< Jób 5 >
1 Kiálts csak! Van-é, a ki felelne néked? A szentek közül melyikhez fordulsz?
“Ó jẹ́ pé nísinsin yìí bí ẹnìkan bá wà tí yóò dá wa lóhùn? Tàbí ta ni nínú àwọn ènìyàn mímọ́ tí ìwọ ó yípadà sí?
2 Mert a bolondot boszúság öli meg, az együgyűt pedig buzgóság veszti el.
Nítorí pé ìbínú pa aláìmòye, ìrunú a sì pa òpè ènìyàn.
3 Láttam, hogy egy bolond gyökerezni kezdett, de nagy hamar megátkoztam szép hajlékát.
Èmi ti rí aláìmòye ti ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lulẹ̀, ṣùgbọ́n lójúkan náà mo fi ibùjókòó rẹ̀ bú.
4 Fiai messze estek a szabadulástól: a kapuban megrontatnak, mert nincs, a ki kimentse őket.
Àwọn ọmọ rẹ̀ kò jìnnà sí ewu, a sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ lójú ibodè, bẹ́ẹ̀ ni kò sí aláàbò kan.
5 A mit learatnak néki, az éhező eszi meg, a töviskerítésből is elviszi azt, kincseiket tőrvetők nyelik el.
Ìkórè oko ẹni tí àwọn tí ebi ń pa sọ̀ di jíjẹ, tí wọ́n sì wọ inú ẹ̀gún lọ kó, àwọn ìgárá ọlọ́ṣà sì gbé ohun ìní wọn mì.
6 Mert nem porból támad a veszedelem s nem földből sarjad a nyomorúság!
Bí ìpọ́njú kò bá ti inú erùpẹ̀ jáde wá ni, tí ìyọnu kò ti ilẹ̀ jáde wá.
7 Hanem nyomorúságra születik az ember, a mint felfelé szállnak a parázs szikrái.
Ṣùgbọ́n a bí ènìyàn sínú wàhálà, gẹ́gẹ́ bí ìpẹ́pẹ́ iná ti máa ń ta sókè.
8 Azért én a Mindenhatóhoz folyamodnám, az Istenre bíznám ügyemet.
“Ṣùgbọ́n bí ó ṣe tèmi, ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní èmi yóò ti ṣìpẹ̀, ní ọwọ́ Ọlọ́run ní èmi yóò máa fi ọ̀rọ̀ mi lé.
9 A ki nagy, végére mehetetlen dolgokat művel, és csudákat, a miknek száma nincsen.
Ẹni tí ó ṣe ohun tí ó tóbi tí a kò lè ṣe àwárí, ohun ìyanu láìní iye.
10 A ki esőt ad a földnek színére, és a mezőkre vizet bocsát.
Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayé tí ó sì ń rán omi sínú ilẹ̀kílẹ̀.
11 Hogy az alázatosokat felmagasztalja, és a gyászolókat szabadulással vidámítsa.
Láti gbé àwọn orílẹ̀-èdè lékè kí á lè gbé àwọn ẹni ìbànújẹ́ ga sí ibi aláìléwu.
12 A ki semmivé teszi a csalárdok gondolatait, hogy szándékukat kezeik véghez ne vihessék.
Ó yí ìmọ̀ àwọn alárékérekè po, bẹ́ẹ̀ ní ọwọ́ wọn kò lè mú ìdáwọ́lé wọn ṣẹ.
13 A ki megfogja a bölcseket az ő csalárdságukban, és a hamisak tanácsát hiábavalóvá teszi.
Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú àrékérekè ara wọn, àti ìmọ̀ àwọn òǹrorò ní ó tì ṣubú ní ògèdèǹgbé.
14 Nappal sötétségre bukkannak, és délben is tapogatva járnak, mint éjszaka.
Wọ́n sáré wọ inú òkùnkùn ní ọ̀sán; wọ́n sì fọwọ́ tálẹ̀ ní ọ̀sán gangan bí ẹni pé ní òru ni.
15 A ki megszabadítja a fegyvertől, az ő szájoktól, és az erősnek kezéből a szegényt;
Ṣùgbọ́n ó gba tálákà là ní ọwọ́ idà, lọ́wọ́ ẹnu wọn àti lọ́wọ́ àwọn alágbára.
16 Hogy legyen reménysége a szegénynek, és a hamisság befogja az ő száját.
Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún tálákà, àìṣòótọ́ sì pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
17 Ímé, boldog ember az, a kit Isten megdorgál; azért a Mindenhatónak büntetését meg ne utáljad!
“Kíyèsi i, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí, nítorí náà, má ṣe gan ìbáwí Olódùmarè.
18 Mert ő megsebez, de be is kötöz, összezúz, de kezei meg is gyógyítanak.
Nítorí pé òun a máa pa ni lára, síbẹ̀ òun a sì tún dì í ní ìdì ìtura, ó sá lọ́gbẹ́, a sì fi ọwọ́ rẹ̀ di ojú ọgbẹ̀ náà jiná.
19 Hat bajodból megszabadít, és a hetedikben sem illet a veszedelem téged.
Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà, àní nínú méje, ibi kan kì yóò bá ọ.
20 Az éhínségben megment téged a haláltól, és a háborúban a fegyveres kezektől.
Nínú ìyanu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú àti nínú ogun, yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.
21 A nyelvek ostora elől rejtve leszel, és nem kell félned, hogy a pusztulás rád következik.
A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́n, bẹ́ẹ̀ ní ìwọ kì yóò bẹ̀rù ìparun tí ó bá dé.
22 A pusztulást és drágaságot neveted, és a fenevadaktól sem félsz.
Ìwọ yóò rẹ́rìn-ín nínú ìparun àti ìyàn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò bẹ̀rù ẹranko ilẹ̀ ayé.
23 Mert a mezőn való kövekkel is frigyed lesz, és a mezei vad is békességben lesz veled.
Nítorí pé ìwọ ti bá òkúta igbó mulẹ̀, àwọn ẹranko igbó yóò wà pẹ̀lú rẹ ní àlàáfíà.
24 Majd megtudod, hogy békességben lesz a te sátorod, s ha megvizsgálod a te hajlékodat, nem találsz benne hiányt.
Ìwọ ó sì mọ̀ pé àlàáfíà ni ibùjókòó rẹ wà, ìwọ yóò sì máa ṣe ìbẹ̀wò ibùjókòó rẹ, ìwọ kì yóò ṣìnà.
25 Majd megtudod, hogy a te magod megszaporodik, és a te sarjadékod, mint a mezőn a fű.
Ìwọ ó sì mọ̀ pẹ̀lú pé irú-ọmọ rẹ ó sì pọ̀ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ yóò rí bí koríko igbó.
26 Érett korban térsz a koporsóba, a mint a maga idején takaríttatik be a learatott gabona.
Ìwọ yóò wọ isà òkú rẹ ní ògbólógbòó ọjọ́, bí síírí ọkà tí ó gbó tí á sì kó ní ìgbà ìkórè rẹ̀.
27 Ímé ezt kutattuk mi ki, így van ez. Hallgass erre, jegyezd meg magadnak.
“Kíyèsi i, àwa ti wádìí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní ó rí! Gbà á gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ìre ara rẹ ni.”