< Lukács 19 >

1 És bemenvén, általméne Jerikhón.
Jesu sì wọ Jeriko lọ, ó sì ń kọjá láàrín rẹ̀.
2 És ímé vala ott egy ember, a kit nevéről Zákeusnak hívtak; és az fővámszedő vala, és gazdag.
Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà tí a ń pè ní Sakeu, ó sì jẹ́ olórí agbowó òde kan, ó sì jẹ́ ọlọ́rọ̀.
3 És igyekezék Jézust látni, ki az; de a sokaságtól nem láthatá, mivelhogy termete szerint kis ember volt.
Ó sì ń fẹ́ láti rí ẹni tí Jesu jẹ́: kò sì lè rí i, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn, àti nítorí tí òun jẹ́ ènìyàn kúkúrú.
4 És előre futván felhága egy eperfüge fára, hogy őt lássa; mert arra vala elmenendő.
Ó sì súré síwájú, ó gun orí igi sikamore kan, kí ó bà lè rí i: nítorí tí yóò kọjá lọ níhà ibẹ̀.
5 És mikor arra a helyre jutott, feltekintvén Jézus, látá őt, és monda néki: Zákeus, hamar szállj alá; mert ma nékem a te házadnál kell maradnom.
Nígbà tí Jesu sì dé ibẹ̀, ó gbé ojú sókè, ó sì rí i, ó sì wí fún un pé, “Sakeu! Yára, kí o sì sọ̀kalẹ̀; nítorí pé èmi yóò wọ ilé rẹ lónìí.”
6 És sietve leszálla, és örömmel fogadá őt.
Ó sì yára, ó sọ̀kalẹ̀, ó sì fi ayọ̀ gbà á.
7 És mikor ezt látták, mindnyájan zúgolódának, mondván hogy: Bűnös emberhez ment be szállásra.
Nígbà tí wọ́n sì rí i, gbogbo wọn ń kùn, wí pé, “Ó lọ bá ọkùnrin ẹlẹ́ṣẹ̀ náà ní àlejò.”
8 Zákeus pedig előállván, monda az Úrnak: Uram, ímé minden vagyonomnak felét a szegényeknek adom, és ha valakitől valamit patvarkodással elvettem, négy annyit adok helyébe.
Sakeu sì dìde, ó sì wí fún Olúwa pé, “Wò ó, Olúwa, ààbọ̀ ohun ìní mi ni mo fi fún tálákà; bí mo bá sì fi èké gba ohun kan lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, èmi san án padà ní ìlọ́po mẹ́rin!”
9 Monda pedig néki Jézus: Ma lett idvessége ennek a háznak! mivelhogy ő is Ábrahám fia.
Jesu sì wí fún un pé, “Lónìí ni ìgbàlà wọ ilé yìí, níwọ̀n bí òun pẹ̀lú ti jẹ́ ọmọ Abrahamu.
10 Mert azért jött az embernek Fia, hogy megkeresse és megtartsa, a mi elveszett.
Nítorí Ọmọ Ènìyàn dé láti wá àwọn tí ó nù kiri, àti láti gbà wọ́n là.”
11 És mikor azok ezeket hallották, folytatá és monda egy példázatot, mivelhogy közel vala Jeruzsálemhez, és azok azt gondolák, hogy azonnal megjelenik az Isten országa.
Nígbà tí wọ́n sì ń gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó sì tẹ̀síwájú láti pa òwe kan, nítorí tí ó súnmọ́ Jerusalẹmu, àti nítorí tí wọn ń rò pé, ìjọba Ọlọ́run yóò farahàn nísinsin yìí.
12 Monda azért: Egy nemes ember elméne messze tartományba, hogy országot vegyen magának, aztán visszatérjen.
Ó sì wí pé, “Ọkùnrin ọlọ́lá kan lọ sí ìlú òkèrè láti gba ìjọba kí ó sì padà.
