< 2 Királyok 9 >

1 Elizeus próféta pedig szólíta egyet a próféták fiai közül, és monda néki: Övezd fel derekadat, és vedd kezedbe e korsócska olajat, és menj el Rámóth Gileádba.
Wòlíì Eliṣa fi àṣẹ pe ọkùnrin kan láti ẹgbẹ́ àwọn wòlíì, ó sì wí fún un pé, “Ki agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè rẹ, gba ṣágo kékeré òróró yìí pẹ̀lú rẹ, kí o sì lọ sí Ramoti Gileadi.
2 És menj be oda, és nézd meg, hol van Jéhu, Josafátnak, a Nimsi fiának fia. Mikor pedig oda érsz, költsd fel őt az ő atyjafiai közül, és vidd be a belső kamarába,
Nígbà tí o bá dé bẹ̀, wá Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi kiri. Lọ sí ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀, mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀, kí o sì mú un wọ inú yàrá lọ́hùn ún lọ.
3 És vedd elő e korsócska olajat, és töltsd az ő fejére, ezt mondván: Azt mondja az Úr: Téged kentelek királylyá Izráelen! És az ajtót kinyitván, fuss el, és semmit ott ne időzz.
Nígbà náà, mú ṣágo kékeré yìí, kí o sì da òróró náà lé e lórí, kí o sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’ Nígbà náà, ṣí ìlẹ̀kùn, kí o sì sáré, má ṣe jáfara!”
4 És elment az ifjú, a próféta tanítványa, Rámóth Gileádba.
Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wòlíì náà lọ sí Ramoti Gileadi.
5 És mikor bement, ímé a seregek fejedelmei ott ültek együtt, és ő monda: Beszédem volna veled, fejedelem! És monda Jéhu: Kivel volna beszéded ennyiőnk közül? És monda: Te veled, fejedelem!
Nígbà tí ó dé, ó rí àwọn olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí wọ́n jókòó papọ̀. “Èmi ní iṣẹ́ fún ọ, olórí,” Ó wí. “Sí ta ni nínú wa?” Jehu béèrè. Òun sì wí pé, “Sí ọ, balógun,” Ó dáhùn.
6 Felkele azért, és bement a házba, és fejére tölté az olajat, és monda néki: Azt mondja az Úr, Izráel Istene: Királylyá kentelek téged az Úrnak népén, az Izráelen,
Jehu dìde sókè, ó sì wọ inú ilé lọ. Nígbà náà, wòlíì náà da òróró náà sórí Jehu; ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn Olúwa Israẹli.
7 Hogy elveszítsed Akhábnak, a te uradnak háznépét; mert bosszút állok az én szolgáimnak, a prófétáknak véréért, és mind az Úr szolgáinak véréért Jézabelen.
Kí ìwọ kí ó pa ilé Ahabu ọ̀gá à rẹ̀ run, Èmi yóò sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Olúwa tí a ta sílẹ̀ látọwọ́ ọ Jesebeli.
8 És kivész egészen az Akháb háza, és kigyomlálom mind az Akhábhoz tartozókat, még az ebet is, mind a berekesztettet, mind az elhagyottat Izráelben;
Gbogbo ilé Ahabu yóò ṣègbé. Èmi yóò gé e kúrò láti orí Ahabu gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó gbẹ̀yìn ni Israẹli, ẹrú tàbí òmìnira.
9 És olyanná teszem az Akháb házát, mint Jeroboámnak, a Nébát fiának házát, és mint Baasának, az Ahija fiának házát.
Èmi yóò ṣe ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati àti ilé Baaṣa ọmọ Ahijah.
10 Jézabelt pedig az ebek eszik meg Jezréel mezején, és nem lesz, a ki eltemesse őt. És kinyitván az ajtót, elfutott.
Fún Jesebeli, ajá ni yóò jẹ ẹ́ ní oko Jesreeli, kò sì sí ẹni tí yóò sin òkú rẹ̀.’” Nígbà náà ó ṣí ìlẹ̀kùn, ó sì sálọ.
11 És mikor Jéhu kiment az ő urának szolgáihoz, mondának néki: Békességes-é a dolog? Miért jött e bolond hozzád? És felele nékik: Hiszen ismeritek ez embert és az ő beszédét!
