< Birák 11 >
1 A Gileádból való Jefte pedig nagy hős volt, és egy parázna asszonynak volt a fia, s Jeftét Gileád nemzette.
Jefta ará Gileadi jẹ́ akọni jagunjagun. Gileadi ni baba rẹ̀; ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ jẹ́ panṣágà.
2 De mikor Gileádnak a felesége is szült néki fiakat, és megnőttek az ő feleségének fiai: akkor elűzték Jeftét és azt mondták néki: Nem fogsz örökösödni atyánknak házában, mert más asszonynak vagy a fia.
Ìyàwó Gileadi sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un, nígbà tí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí dàgbà, wọ́n rán Jefta jáde kúrò nílé, wọ́n wí pé, “Ìwọ kì yóò ní ogún kankan ní ìdílé wa, nítorí pé ìwọ jẹ́ ọmọ obìnrin mìíràn.”
3 És elfutott Jefte az ő atyjafiai elől, és Tób földén telepedett meg, és henyélő emberek gyűltek össze Jefte körül, és együtt portyáztak.
Jefta sì sá kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì pàgọ́ sí ilẹ̀ Tobu, ó sì ń gbé níbẹ̀, níbẹ̀ ni àwọn ènìyàn kan ti ń tẹ òfin lójú parapọ̀ láti máa tẹ̀lé e kiri.
4 És történt napok mulva, hogy az Ammon fiai harczba keveredtek Izráellel.
Ní àsìkò kan, nígbà tí àwọn ará Ammoni dìde ogun sí àwọn Israẹli,
5 És lőn, hogy a mint harczolni kezdtek az Ammon fiai Izráellel, Gileád vénei elmentek, hogy visszahozzák Jeftét a Tób földéről.
Ó sì ṣe nígbà tí àwọn Ammoni bá Israẹli jagun, àwọn àgbàgbà Gileadi tọ Jefta lọ láti pè é wá láti ilẹ̀ Tobu.
6 És mondának Jeftének: Jer el, és légy nékünk fejedelmünk, és harczoljunk az Ammon fiai ellen.
Wọ́n wí fún Jefta wí pé, “Wá kí o sì jẹ́ olórí ogun wa kí a lè kọjú ogun sí àwọn ará Ammoni.”
7 Jefte pedig monda Gileád véneinek: Avagy nem ti vagytok-é, a kik engem meggyűlöltetek, és kiűztetek atyámnak házából? És miért jöttetek most hozzám a ti nyomorúságtoknak idején?
Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Ṣé kì í ṣe pé ẹ kórìíra mi tí ẹ sì lé mi kúrò ní ilé baba mi? Kí ló dé tí ẹ fi tọ̀ mí wá báyìí nígbà tí ẹ wà nínú wàhálà?”
8 És mondának Gileád vénei Jeftének: Azért fordultunk most hozzád, hogy jőjj el velünk, és hadakozzál az Ammon fiai ellen, és légy mi nékünk fejünk, és Gileád minden lakosinak.
Àwọn àgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Nítorí rẹ̀ ni àwa fi yípadà sí ọ báyìí: tẹ̀lé wa, kí a lè dojú ìjà kọ àwọn ará Ammoni, ìwọ yóò sì jẹ olórí wa àti gbogbo àwa tí ń gbé ní Gileadi.”
9 És monda Jefte Gileád véneinek: Ha visszavisztek engem, hogy hadakozzam az Ammon fiai ellen, és kezembe adja őket az Úr: igazán fejetekké leszek?
Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Bí ẹ̀yin bá mú mi padà láti bá àwọn ará Ammoni jà àti tí Olúwa bá fi wọ́n lé mi lọ́wọ́: ṣe èmi yóò jẹ́ olórí yín nítòótọ́?”
10 Akkor mondának Gileád vénei Jeftének: Az Úr a tanúnk, ha a te beszéded szerint nem cselekeszünk!
Àwọn àgbàgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Àwa fi Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí: àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá wí.”
11 És elment Jefte Gileád véneivel, és a nép a maga fejévé és fejedelmévé tette őt. És megmondá Jefte minden beszédit az Úr előtt Mispában.
Jefta sì tẹ̀lé àwọn àgbàgbà Gileadi lọ, àwọn ènìyàn náà sì fi ṣe olórí àti ọ̀gágun wọn. Jefta sì tún sọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ níwájú Olúwa ní Mispa.