13 Előszólítván azért tíz szolgáját, ada nékik tíz gírát, és monda nékik: Kereskedjetek, míg megjövök.
Ó sì pe àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ mẹ́wàá, ó fi owó mina mẹ́wàá fún wọn, ó sì wí fún wọn pé, ‘Ẹ máa ṣòwò títí èmi ó fi dé!’
14 Az ő alattvalói pedig gyűlölék őt, és követséget küldének utána, mondván: Nem akarjuk, hogy ő uralkodjék mi rajtunk.
“Ṣùgbọ́n àwọn ará ìlù rẹ̀ kórìíra rẹ̀, wọ́n sì rán ikọ̀ tẹ̀lé e, wí pé, ‘Àwa kò fẹ́ kí ọkùnrin yìí jẹ ọba lórí wa.’
15 És lőn, mikor megjött az ország vétele után, parancsolá, hogy az ő szolgáit, a kiknek a pénzt adta, hívják ő hozzá, hogy megtudja, ki mint kereskedett.
“Nígbà tí ó gba ìjọba tan, tí ó padà dé, ó pàṣẹ pé, kí a pe àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ wọ̀nyí tí òun ti fi owó fún wá sọ́dọ̀ rẹ̀, nítorí kí ó le mọ iye èrè tí olúkúlùkù ti jẹ nínú iṣẹ́ òwò wọn.
16 Eljöve pedig az első, mondván: Uram, a te gírád tíz gírát nyert.
“Èyí èkínní sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, owó mina rẹ jèrè owó mina mẹ́wàá sí i.’
17 Ő pedig monda néki: Jól vagyon jó szolgám; mivelhogy kevesen voltál hív, legyen birodalmad tíz városon.
“Olúwa rẹ̀ sì wí fún un pé, ‘O ṣeun, ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ rere! Nítorí tí ìwọ ṣe olóòtítọ́ ní ohun kínkínní, gba àṣẹ lórí ìlú mẹ́wàá.’
18 És jöve a második, mondván: Uram, a te gírád öt gírát nyert.
“Èyí èkejì sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, owó mina rẹ jèrè owó mina márùn.’
19 Monda pedig ennek is: Néked is legyen birodalmad öt városon.
“Olúwa rẹ sì wí fún un pẹ̀lú pé, ‘Ìwọ pẹ̀lú joyè ìlú márùn-ún!’
20 És jöve egy másik, mondván: Uram, imhol a te gírád, melyet egy keszkenőben eltéve tartottam;
“Òmíràn sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, wò ó owó mina rẹ tí ń bẹ lọ́wọ́ mi ni mo dì sínú aṣọ pélébé kan;
21 Mert féltem tőled, mivelhogy kemény ember vagy; elveszed a mit nem te tettél el, és aratod, a mit nem te vetettél.
nítorí mo bẹ̀rù rẹ, àti nítorí tí ìwọ ṣe òǹrorò ènìyàn, ìwọ a máa mú èyí tí ìwọ kò fi lélẹ̀, ìwọ a sì máa ká èyí tí ìwọ kò gbìn!’
22 Monda pedig annak: A te szádból ítéllek meg téged, gonosz szolga. Tudtad, hogy én kemény ember vagyok, ki elveszem, a mit nem én tettem el, és aratom, a mit nem én vetettem;
“Olúwa rẹ sì wí fún un pé, ‘Ní ẹnu ara rẹ náà ni èmi ó ṣe ìdájọ́ rẹ, ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ búburú, ìwọ mọ̀ pé òǹrorò ènìyàn ni mí, pé, èmi a máa mú èyí tí èmi kò fi lélẹ̀ èmi a sì máa ká èyí tí èmi kò gbìn.
23 Miért nem adtad azért az én pénzemet a pénzváltók asztalára, és én megjövén, kamatostól kaptam volna azt vissza?
Èéha sì ti ṣe tí ìwọ kò fi owó mi pamọ́ sí ilé ìfowópamọ́, pé nígbà tí mo bá dé, èmi ìbá ti béèrè rẹ̀ pẹ̀lú èlé?’
