< 2 Királyok 16 >

1 Pékának, a Remália fiának tizenhetedik esztendejében kezdett uralkodni Akház, Jótámnak, a Júda királyának fia.
Ní ọdún kẹtàdínlógún Peka ọmọ Remaliah, Ahasi ọmọ Jotamu ọba Juda bẹ̀rẹ̀ sí i jẹ ọba.
2 Húsz esztendős volt Akház, mikor uralkodni kezdett, és tizenhat esztendeig uralkodott Jeruzsálemben; de nem azt cselekedé, a mi az Úrnak, az ő Istenének tetszett volna, a mint Dávid, az ő atyja,
Ẹni ogún ọdún ni Ahasi nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ọdún mẹ́rìndínlógún ní Jerusalẹmu, kò sì ṣe èyí tí ó tọ́ lójú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Dafidi baba rẹ̀.
3 Hanem az Izráel királyainak útjokon járt, még az ő fiát is átvitte a tűzön, a pogányok útálatosságai szerint, a kiket az Úr az Izráel fiai előtt kiűzött volt.
Ṣùgbọ́n ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, nítòótọ́, ó sì sun ọmọ rẹ̀ nínú iná, gẹ́gẹ́ bí ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
4 És ott áldozott és tömjénezett a magaslatokon és a halmokon és minden zöld fa alatt.
Ó sì rú ẹbọ, ó sì sun tùràrí ní àwọn ibi gíga, àti lórí àwọn òkè kéékèèké àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
5 Abban az időben jött fel Réczin, Siria királya, és Péka, a Remália fia, az Izráel királya, Jeruzsálemet vívatni, és körülzárták Akházt, de nem tudták legyőzni.
Nígbà náà ni Resini ọba Siria àti Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli gòkè wá sí Jerusalẹmu láti jagun: wọ́n dó ti Ahasi, ṣùgbọ́n wọn kò lè borí rẹ̀.
6 Akkor nyerte vissza Réczin, Siria királya Elátot a Siriabelieknek, és irtotta ki a zsidókat Elátból; és Siriabeliek jövének Elátba, és ott laknak mind e mai napig.
Ní àkókò náà, Resini ọba Siria gba Elati padà fún Siria, ó sì lé àwọn ènìyàn Juda kúrò ní Elati: àwọn ará Siria sì wá sí Elati, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ títí di òní yìí.
7 És követeket küldött Akház Tiglát-Piléserhez, Assiria királyához, ezt izenvén: Te szolgád és a te fiad vagyok; jőjj fel és szabadíts meg engem Siria királyának kezéből és az Izráel királyának kezéből, a kik reám támadtak.
Ahasi sì rán oníṣẹ́ sọ́dọ̀ Tiglat-Pileseri ọba Asiria wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni èmi, àti ọmọ rẹ; gòkè wá, kí o sì gbà mi lọ́wọ́ ọba Siria, àti lọ́wọ́ ọba Israẹli tí ó dìde sí mi.”
8 És vevé Akház az ezüstöt és aranyat, és a mely találtaték az Úr házában és a király házának kincsei között, és ajándékba küldé Assiria királyának.
Ahasi sì mú fàdákà àti wúrà tí a rí ní ilé Olúwa, àti nínú ìṣúra ilé ọba, ó sì rán an sí ọba Asiria ní ọrẹ.
9 És engedett néki Assiria királya, és feljövén Assiria királya Damaskus ellen, bevette azt, és a benne levőket Kirbe hurczolta; Réczint pedig megölte.
Ọba Asiria sì gbọ́ tirẹ̀: nítorí ọba Asiria gòkè wá sí Damasku, ó sì kó o, ó sì mú un ní ìgbèkùn lọ sí Kiri, ó sì pa Resini.
10 És eleibe ment Akház Tiglát-Pilésernek, Assiria királyának Damaskusba, és mikor meglátta Akház király azt az oltárt, a mely Damaskusban volt, elküldte Akház király annak az oltárnak hasonlatosságát és képét minden felszerelésével Uriás paphoz.
Ọba sì lọ sí Damasku láti pàdé Tiglat-Pileseri, ọba Asiria, ó sì rí pẹpẹ kan tí ó wà ní Damasku: Ahasi ọba sì rán àwòrán pẹpẹ náà, àti àpẹẹrẹ rẹ̀ sí Uriah àlùfáà, gẹ́gẹ́ bí gbogbo iṣẹ́ ọ̀nà rẹ̀.