12 És követeket küldött Jefte az Ammon fiainak királyához, ezt izenvén: Mi dolgom van nékem veled, hogy hozzám jöttél, hogy hadakozzál az én földem ellen?
Jefta sì rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba àwọn ará Ammoni pé, “Kí ni ẹ̀sùn tí o ní sí wa láti fi kàn wá tí ìwọ fi dojú ìjà kọ ilẹ̀ wa?”
13 És monda az Ammon fiainak királya Jefte követeinek: Mert elvette Izráel az én földemet, mikor Égyiptomból feljött, az Arnontól fogva Jabbókig és a Jordánig, most te add azokat vissza békességgel.
Ọba àwọn Ammoni dá àwọn oníṣẹ́ Jefta lóhùn pé, “Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli jáde ti Ejibiti wá. Wọ́n gba ilẹ̀ mi láti Arnoni dé Jabbok, àní dé Jordani, nítorí náà dá wọn padà lọ ní àlàáfíà àti ní pẹ̀lẹ́ kùtù.”
14 Ismét külde pedig Jefte követeket az Ammon fiainak királyához;
Jefta sì tún ránṣẹ́ padà sí ọba àwọn ará Ammoni
15 És monda néki: Ezt izeni Jefte: Nem vette el Izráel sem a Moáb földét, sem az Ammon fiainak földét;
ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Jefta wí: àwọn ọmọ Israẹli kò gba ilẹ̀ Moabu tàbí ilẹ̀ àwọn ará Ammoni.
16 Mert mikor kijött Égyiptomból, a pusztában bolyongott Izráel egész a Veres tengerig, és mikor Kádesbe ért,
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde kúrò ní Ejibiti àwọn ọmọ Israẹli la aginjù kọjá lọ sí ọ̀nà Òkun Pupa wọ́n sì lọ sí Kadeṣi.
17 Követeket küldött Izráel Edom királyához, mondván: Hadd menjek át, kérlek, országodon; de Edom királya nem hallgatta meg. Majd Moáb királyához is küldött; de ez sem engedé, és így Izráel ott maradt Kádesben.
Nígbà náà Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba Edomu pé, ‘Gbà fún wa láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kọjá,’ ṣùgbọ́n ọba Edomu kò fetí sí wọn. Wọ́n tún ránṣẹ́ sí ọba Moabu bákan náà òun náà kọ̀. Nítorí náà Israẹli dúró sí Kadeṣi.
18 És mikor tovább vándorolt a pusztában, megkerülte Edom földét és Moáb földét, és napkelet felől érkezett a Moáb földéhez, és ott táborozott túl az Arnonon; de Moáb határába nem ment be, mert az Arnon Moáb határa.
“Wọ́n rin aginjù kọjá, wọ́n pẹ́ àwọn ilẹ̀ Edomu àti ti Moabu sílẹ̀, nígbà tí wọ́n gba apá ìlà-oòrùn Moabu, wọ́n sì tẹ̀dó sí apá kejì Arnoni. Wọn kò wọ ilẹ̀ Moabu, nítorí pé ààlà rẹ̀ ni Arnoni wà.
19 Ekkor követeket küldött Izráel Szihonhoz, az Emoreusok királyához, Hesbon királyához, és monda néki Izráel: Hadd menjek át, kérlek, országodon az én helyemre.
“Nígbà náà ni Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ń ṣe àkóso ní Heṣboni, wọ́n sì wí fún un pé, ‘Jẹ́ kí a la ilẹ̀ rẹ kọjá lọ sí ibùgbé wa.’
20 De Szihon nem hitt Izráelnek, hogy átvonul az ő határán, hanem összegyűjtötte Szihon az ő egész népét, és táborba szállott Jahásban, és harczolt az Izráel ellen.
Ṣùgbọ́n Sihoni kò gba Israẹli gbọ́ (kò fọkàn tán an) láti jẹ́ kí ó kọjá. Ó kó gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ jọ, ó sì tẹ̀dó sí Jahisa láti bá Israẹli jagun.
21 Az Úr, az Izráel Istene pedig Szihont és egész népét Izráel kezébe adta, és megverték őket, és elfoglalta Izráel az Emoreusoknak, ama föld lakóinak, egész országát.
