< Kolosséiakhoz 1 >

1 Pál, Jézus Krisztusnak apostola Isten akaratjából, és Timótheus atyafi.
Paulu, aposteli Jesu Kristi nípa ìfẹ́ Ọlọ́run àti Timotiu arákùnrin wa,
2 A Kolosséban levő szenteknek és hívő atyafiaknak a Krisztusban: kegyelem néktek és békesség Istentől, a mi Atyánktól, és az Úr Jézus Krisztustól.
Sí àwọn ẹni mímọ́ àti àwọn arákùnrin àti arábìnrin nínú Kristi tí wọ́n ń gbé ní ìlú Kolose: Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà fún un yín láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa.
3 Hálát adunk az Istennek és a mi Urunk Jézus Krisztus Atyjának, mindenkor ti értetek könyörögvén,
Nígbàkígbà tí a bá ń gbàdúrà fún un yín ni a máa ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run Baba Olúwa wa Jesu Kristi.
4 Mivelhogy hallottuk a ti hiteteket a Krisztus Jézusban, és a szeretetet, a melylyel minden szentekhez vagytok,
Nítorí a ti gbúròó ìgbàgbọ́ yín nínú Jesu Kristi, àti bí ẹ ti ṣe fẹ́ràn gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́.
5 A mennyekben néktek eltett reménységért, a melyet már előbb hallottatok az igazság beszédében, mely az evangyéliom:
Ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́ tí ń sàn nínú ìrètí tí a gbé pamọ́ fún un yín ní ọ̀run èyí tí ẹ̀yin sì ti gbọ́ tẹ́lẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ òtítọ́ ìyìnrere náà,
6 Mely eljutott hozzátok, miképen az egész világra is, és gyümölcsöt terem, úgy mint nálatok is a naptól fogva, melyen hallottátok és megismertétek az Isten kegyelmét igazán:
èyí tí ó ti dé ọ̀dọ̀ yín. Káàkiri àgbáyé ni ìyìnrere yìí ń so èso tí ó sì ń dàgbà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń ṣe láàrín yín láti ọjọ́ náà tí ẹ ti gbọ́ ọ, tí ẹ sì ní ìmọ̀ oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run nínú gbogbo òtítọ́ rẹ̀.
7 Úgy a hogy tanultátok is Epafrástól, a mi szerelmes szolgatársunktól, a ki hív szolgája ti érettetek a Krisztusnak,
Ẹ̀yin ti kọ́ ọ lọ́dọ̀ Epafira, ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ wa olùfẹ́, ẹni tí ó jẹ́ olóòtítọ́ ìránṣẹ́ Kristi ní ipò wa.
8 A ki meg is jelentette nékünk a ti Lélekben való szereteteteket.
Ẹni ti ó sọ fún wa nípa ìfẹ́ yín nínú ẹ̀mí.
9 Azért mi is, a mely naptól fogva ezeket hallottuk, nem szűnünk meg érettetek imádkozni, és kérni, hogy betöltessetek az Isten akaratának megismerésével minden lelki bölcseségben és értelemben,
Nítorí ìdí èyí, láti ọjọ́ tí a ti gbọ́ nípa yín, a kò sinmi láti máa gbàdúrà fún yin, tí a sì ń gbàdúrà pé kí Ọlọ́run fi ìmọ̀ ìfẹ́ rẹ̀ kún yín nípasẹ̀ ọgbọ́n àti òye gbogbo tí ń ṣe ti Ẹ̀mí.
10 Hogy járjatok méltóan az Úrhoz, teljes tetszésére, minden jó cselekedettel gyümölcsöt teremvén és nevekedvén az Isten megismerésében;
Àwa sì ń gbàdúrà yìí kí ẹ lè gbé irú ìgbé ayé tó yẹ fún Olúwa kí ẹ sì máa wu ú ní gbogbo ọ̀nà, kí ẹ sì máa so èso rere gbogbo, kí ẹ sì máa dàgbà nínú ìmọ̀ Ọlọ́run,
11 Minden erővel megerősíttetvén az Ő dicsőségének hatalma szerint minden kitartásra és hosszútűrésre örömmel;
pé kí a lè fi ipa gbogbo sọ yín di alágbára gẹ́gẹ́ bí agbára rẹ̀ àti ògo rẹ̀, kí ó lè ṣe é ṣe fún un yín láti máa tẹ̀síwájú nínú sùúrù àti ìpamọ́ra pẹ̀lú ayọ̀.
12 Hálákat adván az Atyának, ki alkalmasakká tett minket a szentek örökségében való részvételre a világosságban;
Kí a máa dúpẹ́ nígbà gbogbo lọ́wọ́ Baba, ẹni tí ó kà yín láti jẹ́ alábápín nínú ogún àwọn ẹni mímọ́ nínú ìjọba ìmọ́lẹ̀.
13 A ki megszabadított minket a sötétség hatalmából, és általvitt az Ő szerelmes Fiának országába;
Nítorí tí ó ti já wa gbà kúrò nínú agbára òkùnkùn ó sì mú wa wá sí ìjọba Ọmọ tí ó fẹ́ràn.
14 Kiben van a mi váltságunk az Ő vére által, bűneinknek bocsánata;
Nínú ẹni tí a ní ìràpadà, àti ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀.
15 A ki képe a láthatatlan Istennek, minden teremtménynek előtte született;
Kristi ni àwòrán Ọlọ́run tí a kò le rí, àkọ́bí gbogbo ẹ̀dá.
