< Jób 22 >
1 Felele pedig a Témánból való Elifáz, és monda:
Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
2 Az Istennek használ-é az ember? Sőt önmagának használ az okos!
“Ènìyàn lè è ṣe rere fún Ọlọ́run? Bí ọlọ́gbọ́n ti í ṣe rere fún ara rẹ̀?
3 Gyönyörűségére van-é az a Mindenhatónak, ha te igaz vagy; avagy nyereség-é, hogy feddhetetlenül jársz?
Ohun ayọ̀ ha ni fún Olódùmarè pé olódodo ni ìwọ? Tàbí èrè kí ni fún un ti ìwọ mú ọ̀nà rẹ̀ pé?
4 A te isteni félelmedért fedd-é téged, és azért perel-é veled?
“Yóò ha bá ọ wí bí, nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ? Yóò ha bá ọ lọ sínú ìdájọ́ bí?
5 Avagy nem sok-é a te gonoszságod, és nem véghetetlen-é a te hamisságod?
Ìwà búburú rẹ kò ha tóbi, àti ẹ̀ṣẹ̀ rẹ láìníye?
6 Hiszen zálogot vettél a te atyádfiától méltatlanul, és a szegényeket mezítelenekké tetted.
Nítòótọ́ ìwọ béèrè fún ààbò ni ọwọ́ arákùnrin rẹ láìnídìí, ìwọ sì tú oníhòhò ní aṣọ wọn.
7 Az eltikkadtnak vizet sem adtál inni, és az éhezőtől megtagadtad a kenyeret.
Ìwọ kò fi omi fún aláàárẹ̀ mu, ìwọ sì háwọ́ oúnjẹ fún ẹni tí ebi ń pa.
8 A ki hatalmas volt, azé vala az ország, és a ki nagytekintélyű volt, az lakik vala rajta.
Bí ó ṣe ti alágbára nì, òun ni ó ní ilẹ̀, ọlọ́lá sì tẹ̀dó sínú rẹ̀.
9 Az özvegyeket üres kézzel bocsátottad el, és az árváknak karjai eltörettek.
Ìwọ ti rán àwọn opó padà lọ ní ọwọ́ òfo, apá àwọn ọmọ aláìní baba ti di ṣiṣẹ́.
10 Azért vett körül téged a veszedelem, és rettegtet téged hirtelen való rettegés;
Nítorí náà ni ìdẹ̀kùn ṣe yí ọ káàkiri, àti ìbẹ̀rù òjijì ń yọ ọ́ lẹ́nu.
11 Avagy a setétség, hogy ne láthass, és a vizek árja, a mely elborít!
Èéṣe tí òkùnkùn fi pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè ríran. Èéṣe tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi sì bò ọ́ mọ́lẹ̀.
12 Hát nem olyan magas-é Isten, mint az egek? És lásd, a csillagok is ott fent mily igen magasak!
“Ọlọ́run kò ha jẹ́ ẹni gíga ọ̀run? Sá wo orí àwọn ìràwọ̀ bí wọ́n ti ga tó!
13 És mégis azt mondod: Mit tud az Isten; megítélheti-é, a mi a homály mögött van?
Ìwọ sì wí pé, Ọlọ́run ti ṣe mọ̀? Òun ha lè ṣe ìdájọ́ láti inú òkùnkùn wá bí?
14 Sűrű felhők leplezik el őt és nem lát, és az ég körületén jár.
Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ tí ó nípọn jẹ ìbora fún un, tí kò fi lè ríran; ó sì ń rìn nínú àyíká ọ̀run.
15 Az ősvilág ösvényét követed-é, a melyen az álnok emberek jártak;
Ǹjẹ́ ìwọ fẹ́ rin ipa ọ̀nà ìgbàanì tí àwọn ènìyàn búburú tí rìn?
16 A kik időnap előtt ragadtattak el, és alapjokat elmosta a víz?!
A ké wọn lulẹ̀ kúrò nínú ayé láìpé ọjọ́ wọn, ìpìlẹ̀ wọn ti da bí odò ṣíṣàn.
