fiai közül és Benjámin fiai közül: Júda fiai közül: Athája, Uzzija fia, ki Zakariás fia, ki Amaria fia, ki Sefátia fia, ki Mahalalél fia vala, a Pérecz fiai közül,
Nígbà tí àwọn ènìyàn tókù nínú àwọn Juda àti Benjamini ń gbé ní Jerusalẹmu). Nínú àwọn ọmọ Juda: Ataiah ọmọ Ussiah ọmọ Sekariah, ọmọ Amariah, ọmọ Ṣefatia, ọmọ Mahalaleli, ìran Peresi;
5 És Maaszéja, Báruk fia, ki Kolhóze fia, ki Hazája fia, ki Adája fia, ki Jójárib fia, ki Zakariás fia, ki Hasilóni fia vala.
àti Maaseiah ọmọ Baruku, ọmọ Koli-Hose, ọmọ Hasaiah, ọmọ Adaiah, ọmọ Joiaribu, ọmọ Sekariah, ọmọ Ṣilo.
6 Pérecz fiai összesen, a kik Jeruzsálemben laknak vala, négyszázhatvannyolcz erős férfi;
Àwọn ìran Peresi tó gbé ní Jerusalẹmu jẹ́ àádọ́rinlénírinwó ó dín méjì alágbára ọkùnrin.
7 Benjámin fiai pedig ezek: Szallu, Mesullám fia, ki Jóed fia, ki Pedája fia, ki Kólája fia, ki Maaszéja fia, ki Ithiel fia, ki Ézsaiás fia vala,
Nínú àwọn ìran Benjamini: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Joẹdi, ọmọ Pedaiah, ọmọ Kolaiah, ọmọ Maaseiah, ọmọ Itieli, ọmọ Jeṣaiah,
8 És ő utána Gabbai, Szallai, kilenczszázhuszonnyolczan;
àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Gabbai àti Sallai jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rún ó lé mẹ́jọ ọkùnrin.
9 És Jóel, a Zikri fia előljárójok volt ezeknek, Júda pedig, a Hasszenua fia, a város másodrendű előljárója.
Joẹli ọmọ Sikri ni olórí òṣìṣẹ́ wọn, Juda ọmọ Hasenuah sì ni olórí agbègbè kejì ní ìlú náà.
10 A papok közül: Jedája, Jójárib fia, Jákhin,
Nínú àwọn àlùfáà: Jedaiah; ọmọ Joiaribu; Jakini;
11 Serája pedig, a Hilkiás fia, ki Mesullám fia, ki Sádók fia, ki Merájóth fia, ki Akhitúb fia volt, az Isten házának fejedelme vala,
Seraiah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, àwọn ni olórí tó ń bojútó ilé Ọlọ́run,
12 És atyjokfiai, a kik a ház munkáját teljesítik vala, nyolczszázhuszonketten; és Adája, a Jeróhám fia, ki Pelália fia, ki Amsi fia, ki Zakariás fia, ki Pashur fia, ki Malkija fia vala,
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, ẹni tí ó ń ṣe iṣẹ́ ní tẹmpili jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó lé mẹ́rìnlélógún ọkùnrin: Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Pelaiah, ọmọ Amisi, ọmọ Sekariah, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah,
13 És az ő atyjafiai, a családfők kétszáznegyvenketten, és Amasszai, Azarél fia, ki Ahzai fia, ki Mesillémóth fia, ki Immér fia vala,
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ olórí ìdílé jẹ́ òjìlúgba ó lé méjì ọkùnrin: Amaṣai ọmọ Asareeli, ọmọ Ahsai, ọmọ Meṣilemoti, ọmọ Immeri,
14 És az ő atyjokfiai, vitéz férfiak, százhuszonnyolczan, előljárójok volt pedig Zabdiel, a Haggedólim fia.
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin jẹ́ méjìdínláàádóje. Olórí òṣìṣẹ́ ẹ wọn ni Sabdieli ọmọ Hagedolimu.
15 A Léviták közül pedig: Semája, Hassub fia, ki Azrikám fia, ki Hasábia fia, ki Bunni fia vala.
Láti inú àwọn ọmọ Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ọmọ Bunni;
16 És Sabbethai és Józabád, az Isten házának külső munkája felett felügyelők valának a Léviták fejei közül,
Ṣabbetai àti Josabadi, olórí méjì nínú àwọn ọmọ Lefi, àwọn tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ tí ó wà ní ẹ̀yìn àgbàlá ilé Ọlọ́run;
17 És Mattánia, – a Mika fia, ki Zabdi fia, ki Asáf fia vala, – a ki vezetője volt a hálaadó éneklésnek, s elkezdé azt az imádság után, és Bakbukia, a ki másodrendű vala atyjafiai között, és Abda, Sammua fia, ki Gálál fia, ki Jeduthun fia vala;
Mattaniah ọmọ Mika, ọmọ Sabdi, ọmọ Asafu, adarí tí ó ń ṣáájú ìdúpẹ́ àti àdúrà; Bakbukiah ẹnìkejì láàrín àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀; àti Abida ọmọ Ṣammua, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni.
