< 2 Krónika 18 >
1 Jósafátnak nagy gazdagsága és dicsősége vala. Ő sógorságot szerze Akhábbal.
Nísinsin yìí Jehoṣafati sì ní ọrọ̀ àti ọlá púpọ̀, ó sì dá àna pẹ̀lú Ahabu nípa fífẹ́ ọmọ rẹ̀.
2 Néhány esztendő mulva aláméne Akhábhoz Samariába, és levágatott Akháb az ő és a vele való nép számára sok juhot és ökröt, és rávette őt, hogy felmenjen vele Rámóth Gileádba.
Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, ó sọ̀kalẹ̀ láti lọ bá Ahabu lálejò ní Samaria. Ahabu sì pa àgùntàn àti màlúù púpọ̀ fún àti àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ó sì rọ̀ ọ́ láti dojú ìjà kọ Ramoti Gileadi.
3 Mert ezt mondá Akháb, az Izráel királya Jósafátnak, a Júda királyának: Feljösz-é velem Rámóth Gileádba? Felele néki, és monda: Úgy én, mint te; úgy az én népem, mint a te néped együtt lesz a harczban.
Ahabu ọba Israẹli sì béèrè lọ́wọ́ ọba Jehoṣafati, ọba Juda pé, “Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi sí Ramoti Gileadi?” Jehoṣafati sì dá a lóhùn pé, “Èmi wà gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe wà, àti àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn rẹ àwa yóò pẹ̀lú rẹ nínú ogun náà”.
4 Azután monda Jósafát az Izráel királyának: Kérdezősködjél még ma az Úr beszéde után.
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati náà sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
5 És összegyűjté az Izráel királya a prófétákat, mintegy négyszáz férfiút, és monda nékik: Elmenjünk-é Rámóth Gileád ellen hadba, vagy elhagyjam? Felelének: Menj el, és az Isten a király kezébe adja.
Bẹ́ẹ̀ ọba Israẹli kó àwọn wòlíì papọ̀, irinwó ọkùnrin ó sì bi wọ́n pé, “Kí àwa kí lọ sí ogun Ramoti Gileadi tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ?” Wọ́n dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Ọlọ́run yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
6 És monda Jósafát: Nincsen-é itt több prófétája az Úrnak, hogy attól is tudakozódhatnánk?
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ṣé kò ha sí wòlíì Olúwa níbí ẹni tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
7 És monda az Izráel királya Jósafátnak: Van még egy férfiú, a ki által az Urat megkérdezhetjük, de én gyűlölöm őt, mert soha nem jövendöl nékem jót, hanem mindig csak rosszat; ez Mikeás, a Jimla fia. És monda Jósafát: Ne beszéljen így a király!
Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan wà síbẹ̀ lọ́dọ̀ ẹni tí àwa ìbá tún béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n èmi kórìíra rẹ̀ nítorí kò jẹ́ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun rere kan nípa mi ṣùgbọ́n bí kò ṣe ohun búburú, ní gbogbo ìgbà òun náà ni Mikaiah ọmọ Imla.” Jehoṣafati sì dá lóhùn pé, “Ọba kò gbọdọ̀ sọ bẹ́ẹ̀.”
8 Szólíta azért az Izráel királya egyet az ő szolgái közül, és monda: Hívd ide hamar Mikeást, a Jimla fiát.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pe ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ó sì wí pé, “Ẹ mú Mikaiah ọmọ Imla kí ó yára wá.”
9 És az Izráel királya és Jósafát, a Júda királya ott ülnek vala, kiki az ő királyiszékében, királyi ruhákba öltözötten; ott ülnek vala Samaria kapuja előtt, a térségen; és a próféták mind prófétálnak vala ő előttök.
Wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn, ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda wọ́n jókòó sórí ìtẹ́ wọ́n ní ìta ẹnu-bodè Samaria, pẹ̀lú gbogbo àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
10 Csináltatott vala pedig magának Sédékiás, a Kénaána fia vasszarvakat, és monda: Ezt mondja az Úr: Ezekkel ökleled a Siriabelieket, mígnem megemészted őket!
Nísinsin yìí Sedekiah ọmọ Kenaana sì ti ṣe ìwo irin, ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Pẹ̀lú èyí ìwọ yóò kan àwọn ará Siria títí ìwọ ó fi pa wọ́n run.’”
