< Ézsaiás 41 >

1 Hallgassatok reám, ti szigetek, és a népek vegyenek új erőt, közelgjenek, majd szóljanak, együtt hadd szálljunk perbe!
“Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú mi ẹ̀yin erékùṣù! Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè tún agbára wọn ṣe! Jẹ́ kí wọn wá síwájú kí wọn sọ̀rọ̀, jẹ́ kí a pàdé pọ̀ ní ibi ìdájọ́.
2 Ki támasztá fel azt keletről, a kit igazságban hív az ő lábához? A népeket kezébe adja és királyok felett uralkodóvá teszi, kardjával mint port szórja szét, mint repülő polyvát kézíve által!
“Ta ni ó ti ru ẹnìkan sókè láti ìlà-oòrùn wá, tí ó pè é ní olódodo sí iṣẹ́ tirẹ̀? Ó gbé àwọn orílẹ̀-èdè lé e lọ́wọ́ ó sì ṣẹ́gun àwọn ọba níwájú rẹ̀. Ó sọ wọ́n di erùpẹ̀ pẹ̀lú idà rẹ̀, láti kù ú ní ìyàngbò pẹ̀lú ọrun rẹ̀.
3 Kergeti őket, békességgel vonul az úton, a melyen lábaival nem járt.
Ó ń lépa wọn ó sì ń kọjá ní àlàáfíà, ní ojú ọ̀nà tí ẹsẹ̀ rẹ̀ kò rìn rí.
4 Ki tette és vitte végbe ezt? A ki elhívja eleitől fogva a nemzetségeket: én, az Úr, az első és utolsókkal is az vagyok én!
Ta ni ó ti ṣe èyí tí ó sì ti jẹ́ kí ó wáyé, tí ó ti pe ìran-ìran láti àtètèkọ́ṣe? Èmi Olúwa pẹ̀lú ẹni kìn-ín-ní wọn àti ẹni tí ó gbẹ̀yìn, Èmi náà ni.”
5 Látták a szigetek és megrémülének, a földnek végei reszkettek, közelegtek és egybegyűltek.
Àwọn erékùṣù ti rí i wọ́n bẹ̀rù; ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé wárìrì. Wọ́n súnmọ́ tòsí wọ́n sì wá síwájú;
6 Kiki társát segíti, és barátjának ezt mondja: Légy erős!
èkínní ran èkejì lọ́wọ́ ó sì sọ fún arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ alágbára!”
7 És bátorítja a mester az ötvöst, és a kalapácscsal simító azt, a ki az ülőt veri; így szól a forrasztásról: jó az, és megerősíti szegekkel, hogy meg ne mozduljon.
Oníṣọ̀nà gba alágbẹ̀dẹ wúrà níyànjú, àti ẹni tí ó fi òòlù dán mú òun lọ́kàn le, àní ẹni tí ó ń lu owú. Ó sọ nípa àjópọ̀ náà pé, “Ó dára.” Ó fi ìṣó kan ère náà mọ́lẹ̀ kí ó má ba à wó lulẹ̀.
8 De te Izráel, én szolgám, Jákób, a kit én elválasztottam, Ábrahámnak, az én barátomnak magva;
“Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ Israẹli, ìránṣẹ́ mi, Jakọbu, ẹni tí mo ti yàn, ẹ̀yin ìran Abrahamu, ọ̀rẹ́ mi,
9 Te, a kit én a föld utolsó részéről hoztalak és véghatárairól elhívtalak, és ezt mondám néked: Szolgám vagy te, elválasztottalak és meg nem útállak:
mo mú ọ láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé, láti kọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ó jìnnà jùlọ ni mo ti pè ọ́. Èmi wí pé, ‘Ìwọ ni ìránṣẹ́ mi’; Èmi ti yàn ọ́ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì tí ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
10 Ne félj, mert én veled vagyok; ne csüggedj, mert én vagyok Istened; megerősítelek, sőt megsegítlek, és igazságom jobbjával támogatlak.