24 És az ott állóknak monda: Vegyétek el ettől a gírát, és adjátok annak, a kinek tíz gírája van.
“Ó sì wí fún àwọn tí ó dúró létí ibẹ̀ pé, ‘Ẹ gba owó mina náà lọ́wọ́ rẹ̀, kí ẹ sì fi í fún ẹni tí ó ní owó mina mẹ́wàá.’
25 És mondának néki: Uram, tíz gírája van!
“Wọ́n sì wí fún un pé, ‘Olúwa, ó ní owó mina mẹ́wàá.’
26 És ő monda: Mert mondom néktek, hogy mindenkinek, a kinek van, adatik; a kinek pedig nincs, még a mije van is, elvétetik tőle.
“Mo wí fún yín pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó ní, ni a ó fi fún, àti lọ́dọ̀ ẹni tí kò ní èyí tí ó ní pàápàá a ó gbà á lọ́wọ́ rẹ̀.
27 Sőt ennek felette amaz én ellenségeimet is, kik nem akarták, hogy én ő rajtok uralkodjam, hozzátok ide, és öljétek meg előttem!
Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá mi wọ̀nyí, tí kò fẹ́ kí èmi jẹ ọba lórí wọn ẹ mú wọn wá ìhín yìí, kí ẹ sì pa wọ́n níwájú mi!’”
28 És ezeket mondván, megy vala elől, felmenvén Jeruzsálembe.
Nígbà tí ó sì ti wí nǹkan wọ̀nyí tan, ó lọ síwájú, ó ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
29 És lőn, mikor közelgetett Béthfágéhoz és Bethániához, a hegyhez, mely Olajfák hegyének hívatik, elkülde kettőt az ő tanítványai közül,
Ó sì ṣe, nígbà tí ó súnmọ́ Betfage àti Betani ní òkè tí a ń pè ní òkè olifi, ó rán àwọn méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
30 Mondván: Menjetek el az átellenben levő faluba; melybe bemenvén, találtok egy megkötött vemhet, melyen soha egy ember sem ült: eloldván azt, hozzátok ide.
Wí pé, “Ẹ lọ sí ìletò tí ó kọjú sí yín; nígbà tí ẹ̀yin bá wọ̀ ọ́ lọ, ẹ̀yin ó rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan tí a so, tí ẹnikẹ́ni kò gùn rí, ẹ tú u, kí ẹ sì fà á wá.
31 És ha valaki kérdez titeket: Miért oldjátok el? ezt mondjátok annak: Mert az Úrnak szüksége van reá.
Bí ẹnikẹ́ni bá sì bi yín pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń tú u?’ Kí ẹ̀yin wí báyìí pé, ‘Olúwa ń fẹ́ lò ó.’”
32 És elmenvén a küldöttek, úgy találák, a mint nékik mondotta.
Àwọn tí a rán sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n, wọ́n sì bá a gẹ́gẹ́ bí ó ti wí fún wọn.
33 És mikor a vemhet eloldák, mondának nékik annak gazdái: Miért oldjátok el a vemhet?
Bí wọ́n sì ti ń tú ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà, àwọn Olúwa rẹ̀ bi wọ́n pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń tu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà?”
34 Ők pedig mondának: Az Úrnak szüksége van reá.
Wọ́n sì wí pé, “Olúwa fẹ́ lò ó.”
35 Elvivék azért azt Jézushoz: és az ő felsőruháikat a vemhére vetvén, Jézust reá helyhezteték.
Wọ́n sì fà á tọ Jesu wá, wọ́n sì tẹ́ aṣọ sí ẹ̀yìn ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà, wọ́n sì gbé Jesu kà á.
36 És mikor ő méne, az ő felsőruháikat az útra teríték.
Bí ó sì ti ń lọ wọ́n tẹ́ aṣọ wọn sí ọ̀nà.