11 És megépítette Uriás pap az oltárt arra a formára, a melyet Akház király Damaskusból küldött, és elkészíté azt Uriás pap, mire Akház király visszajött Damaskusból.
Uriah àlùfáà sì kọ́ pẹpẹ náà gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí Ahasi ọba fi ránṣẹ́ sí i láti Damasku; bẹ́ẹ̀ ni Uriah àlùfáà ṣe é dé ìpadàbọ̀ Ahasi ọba láti Damasku.
12 És mikor megjött a király Damaskusból és meglátta a király az oltárt: az oltárhoz ment a király és áldozott rajta,
Nígbà tí ọba sì ti Damasku dé, ọba sì rí pẹpẹ náà: ọba sì súnmọ́ pẹpẹ náà, ó sì rú ẹbọ lórí rẹ̀.
13 És meggyújtotta az ő égőáldozatját és ételáldozatját, és áldozott italáldozattal is, és az ő hálaáldozatainak vérét elhintette az oltár körül.
Ó sì sun ẹbọ sísun rẹ̀ àti ọrẹ-jíjẹ rẹ̀, o si ta ohun mímu rẹ̀ sílẹ̀, ó sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ ọrẹ àlàáfíà rẹ̀ sí ara pẹpẹ náà.
14 És a rézoltárt, a mely az Úr előtt állott, elviteté a ház elől, hogy ne álljon az ő oltára és az Úr háza között, és helyhezteté azt az oltár szegletéhez észak felől.
Ṣùgbọ́n ó mú pẹpẹ idẹ tí ó wà níwájú Olúwa kúrò láti iwájú ilé náà, láti àárín méjì pẹpẹ náà, àti ilé Olúwa, ó sì fi í sí apá àríwá pẹpẹ náà.
15 És megparancsolta Akház király Uriás papnak, mondván: E nagy oltáron gyújtsd meg a reggeli égőáldozatot és az esteli ételáldozatot, a király égőáldozatját is az ő ételáldozatával együtt, az egész föld népének is mind égőáldozatát, mind ételáldozatját, mind italáldozatját, és az égőáldozat minden vérét és egyéb áldozatnak minden vérét a körül hintsed el; a rézoltár felől pedig még majd gondolkozom.
Ahasi ọba sì pàṣẹ fún Uriah àlùfáà, wí pé, “Lórí pẹpẹ ńlá náà ni kó o máa sun ẹbọ sísun òròwúrọ̀ àti ọrẹ-jíjẹ alaalẹ́, àti ẹbọ sísun ti ọba, àti ọrẹ-jíjẹ rẹ̀, pẹ̀lú ẹbọ sísun tí gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti ọrẹ-jíjẹ wọn, àti ọrẹ ohun mímu wọn; kí o sì wọ́n gbogbo ẹ̀jẹ̀ ẹbọ sísun náà lórí rẹ̀, àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ ẹbọ mìíràn, ṣùgbọ́n ní ti pẹpẹ idẹ náà èmi ó máa gbèrò ohun tí èmi ó fi ṣe.”
16 És Uriás pap mind a szerint cselekedék, a mint Akház király megparancsolta.
Báyìí ni Uriah àlùfáà ṣe, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Ahasi ọba pàṣẹ.
17 És letörte Akház király a talpak oldalait, és lehányta azokról a mosdómedenczéket; a tengert is ledobta a rézökrökről, a melyeken állott, és kőtalapzatra tette.
Ahasi ọba sì gé igi-ìpílẹ̀ àwọn àgbédúró náà, ó ṣí agbada náà kúrò lára wọn; ó sì gbé agbada ńlá náà kalẹ̀ kúrò lára àwọn màlúù idẹ tí ń bẹ lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbé e ka ilẹ̀ tí a fi òkúta tẹ́.
18 És áthelyezte a szombati hajlékot, a melyet a házban építettek, és a király külső bejáró helyét az Úr házában, Assiria királya miatt.
Ibi ààbò fún ọjọ́ ìsinmi tí a kọ́ nínú ilé náà, àti ọ̀nà ìjáde sí òde ọba, ni ó yípadà kúrò ní ilé Olúwa nítorí ọba Asiria.
19 Akháznak egyéb dolgai pedig, a melyeket cselekedett, vajjon nincsenek-é megírva a Júda királyainak krónika-könyvében?
Àti ìyókù ìṣe Ahasi tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
20 És elaluvék Akház az ő atyáival, és eltemetteték az ő atyáival a Dávid városában, és uralkodék ő helyette az ő fia, Ezékiás.
Ahasi sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi: Hesekiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< 2 Királyok 16 >