< Zsidókhoz 2 >
1 Annakokáért annál is inkább szükséges nékünk a hallottakra figyelmeznünk, hogy valaha el ne sodortassunk.
Nítorí náà, ó yẹ kí àwa máa fi iyè sí àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì gidigidi tí àwa ti gbọ́, kí a má ba à gbá wa lọ kúrò nínú wọn nígbà kan.
2 Mert ha az angyaloktól hirdetett beszéd erős volt és minden bűn és engedetlenség elvette igazságos büntetését:
Nítorí bí ọ̀rọ̀ tí a tí ẹnu àwọn angẹli sọ bá sì dúró ṣinṣin, àti tí olúkúlùkù ẹ̀ṣẹ̀ sí òfin àti àìgbọ́ràn gba ìjìyà tí ó tọ́ sí i,
3 Mimódon menekedünk meg mi, hogyha nem törődünk ily nagy idvességgel? a melyet, miután kezdetben hirdetett az Úr, azok, a kik hallották, biztosítottak számunkra,
kín ni ohun náà tí ó mú wa lérò pé a lè bọ́ kúrò nínú ìjìyà bí a kò bá náání ìgbàlà ńlá yìí? Ìgbàlà tí Olúwa fúnra rẹ̀ kọ́kọ́ kéde, èyí tí a sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ fún wa láti ọwọ́ àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà lẹ́nu rẹ̀.
4 Velök együtt bizonyságot tevén arról az Isten, jelekkel meg csodákkal és sokféle erőkkel s a Szent Léleknek közléseivel az ő akarata szerint.
Ọlọ́run jẹ́rìí sí i nípa àwọn iṣẹ́ àmì àti ìyanu àti oríṣìíríṣìí iṣẹ́ agbára àti nípa ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ tí a pín gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀.
5 Mert nem angyaloknak vetette alá a jövendő világot, a melyről szólunk.
Nítorí pé, kì í ṣe abẹ́ ìṣàkóso àwọn angẹli ni ó fi ayé tí ń bọ̀, tí àwa ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ sí.
6 Sőt bizonyságot tett valahol valaki, mondván: Micsoda az ember, hogy megemlékezel ő róla, avagy az embernek fia, hogy gondod van reá?
Ṣùgbọ́n ibìkan wà tí ẹnìkan tí jẹ́rìí pé “Kí ni ènìyàn tí ìwọ fi ń ṣe ìrántí rẹ̀, tàbí ọmọ ènìyàn, tí ìwọ fi ń bẹ̀ ẹ́ wò?
7 Kisebbé tetted őt rövid időre az angyaloknál, dicsőséggel és tisztességgel megkoronáztad őt és úrrá tetted kezeid munkáin,
Ìwọ dá a ní onírẹ̀lẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ; ìwọ fi ògo àti ọlá de e ni adé, ìwọ sì fi í jẹ olórí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ,
8 Mindent lábai alá vetettél. Mert azzal, hogy néki mindent alávetett, semmit sem hagyott alávetetlenül: de most még nem látjuk, hogy néki minden alávettetett.
Ìwọ fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.” Ní ti fífi ohun gbogbo sábẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n àwa kò ì tí ì rí ohun kan tí ó kù tí kò sí ní abẹ́ àkóso rẹ̀. Síbẹ̀ nísinsin yìí àwa kò ì tí ì rí pé ó fi ohun gbogbo sábẹ́ ìṣàkóso rẹ̀.
9 Azt azonban látjuk, hogy Jézus, a ki egy kevés időre kisebbé tétetett az angyaloknál, a halál elszenvedéséért dicsőséggel és tisztességgel koronáztatott meg, hogy az Isten kegyelméből mindenkiért megízlelje a halált.