Nígbà tí Jehu jáde lọ bá àwọn ọgbà ìjòyè e rẹ̀, ọ̀kan nínú wọn sì bi í pé, “Ṣé gbogbo nǹkan dára?” Kí ni ó dé tí aṣiwèrè fi tọ̀ ọ́ wá, “Ìwọ mọ ọkùnrin náà àti irú nǹkan tí ó ń sọ,” Jehu fèsì.
12 És mondának: Hazugság! Mondd meg az igazat. És monda: Így s így szóla nékem, mondván: Azt mondja az Úr: Királylyá kentelek téged Izráelen.
“Ìyẹn kì í ṣe òótọ́!” Wọ́n wí. “Sọ fún wa.” Jehu wí, “Èyí ni ohun tí ó sọ fún mi: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’”
13 Akkor nagy sietséggel kiki mind vevé az ő ruháját, és alája terítették a grádics felső részére és megfuvaták a harsonákat, és kikiálták: Jéhu uralkodik!
Wọ́n ṣe gírí, wọ́n sì mú agbádá a wọn, wọ́n sì tàn wọ́n sí abẹ́ rẹ̀ ní orí àtẹ̀gùn. Nígbà náà, wọ́n fọn ìpè, wọ́n sì kígbe, “Jehu jẹ ọba!”
14 Így ütött pártot Jéhu, Josafátnak, a Nimsi fiának fia, Jórám ellen. Jórám pedig ott táborozott volt Rámóth Gileád alatt az egész Izráellel, Hazáel, Siria királya ellen.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi, dìtẹ̀ sí Joramu. (Nísinsin yìí Joramu àti gbogbo Israẹli ti ń dáàbò bo Ramoti Gileadi nítorí Hasaeli ọba Aramu.
15 De visszatért volt Jórám király, hogy magát Jezréelben gyógyíttassa a sebekből, a melyeket a Siriabeliek ütöttek rajta, mikor Hazáel, Siria királya ellen harczolt. És monda Jéhu: Ha néktek is úgy tetszik, ne engedjetek senkit kimenni a városból, a ki elmenjen és hírül vigye ezt Jezréelbe.
ṣùgbọ́n ọba Joramu ti padà sí Jesreeli láti lọ sàn nínú ọgbẹ́ tí àwọn ará Aramu ti dá sí i lára nínú ogun pẹ̀lú ọba Hasaeli ti Aramu.) Jehu wí pé, “Tí èyí bá jẹ́ ọ̀nà tí ò ń rò, má ṣe jẹ́ kí ẹnìkankan kí ó yọ jáde nínú ìlú ńlá láti lọ sọ ìròyìn náà ní Jesreeli.”
16 És befogatott Jéhu, és elment Jezréelbe, a hol Jórám feküdt, és a hova Akházia is, a Júda királya lement volt, hogy meglátogassa Jórámot.
Nígbà náà Jehu wọ inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó sì gùn ún lọ sí Jesreeli, nítorí Joramu ń sinmi níbẹ̀ àti Ahasiah ọba Juda sì sọ̀kalẹ̀ láti wá wò Joramu.
17 Mikor pedig az őrálló, a ki Jezréelben a tornyon állott, meglátta Jéhu seregét, hogy jő, monda: Valami sereget látok. Akkor monda Jórám: Válaszsz egy lovast és küldj eléjök, és mondja ezt: Békességes-é a dolog?
Nígbà tí olùṣọ́ kan tí ó dúró ní ilé ìṣọ́ ní Jesreeli, rí ọ̀wọ́ ogun Jehu tí wọ́n ń súnmọ́ tòsí, ó pè jáde, “Mo rí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí ó ń bọ̀.” “Mú ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kan,” Joramu pa á láṣẹ. “Rán an lọ sí ọ̀dọ̀ wọn kí o sì béèrè pé, ‘Ṣé ẹ̀yin wá pẹ̀lú àlàáfíà?’”
18 És oda lovagolt a lovas eléjük, és monda: Azt kérdi a király: Békességes-é a dolog? Felele Jéhu: Mi gondod van a békességgel? Kerülj a hátam mögé. Megjelenté pedig ezt az őrálló, mondván: Hozzájok ment ugyan a követ; de nem tért vissza.
Ọkùnrin ẹlẹ́ṣin náà, lọ láti lọ bá Jehu ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba wí: ‘Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?’” “Kí ni ìwọ ní ṣe pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu sì dáhùn. “Bọ́ sí ẹ̀yìn mi.” Olùṣọ́ náà sì wí fún un pé, “Ìránṣẹ́ náà ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́.”
