< János 8 >
1 Jézus pedig elméne az Olajfák hegyére.
Jesu sì lọ sí orí òkè olifi.
2 Jó reggel azonban ismét ott vala a templomban, és az egész nép hozzá méne; és leülvén, tanítja vala őket.
Ó sì tún padà wá sí tẹmpili ní kùtùkùtù òwúrọ̀, gbogbo ènìyàn sì wá sọ́dọ̀ rẹ̀; ó sì jókòó, ó ń kọ́ wọn.
3 Az írástudók és a farizeusok pedig egy asszonyt vivének hozzá, a kit házasságtörésen kaptak vala, és a középre állítván azt,
Àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi sì mú obìnrin kan wá sọ́dọ̀ rẹ̀, tí a mú nínú ṣíṣe panṣágà; wọ́n sì mú un dúró láàrín.
4 Mondának néki: Mester, ez az asszony tetten kapatott, mint házasságtörő.
Wọ́n sì wí fún un pé, “Olùkọ́, a mú obìnrin yìí nínú ìṣe panṣágà.
5 A törvényben pedig megparancsolta nékünk Mózes, hogy az ilyenek köveztessenek meg: te azért mit mondasz?
Ǹjẹ́ nínú òfin, Mose pàṣẹ fún wa láti sọ irú àwọn obìnrin bẹ́ẹ̀ ní òkúta, ṣùgbọ́n ìwọ ha ti wí?”
6 Ezt pedig azért mondák, hogy megkísértsék őt, hogy legyen őt mivel vádolniok. Jézus pedig lehajolván, az ujjával ír vala a földre.
Èyí ni wọ́n wí, láti dán án wò, kí wọn ba à lè rí ẹ̀sùn kan kà sí i lọ́rùn. Ṣùgbọ́n Jesu bẹ̀rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ń fi ìka rẹ̀ kọ̀wé ní ilẹ̀.
7 De mikor szorgalmazva kérdezék őt, felegyenesedve monda nékik: A ki közületek nem bűnös, az vesse rá először a követ.
Nígbà tí wọ́n ń bi í léèrè lemọ́lemọ́, ó gbe orí rẹ sókè, ó sì wí fún wọn pé, “Jẹ́ kí ẹni tí ó wà láìní ẹ̀ṣẹ̀ nínú yín kọ́kọ́ sọ òkúta lù ú.”
8 És újra lehajolván, írt vala a földre.
Ó sì tún bẹ̀rẹ̀ sílẹ̀, ó ń kọ̀wé ní ilẹ̀.
9 Azok pedig ezt hallván és a lelkiismeret által vádoltatván, egymásután kimenének a vénektől kezdve mind az utolsóig; és egyedül Jézus maradt vala és az asszony a középen állva.
Nígbà tí wọ́n gbọ́ èyí, wọ́n sì jáde lọ lọ́kọ̀ọ̀kan, bẹ̀rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn àgbà títí dé àwọn tí ó kẹ́yìn; a sì fi Jesu nìkan sílẹ̀, àti obìnrin náà láàrín, níbi tí ó wà.
10 Mikor pedig Jézus felegyenesedék és senkit sem láta az asszonyon kívül, monda néki: Asszony, hol vannak azok a te vádlóid? Senki sem kárhoztatott-é téged?
Jesu sì dìde, ó sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, àwọn olùfisùn rẹ dà? Kò sí ẹnìkan tí ó dá ọ lẹ́bi?”
11 Az pedig monda: Senki, Uram! Jézus pedig monda néki: Én sem kárhoztatlak: eredj el és többé ne vétkezzél!
Ó wí pé, “Kò sí ẹnìkan, Olúwa.” Jesu wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni èmi náà kò dá ọ lẹ́bi, máa lọ, láti ìgbà yìí lọ, má dẹ́ṣẹ̀ mọ́.”
12 Ismét szóla azért hozzájok Jézus, mondván: Én vagyok a világ világossága: a ki engem követ, nem járhat a sötétségben, hanem övé lesz az életnek világossága.
Jesu sì tún sọ fún wọn pé, “Èmi ni ìmọ́lẹ̀ ayé, ẹni tí ó bá tọ̀ mí lẹ́yìn kì yóò rìn nínú òkùnkùn, ṣùgbọ́n yóò ní ìmọ́lẹ̀ ìyè.”