Nítorí náà má bẹ̀rù, nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ; má ṣe jẹ́ kí àyà kí ó fò ọ́, nítorí èmi ni Ọlọ́run rẹ. Èmi yóò fún ọ lókun èmi ó sì ràn ọ́ lọ́wọ́. Èmi ó gbé ọ ró pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún òdodo mi.
11 Ímé, megszégyenülnek és meggyaláztatnak, a kik fölgerjednek ellened, semmivé lesznek és elvesznek, a kik veled perlekednek.
“Gbogbo àwọn tí ó bínú sí ọ ni ojú yóò tì, tí wọn yóò sì di ẹlẹ́yà; àwọn tó ń bá ọ jà yóò dàbí asán, wọn yóò ṣègbé.
12 Keresed őket és meg nem találod a veled versengőket; megsemmisülnek teljesen, a kik téged háborgatnak.
Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yóò wá àwọn ọ̀tá rẹ, ìwọ kì yóò rí wọn. Gbogbo àwọn tí ó gbóguntì ọ́ yóò dàbí ohun tí kò sí.
13 Mivel én vagyok Urad, Istened, a ki jobbkezedet fogom, és a ki ezt mondom néked: Ne félj, én megsegítelek!
Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó di ọwọ́ ọ̀tún rẹ mú tí ó sì sọ fún ọ pé, má ṣe bẹ̀rù; Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.
14 Ne félj, férgecske Jákób, maroknyi Izráel, én megsegítlek, szól az Úr, a te megváltód, Izráelnek Szentje!
Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu kòkòrò, ìwọ Israẹli kékeré, nítorí Èmi fúnra mi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́,” ni Olúwa wí, olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
15 Ímé, én teszlek éles, új cséplőhengerré, a melynek két éle van; hegyeket csépelj és zúzz össze, és a halmokat pozdorjává tegyed.
“Kíyèsi, Èmi yóò sọ ọ́ di òòlù ìpakà tuntun, tí ó mú ti eyín rẹ̀ mú, ìwọ yóò lu àwọn òkè ńlá, ìwọ yóò fọ́ wọn túútúú, a ó sì sọ òkè kékeré di ìyàngbò.
16 Te szórd, és a szél vigye el őket, és elszéleszsze őket a forgószél, és te örülsz az Úrban, és dicsekedel Izráelnek Szentjében.
Ìwọ yóò fẹ́ wọn, afẹ́fẹ́ yóò sì gbá wọn mú, àti ẹ̀fúùfù yóò sì fẹ́ wọn dànù. Ṣùgbọ́n ìwọ yóò yọ̀ nínú Olúwa ìwọ yóò sì ṣògo nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
17 A nyomorultak és szegények keresnek vizet, de nincs, nyelvök a szomjúságban elepedt: én, az Úr meghallgatom őket, én, Izráel Istene, nem hagyom el őket.
“Àwọn tálákà àti aláìní wá omi, ṣùgbọ́n kò sí; ahọ́n wọn gbẹ fún òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n Èmi Olúwa yóò dá wọn lóhùn; Èmi, Ọlọ́run Israẹli, kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
18 Kopasz hegyeken folyókat nyitok és a rónák közepén forrásokat; a pusztát vizek tavává teszem és az aszú földet vizeknek forrásivá.
Èmi yóò mú kí odò kí ó sàn ní ibi gíga àti orísun omi ní àárín àfonífojì. Èmi yóò sọ aṣálẹ̀ di adágún omi, àti ilẹ̀ tí ó gbẹ gidigidi di orísun omi.
19 A pusztában czédrust, akáczot nevelek és mirtust és olajfát, plántálok a kietlenben cziprust, platánt, sudarczédrussal együtt,
Èmi yóò fi sínú aṣálẹ̀ igi kedari àti kasia, maritili àti olifi. Èmi yóò gbin junifa sí inú aginjù, igi firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀
20 Hogy lássák, megtudják, eszökbe vegyék és megértsék mindnyájan, hogy az Úrnak keze mívelte ezt, és Izráel Szentje teremtette ezt!
tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn yóò fi rí i tí wọn yóò sì fi mọ̀, kí wọn ṣàkíyèsí kí ó sì yé wọn, pé ọwọ́ Olúwa ni ó ti ṣe èyí, àti pé, Ẹni Mímọ́ Israẹli ni ó ti dá èyí.
