< 2 Sámuel 17 >
1 Monda azért Akhitófel Absolonnak: Engedj kiválasztanom tizenkétezer embert, hogy felkeljek, és üldözzem Dávidot ez éjjel.
Ahitofeli sì wí fún Absalomu pé, “Èmi ó yan ẹgbàá mẹ́fà ọkùnrin èmi ó sì dìde, èmi ó sì lépa Dafidi lóru yìí.
2 És megtámadom őt, míg fáradt és erőtlen kezű; megrettentem őt, és megfutamodik az egész nép, mely vele van; és a királyt magát megölöm.
Èmi ó sì yọ sí i nígbà tí àárẹ̀ bá mú un tí ọwọ́ rẹ̀ sì ṣe aláìle, èmi ó sì dá a ní ìjì, gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ yóò sì sá, èmi ó sì kọlu ọba nìkan ṣoṣo.
3 És visszavezetem te hozzád az egész népet, mert az egésznek visszatérése attól a férfiútól függ, a kit te üldözöl; és akkor az egész nép békességben lesz.
Èmi ó sì mú gbogbo àwọn ènìyàn padà sọ́dọ̀ rẹ bi ìgbà tí ìyàwó bá padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ rẹ̀. Ọkàn ẹnìkan ṣoṣo tí ìwọ ń wá yìí ni ó túmọ̀ sí ìpadàbọ̀ gbogbo wọn; gbogbo àwọn ènìyàn yóò sì wà ní àlàáfíà.”
4 Igen tetszék e beszéd Absolonnak és Izráel minden véneinek.
Ọ̀rọ̀ náà sì tọ́ lójú Absalomu, àti lójú gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli.
5 És monda Absolon: Hívják ide mégis az Arkeabeli Khúsait is, és hallgassuk meg, mit szól ő is.
Absalomu sì wí pé, “Ǹjẹ́ pe Huṣai ará Arki, àwa ó sì gbọ́ èyí tí ó wà lẹ́nu rẹ̀ pẹ̀lú.”
6 És mikor megérkezék Khúsai Absolonhoz, monda néki Absolon ilyenképen: Akhitófel ilyen tanácsot ád, megfogadjuk-é az ő szavát, vagy ne? Szólj hozzá.
Huṣai sì dé ọ̀dọ̀ Absalomu, Absalomu sì wí fún un pé, “Báyìí ni Ahitofeli wí, kí àwa ṣe bí ọ̀rọ̀ rẹ bí? Bí ko bá sì tọ́ bẹ́ẹ̀, ìwọ wí.”
7 Monda akkor Khúsai Absolonnak: Nem jó tanács az, a melyet Akhitófel ez egyszer adott.
Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Ìmọ̀ tí Ahitofeli gbà yìí, kò dára nísinsin yìí.”
8 És monda Khúsai: Tudod magad, hogy a te atyád és az ő emberei igen erős vitézek és igen elkeseredett szívűek, mint a kölykeitől megfosztott medve a mezőn. Annakfelette a te atyád igen hadakozó ember, ki nem alszik a néppel együtt.
Huṣai sì wí pé, “Ìwọ mọ baba rẹ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé alágbára ni wọ́n, wọ́n sì wà ní kíkorò ọkàn bí àmọ̀tẹ́kùn tí a gbà ní ọmọ ni pápá, baba rẹ sì jẹ́ jagunjagun ọkùnrin kì yóò bá àwọn ènìyàn náà gbé pọ̀ lóru.
9 Ilyenkor ő valami barlangban lappang, vagy valami más helyen, és meglehet, hogy mindjárt kezdetben elesvén némelyek közülök, valaki meghallja, és azt kezdi mondani: Megveretett az Absolon népe.
Kíyèsi i, ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ nísinsin yìí ni ihò kan, tàbí ní ibòmíràn: yóò sì ṣe, nígbà tí díẹ̀ nínú wọn bá kọ́ ṣubú, ẹnikẹ́ni tí ó bá gbọ́ yóò sì wí pé, ‘Ìparun sì ń bẹ́ nínú àwọn ènìyàn tí ń tọ Absalomu lẹ́yìn.’
10 És még az erős vitéz is, kinek szíve olyan, mint az oroszlánnak szíve, igen megrémül; mert az egész Izráel tudja, hogy a te atyád igen erős vitéz, és azok is, a kik vele vannak, erős vitézek.
Ẹni tí ó sì ṣe alágbára, tí ọkàn rẹ̀ sì dàbí ọkàn kìnnìún, yóò sì rẹ̀ ẹ́: nítorí gbogbo Israẹli ti mọ̀ pé alágbára ni baba rẹ, àti pé, àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ jẹ́ alágbára.
11 Én azért azt tanácsolom, hogy gyűjtsd magadhoz az egész Izráelt Dántól fogva mind Bersebáig, oly számban, mint a tenger partján való föveny; és magad is menj el a hadba.
