< Józsué 1 >

1 És lőn Mózesnek, az Úr szolgájának halála után, szóla az Úr Józsuénak, a Nún fiának, Mózes szolgájának, mondván:
Lẹ́yìn ikú u Mose ìránṣẹ́ Olúwa, Olúwa sọ fún Joṣua ọmọ Nuni, olùrànlọ́wọ́ ọ Mose,
2 Mózes, az én szolgám meghalt; most azért kelj fel, menj át ezen a Jordánon, te és mind ez a nép arra a földre, a melyet én adok nékik, az Izráel fiainak.
“Mose ìránṣẹ́ mi ti kú. Nísinsin yìí, ìwọ àti gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹ múra láti kọjá odò Jordani lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ó fi fún wọn fún àwọn ará Israẹli.
3 Minden helyet, a melyet talpatok érint, néktek adtam, a miképen szólottam Mózesnek.
Èmi yóò fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe ìlérí fún Mose.
4 A pusztától és a Libánontól fogva a nagy folyóvízig, az Eufrates folyóvízig, a Khitteusoknak egész földe és a nagy tengerig napnyugat felé lesz a ti határotok.
Ilẹ̀ ẹ yín yóò fẹ̀ láti aginjù Lebanoni, àti láti odò ńlá, ti Eufurate—gbogbo orílẹ̀-èdè Hiti títí ó fi dé Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
5 Meg nem áll senki előtted életednek minden idejében; a miképen Mózessel vele voltam, teveled is veled leszek; el nem hagylak téged, sem el nem maradok tőled.
Kì yóò sí ẹnikẹ́ni tí yóò le è dúró níwájú rẹ ní ọjọ́ ayé è rẹ gbogbo. Bí mo ti wà pẹ̀lú u Mose, bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, Èmi kì yóò fi ọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Èmi kì yóò kọ̀ ọ́.
6 Légy bátor és erős, mert te teszed majd e népet annak a földnek örökösévé, a mely felől megesküdtem az ő atyáiknak, hogy nékik adom azt.
“Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le, nítorí ìwọ ni yóò ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, láti lè jogún ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fi fún wọn.
7 Csak légy bátor és igen erős, hogy vigyázz és mindent ama törvény szerint cselekedjél, a melyet Mózes, az én szolgám szabott elődbe; attól se jobbra, se balra ne hajolj, hogy jó szerencsés lehess mindenben, a miben jársz!
Jẹ́ alágbára, kí o sì mú àyà le gidigidi. Kí o sì ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin tí Mose ìránṣẹ́ mi fún ọ mọ́, má ṣe yà kúrò nínú u rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì, kí ìwọ kí ó lè ṣe rere níbikíbi tí ìwọ bá ń lọ.
8 El ne távozzék e törvénynek könyve a te szádtól, hanem gondolkodjál arról éjjel és nappal, hogy vigyázz és mindent úgy cselekedjél, a mint írva van abban, mert akkor leszel jó szerencsés a te utaidon és akkor boldogulsz.
Má ṣe jẹ́ kí ìwé òfin yìí kúrò ní ẹnu rẹ, máa ṣe àṣàrò nínú u rẹ̀ ní ọ̀sán àti ní òru, kí ìwọ kí ó lè ṣọ́ra láti ṣe gbogbo nǹkan tí a kọ sí inú u rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dára fún ọ, ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí.
9 Avagy nem parancsoltam-é meg néked: légy bátor és erős? Ne félj, és ne rettegj, mert veled lesz az Úr, a te Istened mindenben, a miben jársz.
Èmi kò ha ti pàṣẹ fún ọ bí? Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le. Má ṣe bẹ̀rù, má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì, nítorí pé Olúwa à rẹ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
10 Parancsola azért Józsué a nép előljáróinak, mondván:
Báyìí ni Joṣua pàṣẹ fún olórí àwọn ènìyàn rẹ̀,
11 Menjetek által a táboron, és parancsoljátok meg a népnek, mondván: Készítsetek magatoknak útravalót, mert harmadnap mulva átmentek ti ezen a Jordánon, hogy bemenjetek és bírjátok azt a földet, a melyet az Úr, a ti Istenetek ád néktek birtokul.
