< Lukács 21 >

1 És mikor feltekintett, látá, hogy a gazdagok hányják az ő ajándékaikat a perselybe.
Nígbà tí ó sì gbé ojú sókè, ó rí àwọn ọlọ́rọ̀ ń fi ẹ̀bùn wọn sínú àpótí ìṣúra.
2 Láta pedig egy szegény özvegy asszonyt is, hogy abba két fillért vete.
Ó sì rí tálákà opó kan pẹ̀lú, ó ń sọ owó idẹ wẹ́wẹ́ méjì síbẹ̀.
3 És monda: Igazán mondom néktek, hogy e szegény özvegy mindenkinél többet vete:
Ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, tálákà opó yìí fi sí i ju gbogbo wọn lọ,
4 Mert mind ezek az ő fölöslegükből vetettek Istennek az ajándékokhoz: ez pedig az ő szegénységéből minden vagyonát, a mije volt, oda veté.
nítorí gbogbo àwọn wọ̀nyí fi sínú ẹ̀bùn Ọlọ́run láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní wọn; ṣùgbọ́n òun nínú àìní rẹ̀ ó sọ gbogbo ohun ìní rẹ̀ tí ó ní sínú rẹ̀.”
5 És mikor némelyek mondának a templom felől, hogy szép kövekkel és ajándékokkal van felékesítve, monda:
Bí àwọn kan sì ti ń sọ̀rọ̀ nípa tẹmpili, bí a ti fi òkúta dáradára àti ẹ̀bùn ṣe é ní ọ̀ṣọ́, fun Ọlọ́run, Jesu wí pé
6 Ezekből, a miket láttok, jőnek napok, melyekben kő kövön nem marad, mely le nem romboltatnék.
“Ohun tí ẹ̀yin ń wò wọ̀nyí, ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí a kì yóò fi òkúta kan sílẹ̀ lórí èkejì tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
7 Megkérdék pedig őt, mondván: Mester, mikor lesznek azért ezek? és mi lesz a jel, mikor mind ezek meglesznek?
Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, pé, “Olùkọ́, nígbà wo ni nǹkan wọ̀nyí yóò rí bẹ́ẹ̀? Àti àmì kín ni yóò wà, nígbà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ?”
8 Ő pedig monda: Meglássátok, hogy el ne hitessenek benneteket: mert sokan jőnek el az én nevemben, kik ezt mondják: Én vagyok; és: Az idő elközelgett; ne menjetek azért utánok.
Ó sì wí pé, “Ẹ máa kíyèsára, kí a má bá à mú yín ṣìnà: nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò wá ní orúkọ mi, tí yóò máa wí pé, ‘Èmi ní Kristi náà àkókò náà sì kù sí dẹ̀dẹ̀.’ Ẹ má ṣe tọ̀ wọ́n lẹ́yìn.
9 És mikor hallotok háborúkról és zendülésekről, meg ne félemljetek; mert ezeknek meg kell lenni előbb, de nem jő mindjárt a vég.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá gbúròó ogun àti ìdágìrì, ẹ má ṣe fòyà; nítorí nǹkan wọ̀nyí ní láti kọ́kọ́ ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin náà kì í ṣe lójúkan náà.”
10 Akkor monda nékik: Nemzet nemzet ellen támad, és ország ország ellen;
Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé, “Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba.
11 És minden felé nagy földindulások lesznek, és éhségek és döghalálok; és rettegtetések és nagy jelek lesznek az égből.
Ilẹ̀-rírì ńlá yóò sì wà káàkiri, àti ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn; ohun ẹ̀rù, àti àmì ńlá yóò sì ti ọ̀run wá.
12 De mind ezeknek előtte kezeiket reátok vetik, és üldöznek titeket, adván a gyülekezetek elé, és tömlöczökbe és királyok és helytartók elé visznek az én nevemért.
“Ṣùgbọ́n ṣáájú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, wọn ó nawọ́ mú yín, wọn ó sì ṣe inúnibíni sí yín, wọn ó mú yín lọ sí Sinagọgu, àti sínú túbú, wọn ó mú yín lọ sọ́dọ̀ àwọn ọba àti àwọn ìjòyè nítorí orúkọ mi.
