< Ezékiel 5 >

1 És te, embernek fia, végy magadnak éles kardot, borbélyok beretvájául vedd azt magadnak, és vond el azt a te fejeden és szakálladon, és végy magadnak mérő serpenyőket, és oszd el szőrüket.
“Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
2 Harmadrészét tűzben égesd meg a város közepette, midőn betelnek a megszállásnak napjai; azután vedd a harmadrészét, vagdald apróra a karddal a város körül, és harmadrészét szórd oda a szélnek, és én kardot vonszok utánok.
Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
3 És végy ki innét szám szerint keveset, és kösd be azokat ruhád csücskébe;
Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
4 És ezekből ismét végy ki, és vesd azokat a tűz közepébe és égesd meg a tűzben; ebből megyen tűz Izráel egész házára.
Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
5 Így szól az Úr Isten: Ez Jeruzsálem, a pogányok közibe helyheztettem őt, és körülte a tartományokat.
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
6 De pártos volt törvényeim iránt, gonoszabbul, mint a pogányok, és rendeléseim iránt inkább, mint a tartományok, a melyek körülte vannak, mert törvényeimet megútálták, és rendeléseimben nem jártak.
Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
7 Azért így szól az Úr Isten: A miért ti pártosabbak valátok, mint a pogányok, a kik körültetek vannak, rendeléseimben nem jártatok és törvényeimet nem cselekedtétek, sőt csak a pogányok törvényei szerint is, a kik körültetek vannak, nem cselekedtetek:
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
8 Ezokért így szól az Úr Isten: Ímé én is ellened leszek, és teszek közötted ítéletet a pogányok szeme láttára;
“Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
9 És cselekszem rajtad azt, mit soha nem cselekedtem és minéműt nem cselekszem többé, – minden te útálatosságidért.
Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
10 Azért az apák egyék meg fiaikat te közötted, és a fiak egyék meg apáikat, és cselekszem rajtad ítéletet, és szétszórom minden maradékodat a szél minden irányában.
Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
11 Ezért, élek én! szól az Úr Isten, bizonyára, mivelhogy szenthelyemet megfertéztetted minden undokságaiddal és minden útálatosságaiddal, azért én is elfordítom rólad irgalom nélkül szememet, s én sem könyörülök rajtad.
Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
12 Harmadrészed döghalállal hal meg és éhség miatt pusztul el közötted, és harmadrészed fegyver miatt hull el körülötted, és harmadrészedet szétszórom a szél minden irányában, és kardot vonszok utánok.
Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
13 És teljessé lesz haragom s nyugtatom rajtok búsulásomat s vígasztalást veszek; és megértik, hogy én, az Úr szóltam buzgó szerelmemben, mikor betöltöm búsulásomat rajtok.
“Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
14 És teszlek pusztasággá és gyalázattá a pogányok között, a kik körülted vannak, minden melletted elmenő szeme láttára.
“Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
15 És leszel gyalázat és csúfság, példa és eliszonyodás a pogányoknak, a kik körülted vannak, mikor ítéletet tartok fölötted haraggal és búsulással és búsult feddésekkel, én, az Úr mondottam;
O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
16 Mikor bocsátom az éhség gonosz nyilait rájok, hogy pusztítsanak, a melyeket a ti pusztítástokra fogok bocsátani; és éhséget halmozok fölétek, és eltöröm köztetek a kenyér botját.
Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
17 És bocsátok reátok éhséget és gonosz vadállatokat, hogy gyermektelenné tegyenek, és döghalál és vérontás megy át rajtad, és fegyvert hozok reád, én, az Úr mondottam.
Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”

< Ezékiel 5 >