< Jeremiás 10 >
1 Halljátok meg a szót, a mit az Úr szól néktek, Izráel háza!
Gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ fún yín ẹ̀yin ilé Israẹli.
2 Ezt mondja az Úr: A pogányok útját el ne tanuljátok, és az égi jelektől ne féljetek, mert a pogányok félnek azoktól!
Báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe kọ́ ìwà àwọn kèfèrí, kí àmì ọ̀run kí ó má sì dààmú yín, nítorí pé wọ́n ń dààmú orílẹ̀-èdè.
3 Mert a népek bálványai csupa hiábavalóság, hiszen az erdő fájából vágják azt; ács-mester kezei készítik bárddal.
Nítorí pé asán ni àṣà àwọn ènìyàn, wọ́n gé igi láti inú igbó, oníṣọ̀nà sì gbẹ́ ẹ pẹ̀lú àáké rẹ̀.
4 Ezüsttel és aranynyal megékesíti azt, szegekkel és pőrölyökkel megerősítik, hogy le ne essék.
Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́. Wọ́n fi òòlù kàn án àti ìṣó kí ó má ba à ṣubú.
5 Olyanok, mint az egyenes pálmafa, és nem beszélnek; viszik-hordják őket, mert mozdulni nem tudnak. Ne féljetek tőlök, mert nem tehetnek rosszat; de jót tenni se képesek!
Wọ́n wé mọ́ igi bí ẹ̀gúnsí inú oko, òrìṣà wọn kò le è fọhùn. Wọ́n gbọdọ̀ máa gbé wọn nítorí pé wọn kò lè rìn. Má ṣe bẹ̀rù wọn; wọn kò le è ṣe ibi kankan bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si lè ṣe rere kan.”
6 Nincs hozzád hasonló, Uram! Nagy vagy és nagy a te neved a te hatalmadért!
Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ Olúwa; o tóbi orúkọ rẹ sì tóbi lágbára.
7 Ki ne félne tőled, nemzetek királya? Bizony tiéd a tisztelet, mert a nemzetek minden bölcse közt és azok minden országában sincs hozzád hasonló!
Ta ni kò yẹ kí ó bẹ̀rù rẹ? Ọba àwọn orílẹ̀-èdè? Nítorí tìrẹ ni. Láàrín àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní orílẹ̀-èdè àti gbogbo ìjọba wọn, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ.
8 Mind egyig balgatagok és bolondok; hiábavalóságokra tanít; fa az.
Gbogbo wọn jẹ́ aláìlóye àti aṣiwèrè, wọ́n ń kọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ère igi tí kò níláárí.
9 Társisból hozott lapított ezüst és Ofirból való arany; az ácsnak és az ötvös kezének munkája; öltözetök kék és piros bíbor; mesterek munkája valahány.
Fàdákà tí a ti kàn ni a mú wá láti Tarṣiṣi, àti wúrà láti Upasi. Èyí tí àwọn oníṣọ̀nà àti alágbẹ̀dẹ ṣe tí wọ́n kùn ní àwọ̀ aró àti elése àlùkò, èyí jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà.
10 De az Úr igaz Isten, élő Isten ő, és örökkévaló király; az ő haragja előtt reszket a föld, és a nemzetek nem szenvedhetik el az ő felindulását.
Ṣùgbọ́n Olúwa ni Ọlọ́run tòótọ́, òun ni Ọlọ́run alààyè, ọba ayérayé. Nígbà tí ó bá bínú, ayé yóò wárìrì; orílẹ̀-èdè kò lè fi ara da ìbínú rẹ̀.
11 (Mondjátok meg hát nékik: Az istenek, a kik az eget és földet nem alkották, el fognak veszni e földről és az ég alól!)
“Sọ èyí fún wọn: ‘Àwọn ọlọ́run kéékèèké tí kò dá ọ̀run àti ayé ni yóò ṣègbé láti ayé àti ní abẹ́ ọ̀run.’”
12 Ő teremtette a földet az ő erejével, ő alkotta a világot az ő bölcseségével, és ő terjesztette ki az egeket az ő értelmével.
Ọlọ́run dá ayé pẹ̀lú agbára rẹ̀, ó dá àgbáyé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, ó mú kí ọ̀run kí ó fẹ̀ síta nípa òye rẹ̀.
13 Szavára víz-zúgás támad az égben, és felhők emelkednek fel a föld határairól; villámlásokat készít az esőnek, és kihozza a szelet az ő rejtekhelyéből.
Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omi lọ́run a sì pariwo; ó mú kí ìkùùkuu ru sókè láti òpin ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.
14 Minden ember bolonddá lett, tudomány nélkül, minden ötvös megszégyenül az ő öntött képével, mert hazugság az ő öntése, és nincsen azokban lélek.