13 Mondának azért néki a farizeusok: Te magadról teszel bizonyságot; a te bizonyságtételed nem igaz.
Nítorí náà àwọn Farisi wí fún un pé, “Ìwọ ń jẹ́rìí ara rẹ; ẹ̀rí rẹ kì í ṣe òtítọ́.”
14 Felele Jézus és monda nékik: Ha magam teszek is bizonyságot magamról, az én bizonyságtételem igaz; mert tudom honnan jöttem és hová megyek; ti pedig nem tudjátok honnan jövök és hová megyek.
Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Bí mo tilẹ̀ ń jẹ́rìí fún ara mi, òtítọ́ ni ẹ̀rí mi: nítorí tí mo mọ ibi tí mo ti wá, mo sì mọ ibi tí mo ń lọ; ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò lè mọ ibi tí mo ti wá, àti ibi tí mo ń lọ.
15 Ti test szerint ítéltek, én nem ítélek senkit.
Ẹ̀yin ń ṣe ìdájọ́ nípa ti ara; èmi kò ṣe ìdájọ́ ẹnikẹ́ni.
16 De ha ítélek is én, az én ítéletem igaz; mert én nem egyedül vagyok, hanem én és az Atya, a ki küldött engem.
Ṣùgbọ́n bí èmi bá sì ṣe ìdájọ́, òtítọ́ ni, nítorí èmi nìkan kọ́, ṣùgbọ́n èmi àti Baba tí ó rán mi.
17 A ti törvényetekben is meg van pedig írva, hogy két ember bizonyságtétele igaz.
A sì kọ ọ́ pẹ̀lú nínú òfin pé, òtítọ́ ni ẹ̀rí ènìyàn méjì.
18 Én vagyok a ki bizonyságot teszek magamról, és bizonyságot tesz rólam az Atya, a ki küldött engem.
Èmi ni ẹni tí ń jẹ́rìí ara mi, Baba tí ó rán mi sì ń jẹ́rìí mi.”
19 Mondának azért néki: Hol van a te Atyád? Felele Jézus: Sem engem nem ismertek, sem az én Atyámat; ha engem ismernétek, az én Atyámat is ismernétek.
Nítorí náà wọ́n wí fún un pé, “Níbo ni Baba rẹ wà?” Jesu dáhùn pé, “Ẹ̀yin kò mọ̀ mí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò mọ Baba mi, ìbá ṣe pé ẹ̀yin mọ̀ mí, ẹ̀yin ìbá sì ti mọ Baba mi pẹ̀lú.”
20 Ezeket a beszédeket mondá Jézus a kincstartó helyen, a mikor tanít vala a templomban; és senki sem fogta meg őt, mert még nem jött el az ő órája.
Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni Jesu sọ níbi ìṣúra, bí ó ti ń kọ́ni ní tẹmpili, ẹnikẹ́ni kò sì mú un; nítorí wákàtí rẹ̀ kò tí ì dé.
21 Ismét monda azért nékik Jézus: Én elmegyek, és kerestek majd engem, és a ti bűneitekben fogtok meghalni: a hová én megyek, ti nem jöhettek oda.
Nítorí náà ó tún wí fún wọn pé, “Èmi ń lọ, ẹ̀yin yóò sì wá mi, ẹ ó sì kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, ibi tí èmi gbé ń lọ, ẹ̀yin kì yóò lè wá.”
22 Mondának azért a zsidók: Avagy megöli-é magát, hogy azt mondja: A hová én megyek, ti nem jöhettek oda?
Nítorí náà àwọn Júù wí pé, “Òun ó ha pa ara rẹ̀ bí? Nítorí tí ó wí pé, ‘Ibi tí èmi gbé ń lọ, ẹ̀yin kì yóò lè wá’?”
23 És monda nékik: Ti innét alól valók vagytok, én onnét felül való vagyok; ti e világból valók vagytok, én nem vagyok e világból való.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ìsàlẹ̀ wá; èmi ti òkè wá; ẹ̀yin jẹ́ ti ayé yìí; èmi kì í ṣe ti ayé yìí.