37 Mikor pedig immár közelgete az Olajfák hegyének lejtőjéhez, a tanítványok egész sokasága örvendezve kezdé dicsérni az Istent fenszóval mindazokért a csodákért, a melyeket láttak;
Bí ó sì ti súnmọ́ etí ibẹ̀ ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè olifi, gbogbo àwọn ọmọ-ẹ̀yìn bẹ̀rẹ̀ sí í yọ̀, wọ́n sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run, nítorí iṣẹ́ ńlá gbogbo tí wọ́n ti rí,
38 Mondván: Áldott a Király, ki jő az Úrnak nevében! Békesség a mennyben, és dicsőség a magasságban!
wí pé, “Olùbùkún ni ọba tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa!” “Àlàáfíà ní ọ̀run, àti ògo ni òkè ọ̀run!”
39 És némelyek a farizeusok közül a sokaságból mondának néki: Mester, dorgáld meg a te tanítványaidat!
Àwọn kan nínú àwọn Farisi nínú àwùjọ náà sì wí fún un pé, “Olùkọ́ bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ wí.”
40 És ő felelvén, monda nékik: Mondom néktek, hogyha ezek elhallgatnak, a kövek fognak kiáltani.
Ó sì dá wọn lóhùn, ó wí fún wọn pé, “Mo wí fún yín, bí àwọn wọ̀nyí bá pa ẹnu wọn mọ́, àwọn òkúta yóò kígbe sókè.”
41 És mikor közeledett, látván a várost, síra azon.
Nígbà tí ó sì súnmọ́ etílé, ó síjú wo ìlú náà, ó sọkún sí i lórí,
42 Mondván: Vajha megismerted volna te is, csak e te mostani napodon is, a mik néked a te békességedre valók! de most elrejtettek a te szemeid elől.
Ó ń wí pé, “Ìbá ṣe pé ìwọ mọ̀, lónìí yìí, àní ìwọ, ohun tí í ṣe tí àlàáfíà rẹ! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n pamọ́ kúrò lójú rẹ.
43 Mert jőnek reád napok, mikor a te ellenségeid te körülted palánkot építenek, és körülvesznek téged, és mindenfelől megszorítanak téged.
Nítorí ọjọ́ ń bọ̀ fún ọ, tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò mọ odi bèbè yí ọ ká, àní tí wọn yóò sì yí ọ ká, wọn ó sì ká ọ mọ́ níhà gbogbo.
44 És a földre tipornak téged, és a te fiaidat te benned; és nem hagynak te benned követ kövön; mivelhogy nem ismerted meg a te meglátogatásodnak idejét.
Wọn ó sì wó ọ palẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú rẹ; wọn kì yóò sì fi òkúta kan sílẹ̀ lórí ara wọn; nítorí ìwọ kò mọ ọjọ́ ìbẹ̀wò rẹ.”
45 És bemenvén a templomba, kezdé kiűzni azokat, a kik adnak és vesznek vala abban,
Ó sì wọ inú tẹmpili lọ, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí lé àwọn tí ń tà nínú rẹ̀ sóde;
46 Mondván nékik: Meg van írva: Az én házam imádságnak háza; ti pedig azt latroknak barlangjává tettétek.
Ó sì wí fún wọn pé, “A ti kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ilé mi yóò jẹ́ ilé àdúrà?’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti sọ ọ́ di ihò àwọn ọlọ́ṣà.”
47 És tanít vala minden nap a templomban. A főpapok pedig és az írástudók és a nép előkelői igyekeznek vala őt elveszteni:
Ó sì ń kọ́ni lójoojúmọ́ ní tẹmpili, ṣùgbọ́n àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, àti àwọn olórí àwọn ènìyàn ń wá ọ̀nà láti pa á.
48 És nem találták el, mit cselekedjenek; mert az egész nép ő rajta függ vala, reá hallgatván.
Wọn kò sì rí nǹkan kan tí wọn ìbá ṣe; nítorí gbogbo ènìyàn ṣù mọ́ ọn láti gbọ́rọ̀ rẹ̀.

< Lukács 19 >