19 Akkor elküldött egy másik lovast, a ki hozzájok ment, és monda: Azt kérdi a király: Békességes-é a dolog? Felele Jéhu: Mi gondod van a békességgel? Kerülj a hátam mögé.
Bẹ́ẹ̀ ni, ọba rán ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kejì. Nígbà náà ó wá sí ọ̀dọ̀ wọn, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba sọ: “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu dáhùn, “Dúró sí ẹ̀yìn mi.”
20 Hírül adá ezt is az őrálló, mondván: Hozzájok ment ugyan; de nem jött vissza. De a hajtás olyan, mint Jéhunak, a Nimsi fiának hajtása; mert mint egy őrült, úgy hajt.
Olùṣọ́ náà sì fi sùn. “Ó ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́ pẹ̀lú. Wíwá rẹ̀ sì dàbí ti Jehu ọmọ Nimṣi, ó ń wa kẹ̀kẹ́ bí ti aṣiwèrè.”
21 Akkor monda Jórám: Fogjatok be! És befogván az ő szekerét, kiméne Jórám, az Izráel királya, és Akházia, a Júda királya, mindenik a maga szekerén, Jéhu eleibe, és a Jezréelbeli Nábót mezején találkoztak vele.
“Fi ìwọ̀ kọ́ kẹ̀kẹ́ ogun mi.” Joramu pa á láṣẹ. Àti nígbà tí a fi kọ́, Joramu ọba Israẹli àti Ahasiah ọba Juda, gun kẹ̀kẹ́ lọ, olúkúlùkù nínú kẹ̀kẹ́ ogun tirẹ̀, láti lọ bá Jehu. Wọ́n bá a pàdé ní ibi oko tí ó ti jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli.
22 És mikor meglátta Jórám Jéhut, monda: Békességes-é a dolog, Jéhu? Felele ő: Mit békesség?! Mikor Jézabelnek, a te anyádnak paráznasága és varázslása mindig nagyobb lesz!
Nígbà tí Joramu rí Jehu, ó béèrè pé, “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà, Jehu?” “Báwo ni àlàáfíà yóò ṣe wà,” Jehu dáhùn, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí gbogbo ìbọ̀rìṣà àti iṣẹ́ àjẹ́ ti màmá rẹ Jesebeli di púpọ̀?”
23 Akkor megfordítá Jórám az ő kezét és futni kezde, és monda Akháziának: Árulás ez, Akházia?
Joramu yí ọwọ́ rẹ̀ padà, ó sì sálọ, ó sì ń pe Ahasiah, “Ọ̀tẹ̀ dé, Ahasiah!”
24 Jéhu pedig meghúzván az ívét, Jórámot hátba lövé a lapoczkák között úgy, hogy a szívén ment át a nyíl, és lerogyott a szekérben.
Nígbà náà, Jehu fa ọrun rẹ̀, ó sì yin Joramu láàrín èjìká méjèèjì. Ọfà náà sì wọ inú ọkàn rẹ̀, ó sì ṣubú lulẹ̀ láti orí kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
25 És monda Bidkárnak, az ő hadnagyának: Fogd meg és vesd a Jezréelbeli Nábót mezejére; mert emlékezz csak vissza, mikor mi, én és te, ketten az ő atyja, Akháb után lovagoltunk, és az Úr ő felőle ezt a fenyegetést mondotta:
Jehu sọ fún Bidikari, balógun kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Gbé e sókè kí ó sì jù ú sí orí oko tí ó jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli. Rántí bí èmi àti ìwọ ti ń gun kẹ̀kẹ́ papọ̀ lẹ́yìn Ahabu baba à rẹ nígbà tí Olúwa sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀,
26 Bizonyára megkeresem a Nábót vérét és az ő fiainak vérét, a melyet tegnap láttam, azt mondja az Úr: Azért megfizetek néked ezen a szántóföldön, azt mondja az Úr: Most azért fogjad őt, és vesd a szántóföldre, az Úr beszéde szerint.
‘Ní àná, mo rí ẹ̀jẹ̀ Naboti pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ni Olúwa wí.’ Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ gbé e sókè, kí o sì jù ú sí orí ilẹ̀ oko náà ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa.”
