< Ezékiel 11 >

1 És fölemelt engem a lélek, és bevive az Úr házának keleti kapujához, a mely néz keletnek, és ímé, a kapu bejáratánál huszonöt férfi vala, kik között látám Jaazanját, Azzur fiát, és Pelatjáhut, Benájáhu fiát, a nép fejedelmeit.
Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
2 És mondá nékem: Embernek fia! ezek a férfiak, a kik gonoszt eszelnek ki és rossz tanácsot adnak ebben a városban,
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
3 Mondván: Nem egyhamar fogunk házakat építeni; ez a város a fazék, mi pedig a hús.
Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
4 Azért prófétálj ellenök; prófétálj, embernek fia!
Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
5 És esék reám az Úr lelke, és mondá nékem: Mondjad, így szól az Úr: Így szólottatok, Izráel háza! és a mi lelketekben készül, én tudom.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
6 Sokakat öltetek meg ebben a városban, és utczáit megtöltöttétek megölettekkel.
Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
7 Ezért, így szól az Úr Isten: Megöletteitek, kiket a város közepére vetettetek, ezek a hús, a város pedig a fazék, és titeket kivisznek belőle.
“Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
8 Fegyvertől féltetek, fegyvert hozok reátok, azt mondja az Úr Isten.
Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 És kiviszlek titeket belőle, és adlak titeket idegenek kezébe, és tartok ítéletet fölöttetek.
Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
10 Fegyver miatt hulljatok el, Izráel határán ítéllek meg titeket, és megtudjátok, hogy én vagyok az Úr.
Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
11 E város ne legyen fazekatok, hogy ti benne hús legyetek, Izráel határán ítéllek el titeket.
Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
12 És megtudjátok, hogy én vagyok az Úr, mert az én végzéseimben nem jártatok, és rendeléseimet nem cselekedtétek, hanem a pogányok módja szerint cselekedtetek, a kik körültetek vannak.
Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
13 És lőn, mikor prófétáltam, Pelatjáhu, Benájáhu fia meghala, én pedig orczámra esém és kiálték nagy felszóval, és mondék: Ah, ah, Uram Isten, te véget vetsz Izráel maradékának!
Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
14 És lőn az Úrnak szava én hozzám, mondván:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
15 Embernek fia! a te atyádfiai, atyádfiai, a te rokonaid és Izráel egész háza együtt azok, a kikről Jeruzsálem lakói ezt mondják: távozzatok el az Úrtól, nékünk adatott ez a föld örökségül.
“Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
16 Ezokáért mondjad: így szól az Úr Isten: Mivelhogy távol vetettem őket a pogányok közé, és szétszórtam őket a tartományokba, tehát én leszek nékik templomul rövid időre a tartományokban, a melyekbe mentek.
“Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
17 Ennekokáért mondjad: Így szól az Úr Isten: Egybegyűjtelek titeket a népek közül és együvé hozlak titeket a tartományokból, a melyekben szétszórattatok, és adom néktek Izráel földjét.
“Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
18 És bemennek oda és eltávolítják minden ő fertelmességeit és minden útálatosságait ő belőle.
“Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
19 És adok nékik egy szívet, és új lelket adok belétek, és eltávolítom a kőszívet az ő testökből, és adok nékik hússzívet;
Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
20 Hogy az én végzéseimben járjanak és rendeléseimet megőrizzék és cselekedjék azokat, és legyenek nékem népem és én leszek nékik Istenök.
Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
21 De a kiknek szívök az ő fertelmességeik és útálatosságaik szíve szerint jár, azoknak útját fejökhöz verem, mondja az Úr Isten.
Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
22 És fölemelék a Kérubok szárnyaikat s a kerekek mellettök, és Izráel Istenének dicsősége rajtok felül vala.
Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
23 És felszálla az Úrnak dicsősége a város közepéből, és álla a hegyre, mely a várostól keletre van.
Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
24 A lélek pedig felvőn engem, és vive Káldeába a foglyokhoz látásban az Isten lelke által, és felszálla előlem a látás, a melyet láttam.
Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
25 És elbeszélém a foglyoknak az Úrnak minden beszédét, a melyet nékem megjelentetett.
mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.

< Ezékiel 11 >