Gbogbo ènìyàn jẹ́ aṣiwèrè àti aláìnímọ̀, ojú ti gbogbo alágbẹ̀dẹ níwájú ère rẹ̀, nítorí ère dídá rẹ̀ èké ni, kò sì ṣí ẹ̀mí nínú rẹ̀.
15 Hiábavalók azok, nevetségre való munka, elvesznek az ő megfenyíttetésök idején!
Asán ni wọ́n, iṣẹ́ ìṣìnà; nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn yóò ṣègbé.
16 Nem ilyen a Jákób része, mint ezek; mert a mindenség alkotója ő, és Izráel az ő örökségének pálczája; Seregek Ura az ő neve!
Ẹni tí ó bá jẹ́ ìpín Jakọbu kò sì dàbí èyí, nítorí òun ni ó ṣẹ̀dá ohun gbogbo àti Israẹli tí ó jẹ́ ẹ̀yà ìjogún rẹ̀. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
17 Gyűjtsd össze a földről a te árúidat, a ki erősített városban lakozol!
Kó ẹrù rẹ kúrò láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀ ìwọ tí o ń gbé ní ìlú tí a dó tì.
18 Mert ezt mondja az Úr: Ímé, én elvetem ezúttal e föld lakosait, és megsanyargatom őket, hogy megtaláljanak.
Nítorí èyí ni Olúwa wí: “Ní àkókò yìí, èmi yóò gbọn àwọn tí ó ń gbé ilẹ̀ náà jáde. Èmi yóò mú ìpọ́njú bá wọn, kí wọn kí ó lè rí wọn mú.”
19 Jaj nékem az én romlásom miatt, gyógyíthatatlan az én sebem! De azt mondom mégis: Bizony ilyen az én vereségem, és szenvedem azt!
Ègbé ni fún mi nítorí ìpalára mi! Ọgbẹ́ mi jẹ́ èyí tí kò lè sàn, bẹ́ẹ̀ ni mọ sọ fún ara mi, “Èyí ni àìsàn mi, mo sì gbọdọ̀ fi orí tì í.”
20 Sátorom elpusztíttatott, köteleim mind elszakadoztak, fiaim elszakadtak tőlem és oda vannak ők; nincs többé, a ki kifeszítse sátoromat, és felvonja kárpitjaimat!
Àgọ́ mi bàjẹ́, gbogbo okùn rẹ̀ sì já. Àwọn ọmọ mi ti lọ lọ́dọ̀ mi, wọn kò sì sí mọ́, kò sí ẹnìkankan tí yóò na àgọ́ mi ró mọ́, tàbí yóò ṣe ibùgbé fún mi.
21 Mert oktalanok voltak a pásztorok, és nem keresték az Urat; ezért nem lettek szerencsésekké, és minden nyájuk szétszóratott.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn jẹ́ aṣiwèrè, wọn kò sì wá Olúwa: nítorí náà wọn kì yóò ṣe rere àti pé gbogbo agbo wọn ni yóò túká.
22 A hír hangja ímé megjött, és nagy zúgás kél észak földe felől, hogy pusztává tegyék Júdának városait, és sakálok tanyájává.
Fetísílẹ̀! ariwo igbe ń bọ̀, àti ìdàrúdàpọ̀ ńlá láti ilẹ̀ àríwá wá! Yóò sì sọ ìlú Juda di ahoro, àti ihò ọ̀wàwà.
23 Tudom Uram, hogy az embernek nincs hatalmában az ő útja, és egyetlen járókelő sem teheti, hogy irányozza a maga lépését!
Èmi mọ̀ Olúwa wí pé ọ̀nà ènìyàn kì í ṣe ti ara rẹ̀, kì í ṣe fún ènìyàn láti tọ́ ìgbésẹ̀ ara rẹ̀.
24 Fenyíts meg engem, Uram, de mértékkel, nem haragodban, hogy szét ne morzsolj engem!
Tún mi ṣe Olúwa, pẹ̀lú ìdájọ́ nìkan kí o má sì ṣe é nínú ìbínú rẹ, kí ìwọ má ṣe sọ mí di òfo.
25 Öntsd ki haragodat ama nemzetekre, a melyek nem ismernek téged, és ama nemzetségekre, a melyek nem hívják segítségül a te nevedet; mert megették Jákóbot, bizony megették őt, és elemésztették őt, és lakóhelyét elpusztították!
Tú ìbínú rẹ jáde sórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́n, sórí àwọn ènìyàn tí wọn kò pe orúkọ rẹ. Nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run, wọ́n ti jẹ ẹ́ run pátápátá, wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ̀ di ahoro.