< Jeremiás 1 >
1 Jeremiásnak, Hilkiás fiának beszédei, a ki az Anatótban, Benjámin földén lakó papok közül vala;
Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini.
2 A kihez szóla az Úr Jósiásnak, az Ammon fiának, Júda királyának napjaiban, az ő uralkodásának tizenharmadik esztendejében;
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda,
3 Továbbá Jójakimnak, a Jósiás fiának, Júda királyának napjaiban, Sedékiásnak, a Jósiás fiának, Júda királyának egészen tizenegyedik esztendejéig, Jeruzsálem fogságba viteléig, a mi az ötödik hónapban vala;
àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.
4 Szóla pedig az Úr nékem, mondván:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,
5 Mielőtt az anyaméhben megalkottalak, már ismertelek, és mielőtt az anyaméhből kijövél, megszenteltelek; prófétának rendeltelek a népek közé.
“Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n, kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀. Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.”
6 És mondék: Ah, ah Uram Isten! Ímé, én nem tudok beszélni; hiszen ifjú vagyok én!
Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”
7 Az Úr pedig monda nékem: Ne mondd ezt: Ifjú vagyok én; hanem menj mind azokhoz, a kikhez küldelek téged, és beszéld mindazt, a mit parancsolok néked.
Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.”
8 Ne félj tőlök, mert én veled vagyok, hogy megszabadítsalak téged! mond az Úr.
Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.
9 És kinyújtá az Úr az ő kezét, és megilleté számat, és monda nékem az Úr: Ímé, az én igéimet adom a te szádba!
Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí, mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ.
10 Lásd, én e mai napon népek fölé és országok fölé rendellek téged, hogy gyomlálj, irts, pusztíts, rombolj, építs és plántálj!
Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.
11 Szóla továbbá nékem az Úr, mondván: Mit látsz te, Jeremiás? És mondék: Mandulavesszőt látok én.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé: “Kí ni o rí Jeremiah?” Mo sì dáhùn wí pé, “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”
12 És monda nékem az Úr: Jól láttál, mert gondom van az én igémre, hogy beteljesítsem azt.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”
13 És másodszor is szóla hozzám az Úr, mondván: Mit látsz te? És felelék: Forró fazekat látok én, és pedig a szája észak felől van.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.
14 És monda nékem az Úr: Észak felől támad a veszedelem e földnek minden lakosára.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà.
15 Mert ímé, előhívom én az északi országok minden nemzetségét, mondja az Úr, és eljőnek, és kiki felállítja az ő királyi székét Jeruzsálem kapui előtt, és köröskörül minden kerítése ellen, és Júdának minden városa ellen.
Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọba wọn yóò wá gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn ìlú Juda.
16 És kimondom ítéleteimet felettök az ő mindenféle gonoszságukért, minthogy elszakadtak tőlem, és idegen isteneknek áldoztak, és tulajdon kezeik munkáit imádták.
Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀, nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.
17 Te azért övezd fel derekadat, és kelj fel, és mondd meg nékik mindazt, a mit én parancsolok néked; meg ne riadj tőlök, különben én riasztalak el téged előlök!
“Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn.
18 Mert ímé én erősített várossá, vasoszloppá és érczbástyává teszlek ma téged mind ez egész földön, Júda királyai, fejedelmei és papjai ellen és a föld népe ellen.
Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
19 Viaskodni fognak ugyan ellened, de nem győznek meg téged, mert én veled vagyok, azt mondja az Úr, hogy megszabadítsalak téged.
Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.