13 De ebből néktek lesz tanúbizonyságotok.
Ẹ o si jẹ́rìí nípa mi.
14 Tökéljétek el azért a ti szívetekben, hogy nem gondoskodtok előre, hogy mit feleljetek védelmetekre:
Nítorí náà ẹ pinnu rẹ̀ ní ọkàn yín pé ẹ ko ronú ṣáájú, bí ẹ ó ti dáhùn.
15 Mert én adok néktek szájat és bölcseséget, melynek ellene nem szólhatnak, sem ellene nem állhatnak mind azok, a kik magokat ellenetekbe vetik.
Nítorí tí èmi ó fún yín ní ẹnu àti ọgbọ́n, tí gbogbo àwọn ọ̀tá yín kì yóò lè sọ̀rọ̀-òdì sí, tí wọn kì yóò sì lè kò lójú.
16 Elárulnak pedig titeket szülők és testvérek is, rokonok és barátok is; és megölnek némelyeket ti közületek.
A ó sì fi yín hàn láti ọwọ́ àwọn òbí yín wá, àti àwọn arákùnrin, àti àwọn ìbátan, àti àwọn ọ̀rẹ́; òun ó sì mú kì a pa nínú yín.
17 És gyűlöletesek lesztek mindenki előtt az én nevemért.
A ó sì kórìíra yín lọ́dọ̀ gbogbo ènìyàn nítorí orúkọ mi.
18 De fejeteknek egy hajszála sem vész el.
Ṣùgbọ́n irun orí yín kan kì yóò ṣègbé.
19 A ti béketűréstek által nyeritek meg lelketeket.
Nínú ìdúró ṣinṣin yín ni ẹ̀yin ó jèrè ọkàn yín.
20 Mikor pedig látjátok Jeruzsálemet hadseregektől körülvéve, akkor tudjátok meg, hogy elközelgett az ő elpusztulása.
“Nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí ti a fi ogun yí Jerusalẹmu ká, ẹ mọ̀ nígbà náà pé, ìsọdahoro rẹ̀ kù sí dẹ̀dẹ̀.
21 Akkor a kik Júdeában lesznek, fussanak a hegyekre; és a kik annak közepette, menjenek ki abból; és a kik a mezőben, ne menjenek be abba.
Nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ní Judea sálọ sórí òkè; àti àwọn tí ń bẹ láàrín rẹ̀ kí wọn jáde kúrò; kí àwọn tí ó sì ń bọ̀ ní ìgbèríko má ṣe wọ inú rẹ̀ wá.
22 Mert azok a bosszúállásnak napjai, hogy beteljesedjenek mind azok, a mik megírattak.
Nítorí ọjọ́ ẹ̀san ni ọjọ́ wọ̀nyí, kì a lè mú ohun gbogbo tí a ti kọ̀wé rẹ̀ ṣẹ.
23 Jaj pedig a terhes és szoptató asszonyoknak azokban a napokban; mert nagy szükség lesz e földön, és harag e népen.
Ṣùgbọ́n ègbé ni fún àwọn tí ó lóyún, àti àwọn tí ó fi ọyàn fún ọmọ mu ní ọjọ́ wọ̀nyí! Nítorí tí ìpọ́njú púpọ̀ yóò wà lórí ilẹ̀ àti ìbínú sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
24 És elhullanak fegyvernek éle által, és fogva vitetnek minden pogányok közé; és Jeruzsálem megtapodtatik a pogányoktól, míglen betelik a pogányok ideje.
Wọn ó sì ti ojú idà ṣubú, a ó sì dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ sí orílẹ̀-èdè gbogbo; Jerusalẹmu yóò sì di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ lẹ́sẹ̀ àwọn aláìkọlà, títí àkókò àwọn aláìkọlà yóò fi kún.
25 És lesznek jelek a napban, holdban és csillagokban; és a földön pogányok szorongása a kétség miatt, mikor a tenger és a hab zúgni fog,
“Àmì yóò sì wà ní oorun, àti ní òṣùpá, àti ní ìràwọ̀; àti lórí ilẹ̀ ayé ìdààmú fún àwọn orílẹ̀-èdè nínú ìpayà híhó Òkun àti ìgbì omi.