18 A Léviták összesen a szent városban: kétszáznyolczvannégyen.
Àwọn ọmọ Lefi nínú ìlú mímọ́ jẹ́ ọ̀rìnlélúgba ó lé mẹ́rin.
19 A kapunállók pedig: Akkub, Talmón és atyjokfiai, a kapukat őrizők százhetvenketten.
Àwọn aṣọ́nà: Akkubu, Talmoni, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, tí wọ́n máa ń ṣọ́nà jẹ́ méjìléláàádọ́sàn-án ọkùnrin.
20 A többi Izráeliták pedig, a papok, a Léviták lakozának Júdának minden városaiban, kiki az ő örökségében.
Àwọn tókù nínú àwọn ọmọ Israẹli, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wà ní gbogbo ìlú u Juda, olúkúlùkù lórí ilẹ̀ ìní tirẹ̀.
21 A Léviták szolgái pedig lakozának az Ófelben, és Siha és Gipsa valának előljáróik a Léviták szolgáinak.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili ń gbé lórí òkè Ofeli, Siha àti Giṣpa sì ni alábojútó wọn.
22 A Léviták előljárója vala Jeruzsálemben, az Isten háza szolgálatjánál, Uzzi, a Báni fia, – ki Hasábia fia, ki Mattánia fia, ki Mika fia volt, – Asáf fiai, az énekesek közül;
Olórí òṣìṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ní Jerusalẹmu ní Ussi ọmọ Bani, ọmọ Haṣabiah, ọmọ Mattaniah ọmọ Mika. Ussi jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ìran Asafu tí wọ́n jẹ́ akọrin ojúṣe nínú ìjọ́sìn ní ilé Ọlọ́run.
23 Mert ők, a Léviták, a király parancsolata szerint, az énekesek pedig kötés szerint végezék naponként való teendőjüket;
Àwọn akọrin wà ní abẹ́ àṣẹ ọba, èyí tí ó n díwọ̀n iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn.
24 Petáhja pedig, a Mesézabel fia, Júda fiának, Zerahnak fiai közül, a király oldala mellett vala a nép minden dolgában.
Petahiah ọmọ Meṣesabeli, ọ̀kan nínú àwọn Sera ọmọ Juda ní aṣojú ọba nínú ohun gbogbo tí ó jẹ mọ́ ti àwọn ènìyàn náà.
25 A falukban, ezek határaiban pedig Júda fiai közül lakozának Kirjáth-Arbában és mezővárosaiban, Dibonban és mezővárosaiban, Jekabseélben és faluiban.
Fún ìletò pẹ̀lú oko wọn, díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn Juda tí ń gbé Kiriati-Arba, àti àwọn ìletò agbègbè e rẹ̀, ní Diboni àti ìletò rẹ̀, ní Jekabseeli.
26 Jésuában, Móladában és Beth-Péletben.
Ní Jeṣua, ní Molada, ní Beti-Peleti
27 Hasár-Suálban, Beér-Sebában és mezővárosaiban,
ní Hasari-Ṣuali, ní Beerṣeba àti àwọn agbègbè rẹ̀.
28 Siklágban, Mekónában és mezővárosaiban,
Ní Siklagi, ní Mekona àti àwọn ìletò rẹ̀,
29 En-Rimmonban, Sorában, Jarmuthban,
ní Ẹni-Rimoni, ní Sora, ní Jarmatu,
30 Zánoáhban, Adullámban és faluiban, Lákisban és határaiban, Azékában és mezővárosaiban, – ekként laknak vala Beér-Sebától mind a Hinnóm völgyéig.
Sanoa, Adullamu àti àwọn ìletò o wọn, ní Lakiṣi àti àwọn oko rẹ̀, àti ní Aseka àti àwọn ìletò rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé láti Beerṣeba títí dé àfonífojì Hinnomu.
31 Benjámin fiai pedig laknak vala Gebától fogva Mikmásban, Ajában, Béthelben és mezővárosaiban.
Àwọn ọmọ Benjamini láti Geba ń gbé ní Mikmasi, Aija, Beteli àti àwọn ìletò rẹ̀.
32 Anatótban, Nóbban, Anániában,
Ní Anatoti, Nobu àti Ananiah,
33 Hásórban, Rámában, Gittajimban,
ní Hasori Rama àti Gittaimu,
34 Hádidban, Sebóimban, Neballátban,
ní Hadidi, Seboimu àti Neballati,
35 Lódban, Onóban, s a mesteremberek völgyében.
ní Lodi àti Ono, àti ní àfonífojì àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà.
36 A Léviták közül pedig némely júdai osztályok Benjáminhoz csatlakozának.
Nínú ìpín àwọn ọmọ Lefi ni Juda tẹ̀dó sí Benjamini.

< Nehemiás 11 >