21 Hozzátok ide ügyeteket, szól az Úr, adjátok elő erősségeiteket, így szól Jákób királya.
“Mú ẹjọ́ wá,” ni Olúwa wí. “Tẹ́ àwọn àwíjàre rẹ sílẹ̀,” ni ọba Jakọbu wí,
22 Adják elő és jelentsék meg nékünk, a mik történni fognak; a mik először lesznek, jelentsétek meg, hogy eszünkbe vegyük és megtudjuk végöket, vagy a jövendőket tudassátok velünk!
“Mú àwọn ère òrìṣà rẹ wọlé láti sọ fún wa ohun tí yóò ṣẹlẹ̀. Sọ fún wa ohun tí àwọn nǹkan àtijọ́ jẹ́, kí àwa lè ṣe àgbéyẹ̀wò wọn kí àwa sì mọ àbájáde wọn ní ìparí. Tàbí kí o sọ fún wa ohun tí ó ń bọ̀ wá,
23 Jelentsétek meg, mik lesznek ezután, hogy megtudjuk, hogy ti Istenek vagytok; vagy hát míveljetek jót vagy gonoszt, hogy mérkőzzünk és majd lássuk együtt!
ẹ sọ fún wa ohun ti ọjọ́ iwájú mú dání kí àwa kí ó lè mọ̀ pé ọlọ́run ni yín. Ẹ ṣe nǹkan kan, ìbá à ṣe rere tàbí búburú, tó bẹ́ẹ̀ tí àyà yóò fi fò wá tí ẹ̀rù yóò sì fi kún inú wa.
24 Ímé, ti semmiből valók vagytok, és dolgotok is semmiből való; útálat az, a ki titeket szeret.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yìn ko jásí nǹkan kan iṣẹ́ yín ni kò sì wúlò fún ohunkóhun; ẹni tí ó yàn yín jẹ́ ẹni ìríra.
25 Feltámasztám északról, és eljött napkelet felől; hirdeti nevemet, és tapodja a fejedelmeket, mint az agyagot, és mint a fazekas a sarat tapossa.
“Èmi ti ru ẹnìkan sókè láti àríwá, òun sì ń bọ ẹnìkan láti ìlà-oòrùn tí ó pe orúkọ mi. Òun gun àwọn aláṣẹ mọ́lẹ̀ bí ẹni pé odò ni wọ́n, àfi bí ẹni pé amọ̀kòkò nì ti ń gún amọ̀.
26 Ki jelenté meg ezt eleitől fogva, hogy megtudnók? vagy régen, hogy ezt mondanók: Igaz? De nem jelenté meg, de nem tudatá senki, nem hallá szavatokat senki sem!
Ta ni ó sọ èyí láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, tí àwa kò bá fi mọ̀, tàbí ṣáájú àkókò, tí àwa kò bá fi wí pé, ‘Òun sọ òtítọ́’? Ẹnikẹ́ni kò sọ nípa èyí, ẹnikẹ́ni kò sàsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni kò gbọ́ ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.
27 Sionnak először én hirdetém, ímé itt vannak a tanúk, és örömmondót adtam Jeruzsálemnek.
Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Wò ó, àwọn nìyìí!’ Mo fún Jerusalẹmu ní ìránṣẹ́ ìrò ìròyìn ayọ̀ kan.
28 És néztem és nem volt senki, ezek közül nem volt tanácsadó, hogy megkérdezzem őket és feleljenek nékem.
Èmi wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan— kò sí ẹnìkan nínú wọn tí ó lè mú ìmọ̀ràn wá, kò sí ẹnìkan tí ó lè dáhùn nígbà tí mo bi wọ́n.
29 Ímé, mindnyájan semmik ők, semmiség cselekedetök, szél és hiábavalóság képeik.
Kíyèsi i, irọ́ ni gbogbo wọn! Gbogbo ìṣe wọn jásí asán; àwọn ère wọn kò ṣé kò yà fún afẹ́fẹ́ àti dàrúdàpọ̀.

< Ézsaiás 41 >