11 A többi próféták is mind ekképen jövendöltek, mondván: Menj fel Rámóth Gileád ellen, szerencsés leszel; mert azt az Úr a király kezébe adja.
Gbogbo àwọn wòlíì tí ó kù ni wọn ń sọtẹ́lẹ̀ ní àkókò kan náà. Wọ́n sì wí pé, “Dojúkọ Ramoti Gileadi ìwọ yóò sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
12 A követ pedig, a ki elment volt, hogy elhívná Mikeást, szóla néki, mondván: Ímé a próféták egyenlő akarattal jót jövendölnek a királynak; szólj, kérlek, te is úgy, mint azok közül egy, és jövendölj jót.
Ìránṣẹ́ tí ó ti lọ pe Mikaiah sì wí fún un pé, “Ẹ wò ó, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin kan àti òmíràn wòlíì fi ẹnu kan sọ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ kí ó dàbí ọ̀kan nínú tiwọn, kí o sì sọ rere.”
13 Akkor monda Mikeás: Él az Úr, hogy csak azt fogom mondani, a mit az én Istenem nékem mondánd!
Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pe, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa ń bẹ láààyè, èmi yóò sọ ohun tí Ọlọ́run mi sọ.”
14 Mikor azért a király elé jutott, akkor monda a király néki: Mikeás! elmenjünk-é Rámóth Gileád ellen hadba, vagy elhagyjam? És monda: Menjetek el, és jó szerencsétek leszen, kezetekbe adattatnak azok.
Nígbà tí ó dé, ọba béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, “Mikaiah, ṣe kí àwa ki ó lọ sí ogun ti Ramoti Gileadi, tàbí kí àwa kí ó fàsẹ́yìn?” Ó sì dáhùn pé, “Ẹ dojúkọ wọ́n kí ẹ sì ṣẹ́gun, nítorí a ó fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
15 És monda a király néki: Hányszor esküdtesselek meg téged, hogy az igaznál egyebet ne mondj nékem az Úr nevében?
Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi ó fi ọ́ búra láti sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
16 Akkor monda: Látám az egész Izráelt elszéledve a hegyeken, mint a juhokat, melyeknek pásztoruk nincsen. És azt mondá az Úr: Nincsen ezeknek urok. Térjen meg kiki az ő házához békességben.
Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
17 És monda az Izráel királya Jósafátnak: Nemde nem megmondottam-é, hogy nem fog nékem jót jövendölni, hanem rosszat?
Ọba Israẹli wí fún Jehoṣafati pé, “Ṣe èmi kò sọ fún ọ wí pé òun kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kankan nípa mi rí, ṣùgbọ́n búburú nìkan?”
18 Ismét monda: Halljátok meg azért az Úr szavát. Látám az Urat ülni az ő királyiszékében, és az egész mennyei sereget jobb és balkeze felől mellette állani.
Mikaiah tẹ̀síwájú pé, “Nítorí náà, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ gbogbo ogun ọ̀run sì dúró lápá ọ̀tún àti lápá òsì.
19 És monda az Úr: Kicsoda csalja meg Akhábot, az Izráel királyát, hogy felmenjen és elveszszen Rámóth Gileádban? És ki egyet, ki mást szóla.
Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu ọba Israẹli lọ sí Ramoti Gileadi kí ó sì lọ kú ikú rẹ̀ níbẹ̀?’ “Èkínní sì sọ tìhín, òmíràn sì sọ tọ̀hún.
20 Akkor eljöve egy lélek, a ki megállván az Úr előtt, monda: Én akarom megcsalni őt. Az Úr pedig monda néki: Mimódon?
Ní ìparí, ni ẹ̀mí kan wá síwájú, ó dúró níwájú Olúwa ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’ “‘Nípa ọ̀nà wo?’ Olúwa béèrè.
21 És felele: Kimegyek és leszek hazug lélek az ő összes prófétái szájában. Monda azért: Csald meg és győzd meg, menj ki és cselekedjél úgy.
“‘Èmi yóò lọ láti lọ di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì.’ “‘Ìwọ yóò sì borí nínú ìtànjẹ rẹ̀ báyìí,’ ni Olúwa wí. ‘Lọ kí ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
22 Ímé azért most az Úr adta a hazugságnak lelkét ezen te prófétáid szájába, és az Úr szólott veszedelmes dolgot ellened.
“Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu àwọn wòlíì rẹ. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
23 Akkor oda lépett Sédékiás, a Kénaána fia, s arczul csapá Mikeást, és monda: Melyik úton távozott el az Úrnak lelke tőlem, hogy csak néked szólana?
Nígbà náà Sedekiah ọmọ Kenaana lọ sókè ó sì gbá Mikaiah ní ojú. Ó sì béèrè pé, “Ní ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà kọjá lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
24 Felele Mikeás: Ímé meglátod magad azon a napon, a mikor egyik kamarából a másik kamarába mégy, hogy elrejtőzhessél.
Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
25 Akkor monda az Izráel királya: Fogjátok meg Mikeást, és vigyétek Amonhoz, a város fejedelméhez, és Joáshoz, a király fiához.
Ọba Israẹli pa á láṣẹ pé, “Mú Mikaiah kí o sì ran padà sí Amoni olórí ìlú àti sí Joaṣi ọmọ ọba,
26 És mondjátok: Ezt mondja a király: Vessétek őt a tömlöczbe, s tápláljátok őt a nyomorúság kenyerével és a nyomorúság vizével, míg békességgel megjövök.
Ó sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí ọba sọ, ẹ fi ènìyàn yìí sínú túbú kí ẹ má sì ṣe fún un ní ohunkóhun ṣùgbọ́n àkàrà àti omi títí tí èmi yóò fi dé ní àlàáfíà.’”
27 És monda Mikeás: Ha békével térsz vissza, akkor nem az Úr szólott én általam. Ismét monda: Halljátok meg minden népek!
Mikaiah sì wí pe, “Tí ìwọ bá padà ní àlàáfíà, Olúwa kò sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà náà, ó sì fi kún un pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn!”
28 És felvonult az Izráel királya és Jósafát a Júda királya Rámóth Gileád ellen.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda lọ sókè ní Ramoti Gileadi.
29 És monda az Izráel királya Jósafátnak: Ruhámat megváltoztatom, és úgy megyek a viadalra; te pedig öltözzél fel ruhádba. És megváltoztatá az Izráel királya az ő ruháját, és menének viadalra.
Ọba Israẹli sọ fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ rẹ̀ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
30 Siria királya pedig meghagyta vala az ő szekerei fejedelmeinek, mondván: Ne harczoljatok se kicsiny, se nagy ellen, hanem csak az Izráel királya ellen.
Nísinsin yìí ọba Siria ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ má ṣe jà pẹ̀lú ẹnìkankan, èwe tàbí àgbà àyàfi ọba Israẹli.”
31 És a mikor meglátták a szekerek fejedelmei Jósafátot, mondának: Ez az Izráel királya! És körülfogták őt, hogy legyőzzék. Akkor felkiálta Jósafát, és az Úr megsegéllé őt, és az Isten azokat elfordítá tőle;
Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rí Jehoṣafati, wọ́n rò wí pé, “Èyí ní ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yípadà láti bá a jà. Ṣùgbọ́n Jehoṣafati kégbe sókè, Olúwa sì ràn án lọ́wọ́. Ọlọ́run sì lé wọn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀,
32 Mert mikor látták a szekerek fejedelmei, hogy nem az Izráel királya, ott hagyták.
Ó sì ṣe, nígbà tí olórí kẹ̀kẹ́ rí i wí pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì dáwọ́ lílé rẹ̀ dúró.
33 Egy férfi pedig kifeszíté kézívét csak úgy találomra, és találá az Izráel királyát a pánczél és a kapocs között. És ő monda az ő kocsisának: Fordulj meg, és vígy ki engem a táborból, mert megsebesültem.
Ṣùgbọ́n ẹnìkan fa ọrun rẹ̀ láì pète, ó sì bá ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin, ọba sì sọ fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ padà, kí o sì wà mí jáde kúrò lójú ìjà. Nítorí èmi ti gbọgbẹ́.”
34 És az ütközet mind erősebb lett azon a napon, és az Izráel királya az ő szekerében állott a Siriabeliek ellen estvéig, és naplementekor meghala.
Ní ọjọ́ pípẹ́, ìjà náà sì ń pọ̀ sí i, ọba Israẹli dúró nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ kọjú sí àwọn ará Siria títí ó fi di àṣálẹ́. Lẹ́yìn náà ní àkókò ìwọ oòrùn, ó sì kú.