24 Azért mondám néktek, hogy a ti bűneitekben haltok meg: mert ha nem hiszitek, hogy én vagyok, meghaltok a ti bűneitekben.
Nítorí náà ni mo ṣe wí fún yín pé, ẹ ó kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, nítorí bí kò ṣe pé ẹ bá gbàgbọ́ pé èmi ni, ẹ ó kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín.”
25 Mondának azért néki: Ki vagy te? És monda nékik Jézus: A mit eleitől fogva mondok is néktek.
Nítorí náà wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ jẹ́?” Jesu sì wí fún un pé, “Èmi ni èyí tí mo ti wí fún yín ní àtètèkọ́ṣe.
26 Sok beszélni és ítélni valóm van felőletek: de igaz az, a ki küldött engem; és én azokat beszélem a világnak, a miket tőle hallottam vala.
Mo ní ohun púpọ̀ láti sọ, àti láti ṣe ìdájọ́ nípa yín, ṣùgbọ́n olóòtítọ́ ni ẹni tí ó rán mi, ohun tí èmi sì ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá, wọ̀nyí ni èmi ń sọ fún aráyé.”
27 Nem vevék észre, hogy az Atyáról szól vala nékik.
Kò yé wọn pé ti Baba ni ó ń sọ fún wọn.
28 Monda azért nékik Jézus: Mikor felemelitek az embernek Fiát, akkor megismeritek, hogy én vagyok és semmit sem cselekszem magamtól, hanem a mint az Atya tanított engem, úgy szólok.
Lẹ́yìn náà Jesu wí fún wọn pé, “Nígbà tí ẹ mọ̀ pé, nígbà tí ẹ bá gbé Ọmọ Ènìyàn sókè, nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ pé èmi ni àti pé èmi kò dá ohunkóhun ṣe fún ara mi, ṣùgbọ́n bí Baba ti kọ́ mi, èmí ń sọ nǹkan wọ̀nyí.
29 És a ki küldött engem, én velem van. Nem hagyott engem az Atya egyedül, mert én mindenkor azokat cselekszem, a melyek néki kedvesek.
Ẹni tí ó rán mí sì ń bẹ pẹ̀lú mi, kò fi mí sílẹ̀ ní èmi nìkan; nítorí tí èmi ń ṣe ohun tí ó wù ú nígbà gbogbo.”
30 A mikor ezeket mondá, sokan hivének ő benne.
Bí ó ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí, ọ̀pọ̀ ènìyàn gbà á gbọ́.
31 Monda azért Jézus a benne hívő zsidóknak: Ha ti megmaradtok az én beszédemben, bizonynyal az én tanítványaim vagytok;
Nítorí náà Jesu wí fún àwọn Júù tí ó gbà á gbọ́, pé, “Bí ẹ bá tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ mi ẹ ó jẹ́ ọmọ-ẹ̀yìn mi nítòótọ́.
32 És megismeritek az igazságot, és az igazság szabadokká tesz titeket.
Ẹ ó sì mọ òtítọ́, òtítọ́ yóò sì sọ yín di òmìnira.”
33 Felelének néki: Ábrahám magva vagyunk, és nem szolgáltunk soha senkinek: mimódon mondod te, hogy szabadokká lesztek?
Wọ́n dá a lóhùn pé, “Irú-ọmọ Abrahamu ni àwa jẹ́, àwa kò sì ṣe ẹrú fún ẹnikẹ́ni rí láé; ìwọ ha ṣe wí pé, ‘Ẹ ó di òmìnira’?”
34 Felele nékik Jézus: Bizony, bizony mondom néktek, hogy mindaz, a ki bűnt cselekszik, szolgája a bűnnek.
Jesu dá wọn lóhùn pé, “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá ń dẹ́ṣẹ̀, ẹrú ẹ̀ṣẹ̀ ni.
35 A szolga pedig nem marad mindörökké a házban: a Fiú marad ott mindörökké. (aiōn )
Ẹrú kì í sì í gbé ilé títí láé, ọmọ ní ń gbé ilé títí láé. (aiōn )
36 Azért ha a Fiú megszabadít titeket, valósággal szabadok lesztek.
Nítorí náà, bí Ọmọ bá sọ yín di òmìnira ẹ ó di òmìnira nítòótọ́.