“Nítorí náà èmi dámọ̀ràn pé, kí gbogbo Israẹli wọ́jọ pọ̀ sọ́dọ̀ rẹ, láti Dani títí dé Beerṣeba, gẹ́gẹ́ bí iyanrìn létí òkun fún ọ̀pọ̀lọpọ̀; àti pé, kí ìwọ tìkára rẹ̀ ó lọ sí ogun náà.
12 Akkor aztán támadjuk meg őt azon a helyen, a hol található, és úgy lepjük meg őt, miként a harmat a földre esik, hogy se közüle, se azok közül, a kik vele vannak, egy se maradjon meg.
Àwa ó sì yọ sí i níbikíbi tí àwa o gbé rí i, àwa ó sì yí i ká bí ìrì ti ń ṣẹ̀ sí ilẹ̀ àní, ọkàn kan kì yóò kù pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀.
13 Ha pedig városba szaladna, mind az egész Izráel köteleket húzzon a város körül, és vonjuk azt a patakba, hogy még csak egy kövecskét se találjanak ott.
Bí o bá sì bọ́ sí ìlú kan, gbogbo Israẹli yóò mú okùn wá sí ìlú náà, àwa ó sì fà á lọ sí odò, títí a kì yóò fi rí òkúta kéékèèké kan níbẹ̀.”
14 És monda Absolon és Izráelnek minden férfia: Jobb az Arkeabeli Khúsainak tanácsa az Akhitófel tanácsánál. Az Úr parancsolta vala pedig, hogy az Akhitófel tanácsa elvettessék, mely jó vala, hogy veszedelmet hozzon az Úr Absolonra.
Absalomu àti gbogbo ọkùnrin Israẹli sì wí pé, “Ìmọ̀ Huṣai ará Arki sàn ju ìmọ̀ Ahitofeli lọ! Nítorí Olúwa fẹ́ láti yí ìmọ̀ rere ti Ahitofeli po.” Nítorí kí Olúwa lè mú ibi wá sórí Absalomu.
15 Monda pedig Khúsai Sádók és Abjátár papoknak: Ilyen s ilyen tanácsot adott Akhitófel Absolonnak és Izráel véneinek; én pedig ilyen s ilyen tanácsot adtam.
Huṣai sì wí fún Sadoku àti fún Abiatari àwọn àlùfáà pé, “Báyìí ni Ahitofeli ti bá Absalomu àti àwọn àgbàgbà Israẹli dámọ̀ràn, báyìí lèmi sì bá a dámọ̀ràn.
16 Azért sietve küldjetek el, és izenjétek meg Dávidnak ilyen szóval: Ne maradj ez éjjel a pusztának mezején, hanem inkább menj át, hogy valamiképen el ne nyelettessék a király és az egész nép, mely vele van.
Nítorí náà yára ránṣẹ́ nísinsin yìí kí o sì sọ fún Dafidi pé, ‘Má ṣe dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ijù náà lálẹ́ yìí, ṣùgbọ́n yára rékọjá kí a má bá a gbé ọba mì, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ.’”
17 Jonathán pedig és Akhimás a Rógel forrásánál állanak vala, a hová méne egy leányzó, ki megmondá ezeket nékik, és ők elmenvén, megmondák Dávid királynak, mert nem akarják vala magokat megmutatni, bemenvén a városba.
Jonatani àti Ahimasi sì dúró ní En-Rogeli ọ̀dọ́mọdébìnrin kan sì lọ, ó sì sọ fún wọn, wọ́n sì lọ wọ́n sọ fún Dafidi ọba nítorí pé kí a má bá à rí wọn pé wọ́n wọ ìlú.
18 Meglátá mindazáltal őket egy szolga, és megmondá Absolonnak: Elmenének azért ők ketten sietséggel, és menének egy ember házába Bahurim városában, kinek tornáczában volt egy kút, és oda szállának alá.
Ṣùgbọ́n ọ̀dọ́mọdékùnrin kan rí wọn, ó sì wí fún Absalomu, ṣùgbọ́n àwọn méjèèjì sì yára lọ kúrò, wọ́n sì wá sí ilé ọkùnrin kan ní Bahurimu, ẹni tí ó ní kànga kan ní ọgbà rẹ̀, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ sí ibẹ̀.
19 Az asszony pedig egy terítőt vőn és beteríté a kút száját, arra pedig darált árpát hintett; és nem vevék észre.
Obìnrin rẹ̀ sì mú nǹkan ó fi bo kànga náà, ó sì sá àgbàdo sórí rẹ̀, a kò sì mọ̀.
20 Menének pedig az Absolon szolgái az asszonyhoz a házba, és mondának: Hol van Akhimás és Jonathán? Felele nékik az asszony: Általgázolának a patakon. És keresék őket, de mivel nem találták, visszatérének Jeruzsálembe.
Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì tọ obìnrin náà wá sí ilé náà, wọ́n sì béèrè pé, “Níbo ni Ahimasi àti Jonatani gbé wà?” Obìnrin náà sì wí fún wọn pé, “Wọ́n ti gòkè rékọjá ìṣàn odò náà.” Wọ́n sì wá wọn kiri, wọn kò sì rí wọn, wọ́n sì yípadà sí Jerusalẹmu.
21 Mikor pedig elmentek, kijövének a kútból, és elmenvén, megmondák ezeket Dávid királynak, és mondának Dávidnak: Keljetek fel és menjetek által gyorsan a vizen; mert ilyen tanácsot adott ti ellenetek Akhitófel.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti lọ tán, àwọn ọkùnrin náà sì jáde kúrò nínú kànga, wọ́n sì lọ wọ́n sì rò fún Dafidi ọba. Wọ́n sọ fún Dafidi pé, “Dìde kí o sì gòkè odò kánkán, nítorí pé báyìí ni Ahitofeli gbìmọ̀ sí ọ.”
22 Felkele azért Dávid és mind a vele való nép, és általkelének a Jordánon, míg megvirrada; egy sem hiányzék, a ki által nem ment volna a Jordánon.
Dafidi sì dìde, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì gòkè odò Jordani: kí ilẹ̀ tó mọ́, ènìyàn kò kù tí kò gòkè odò Jordani.
23 Látván pedig Akhitófel, hogy az ő tanácsát nem hajtották végre: megnyergelé szamarát, és felkelvén elméne házához, az ő városába; és elrendezvén háznépének dolgát, megfojtá magát, és meghala; és eltemetteték az ő atyjának sírjába.
Nígbà tí Ahitofeli sì rí i pé wọn kò fi ìmọ̀ tirẹ̀ ṣe, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ni gàárì, ó sì dìde, ó lọ ilé rẹ̀, ó sì palẹ̀ ilé rẹ̀ mọ̀, ó sì so, ó sì kú, a sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀. Absalomu gbógun ti Dafidi.
24 És midőn Dávid Mahanáimba érkezett, átkele Absolon a Jordánon, ő és Izráelnek férfiai mindnyájan ő vele.
Dafidi sì wá sí Mahanaimu, Absalomu sì gòkè odò Jordani, òun àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli pẹ̀lú rẹ̀.
25 És Amasát tevé Absolon fővezérré a sereg felett Joáb helyett. Amasa pedig egy férfi fia vala, a kinek a neve az Izráelita Jithra vala, a ki beméne Abigailhoz, a Náhás leányához, ki Sérujának, a Joáb anyjának nővére vala.
Absalomu sì fi Amasa ṣe olórí ogun ní ipò Joabu: Amasa ẹni tí í ṣe ọmọ ẹnìkan, orúkọ ẹni tí a ń pè ní Itira, ará Israẹli, tí ó wọlé tọ Abigaili ọmọbìnrin Nahaṣi, arábìnrin Seruiah, ìyá Joabu.
26 És tábort jára Izráel és Absolon a Gileád földén.
Israẹli àti Absalomu sì dó ní ilẹ̀ Gileadi.
27 Lőn pedig, hogy mikor Dávid Mahanáimba jutott, ímé Sóbi, az Ammoniták városából, Rabbából való Náhásnak fia, és a Ló-Debár városból való Ammielnek fia, Mákir, és a Gileád tartományában, Rógelimban lakozó Barzillai.
Nígbà tí Dafidi sì wá sí Mahanaimu, Ṣobi ọmọ Nahaṣi ti Rabba tí àwọn ọmọ Ammoni, àti Makiri ọmọ Ammieli ti Lo-Debari, àti Barsillai ará Gileadi ti Rogelimu.
28 Ágyneműt, medenczéket és cserépedényeket, búzát, árpát, lisztet, pergelt búzát, babot, lencsét, pergelt árpát,
Mú àwọn àkéte, àti àwọn àwo, àti ìkòkò amọ̀, àti alikama, àti ọkà barle, àti ìyẹ̀fun, àti àgbàdo díndín, àti ẹ̀wà, àti erèé, àti lẹntili.
29 Mézet, vajat, juhot, ünősajtokat hozának Dávidnak és az ő vele való népnek eleségül. Mert azt gondolják vala magokban: A nép éhes, fáradt és eltikkadt a pusztában.
Àti oyin, àti òrí-àmọ́, àti àgùntàn, àti wàràǹkàṣì màlúù, wá fún Dafidi àti fún àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀, láti jẹ: nítorí tí wọ́n wí pé, “Ebi ń pa àwọn ènìyàn, ó sì rẹ̀ wọ́n, òǹgbẹ sì ń gbẹ wọ́n ní aginjù.”