“Ẹ la ibùdó já, kí ẹ sì sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Ẹ pèsè oúnjẹ yín sílẹ̀. Ní ìwòyí ọ̀túnla, ẹ̀yin yóò la Jordani yìí kọjá, láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín láti ní.’”
12 A Rúben és Gád nemzetségének pedig, és a Manassé nemzetség felének szóla Józsué, mondván:
Ṣùgbọ́n Joṣua sọ fún àwọn ará a Reubeni, àwọn ará Gadi àti fún ìdajì ẹ̀yà Manase pé,
13 Emlékezzetek meg a dologról, a mit megparancsolt néktek Mózes, az Úrnak szolgája, mondván: Az Úr, a ti Istenetek megnyugtatott titeket, és néktek adta ezt a földet.
“Rántí àṣẹ tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pa fún yín: ‘Olúwa Ọlọ́run yín á fún yin ní ìsinmi, òun yóò sì fún un yín ní ilẹ̀ yìí.’
14 Feleségeitek, gyermekeitek és barmaitok maradjanak e földön, a melyet adott néktek Mózes a Jordánon túl; ti pedig fegyveres kézzel menjetek át atyátokfiai előtt, mindnyájan, a kik közületek erős vitézek, és segéljétek meg őket;
Àwọn ìyàwó yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ẹran ọ̀sìn yín lè dúró ní ilẹ̀ tí Mose fún un yin ní ìlà-oòrùn Jordani; ṣùgbọ́n gbogbo àwọn jagunjagun un yín, pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín. Ẹ̀yin yóò sì rán àwọn arákùnrin yín lọ́wọ́
15 A míg megnyugosztja az Úr a ti atyátokfiait is, mint titeket, és bírják ők is a földet, a melyet az Úr, a ti Istenetek ád nékik: akkor aztán térjetek vissza a ti örökségtek földére és bírjátok azt, a melyet Mózes, az Úr szolgája adott néktek a Jordánon túl, napkelet felől.
títí Olúwa yóò fi fún wọn ní ìsinmi, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún un yín, àti títí tí àwọn pẹ̀lú yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún wọn. Lẹ́yìn náà, ẹ̀yin lè padà sí ilẹ̀ ìní in yín, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún un yin ní agbègbè ìlà-oòrùn ti Jordani.”
16 Azok pedig felelének Józsuénak, mondván: Mindent megcselekszünk, a mit parancsoltál nékünk, és a hová küldesz minket, oda megyünk.
Nígbà náà ni wọ́n dá Joṣua lóhùn pé, “Ohunkóhun tí ìwọ pàṣẹ fún wa ni àwa yóò ṣe, ibikíbi tí ìwọ bá rán wa ni àwa yóò lọ.
17 A mint Mózesre hallgattunk, épen úgy hallgatunk majd te reád, csak legyen veled az Úr, a te Istened, a miképen vele volt Mózessel.
Gẹ́gẹ́ bí àwa ti gbọ́rọ̀ sí Mose nínú ohun gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò máa gbọ́ tìrẹ. Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà pẹ̀lú u Mose.
18 Mindenki, a ki ellene szegül a te szódnak, és nem hallgat a te beszédedre mindabban, a mit parancsolsz néki, megölettessék. Csak bátor légy és erős!
Ẹnikẹ́ni tí ó bá tàpá sí ọ̀rọ̀ rẹ, tí kò sì ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ nínú ohun gbogbo tí ìwọ yóò pàṣẹ fún wọn, pípa ni a ó pa á. Kí ìwọ sá à ṣe gírí, kí ó sì mú àyà le!”

< Józsué 1 >