< Ezsdrás 9 >
1 Minekutána ezek elvégeződének, jövének hozzám a főemberek, mondván: Izráel népe és a papok és a Léviták nem különíték el magokat e tartományok népeitől, a miképen pedig azoknak, a Kananeusoknak, Hitteusoknak, Perizeusoknak, Jebuzeusoknak, Ammonitáknak, Moábitáknak, Égyiptomiaknak és Emoreusoknak útálatos vétke szerint el kellett volna,
Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí tán, àwọn olórí tọ̀ mí wá, wọ́n sì wí pé, “Àwọn ènìyàn Israẹli, tí ó fi mọ́ àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, kò tì í ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn agbègbè tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra bí i ti àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, àwọn ará Peresi, àwọn ará Jebusi, àwọn ará Ammoni, àwọn ará Moabu, àwọn ará Ejibiti àti ti àwọn ará Amori.
2 Mert ezek leányai közül vettek vala feleséget magoknak és fiaiknak, és megelegyedett a szent mag e tartományok népeivel; és pedig a fejedelmek és főemberek valának elsők e bűnben.
Wọ́n ti fẹ́ lára àwọn ọmọbìnrin wọn fún ara wọn àti fún àwọn ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí aya, wọ́n ti da irú-ọmọ ìran mímọ́ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn ti ó wà ní àyíká wọn. Àwọn olórí àti àwọn ìjòyè ta àwọn ènìyàn tókù yọ nínú híhu ìwà àìṣòótọ́.”
3 Mihelyt e dolgot meghallottam, megszaggatám alsó- és felső ruhámat, s téptem fejem hajszálait és szakállamat, és veszteg ültem.
Nígbà tí mo gbọ́ èyí, mo fa àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi ya, mo tu irun orí àti irùngbọ̀n mi, mo sì jókòó ní ìjayà.
4 És hozzám gyűlének mindnyájan, a kik reszketve gondoltak Izráel Istenének beszédeire azoknak vétke miatt, a kik a fogságból megjöttek vala; és én veszteg ülök vala mind az estvéli áldozatig.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn tí ó wárìrì sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Israẹli kó ara wọn jọ yí mi ká nítorí àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn yìí. Èmi sì jókòó níbẹ̀ ní ìjayà títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́.
5 Az estvéli áldozatkor pedig felkeltem sanyargatásomból, megszaggatván alsó- és felső ruhámat; és térdeimre esvén, kiterjesztém kezeimet az Úrhoz, az én Istenemhez.
Ní ìgbà tí ó di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, mo dìde kúrò nínú ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn mi, pẹ̀lú àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi yíya ní ọrùn mi, mo kúnlẹ̀ lórí eékún mi méjèèjì, mo sì tẹ́ ọwọ́ mi méjèèjì sí Olúwa Ọlọ́run mi.
6 És mondék: Én Istenem, szégyenlem és átallom felemelni, én Istenem, az én orczámat te hozzád, mert a mi álnokságaink felülhaladtak fejünk fölött és a mi vétkeink mind az égig nevekedtek!
Mo sì gbàdúrà: “Ojú tì mí gidigidi, tí n kò fi lè gbé ojú mi sókè sí ọ̀dọ̀ rẹ, Ọlọ́run mi, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wá di púpọ̀ ní orí wa, ẹ̀bi wa sì ga kan àwọn ọ̀run.
7 A mi atyáink napjaitól fogva nagy vétekben vagyunk mi mind e mai napig, és a mi álnokságainkért adattunk vala mi, a mi királyaink és a mi papjaink a földi királyok kezébe, fegyver által rabságra és ragadományra és orczapirulásra, a mint ez a mai nap is van.
Láti ọjọ́ àwọn baba wá ni ẹ̀bi wa ti pọ̀ jọjọ títí di ìsinsin yìí. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa, àwa àti àwọn ọba wa àti àwọn àlùfáà wa ni a ti sọ di ẹni idà, ẹni ìgbèkùn, ìkógun àti ẹni ẹ̀sín lọ́wọ́ àwọn àjèjì ọba, bí ó ti rí lónìí.
8 És most nem sok ideje, hogy az Úr, a mi Istenünk rajtunk könyörült, hogy hagyjon minékünk maradékot, és hogy adjon nékünk egy szeget az ő szent helyén, hogy így megvilágosítsa szemeinket a mi Istenünk, s hogy megelevenítsen bennünket egy kissé a mi szolgaságunkban.
“Ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí, fún ìgbà díẹ̀, ni a ti fi oore-ọ̀fẹ́ fún wa láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa wá láti sálà, àti láti fi èèkàn fún wa ni ibi mímọ́ rẹ̀, nítorí kí Ọlọ́run kí ó lè mú ojú wa mọ́lẹ̀, kí ó sì tún wa gbé dìde díẹ̀ kúrò nínú ìgbèkùn wa.