37 Tudom, hogy Ábrahám magva vagytok; de meg akartok engem ölni, mert az én beszédemnek nincs helye nálatok.
Mo mọ̀ pé irú-ọmọ Abrahamu ni ẹ̀yin jẹ́; ṣùgbọ́n ẹ ń wá ọ̀nà láti pa mí nítorí ọ̀rọ̀ mi kò rí ààyè nínú yín. Jesu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ nípa ara rẹ̀.
38 Én azt beszélem, a mit az én Atyámnál láttam; ti is azt cselekszitek azért, a mit a ti atyátoknál láttatok.
Ohun tí èmi ti rí lọ́dọ̀ Baba ni mo sọ, ẹ̀yin pẹ̀lú sì ń ṣe èyí tí ẹ̀yin ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ baba yín.”
39 Felelének és mondának néki: A mi atyánk Ábrahám. Monda nékik Jézus: Ha Ábrahám gyermekei volnátok, az Ábrahám dolgait cselekednétek.
Wọ́n dáhùn, wọ́n sì wí fún un pé, “Abrahamu ni baba wa!” Jesu wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ìbá ṣe iṣẹ́ Abrahamu.
40 Ámde meg akartok engem ölni, olyan embert, a ki az igazságot beszéltem néktek, a melyet az Istentől hallottam. Ábrahám ezt nem cselekedte.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin ń wá ọ̀nà láti pa mí, ẹni tí ó sọ òtítọ́ fún yín, èyí tí mo ti gbọ́ lọ́dọ̀ Ọlọ́run, Abrahamu kò ṣe èyí.
41 Ti a ti atyátok dolgait cselekszitek. Mondának azért néki: Mi nem paráznaságból születtünk; egy atyánk van, az Isten.
Ẹ̀yin ń ṣe iṣẹ́ baba yín.” Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “a kò bí wa nípa panṣágà, a ní Baba kan, èyí sì ni Ọlọ́run.”
42 Monda azért nékik Jézus: Ha az Isten volna a ti atyátok, szeretnétek engem: mert én az Istentől származtam és jöttem; mert nem is magamtól jöttem, hanem ő küldött engem.
Jesu wí fún wọn pé, “Ìbá ṣe pé Ọlọ́run ni Baba yín, ẹ̀yin ìbá fẹ́ràn mi, nítorí tí èmi ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run jáde, mo sì wá; bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì wá fún ara mi, ṣùgbọ́n òun ni ó rán mi.
43 Miért nem értitek az én beszédemet? Mert nem hallgatjátok az én szómat.
Èéṣe tí èdè mi kò fi yé yín? Nítorí ẹ kò lè gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.
44 Ti az ördög atyától valók vagytok, és a ti atyátok kívánságait akarjátok teljesíteni. Az emberölő volt kezdettől fogva, és nem állott meg az igazságban, mert nincsen ő benne igazság. Mikor hazugságot szól, a sajátjából szól; mert hazug és hazugság atyja.
Ti èṣù baba yin ni ẹ̀yin jẹ́, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ baba yín ni ẹ sì ń fẹ́ ṣe. Apànìyàn ni òun jẹ́ láti àtètèkọ́ṣe, kò sì dúró nínú òtítọ́; nítorí tí kò sí òtítọ́ nínú rẹ̀. Nígbà tí ó bá ń ṣèké, nínú ohun tirẹ̀ ni ó ń sọ nítorí èké ni, àti baba èké.
45 Mivelhogy pedig én igazságot szólok, nem hisztek nékem.
Ṣùgbọ́n nítorí tí èmi ń sọ òtítọ́ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbà mí gbọ́.
46 Ki vádol engem közületek bűnnel? Ha pedig igazságot szólok: miért nem hisztek ti nékem?
Ta ni nínú yín tí ó ti dá mi lẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀? Bí mo bá ń ṣọ òtítọ́, èéṣe tí ẹ̀yin kò fi gbà mí gbọ́?
47 A ki az Istentől van, hallgatja az Isten beszédeit; azért nem hallgatjátok ti, mert nem vagytok az Istentől valók.
Ẹni tí ń ṣe ti Ọlọ́run, a máa gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, nítorí èyí ni ẹ̀yin kò ṣe gbọ́, nítorí ẹ̀yin kì í ṣe ti Ọlọ́run.”
