< Jób 9 >
1 Felele pedig Jób, és monda:
Jobu sì dáhùn ó sì wí pé,
2 Igaz, jól tudom, hogy így van; hogyan is lehetne igaz a halandó ember Istennél?
“Èmi mọ̀ pe bẹ́ẹ̀ ni ní òtítọ́. Báwo ní ènìyàn yóò ha ti ṣe jẹ́ aláre níwájú Ọlọ́run?
3 Ha perelni akarna ő vele, ezer közül egy sem felelhetne meg néki.
Bí ó bá ṣe pé yóò bá a jà, òun kì yóò lè dalóhùn kan nínú ẹgbẹ̀rún ọ̀rọ̀.
4 Bölcs szívű és hatalmas erejű: ki szegülhetne ellene, hogy épségben maradjon?
Ọlọ́gbọ́n nínú àwọn alágbára ní ipa ní Òun. Ta ni ó ṣe agídí sí i tí ó sì gbé fún rí?
5 A ki hegyeket mozdít tova, hogy észre se veszik, és megfordítja őket haragjában.
Ẹni tí ó sí òkè nídìí tí wọn kò sì mọ́: tí ó taari wọn ṣubú ní ìbínú rẹ̀.
6 A ki kirengeti helyéből a földet, úgy hogy oszlopai megrepedeznek.
Tí ó mi ilẹ̀ ayé tìtì kúrò ní ipò rẹ̀, ọwọ̀n rẹ̀ sì mì tìtì.
7 A ki szól a napnak és az fel nem kél, és bepecsételi a csillagokat.
Ó pàṣẹ fún oòrùn kò sì le è ràn, kí ó sì dí ìmọ́lẹ̀ ìràwọ̀ mọ́.
8 A ki egymaga feszítette ki az egeket, és a tenger hullámain tapos.
Òun nìkan ṣoṣo ni ó ta ojú ọ̀run, ti ó sì ń rìn lórí ìgbì Òkun.
9 A ki teremtette a gönczölszekeret, a kaszás csillagot és a fiastyúkot és a délnek titkos tárait.
Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Beari àti Orioni, Pleiadesi àti ìràwọ̀ púpọ̀ ti gúúsù.
10 A ki nagy dolgokat cselekszik megfoghatatlanul, és csudákat megszámlálhatatlanul.
Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwárí lọ, àní ohun ìyanu láìní iye.
11 Ímé, elvonul mellettem, de nem látom, átmegy előttem, de nem veszem észre.
Kíyèsi i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi, èmi kò sì rí i, ó sì kọjá síwájú, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò rí ojú rẹ̀.
12 Ímé, ha elragad valamit, ki akadályozza meg; ki mondhatja néki: Mit cselekszel?
Kíyèsi i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà? Ta ni yóò bi í pé kí ni ìwọ ń ṣe nì?
13 Ha az Isten el nem fordítja az ő haragját, alatta meghajolnak Ráháb czinkosai is.
Ọlọ́run kò ní fa ìbínú rẹ̀ sẹ́yìn, àwọn onírànlọ́wọ́ ti Rahabu a sì tẹríba lábẹ́ rẹ̀.
14 Hogyan felelhetnék hát én meg ő néki, és lelhetnék vele szemben szavakat?
“Kí ní ṣe tí èmi ti n o fi ba ṣàròyé? Tí èmi yóò fi ma ṣe àwáwí?
15 A ki, ha szinte igazam volna, sem felelhetnék néki; kegyelemért könyörögnék ítélő birámhoz.
Bí ó tilẹ̀ ṣe pé mo ṣe aláìlẹ́bi, èmi kò gbọdọ̀ dá a lóhùn; ṣùgbọ́n èmi ó gbàdúrà fún àánú.
16 Ha segítségül hívnám és felelne is nékem, még sem hinném, hogy szavamat fülébe vevé;
Bí èmi bá sì ké pè é, tí Òun sì dá mi lóhùn, èmi kì yóò sì gbàgbọ́ pé, Òun ti fetí sí ohùn mi.
17 A ki forgószélben rohan meg engem, és ok nélkül megsokasítja sebeimet.
Nítorí pé òun yóò lọ̀ mí lúúlúú pẹ̀lú ìjì ńlá, ó sọ ọgbẹ́ mi di púpọ̀ láìnídìí.
18 Nem hagyna még lélekzetet se vennem, hanem keserűséggel lakatna jól.
Òun kì yóò jẹ́ kí èmi kí ó rí ẹ̀mí mi, ṣùgbọ́n ó mú ohun kíkorò kún un fún mi.