9 Mert szolgák vagyunk mi, de szolgaságunkban nem hagyott el minket a mi Istenünk, hanem hozzánk fordítá irgalmasságát Persiának királyai előtt, hogy megelevenítene bennünket, hogy felemelhessük a mi Istenünk házát s megépíthessük annak romjait, és hogy adjon nékünk bátorságos lakást Júdában és Jeruzsálemben.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwa jẹ́ ẹrú, Ọlọ́run wa kò fi wa sílẹ̀ nínú ìgbèkùn wa. Ó ti fi àánú hàn fún wa ni iwájú àwọn ọba Persia: Ó ti fún wa ní ìgbé ayé tuntun láti tún odi ilé Ọlọ́run wa mọ, kí a sì tún àwókù rẹ̀ ṣe, ó sì fi odi ààbò fún wa ní Juda àti ní Jerusalẹmu.
10 És most mit mondjunk, óh mi Istenünk, mindezek után? Azt, hogy mi mégis elhagytuk parancsolataidat,
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, kí ni àwa yóò wí lẹ́yìn èyí? Nítorí tí àwa kọ àṣẹ rẹ sílẹ̀
11 A melyeket parancsoltál szolgáid, a próféták által, mondván: A föld, melyre bementek, hogy bírjátok azt, tisztátalan föld, a tartományok népeinek tisztátalansága miatt, útálatosságaik miatt, melyekkel betölték azt egyik végétől a másikig tisztátalanságukban;
èyí tí ìwọ ti pa fún wa láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, nígbà ti ìwọ wí pé, ‘Ilẹ̀ náà ti ẹ̀yin ń wọ̀ lọ láti gbà n nì jẹ́ ilẹ̀ aláìmọ́ tó kún fún ẹ̀gbin àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, nípa ṣíṣe ohun ìríra àti híhu ìwà èérí ti kún ún láti ìkángun kan dé èkejì.
12 Annakokáért leányaitokat ne adjátok az ő fiaiknak és az ő leányaikat ne vegyétek fiaitoknak, és ne keressétek barátságukat, sem javokat soha, hogy megerősödjetek és éljetek e föld javaival, és örökségképen adhassátok azt fiaitoknak mindörökké.
Nítorí náà, ẹ má ṣe fi àwọn ọmọbìnrin yín fún àwọn ọmọkùnrin wọn ní ìyàwó tàbí kí ẹ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó. Ẹ má ṣe dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn nígbàkígbà kí ẹ̀yin kí ó sì le lágbára, kí ẹ sì le máa jẹ ire ilẹ̀ náà, kí ẹ sì le fi í sílẹ̀ fún àwọn ọmọ yín gẹ́gẹ́ bí ogún ayérayé.’
13 Mindazok után pedig, a mik reánk jövének gonosz cselekedeteinkért és nagy vétkünkért, hiszen te, mi Istenünk, jobban kedveztél nékünk, sem mint bűneink miatt érdemeltünk volna, s adád nékünk e maradékot,
“Ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa jẹ́ àyọríṣí iṣẹ́ búburú wa àti ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ńlá wa, síbẹ̀, Ọlọ́run wa, ìjìyà ti ìwọ fún wa kéré si ìjìyà tí ó yẹ fún ẹ̀ṣẹ̀ ti a dá, ìwọ sì fún wa ní àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù bí èyí.
14 Hát megrontjuk-é ismét parancsolataidat s összeházasodunk-é ez útálatos népekkel? Nem fogsz-é haragudni reánk mindaddig, míg megemésztetünk, hogy sem maradékunk, sem hírmondónk ne legyen?
Ǹjẹ́ ó yẹ kí àwa tún yẹ̀ kúrò nínú àṣẹ rẹ, kí a sì máa ṣe ìgbéyàwó papọ̀ pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọn ti ṣe onírúurú ohun ìríra báyìí? Ṣe ìwọ kò ní bínú sí wa láti pa wá run tí kì yóò sẹ́ ku ẹnikẹ́ni tí yóò là?
15 Oh Uram, Izráel Istene! igaz vagy te, mert meghagytál minket, maradék gyanánt, mint e mai nap bizonyítja. Ímé előtted vagyunk vétkünkben, és nem állhatunk meg előtted e miatt!
Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ìwọ jẹ́ olódodo! Àwa ìgbèkùn tí ó ṣẹ́kù bí ó ti rí lónìí. Àwa dúró níwájú rẹ nínú ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé nítorí èyí ẹnikẹ́ni nínú wa kò lè dúró níwájú rẹ”.