< Ézsaiás 38 >
1 Azon napokban halálos betegségbe esék Ezékiás, és eljött hozzá Ésaiás Ámós fia, a próféta, és mondá néki: Ezt mondja az Úr: rendeld el házadat, mert meghalsz és meg nem gyógyulsz!
Ní ọjọ́ náà ni Hesekiah ṣe àìsàn dé ojú ikú. Wòlíì Isaiah ọmọ Amosi sì lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ohun tí Olúwa wí nìyìí: Palẹ̀ ilé è rẹ mọ́, bí ó ti yẹ nítorí pé ìwọ yóò kú; ìwọ kì yóò dìde àìsàn yìí.”
2 És Ezékiás arczczal a falnak fordulván, könyörge az Úrnak,
Hesekiah yí ojú u rẹ̀ sí ara ògiri, ó sì gba àdúrà sí Olúwa,
3 És monda: Oh Uram, emlékezzél meg arról, hogy én előtted jártam, igazságban és egész szívvel, és hogy a mi jó előtted, azt műveltem! és sírt Ezékiás keservesen.
“Rántí, Ìwọ Olúwa, bí mo ti rìn pẹ̀lú òtítọ́ níwájú rẹ, àti bí mo ti fi ọkàn dídúró ṣinṣin ṣe ohun tí ó dára ní ojú ù rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni Hesekiah sì sọkún kíkorò.
4 És lőn az Úr beszéde Ésaiáshoz, mondván:
Lẹ́yìn náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Isaiah wá pé,
5 Menj el, és mondd Ezékiásnak: így szól az Úr, Dávidnak, atyádnak Istene: Hallottam imádságodat, láttam könyeidet, ímé, még napjaidhoz tizenöt esztendőt adok.
“Lọ kí o sì sọ fún Hesekiah pé, ‘Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ọlọ́run Dafidi baba rẹ sọ pé, Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti rí omijé rẹ, Èmi yóò fi ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún kún ọjọ́ ayé rẹ.
6 És az assiriai király kezéből megszabadítlak téged és e várost; megoltalmazom e várost!
Èmi yóò sì gba ìwọ àti ìlú yìí sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria. Èmi yóò sì dáàbò bo ìlú yìí.
7 Ez legyen jel néked az Úrtól, hogy teljesíti azt az Úr, a mit mondott:
“‘Èyí yìí ni àmì tí Olúwa fún ọ láti fihàn wí pé Olúwa yóò mú ìpinnu rẹ̀ ṣẹ.
8 Ímé, visszatérítem az árnyékot, azokon a fokokon, a melyeken az Akház napóráján a nap már átvonult, tíz fokkal; és visszatért az árnyék tíz fokkal azokon a fokokon, a melyeken már átvonult.
Èmi yóò mú òjìji oòrùn kí ó padà sẹ́yìn ní ìṣísẹ̀ mẹ́wàá nínú èyí tí ó fi sọ̀kalẹ̀ ní ibi àtẹ̀gùn ti Ahasi.’” Bẹ́ẹ̀ ni oòrùn padà sẹ́yìn ní ìṣísẹ̀ mẹ́wàá sí ibi tí ó ti dé tẹ́lẹ̀.
9 Ezékiásnak, Júda királyának följegyzése, mikor megbetegedett, és betegségéből fölgyógyult.
Ìwé tí Hesekiah ọba Juda kọ lẹ́yìn àìsàn rẹ̀ nígbà tí ó ti gbádùn tán.
10 Én azt mondám: hát napjaimnak nyugalmában kell alászállanom a sír kapuihoz, megfosztva többi éveimtől! (Sheol )
Èmi wí pé, “Ní àárín gbùngbùn ọjọ́ ayé mi èmi ó ha kọjá lọ ní ibodè ikú kí a sì dùn mí ní àwọn ọdún mi tí ó ṣẹ́kù?” (Sheol )
11 Mondám: nem látom az Urat, az Urat az élők földében, nem szemlélek embert többé a nyugalom lakói közt.
Èmi wí pé, “Èmi kì yóò lè tún rí Olúwa mọ́, àní Olúwa, ní ilẹ̀ àwọn alààyè; èmi kì yóò lè síjú wo ọmọ ènìyàn mọ́, tàbí kí n wà pẹ̀lú àwọn tí ó sì ń gbe orílẹ̀ ayé báyìí.
12 Porsátorom lerontatik, és elmegy tőlem, mint a pásztor hajléka! Összehajtám, mint a takács, életemet; hiszen levágott a fonalról engem; reggeltől estig végzesz velem!