19 Ha erőre kerülne a dolog? Ímé, ő igen erős; és ha ítéletre? Ki tűzne ki én nékem napot?
Bí mo bá sọ ti agbára, wò ó! Alágbára ni, tàbí ní ti ìdájọ́, ta ni yóò dá àkókò fún mi láti rò?
20 Ha igaznak mondanám magamat, a szájam kárhoztatna engem; ha ártatlannak: bűnössé tenne engemet.
Bí mo tilẹ̀ dá ara mi láre, ẹnu ara mi yóò dá mi lẹ́bi; bí mo wí pé olódodo ni èmi yóò sì fi mí hàn ní ẹni ẹ̀bi.
21 Ártatlan vagyok, nem törődöm lelkemmel, útálom az életemet.
“Olóòótọ́ ni mo ṣe, síbẹ̀ èmi kò kíyèsi ara mi, ayé mi ní èmi ìbá máa gàn.
22 Mindegy ez! Azért azt mondom: elveszít ő ártatlant és gonoszt!
Ohùn kan náà ni, nítorí náà ni èmi ṣe sọ: ‘Òun a pa ẹni òtítọ́ àti ènìyàn búburú pẹ̀lú.’
23 Ha ostorával hirtelen megöl, neveti a bűntelenek megpróbáltatását.
Bí ìjàǹbá bá pa ni lójijì, yóò rẹ́rìn-ín nínú ìdààmú aláìṣẹ̀.
24 A föld a gonosz kezébe adatik, a ki az ő biráinak arczát elfedezi. Nem így van? Kicsoda hát ő?
Nígbà tí a bá fi ayé lé ọwọ́ ènìyàn búburú; ó sì bo àwọn onídàájọ́ rẹ̀ lójú; bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ ǹjẹ́ ta ni?
25 Napjaim gyorsabbak valának a kengyelfutónál: elfutának, nem láttak semmi jót.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí ọjọ́ mi yára ju oníṣẹ́ lọ, wọ́n fò lọ, wọn kò rí ayọ̀.
26 Ellebbentek, mint a gyorsan járó hajók, miként zsákmányára csap a keselyű.
Wọ́n kọjá lọ bí ọkọ̀ eèsún papirusi tí ń sáré lọ; bí idì tí ń yára si ohùn ọdẹ.
27 Ha azt mondom: Nosza elfelejtem panaszomat, felhagyok haragoskodásommal és vidám leszek:
Bí èmi bá wí pé, ‘Èmi ó gbàgbé arò ìbìnújẹ́ mi, èmi ó fi ọkàn lélẹ̀, èmi ó sì rẹ ara mi lẹ́kún.’
28 Megborzadok az én mindenféle fájdalmamtól; tudom, hogy nem találsz bűntelennek engem.
Ẹ̀rù ìbànújẹ́ mi gbogbo bà mí, èmi mọ̀ pé ìwọ kì yóò mú mi bí aláìṣẹ̀.
29 Rossz ember vagyok én! Minek fáraszszam hát magamat hiába?
Bí ó bá ṣe pé ènìyàn búburú ni èmi, ǹjẹ́ kí ni èmi ń ṣe làálàá lásán sí?
30 Ha hóvízzel mosakodom is meg, ha szappannal mosom is meg kezeimet:
Bí mo tilẹ̀ fi ọṣẹ dídì wẹ ara mi, tí mo fi omi aró wẹ ọwọ́ mi mọ́,
31 Akkor is a posványba mártanál engem és az én ruháim is útálnának engem.
síbẹ̀ ìwọ ó gbé mi wọ inú ihò ọ̀gọ̀dọ̀ aṣọ ara mi yóò sọ mi di ìríra.
32 Mert nem ember ő, mint én, hogy néki megfelelhetnék, és együtt pörbe állanánk.
“Nítorí Òun kì í ṣe ènìyàn bí èmi, tí èmi ó fi dá a lóhùn tí àwa o fi pàdé ní ìdájọ́.
33 Nincs is közöttünk igazlátó, a ki kezét közbe vethesse kettőnk között!
Bẹ́ẹ̀ ni kò sí alátúnṣe kan ní agbede-méjì wa tí ìbá fi ọwọ́ rẹ̀ lé àwa méjèèjì lára.
34 Venné csak el rólam az ő veszszejét, és az ő rettentésével ne rettegtetne engem:
Kí ẹnìkan sá à mú ọ̀pá Ọlọ́run kúrò lára mi, kí ìbẹ̀rù rẹ̀ kí ó má sì ṣe dáyà fò mí.
35 Akkor szólanék és nem félnék tőle: mert nem így vagyok én magammal!
Nígbà náà ni èmi ìbá sọ̀rọ̀, èmi kì bá sì bẹ̀rù rẹ̀; ṣùgbọ́n bí ó tí dúró tì mí, kò ri bẹ́ẹ̀ fún mi.