“Olúwa Ọlọ́run Israẹli sì fi Sihoni àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́, wọ́n sì ṣẹ́gun wọn. Israẹli sì gba gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Amori tí wọ́n ń gbé ní agbègbè náà,
22 És birtokába vette az Emoreusok egész határát, az Arnontól fogva Jabbókig, és a pusztától a Jordánig.
wọ́n gbà gbogbo agbègbè àwọn ará Amori, láti Arnoni tí ó fi dé Jabbok, àti láti aginjù dé Jordani.
23 És mikor az Úr, az Izráel Istene maga űzte ki az Emoreusokat az ő népe, az Izráel elől, most te akarnád ezt elfoglalni?
“Wàyí o, nígbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti lé àwọn ará Amori kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀; Israẹli, ẹ̀tọ́ wo ni ẹ ní láti gba ilẹ̀ náà?
24 Hát nem úgy van-é, hogy a mit bírnod adott néked Kámos, a te istened, azt bírod? Mi meg mindazoknak örökségét bírjuk, a kiket az Úr, a mi Istenünk űzött ki mi előlünk.
Ǹjẹ́ ìwọ kì yóò ha gba èyí tí Kemoṣi òrìṣà rẹ fi fún ọ? Bákan náà àwa yóò gba èyíkéyìí tí Olúwa Ọlọ́run wa fi fún wa.
25 És most vajjon mennyivel vagy te különb Báláknál, Czippor fiánál, Moáb királyánál? Avagy versengett-é ez az Izráellel, és hadakozott-é valaha ellenük?
Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu lọ? Ǹjẹ́ òun ha ṣe gbólóhùn asọ̀ pẹ̀lú Israẹli bí? Tàbí òun dojú ìjà kọ wọ́n rí bí?
26 Míg Izráel Hesbonban és annak mezővárosaiban, Aroerben és ennek mezővárosaiban és az Arnon mellett való összes városokban háromszáz esztendőn át lakott: miért nem foglaltátok el abban az időben?
Fún ọ̀ọ́dúnrún ọdún ni Israẹli fi ṣe àtìpó ní Heṣboni, Aroeri àti àwọn ìgbèríko àti àwọn ìlú tí ó yí Arnoni ká. Èéṣe tí ìwọ kò fi gbà wọ́n padà ní àsìkò náà?
27 Én nem vétettem te ellened, hanem te cselekszel velem gonoszt, hogy harczolsz ellenem. Az Úr, a biró, tegyen ma ítéletet az Izráel és az Ammon fiai között.
Èmi kọ́ ni ó ṣẹ̀ ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ ni ó ṣẹ̀ mí nípa kíkógun tọ̀ mí wá. Jẹ́ kí Olúwa olùdájọ́, ṣe ìdájọ́ lónìí láàrín àwọn ọmọ Israẹli àti àwọn ará Ammoni.”
28 De az Ammon fiainak királya nem hallgatott Jefte szavaira, a melyeket izent néki.
Ṣùgbọ́n ọba àwọn Ammoni kò fetí sí iṣẹ́ tí Jefta rán sí i.
29 Jeftén pedig lőn az Úrnak lelke, és általméne Gileádon és Manassén, és általméne Gileád Mispén, és Gileád Mispéből felvonult az Ammon fiai ellen.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jefta òun sì la Gileadi àti Manase kọjá. Ó la Mispa àti Gileadi kọjá láti ibẹ̀, ó tẹ̀síwájú láti bá àwọn ará Ammoni jà.
30 És fogadást tőn Jefte az Úrnak, és monda: Ha mindenestől kezembe adod az Ammon fiait:
Jefta sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí ìwọ bá fi àwọn ará Ammoni lé mi lọ́wọ́,
31 Akkor valami kijövénd az én házamnak ajtaján előmbe, mikor békével visszatérek az Ammon fiaitól, legyen az Úré, és megáldozom azt egészen égőáldozatul.
yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ó bá jáde láti ẹnu-ọ̀nà ilé mi láti wá pàdé mi, nígbà tí èmi bá ń padà bọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ammoni ní àlàáfíà, yóò jẹ́ ti Olúwa, èmi yóò sì fi rú ẹbọ bí ọrẹ ẹbọ sísun.”
32 És kivonult Jefte az Ammon fiai ellen, hogy hadakozzék velök, és kezébe adá néki azokat az Úr.
