< 1 Sámuel 1 >

1 Volt egy ember, Ramataim-Czofimból, az Efraim hegységéről való, és az ő neve Elkána vala, Jerohámnak fia, ki Elihu fia, ki Tohu fia, ki Sof fia volt; Efraimita vala.
Ọkùnrin kan wà, láti Ramataimu-Sofimu, láti ìlú olókè Efraimu, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elihu, ọmọ Tohu, ọmọ Sufu, ará Efrata.
2 És két felesége volt néki; az egyiket Annának, a másikat pedig Peninnának hívták. Peninnának gyermekei valának, de Annának nem valának gyermekei.
Ó sì ní ìyàwó méjì, orúkọ wọn ni Hana àti Penina: Penina ní ọmọ, ṣùgbọ́n Hana kò ní.
3 És ez az ember felmegy vala esztendőnként az ő városából, hogy imádkozzék és áldozatot tegyen a Seregek Urának Silóban. Ott pedig Éli két fia, Hofni és Fineás valának az Úrnak papjai.
Ní ọdọọdún, ọkùnrin yìí máa ń gòkè láti ìlú rẹ̀ láti lọ sìn àti láti ṣe ìrúbọ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ ní Ṣilo, níbi tí àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì, Hofini àti Finehasi ti jẹ́ àlùfáà Olúwa.
4 És azon a napon, melyen Elkána áldozni szokott, Peninnának, az ő feleségének, és minden fiának és leányának áldozati részt ád vala;
Nígbàkígbà tí ó bá kan Elkana láti ṣe ìrúbọ, òun yóò bù lára ẹran fún aya rẹ̀ Penina àti fún gbogbo àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin.
5 Annának pedig kétakkora részt ád vala, mivel Annát igen szerette; de az Úr bezárá az ő méhét.
Ṣùgbọ́n ó máa ń pín ìlọ́po fun Hana nítorí pé ó fẹ́ràn rẹ̀ àti pé Olúwa ti sé e nínú.
6 Igen bosszantja vala pedig Annát vetélkedő társa, hogy felingerelje, mivel az Úr bezárá az ő méhét.
Nítorí pé Olúwa ti sé e nínú, orogún rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní fín níràn láti lè mú kí ó bínú.
7 És így történt ez esztendőről esztendőre; valahányszor felment az Úrnak házába, ekképen bosszantá őt, ő pedig sír vala és semmit sem evék.
Eléyìí sì máa ń ṣẹlẹ̀ ní ọdọọdún. Nígbàkígbà tí Hana bá gòkè lọ sí ilé Olúwa, orogún rẹ̀ a máa fín níràn títí tí yóò fi máa sọkún tí kò sì ní lè jẹun.
8 És monda néki Elkána, az ő férje: Anna, miért sírsz, és miért nem eszel? Mi felett bánkódol szívedben? Avagy nem többet érek-é én néked tíz fiúnál?
Elkana ọkọ rẹ̀ yóò sọ fún un pé, “Hana èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Èéṣe tí ìwọ kò fi jẹun? Èéṣe tí ìwọ fi ń ba ọkàn jẹ́? Èmi kò ha ju ọmọ mẹ́wàá lọ fún ọ bí?”
9 És felkele Anna, minekutána evének Silóban és minekutána ivának, (Éli pap pedig az Úrnak templomában az ajtófélnél ül vala székében),
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹ, tí wọ́n tún mu tán ní Ṣilo, Hana dìde wá síwájú Olúwa. Nígbà náà, Eli àlùfáà wà lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ní ibi tí ó máa ń jókòó.
10 És lelkében elkeseredve, könyörge az Úrnak, és igen sír vala.
Pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn Hana sọkún gidigidi, ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
11 És fogadást tőn, mondván: Seregeknek Ura! ha megtekinted a te szolgáló leányodnak nyomorúságát, és megemlékezel rólam, és nem feledkezel el szolgáló leányodról, hanem fiúmagzatot adsz szolgáló leányodnak: én őt egész életére az Úrnak ajánlom, és borotva nem érinti az ő fejét soha!