16 Mert Ő benne teremtetett minden, a mi van a mennyekben és a földön, láthatók és láthatatlanok, akár királyi székek, akár uraságok, akár fejedelemségek, akár hatalmasságok; mindenek Ő általa és Ő reá nézve teremttettek;
Nítorí nípa rẹ̀ ní a dá ohun gbogbo: àwọn ohun tí ń bẹ ní ọ̀run àti ní ayé, ohun tí a rí àti èyí tí a kò rí, wọn ìbá ṣe ìtẹ́, tàbí agbára, tàbí àṣẹ, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo àti fún un.
17 És Ő előbb volt mindennél, és minden Ő benne áll fenn.
Ó ti wà ṣáájú kí ohunkóhun tó wà, nínú rẹ̀ ni a sì so ohun gbogbo papọ̀ ṣọ̀kan.
18 És Ő a feje a testnek, az egyháznak: a ki a kezdet, elsőszülött a halottak közül; hogy mindenekben Ő legyen az első;
Òun ni orí fún ara, èyí tí í ṣe ìjọ; òun ni ìbẹ̀rẹ̀ àti àkọ́bí nínú àwọn òkú, pé nínú ohun gbogbo kí òun lè ní ipò tí ó ga jùlọ nínú ohunkóhun.
19 Mert tetszett az Atyának, hogy Ő benne lakozzék az egész teljesség;
Nítorí ìfẹ́ Ọlọ́run ni pé kí gbogbo ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ òun tìkára rẹ̀ lè máa gbé nínú rẹ̀.
20 És hogy Ő általa békéltessen meg mindent Magával, békességet szerezvén az Ő keresztjének vére által; Ő általa mindent, a mi csak van, akár a földön, akár a mennyekben.
Àti nípasẹ̀ rẹ̀ láti bá ohun gbogbo làjà àwọn nǹkan tí ń bẹ láyé àti èyí tí ń bẹ ní ọ̀run, nípa mímú àlàáfíà wá nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, tí a ta sílẹ̀ lórí igi àgbélébùú.
21 Titeket is, kik hajdan elidegenültek és ellenségek valátok gonosz cselekedetekben gyönyörködő értelmetek miatt, most mégis megbékéltetett.
Ẹ̀yin ya ara yín nípá kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run nígbà kan rí, ẹ jẹ́ ọ̀tá nínú ọkàn yín nítorí ìwà búburú yín.
22 Az Ő emberi testében a halál által, hogy mint szenteket, tisztákat és feddhetetleneket állasson titeket Ő maga elé:
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti bá yín làjà nípa ara Kristi nípa ikú láti mú un yín lọ sí iwájú rẹ̀ ní mímọ́, aláìlábàwọ́n àti kúrò nínú ìdálẹ́bi,
23 Ha ugyan megmaradtok a hitben alaposan és erősen, és el nem távoztok az evangyéliom reménységétől, a melyet hallottatok, a mely hirdettetett minden teremtménynek az ég alatt; a melynek lettem én, Pál, szolgájává.
bí ẹ̀yin bá dúró nínú ìgbàgbọ́ yín, tí ẹ fi ẹsẹ̀ múlẹ̀, tí ẹ sì dúró ṣinṣin, láláìyẹsẹ̀ kúrò nínú ìrètí ti ìyìnrere ti ẹ̀yin ti gbọ́, èyí tí a ti wàásù rẹ̀ fún gbogbo ẹ̀dá lábẹ́ ọ̀run, àti èyí ti èmi Paulu ṣe ìránṣẹ́ fún.
24 Most örülök a ti érettetek való szenvedéseimnek, és a magam részéről betöltöm a mi híja van a Krisztus szenvedéseinek az én testemben az Ő testéért, a mi az egyház;
Nísinsin yìí èmi ń yọ̀ nínú ìjìyà fún un yín. Inú mi sì dùn, nítorí mo ń ṣe ìrànlọ́wọ́ láti jẹ ìyà tó ṣẹ́kù nínú ìyà Kristi fún ara rẹ̀, èyí tí ì ṣe ìjọ.
25 A melynek lettem én szolgájává az Isten sáfársága szerint, a melyet nékem adott ti rátok nézve, hogy betöltsem az Isten ígéjét,
Nínú èyí tí a fi ṣe ìránṣẹ́ fún gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ìríjú Ọlọ́run tí a fi fún mi fún yín láti mú ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ṣẹ.
26 Tudniillik ama titkot, mely el vala rejtve ősidők óta és nemzetségek óta, most pedig megjelentetett az Ő szenteinek, (aiōn g165)
Ó ti pa àṣírí ìjìnlẹ̀ yìí mọ́ fún ayérayé àti láti ìrandíran. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ̀, ó ti fihàn fún àwọn ẹni mímọ́. (aiōn g165)
27 A kikkel az Isten meg akarta ismertetni azt, hogy milyen nagy a pogányok között eme titok dicsőségének gazdagsága, az tudniillik, hogy a Krisztus ti köztetek van, a dicsőségnek ama reménysége:
Àwọn ẹni tí Ọlọ́run yàn láti fihàn láàrín àwọn aláìkọlà nípa ọ̀rọ̀ ògo ohun ìjìnlẹ̀ yìí, èyí tí í ṣe Kristi ìrètí ògo nínú yín.
28 A kit mi prédikálunk, intvén minden embert, és tanítván minden embert minden bölcseséggel, hogy minden embert tökéletesnek állassunk elő a Krisztus Jézusban;
Àwa ń wàásù rẹ̀, a ń gbani níyànjú a sì ń kọ olúkúlùkù ènìyàn ní ọgbọ́n gbogbo, kí a lè mú olúkúlùkù dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní pípé nínú Kristi.
29 A mire igyekezem is, tusakodván az Ő ereje szerint, mely én bennem hatalmasan munkálkodik.
Sí èyí sì ni èmi ń ṣe làálàá, ti mo sì ń làkàkà pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀, èyí tó ń ṣiṣẹ́ nínú mi.

< Kolosséiakhoz 1 >