17 A kik azt mondják vala Istennek: Távozzál el tőlünk! És mit cselekedék velök a Mindenható?
Àwọn ẹni tí ó wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa! Kí ni Olódùmarè yóò ṣe fún wọn?’
18 Ő pedig megtöltötte házaikat jóval. De az istentelenek tanácsa távol legyen tőlem.
Síbẹ̀ ó fi ohun rere kún ilé wọn! Ṣùgbọ́n ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi!
19 Látják ezt az igazak és örülnek rajta, az ártatlan pedig csúfolja őket:
Àwọn olódodo rí ìparun wọn, wọ́n sì yọ̀, àwọn aláìlẹ́ṣẹ̀ sì fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà pé,
20 Valósággal kigyomláltatott a mi ellenségünk, és az ő maradékjokat tűz emészti meg!
‘Lóòtítọ́ àwọn ọ̀tá wa ni a ké kúrò, iná yóò sì jó oró wọn run.’
21 Bízd csak azért magadat ő reá és légy békességben: ezekből jó származik reád.
“Fa ara rẹ súnmọ́ Ọlọ́run, ìwọ ó sì rí àlàáfíà; nípa èyí ni rere yóò wá bá ọ.
22 Végy csak oktatást az ő szájából, és vésd szívedbe az ő beszédeit!
Èmi bẹ̀ ọ́, gba òfin láti ẹnu rẹ̀ wá, kí o sì to ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí àyà rẹ.
23 Ha megtérsz a Mindenhatóhoz, megépíttetel, és az álnokságot távol űzöd a te sátorodtól.
Bí ìwọ bá yípadà sọ́dọ̀ Olódùmarè, a sì gbé ọ ró. Bí ìwọ bá sì mú ẹ̀ṣẹ̀ jìnnà réré kúrò nínú àgọ́ rẹ,
24 Vesd a porba a nemes érczet, és a patakok kavicsába az ofiri aranyat:
tí ìwọ bá tẹ́ wúrà dáradára sílẹ̀, lórí erùpẹ̀ àti wúrà Ofiri lábẹ́ òkúta odò,
25 És akkor a Mindenható lesz a te nemes érczed és a te ragyogó ezüstöd.
nígbà náà ní Olódùmarè yóò jẹ́ wúrà rẹ, àní yóò sì jẹ́ fàdákà fún ọ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
26 Bizony akkor a Mindenhatóban gyönyörködöl, és a te arczodat Istenhez emeled.
Lóòtítọ́ nígbà náà ní ìwọ ó ní inú dídùn nínú Olódùmarè, ìwọ ó sì gbé ojú rẹ sókè sọ́dọ̀ Ọlọ́run.
27 Hozzá könyörögsz és meghallgat téged, és lefizeted fogadásaidat.
Bí ìwọ bá gbàdúrà rẹ sọ́dọ̀ rẹ̀, yóò sì gbọ́ tìrẹ, ìwọ ó sì san ẹ̀jẹ́ rẹ.
28 Mihelyt valamit elgondolsz, sikerül az néked, és a te utaidon világosság fénylik.
Ìwọ ó sì gbìmọ̀ ohun kan pẹ̀lú, yóò sì fi ìdí múlẹ̀ fún ọ; ìmọ́lẹ̀ yóò sì mọ́ sípa ọ̀nà rẹ.
29 Hogyha megaláznak, felmagasztalásnak mondod azt, és ő az alázatost megtartja.
Nígbà tí ipa ọ̀nà rẹ bá lọ sísàlẹ̀, nígbà náà ni ìwọ o wí pé, ‘Ìgbésókè ń bẹ!’ Ọlọ́run yóò sì gba onírẹ̀lẹ̀ là!
30 Megszabadítja a nem ártatlant is, és pedig a te kezeidnek tisztaságáért szabadul meg az.
Yóò gba ẹni tí kì í ṣe aláìjẹ̀bi là, a ó sì gbà á nípa mímọ́ ọwọ́ rẹ̀.”