Ṣùgbọ́n àwa rí Jesu ẹni tí a rẹ̀ sílẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ fún àkókò díẹ̀, àní Jesu, ẹni tí a fi ògo àti ọlá dé ní adé nítorí ìjìyà wa; kí ó lè tọ́ ikú wò fún olúkúlùkù ènìyàn nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
10 Mert illendő vala, hogy a kiért minden és a ki által minden, sok fiakat vezérelvén dicsőségre, az ő idvességök fejedelmét szenvedések által tegye tökéletessé.
Nítorí pé ó yẹ fún Ọlọ́run, nítorí nípasẹ̀ ẹni tí ohun gbogbo ṣẹ̀ wà, láti mú àwọn ọmọ púpọ̀ wá sínú ògo, láti ṣe balógun ìgbàlà wọn ni àṣepé nípa ìjìyà.
11 Mert a megszentelő és a megszenteltek egytől valók mindnyájan, a mely oknál fogva nem szégyenli őket atyjafiainak hívni,
Nítorí àti ẹni tí ń sọ ni di mímọ́ àti àwọn tí a ń sọ di mímọ́, láti ọ̀dọ̀ ẹnìkan ṣoṣo ni gbogbo wọn ti wá, nítorí èyí ni kò ṣe tijú láti pè wọ́n ni arákùnrin.
12 Mondván: Hirdetem a te nevedet az én atyámfiainak, az anyaszentegyháznak közepette dícséretet mondok néked.
Àti wí pé, “Èmi ó sọ̀rọ̀ orúkọ rẹ̀ fún àwọn ará mi, ni àárín ìjọ ni èmi yóò kọrin ìyìn rẹ̀.”
13 És ismét: Én ő benne bízom; és ismét: Ímhol vagyok én és a gyermekek, a kiket az Isten nékem adott.
Àti pẹ̀lú, “Èmi yóò gbẹ́kẹ̀ mi lé e.” Àti pẹ̀lú, “Kíyèsi í, èmi rèé, èmi àti àwọn ọmọ tí Ọlọ́run fi fún mi.”
14 Mivel tehát a gyermekek testből és vérből valók, ő is hasonlatosképen részese lett azoknak, hogy a halál által megsemmisítse azt, a kinek hatalma van a halálon, tudniillik az ördögöt,
Ǹjẹ́ ni ìwọ̀n bí àwọn ọmọ tí ṣe alábápín ará àti ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni òun pẹ̀lú sì ṣe alábápín nínú ohun kan náà; kí ó lè ti ipa ikú rẹ̀ pa ẹni tí ó ní agbára ikú run, èyí ni èṣù.
15 És megszabadítsa azokat, a kik a haláltól való félelem miatt teljes életökben rabok valának.
Kí o sì lè gba gbogbo àwọn tí ó tìtorí ìbẹ̀rù ikú wà lábẹ́ ìdè lọ́jọ́ ayé wọn gbogbo kúrò lọ́wọ́ ìbẹ̀rù.
16 Mert nyilván nem angyalokat karolt fel, hanem az Ábrahám magvát karolta fel.
Nítorí pé, nítòótọ́, kì í ṣe àwọn angẹli ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún, ṣùgbọ́n àwọn irú-ọmọ Abrahamu ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún.
17 Annakokáért mindenestől fogva hasonlatosnak kellett lennie az atyafiakhoz, hogy könyörülő legyen és hív főpap az Isten előtt való dolgokban, hogy engesztelést szerezzen a nép bűneiért.
Nítorí náà, ó yẹ pé nínú ohun gbogbo kí ó dàbí àwọn ará rẹ̀, kí ó lè jẹ́ aláàánú àti olóòtítọ́ alábojútó Àlùfáà nínú ohun tí i ṣe ti Ọlọ́run, kí o lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn.
18 Mert a mennyiben szenvedett, ő maga is megkísértetvén, segíthet azokon, a kik megkísértetnek.
Nítorí níwọ̀n bí òun tìkára rẹ̀ ti jìyà tí a sì ti dán an wò, òun ní agbára láti ran àwọn tí a ń dánwò lọ́wọ́.