< Ezékiel 30 >
1 És lőn az Úr beszéde hozzám, mondván:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: wí pé:
2 Embernek fia! prófétálj és mondd: Így szól az Úr Isten: Jajgassatok! Jaj annak a napnak!
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí o sì wí pé: ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Hu, kí o sì wí pé, “Ó ṣe fún ọjọ́ náà!”
3 Mert közel egy nap és közel az Úrnak napja, felhőnek napja, a pogányok ideje lesz az.
Nítorí ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí àní ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, ọjọ́ tí ọjọ́ ìkùùkuu ṣú dúdú, àsìkò ìparun fún àwọn kèfèrí.
4 És bemegy a fegyver Égyiptomba, és lesz reszketés Szerecsenországban, mikor hullanak a sebesültek Égyiptomban, és elviszik gazdagságát, s elrontatnak fundamentomai.
Idà yóò wá sórí Ejibiti ìrora ńlá yóò sì wá sórí Kuṣi. Nígbà tí àwọn tí a pa yóò ṣubú ní Ejibiti wọn yóò kò ọrọ̀ rẹ̀ lọ ìpìlẹ̀ rẹ̀ yóò sì wó lulẹ̀.
5 A szerecsenek s a libiaiak s a lidiaiak és az egész gyülevész és Kúb és a frigy földének fiai velök együtt fegyver miatt hullnak el.
Kuṣi àti Puti, Libia, Ludi àti gbogbo Arabia, Kubu àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó mulẹ̀ yóò ṣubú nípa idà pẹ̀lú Ejibiti.
6 Így szól az Úr: És elessenek, a kik Égyiptomot támogatják, és alászálljon erősségének kevélysége: Migdoltól fogva Siénéig fegyver miatt hullanak el benne, ezt mondja az Úr Isten.
“‘Èyí yìí ní Olúwa wí: “‘Àwọn àlejò Ejibiti yóò ṣubú agbára ìgbéraga rẹ yóò kùnà láti Migdoli títí dé Siene, wọn yóò ti ipa idà ṣubú nínú rẹ; ní Olúwa Olódùmarè wí.
7 És elpusztulnak elpusztult tartományok között, és városai elpusztult városoknak közepette lesznek.
Wọn yóò sì wà lára àwọn ilẹ̀ tí ó di ahoro, ìlú rẹ yóò sì wà ní ara àwọn ìlú tí ó di ahoro.
8 És megtudják, hogy én vagyok az Úr, mikor tüzet vetek Égyiptomra, és összetörik minden segítője.
Lẹ́yìn náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá gbé iná kalẹ̀ ní Ejibiti tí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá parun.
9 Azon a napon követek mennek ki előttem hajókon a bátorságban lakó Szerecsenország elrémítésére, s lészen rettegés bennök Égyiptom ama napján; mert ímé jön!
“‘Ní ọjọ́ náà oníṣẹ́ yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde nínú ọkọ̀ ojú omi láti dẹ́rùbà Kuṣi tí ó wà nínú àlàáfíà. Ìrora yóò wá sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ ìparun Ejibiti. Kíyèsi i, ó dé.
10 Ezt mondja az Úr Isten: És megszüntetem Égyiptom lármáját Nabukodonozor, babiloni király keze által.
“‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò mú òpin bá ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn Ejibiti láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli.
11 Ő és az ő népe ő vele együtt, a nemzetek legkegyetlenebbjei, elhozatnak a föld elvesztésére, és kivonszák fegyveröket Égyiptom ellen, és betöltik a földet megölettekkel.
Òun àti àwọn ológun rẹ̀ ẹ̀rù àwọn orílẹ̀-èdè ní a o mú wá láti pa ilẹ̀ náà run. Wọn yóò fa idà wọn yọ sí Ejibiti ilẹ̀ náà yóò sì kún fún àwọn tí a pa.
12 És a folyóvizeket kiszárasztom, és eladom a földet gonoszok kezébe, és elpusztítom a földet s teljességét idegenek keze által, én, az Úr szólottam.
Èmi yóò mú kí àwọn odò Naili gbẹ, Èmi yóò sì ta ilẹ̀ náà fún àwọn ènìyàn búburú: láti ọwọ́ àwọn àjèjì ènìyàn, Èmi yóò jẹ́ kí ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tí ó wá nínú rẹ ṣòfò. Èmi Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
13 Így szól az Úr Isten: És elvesztem a bálványokat és megszüntetem a bálványképeket Nófból s a fejedelmet Égyiptom földjéről, nem lészen többé, és bocsátok félelmet Égyiptom földjére.
“‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò pa àwọn òrìṣà run, Èmi yóò sì mú kí òpin dé bá ère gbígbẹ́ ni Memfisi. Kò ní sí ọmọ-aládé mọ́ ní Ejibiti, Èmi yóò mú kí ìbẹ̀rù gba gbogbo ilẹ̀ náà.
14 És elpusztítom Pathróst, s vetek tüzet Zoánra, és teszek ítéleteket Nóban.
Èmi yóò sì mú kí Paturosi di ahoro, èmi yóò fi iná sí Ṣoani, èmi yóò sì fi ìyà jẹ Tebesi.
15 És kiöntöm haragomat Sinre, Égyiptom erősségére, és kivágom a sokaságot Nóból.
Èmi yóò tú ìbínú mi jáde sórí Pelusiumu ìlú odi Ejibiti èmi yóò sì ké àkójọpọ̀ Tebesi kúrò.
16 És vetek tüzet Égyiptomra, kínok közt vergődik Sin, és Nó megtörik és Nófba betörnek fényes nappal.
Èmi yóò ti iná bọ Ejibiti Pelusiumu yóò japoró ní ìrora. Ìjì líle yóò jà ní Tebesi Memfisi yóò wà ìpọ́njú ní ìgbà gbogbo.
17 Aven és Fibéseth ifjai fegyver miatt hullanak el, és ők magok fogságra mennek.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ní Heliopolisi àti Bubasiti yóò ti ipa idà ṣubú wọn yóò sì kó àwọn ìlú wọn ní ìgbèkùn.
18 És Tehafneheszben megsötétedik a nap, mikor ott összetöröm Égyiptom pálczáját, és megszünik benne erejének kevélysége, őt magát felhő takarja el, és leányai fogságra mennek.
Ojú ọjọ́ yóò ṣókùnkùn ní Tafanesi nígbà tí mo bá já àjàgà Ejibiti kúrò; níbẹ̀ agbára iyì rẹ̀ yóò dópin wọn yóò fi ìkùùkuu bò ó àwọn abúlé rẹ ní wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
19 És cselekszem ítéleteket Égyiptomban, és megtudják, hogy én vagyok az Úr.
Nítorí náà, Èmi yóò mú ki ìjìyà wá sórí Ejibiti, wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
20 És lőn a tizenegyedik esztendőben, az első hónapban, a hónap hetedikén, lőn az Úr beszéde hozzám, mondván:
Ní ọjọ́ keje oṣù kìn-ín-ní ọdún kọkànlá ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
21 Embernek fia! A Faraónak, Égyiptom királyának karját eltörtem, és ímé be nem kötötték, hogy megorvosolják, hogy tegyenek körülkötést reá, hogy megerősödjék fegyverfogásra.
“Ọmọ ènìyàn, Èmi ti ṣẹ́ apá Farao ọba Ejibiti. A kò ì tí ì di apá náà papọ̀ láti mu kí ó san, a kò sì ti di i si àárín igi pẹlẹbẹ kí o lè ni agbára tó láti di idà mú.
22 Ennekokáért így szól az Úr Isten: Ímé, a Faraó ellen megyek, Égyiptomnak királya ellen, és eltöröm mind a két karját, azt, amely még erős, és azt, amely már eltörött, s elejtetem vele kezéből a fegyvert.
Nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí Farao ọba Ejibiti. Èmi yóò sẹ́ apá rẹ̀ méjèèjì, èyí tí ó dára àti èyí tí a ti ṣẹ́ pẹ̀lú, yóò sì mú kí idà bọ́ sọnù ní ọwọ́ rẹ̀.
23 És eloszlatom az Égyiptombelieket a nemzetek közé, és szétszórom őket a tartományokba.
Èmi yóò sì fọ́n àwọn ènìyàn Ejibiti ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká gbogbo ilẹ̀.
24 És megerősítem Babilon királyának karjait, és adom az én fegyveremet kezébe, és eltöröm a Faraó karjait, és nyögni fog előtte, mint a megsebesültek szoktak.
Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli ní agbára, èmi yóò sì fi idà mi sí ọwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ apá Farao, yóò sì kérora níwájú rẹ̀ bí ọkùnrin tí a sá ní àṣápa.
25 Megerősítem azért Babilon királyának karjait, a Faraó karjai pedig leessenek, hogy megtudják, hogy én vagyok az Úr, mikor adom fegyveremet Babilon királyának kezébe, hogy azt kinyújtsa Égyiptomnak földje ellen.
Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli lé, ṣùgbọ́n apá Farao yóò sì rọ. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú idà mi sí ọwọ́ ọba Babeli yóò sì fi idà náà kọlu Ejibiti.
26 És eloszlatom az égyiptomiakat a nemzetek közé, és szétszórom őket a tartományokba, hogy megtudják, hogy én vagyok az Úr.
Èmi yóò fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí gbogbo ilẹ̀. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”