27 Akházia pedig, a Júda királya, mikor látta ezt, futni kezde a kert házának útján; de Jéhu utána menvén, monda: Ezt is vágjátok le a szekérben és megsebesíték őt a Gúr hágójánál, a mely Jibleám mellett van; és ő Megiddóba menekülvén, ott meghalt.
Nígbà tí Ahasiah ọba, Juda rí ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀, ó sálọ sójú ọ̀nà sí Beti-Haggani. Jehu sì lépa rẹ̀, ó ń kígbe, “Pa á pẹ̀lú!” Wọ́n ṣá a ní ọgbẹ́ nínú kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Guri lẹ́bàá a Ibleamu, ṣùgbọ́n ó sálọ sí Megido, ó sì kú síbẹ̀.
28 És az ő szolgái elvitték őt szekéren Jeruzsálembe, és eltemették az ő sirboltjába az ő atyáival a Dávid városában.
Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì gbé e pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lọ sí Jerusalẹmu, ó sì sin ín pẹ̀lú, baba a rẹ̀ nínú ibojì rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi.
29 Akházia pedig uralkodni kezdett Júdában Jórámnak, az Akháb fiának tizenegyedik esztendejében.
(Ní ọdún kọkànlá ti Joramu ọmọ Ahabu, Ahasiah ti di ọba Juda.)
30 És mikor Jéhu Jezréelbe ment és Jézabel ezt meghallotta, arczát megékesíté kenettel, felékesítette fejét, és kitámaszkodott az ablakon.
Nígbà náà Jehu lọ sí Jesreeli. Nígbà tí Jesebeli gbọ́ nípa rẹ̀, ó kun ojú u rẹ̀, ó to irun rẹ̀, ó sì wò jáde láti ojú fèrèsé.
31 És mikor Jéhu bevonult a kapun, monda: Békesség van-é, óh Zimri! uradnak gyilkosa?
Bí Jehu ti wọ ẹnu ìlẹ̀kùn, ó béèrè, “Ṣé ìwọ wá ní àlàáfíà, Simri, ìwọ olùpa ọ̀gá à rẹ?”
32 Ő pedig feltekintve az ablakra, monda: Ki van ott velem? Ki? És alátekintett két vagy három főember.
Ó gbójú sókè láti wo fèrèsé, ó sì pè jáde, “Ta ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ mi? Ta ni?” Ìwẹ̀fà méjì tàbí mẹ́ta bojú wò ó nílẹ̀.
33 És monda azoknak: Vessétek alá őt. És aláveték, és az ő vére szétfrecskendezett a falra és a lovakra, és eltapodtatá őt.
Jehu sọ wí pé, “Gbé e jù sílẹ̀!” Wọ́n sì jù ú sílẹ̀. Díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì fọ́n sí ara ògiri àti àwọn ẹṣin bí wọ́n ti tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ wọn.
34 Bemenvén pedig oda, evett és ivott, és monda: Nézzetek utána annak az átkozottnak és temessétek el; hiszen mégis csak király leánya.
Jehu wọ inú ilé lọ, ó jẹ, ó sì mu. “Tọ́jú obìnrin yẹn tí a fi bú,” Ó wí, “Kí o sì sin ín, nítorí ọmọbìnrin ọba ni ó jẹ́.”
35 De mikor kimentek, hogy eltemetnék őt, már semmit sem találtak belőle, csak a koponyáját, a lábait és a keze fejeit.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde lọ láti lọ sin ín, wọn kò rí nǹkan kan àyàfi agbárí i rẹ̀, ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì àti ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì.
36 És visszamenvén, megmondák néki, és ő monda: Ez az Úr beszéde, a melyet szólott az ő szolgája, Thesbites Illés által, mondván: Az ebek eszik meg Jézabel testét a Jezréel földén,
Wọ́n padà lọ sọ fún Jehu, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah ará Tiṣibi wí pé, ‘Ní orí oko Jesreeli ni àwọn ajá yóò ti jẹ ẹran-ara Jesebeli.
37 És olyan lesz Jezréel földjén a Jézabel teste, mint a mezőn a ganéj, úgy, hogy senki meg nem mondhatja: Ez Jézabel!
Òkú Jesebeli yóò dàbí ohun ẹ̀gbin ní orí oko Jesreeli, dé bi pé, ẹnikẹ́ni kì yóò lè sọ pé, “Jesebeli ni èyí.”’”

< 2 Királyok 9 >