26 Mikor az emberek elhalnak a félelem miatt és azoknak várása miatt, a mik e föld kerekségére következnek: mert az egek erősségei megrendülnek.
Àyà àwọn ènìyàn yóò máa já fún ìbẹ̀rù, àti ìrètí nǹkan wọ̀nyí tí ń bọ̀ sórí ayé: nítorí àwọn agbára ọ̀run ni a ó mì tìtì.
27 És akkor meglátják az embernek Fiát eljőni a felhőben, hatalommal és nagy dicsőséggel.
Nígbà náà ni wọn ó sì rí Ọmọ Ènìyàn tí yóò máa bọ̀ wá nínú àwọsánmọ̀ pẹ̀lú agbára àti ògo ńlá.
28 Mikor pedig ezek kezdenek meglenni, nézzetek fel és emeljétek fel a ti fejeteket; mert elközelget a ti váltságtok.
Ṣùgbọ́n nígbà tí nǹkan wọ̀nyí bá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣẹ, ǹjẹ́ kí ẹ wo òkè, kí ẹ sì gbé orí yín sókè; nítorí ìdáǹdè yín kù sí dẹ̀dẹ̀.”
29 Monda pedig nékik egy példázatot: Tekintsétek meg a fügefát és minden fákat:
Ó sì pa òwe kan fún wọn pé, “Ẹ kíyèsi igi ọ̀pọ̀tọ́, àti sí gbogbo igi.
30 Mikor immár hajtanak, és ezt látjátok, ti magatoktól tudjátok, hogy már közel van a nyár.
Nígbà tí wọ́n bá rúwé, ẹ̀yin rí i, ẹ sì mọ̀ fúnra ara yín pé, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn kù fẹ́ẹ́rẹ́.
31 Ezenképen ti is, mikor látjátok, hogy ezek meglesznek, tudjátok meg, hogy közel van az Isten országa.
Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀yin, nígbà tí ẹ̀yin bá rí nǹkan wọ̀nyí tí o ṣẹ, kí ẹ̀yin mọ̀ pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.
32 Bizony mondom néktek, hogy e nemzetség el nem múlik, mígnem mind ezek meglesznek.
“Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ìran yìí kì yóò rékọjá, títí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ.
33 Az ég és a föld elmúlnak, de az én beszédeim semmiképen el nem múlnak.
Ọ̀run àti ayé yóò rékọjá, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi kì yóò rékọjá.
34 De vigyázzatok magatokra, hogy valamikor meg ne nehezedjék a ti szívetek dobzódásnak, részegségnek és ez élet gondjainak miatta, és váratlanul reátok ne jőjjön az a nap:
“Ṣùgbọ́n ẹ máa kíyèsára yín, kí ọkàn yín má ṣe kún fún wọ̀bìà, àti fún ọtí àmupara, àti fún àníyàn ayé yìí, tí ọjọ́ náà yóò sì fi dé bá yín lójijì bí ìkẹ́kùn.
35 Mert mintegy tőr, úgy lep meg mindeneket, a kik az egész föld színén lakoznak.
Nítorí bẹ́ẹ̀ ni yóò dé bá gbogbo àwọn tí ń gbé orí gbogbo ilẹ̀ ayé.
36 Vigyázzatok azért minden időben, kérvén, hogy méltókká tétessetek arra, hogy elkerüljétek mindezeket, a mik bekövetkeznek, és megállhassatok az embernek Fia előtt!
Ǹjẹ́ kì ẹ máa ṣọ́nà, kí ẹ sì máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí ẹ ba à lè la gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí yóò ṣẹlẹ̀, kí ẹ sì lè dúró níwájú Ọmọ Ènìyàn.”
37 Tanít vala pedig naponta a templomban; éjszakára pedig kimenvén, a hegyen vala, mely Olajfák hegyének neveztetik.
Lọ́sàn án, Jesu a sì máa kọ́ni ní tẹmpili, lóru, a sì máa jáde lọ í wọ̀ ní òkè tí à ń pè ní Òkè Olifi.
38 És kora reggel hozzá megy vala az egész nép, hogy őt hallgassa a templomban.
Gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá ní tẹmpili ní kùtùkùtù òwúrọ̀, láti gbọ́rọ̀ rẹ̀.

< Lukács 21 >