Gẹ́gẹ́ bí àgọ́ olùṣọ́-àgùntàn, ilé mi ni a ti wó lulẹ̀ tí a sì gbà kúrò lọ́wọ́ mi. Gẹ́gẹ́ bí ahunṣọ mo ti ká ayé mi nílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni òun sì ti ké mi kúrò lára àṣà; ọ̀sán àti òru ni ìwọ ṣe òpin mi.
13 Reggelig nyugton vártam; mint oroszlán, úgy törte össze minden csontjaimat; reggeltől estig végzesz velem!
Èmi fi sùúrù dúró títí di àfẹ̀mọ́júmọ́, ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí kìnnìún ó ti fọ́ gbogbo egungun mi; ọ̀sán àti òru ni ìwọ fi ṣe òpin mi.
14 Mint a fecske és a daru, sipogtam, nyögtem mint a galamb, szemeim a magasságba meredtek: Uram! erőszak rajtam, szabadíts meg!
Èmi dún gẹ́gẹ́ bí àkọ̀ tàbí alápáǹdẹ̀dẹ̀, èmi káàánú gẹ́gẹ́ bí aṣọ̀fọ̀ àdàbà. Ojú mi rẹ̀wẹ̀sì gẹ́gẹ́ bí mo ti ń wo àwọn ọ̀run. Ìdààmú bá mi, Ìwọ Olúwa, wá fún ìrànlọ́wọ́ mi!”
15 Mit mondjak? hogy szólott nékem és Ő azt meg is cselekedé! Nyugton élem le éveimet lelkem keserűsége után!
Ṣùgbọ́n kí ni èmi lè sọ? Òun ti bá mi sọ̀rọ̀ àti pé òun tìkára rẹ̀ ló ti ṣe èyí. Èmi yóò máa rìn ní ìrẹ̀lẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ mi nítorí ìpọ́njú ẹ̀mí mi yìí.
16 Oh Uram! ezek által él minden! és ezekben van teljességgel lelkem élete. Te meggyógyítasz és éltetsz engemet!
Olúwa, nípa nǹkan báwọ̀nyí ni àwọn ènìyàn ń gbé; àti pé ẹ̀mí mi rí iyè nínú wọn pẹ̀lú. Ìwọ dá ìlera mi padà kí o sì jẹ́ kí n wà láààyè.
17 Ímé, áldásul volt nékem a nagy keserűség, és Te szeretettel kivontad lelkemet a pusztulásnak verméből, mert hátad mögé vetetted minden bűneimet!
Nítòótọ́ fún àlàáfíà ara mi ni, ní ti pé mo ní ìkorò ńlá. Nínú ìfẹ́ rẹ ìwọ pa mí mọ́, kúrò nínú ọ̀gbun ìparun; ìwọ sì ti fi gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ẹ̀yìn rẹ.
18 Mert nem a sír dicsőít Téged, és nem a halál magasztal Téged, hűségedre nem a sírverembe szállók várnak! (Sheol )
Nítorí pé isà òkú kò le è yìn ọ́, ipò òkú kò le è kọ orin ìyìn rẹ; àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ sínú ọ̀gbun kò lè ní ìrètí fún òtítọ́ rẹ. (Sheol )
19 Ki él, ki él, csak az dicsőít Téged, mint ma én! Az atya a fiaknak hirdeti hűségedet!
Alààyè, àwọn alààyè wọ́n ń yìn ọ́, gẹ́gẹ́ bí èmi ti ń ṣe lónìí; àwọn baba sọ fún àwọn ọmọ wọn nípa òtítọ́ rẹ.
20 Az Úr szabadított meg engemet; azért énekeljük énekimet éltünk minden napjaiban az Úrnak házában!
Olúwa yóò gbà mí là bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò sì kọrin pẹ̀lú ohun èlò olókùn ní gbogbo ọjọ́ ayé wa nínú tẹmpili ti Olúwa.
21 Akkor mondá Ésaiás, hogy vegyenek egy fügekalácsot, és dörzsöljék rá a fekélyre, hogy meggyógyuljon.
Isaiah ti sọ pé, “Pèsè ìṣù ọ̀pọ̀tọ́ (ohun gbígbóná tí a dì mọ́ ojú egbò) kí o sì fi sí ojú oówo náà, òun yóò sì gbádùn.”
22 És mondá Ezékiás: Mi lesz a jele, hogy fölmegyek az Úr házába?
Hesekiah sì béèrè pé, “Kí ni yóò jẹ́ àmì pé èmi yóò gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa?”