< Jób 4 >
1 És felele a témáni Elifáz, és monda:
Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé,
2 Ha szólni próbálunk hozzád, zokon veszed-é? De hát ki bírná türtőztetni magát a beszédben?
“Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́? Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?
3 Ímé sokakat oktattál, és a megfáradott kezeket megerősítetted;
Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn, ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.
4 A tántorgót a te beszédeid fentartották, és a reszkető térdeket megerősítetted;
Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró, ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.
5 Most, hogy rád jött a sor, zokon veszed; hogy téged ért a baj, elrettensz!
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́; ara rẹ kò lélẹ̀.
6 Nem bizodalmad-é a te istenfélelmed, s nem reménységed-é utaidnak becsületessége?
Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ àti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?
7 Emlékezzél, kérlek, ki az, a ki elveszett ártatlanul, és hol töröltettek el az igazak?
“Èmi bẹ̀ ọ́ rántí, ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀? Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?
8 A mint én láttam, a kik hamisságot szántanak és gonoszságot vetnek, ugyanazt aratnak.
Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀, tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.
9 Az Istennek lehelletétől elvesznek, az ő haragjának szelétől elpusztulnak.
Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé, nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.
10 Az oroszlán ordítása, a sakál üvöltése, és az oroszlán-kölykök fogai megsemmisülnek.
Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún àti eyín àwọn ẹgbọrọ kìnnìún ní a ká.
11 Az agg oroszlán elvész, ha nincs martaléka, a nőstény oroszlán kölykei elszélednek.
Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ, àwọn ẹgbọrọ kìnnìún sísanra ni a túká kiri.
12 Szó lopódzék hozzám, s valami nesz üté meg abból fülemet.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi, etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.
13 Éjjeli látásokon való töprengések között, mikor mély álom fogja el az embereket.
Ní ìrò inú lójú ìran òru, nígbà tí oorun èjìká kùn ènìyàn.
14 Félelem szálla rám, és rettegés, s megreszketteté minden csontomat.
Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì tí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.
15 Valami szellem suhant el előttem, s testemnek szőre felborzolódék.
Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi, irun ara mi dìde dúró ṣánṣán.
16 Megálla, de ábrázatját föl nem ismerém, egy alak vala szemeim előtt, mély csend, és ilyen szót hallék:
Ó dúró jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀, àwòrán kan hàn níwájú mi, ìdákẹ́rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé,
17 Vajjon a halandó igaz-é Istennél: az ő teremtője előtt tiszta-é az ember?
‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run, ènìyàn ha le mọ́ ju ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?
18 Ímé az ő szolgáiban sem bízhatik és az ő angyalaiban is talál hibát:
Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, nínú àwọn angẹli rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀.
19 Mennyivel inkább a sárházak lakosaiban, a kiknek fundamentumok a porban van, és könnyebben szétnyomhatók a molynál?!
Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀, ẹni tí ìpìlẹ̀ wọ́n jásí erùpẹ̀ tí yóò di rírun kòkòrò.
20 Reggeltől estig gyötrődnek, s a nélkül, hogy észrevennék, elvesznek örökre.
A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́ wọ́n sì parun títí láé, láìrí ẹni kà á sí.
21 Ha kiszakíttatik belőlök sátoruk kötele, nem halnak-é meg, és pedig bölcsesség nélkül?
A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí? Wọ́n kú, àní láìlọ́gbọ́n?’