Jefta sì jáde lọ láti bá àwọn ará Ammoni jagun, Olúwa sì fi wọ́n lé e lọ́wọ́.
33 És veré őket Aroertől fogva mindaddig, míg mennél Minnithbe, húsz városon át, és egész Abel-Keraminig nagy vérontással, és az Ammon fiai megaláztattak az Izráel fiai előtt.
Òun sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa wọ́n ní à pa tán láti Aroeri títí dé agbègbè Minniti, ó jẹ́ ogún ìlú, títí dé Abeli-Keramimu. Báyìí ni Israẹli ti ṣẹ́gun àwọn ará Ammoni.
34 Mikor pedig méne Jefte Mispába az ő házához: ímé az ő leánya jött ki eleibe dobokkal és tánczoló sereggel; ez volt az ő egyetlenegyje, mert nem volt néki kivülötte sem fia, sem leánya.
Nígbà tí Jefta padà sí ilé rẹ̀ ní Mispa, wò ó, ọmọ rẹ̀ obìnrin ń jáde bọ̀ wá pàdé rẹ̀ pẹ̀lú timbrili àti ijó. Òun ni ọmọ kan ṣoṣo tí ó ní: kò ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn yàtọ̀ sí òun nìkan.
35 És mikor meglátta őt, megszaggatá ruháit, és monda: Óh leányom, de megszomorítottál és megháborítottál engem! Mert én fogadást tettem az Úrnak, és nem vonhatom vissza.
Ní ìgbà tí ó rí i ó fa aṣọ rẹ̀ ya ní ìbànújẹ́, ó sì ké wí pé, “Háà! Ọ̀dọ́mọbìnrin mi, ìwọ fún mi ní ìbànújẹ́ ọkàn ìwọ sì rẹ̀ mí sílẹ̀ gidigidi, nítorí pé èmi ti ya ẹnu mi sí Olúwa ní ẹ̀jẹ́, èmi kò sì le sẹ́ ẹ̀jẹ́ mi.”
36 Az pedig monda néki: Atyám, ha fogadást tettél az Úrnak, úgy cselekedjél velem, a mint fogadtad, miután az Úr megadta az ellenségiden: az Ammon fiain való bosszút.
Ọmọ náà sì dáhùn pé, “Baba mi bí ìwọ bá ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa, ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ, ní báyìí tí Olúwa ti gba ẹ̀san fún ọ lára àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ará Ammoni.
37 És monda az ő atyjának: Csak azt az egyet tedd meg nékem; ereszsz el engem két hónapra, hadd menjek el és vonulhassak félre a hegyekre, hogy sírjak szűzességemen leánybarátaimmal.
Ṣùgbọ́n yọ̀ǹda ìbéèrè kan yìí fún mi, gbà mí láààyè oṣù méjì láti rìn ká orí àwọn òkè, kí n sọkún pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ mi torí mo jẹ́ wúńdíá tí n kò sì ní lè ṣe ìgbéyàwó.”
38 És ő monda: Menj el. És elbocsátá őt két hónapra. Az pedig elment és az ő leánybarátai, és siratta az ő szűzességét a hegyeken.
Jefta dá lóhùn pé, “Ìwọ lè lọ.” Ó sì gbà á láààyè láti lọ fún oṣù méjì. Òun àti àwọn ọmọbìnrin yòókù lọ sí orí àwọn òkè, wọ́n sọkún nítorí pé kì yóò lè ṣe ìgbéyàwó.
39 És a két hónap elteltével visszatért atyjához, és betöltötte az ő felőle való fogadást, a melyet tett, és ő soha nem ismert férfiút. És szokássá lett Izráelben,
Lẹ́yìn oṣù méjì náà, ó padà tọ baba rẹ̀ wá òun sì ṣe sí i bí ẹ̀jẹ́ tí ó ti jẹ́. Ọmọ náà sì jẹ́ wúńdíá tí kò mọ ọkùnrin rí. Èyí sì bẹ̀rẹ̀ àṣà kan ní Israẹli
40 Hogy esztendőnként elmentek az Izráel leányai, hogy dicsőítsék a gileádbeli Jefte leányát esztendőnként négy napon át.
wí pé ní ọjọ́ mẹ́rin láàrín ọdún àwọn obìnrin Israẹli a máa lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti ṣe ìrántí ọmọbìnrin Jefta ti Gileadi.