48 Felelének azért a zsidók és mondának néki: Nem jól mondjuk-é mi, hogy te Samaritánus vagy, és ördög van benned?
Àwọn Júù dáhùn wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa kò wí nítòótọ́ pé, ará Samaria ni ìwọ jẹ́, àti pé ìwọ ní ẹ̀mí èṣù?”
49 Felele Jézus: Nincs én bennem ördög; hanem tisztelem az én Atyámat, és ti gyaláztok engem.
Jesu sì dáhùn pé, “Èmi kò ní ẹ̀mí èṣù, ṣùgbọ́n èmi ń bu ọlá fún Baba mi, ẹ̀yin kò sì bu ọlá fún mi.
50 Pedig én nem keresem az én dicsőségemet: van a ki keresi és megítéli.
Èmi kò wá ògo ara mi, ẹnìkan ń bẹ tí ó ń wá a tí yóò sì ṣe ìdájọ́.
51 Bizony, bizony mondom néktek, ha valaki megtartja az én beszédemet, nem lát halált soha örökké. (aiōn )
Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí ẹnìkan bá pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, kì yóò rí ikú láéláé.” (aiōn )
52 Mondának azért néki a zsidók: Most értettük meg, hogy ördög van benned. Ábrahám meghalt, a próféták is; és te azt mondod: Ha valaki megtartja az én beszédemet, nem kóstol halált örökké. (aiōn )
Àwọn Júù wí fún un pé, “Nígbà yìí ni àwa mọ̀ pé ìwọ ní ẹ̀mí èṣù. Abrahamu kú, àti àwọn wòlíì; ìwọ sì wí pé, ‘Bí ẹnìkan bá pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, kì yóò tọ́ ikú wò láéláé.’ (aiōn )
53 Avagy nagyobb vagy-é te a mi atyánknál Ábrahámnál, a ki meghalt? A próféták is meghaltak: kinek állítod te magadat?
Ìwọ ha pọ̀ ju Abrahamu Baba wa lọ, ẹni tí ó kú? Àwọn wòlíì sì kú, ta ni ìwọ ń fi ara rẹ pè?”
54 Felele Jézus: Ha én dicsőítem magamat, az én dicsőségem semmi: az én Atyám az, a ki dicsőít engem, a kiről ti azt mondjátok, hogy a ti Istenetek,
Jesu dáhùn wí pé, “Bí mo bá yin ara mi lógo, ògo mi kò jẹ́ nǹkan, Baba mi ni ẹni tí ń yìn mí lógo, ẹni tí ẹ̀yin wí pé, Ọlọ́run yín ní i ṣe.
55 És nem ismeritek őt: de én ismerem őt; és ha azt mondom, hogy nem ismerem őt, hozzátok hasonlóvá, hazuggá leszek: de ismerem őt, és az ő beszédét megtartom.
Ẹ kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, bí mo bá sì wí pé, èmi kò mọ̀ ọ́n, èmi yóò di èké gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin, ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, mo sì pa ọ̀rọ̀ rẹ̀ mọ́.
56 Ábrahám a ti atyátok örvendezett, hogy meglátja az én napomat; látta is, és örült.
Abrahamu baba yín yọ̀ láti rí ọjọ́ mi, ó sì rí i, ó sì yọ̀.”
57 Mondának azért néki a zsidók: Még ötven esztendős nem vagy, és Ábrahámot láttad?
Nítorí náà, àwọn Júù wí fún un pé, “Ọdún rẹ kò ì tó àádọ́ta, ìwọ sì ti rí Abrahamu?”
58 Monda nékik Jézus: Bizony, bizony mondom néktek: Mielőtt Ábrahám lett, én vagyok.
Jesu sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kí Abrahamu tó wà, èmi ti wa.”
59 Köveket ragadának azért, hogy reá hajigálják; Jézus pedig elrejtőzködék, és kiméne a templomból, átmenvén közöttük; és ilyen módon eltávozék.
Nítorí náà wọ́n gbé òkúta láti sọ lù ú, ṣùgbọ́n Jesu fi ara rẹ̀ pamọ́, ó sì jáde kúrò ní tẹmpili.