Ó sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, jùlọ tí ìwọ bá le bojú wo ìránṣẹ́bìnrin rẹ kí ìwọ sì rántí rẹ̀, tí ìwọ kò sì gbàgbé ìránṣẹ́ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ yóò fún un ní ọmọkùnrin, nígbà náà èmi yóò sì fi fún Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ a kì yóò sì fi abẹ kàn án ní orí.”
12 Mivelhogy pedig hosszasan imádkozék az Úr előtt: Éli figyel vala az ő szájára;
Bí ó sì ṣe ń gbàdúrà sí Olúwa, Eli sì kíyèsi ẹnu rẹ̀.
13 És mivel Anna szívében könyörge (csak ajka mozgott, szava pedig nem volt hallható): Éli gondolá, hogy részeg.
Hana ń gbàdúrà láti inú ọkàn rẹ̀, ṣùgbọ́n ètè rẹ̀ ni ó ń mì, a kò gbọ́ ohùn rẹ̀. Eli rò wí pé ó ti mu ọtí yó.
14 Monda azért néki Éli: Meddig leszel részeg? Távolítsd el mámorodat magadtól.
Eli sì wí fún un pé, “Yóò ti pẹ́ fún ọ tó tí ìwọ yóò máa yó? Mú ọtí wáìnì rẹ̀ kúrò.”
15 Anna pedig felele, és monda néki: Nem, Uram! bánatos lelkű asszony vagyok én; sem bort, sem részegítő italt nem ittam, csak szívemet öntöttem ki az Úr előtt.
Hana dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, Olúwa mi, èmi ni obìnrin oníròbìnújẹ́. Èmi kò mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle; èmi ń tú ọkàn mi jáde sí Olúwa ni.
16 Ne tartsd a te szolgáló leányodat rossz asszonynak, mert az én bánatomnak és szomorúságomnak teljességéből szólottam eddig.
Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí obìnrin búburú. Èmi ti ń gbàdúrà níhìn-ín nínú ìrora ọkàn àti ìbànújẹ́ mi.”
17 És felele Éli, és monda: Eredj el békességgel, és Izráelnek Istene adja meg a te kérésedet, a melyet kértél tőle.
Eli dáhùn pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, kí Ọlọ́run Israẹli fi ohun tí ìwọ ti béèrè ní ọwọ́ rẹ̀ fún ọ.”
18 Ő pedig monda: Legyen kedves előtted a te szolgáló leányod! És elméne az asszony az ő útjára és evék, és arcza nem vala többé szomorú.
Ó wí pé, “Kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà bá tirẹ̀ lọ, ó sì jẹun, kò sì fa ojú ro mọ́.
19 És reggel felkelének, és minekutána imádkozának az Úr előtt, visszatértek, és elmenének haza Rámába. És ismeré Elkána az ő feleségét, Annát, és az Úr megemlékezék róla.
Wọ́n sì dìde ni kùtùkùtù òwúrọ̀, wọn wólẹ̀ sìn níwájú Olúwa, wọn padà wa sí ilé wọn ni Rama: Elkana si mọ Hana aya rẹ̀: Olúwa sì rántí rẹ̀.
20 És történt idő multával, hogy terhes lőn Anna, és szüle fiat és nevezé őt Sámuelnek, mert úgymond az Úrtól kértem őt.
Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ rẹ̀ pé, lẹ́yìn ìgbà tí Hana lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Samuẹli, pé, “Nítorí tí mo béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ Olúwa.”
21 És mikor felméne a férfi, Elkána és az ő egész háznépe, hogy bemutassa az Úrnak esztendőnként való áldozatát és fogadását:
Ọkùnrin náà Elkana, àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, gòkè lọ láti rú ẹbọ ọdún sí Olúwa, àti láti sán ẹ̀jẹ́ rẹ̀.
22 Anna nem ment fel, hanem monda férjének: Mihelyt a gyermeket elválasztándom, felviszem őt, hogy az Úr előtt megjelenjen, és ott maradjon örökké.
Ṣùgbọ́n Hana kò gòkè lọ; nítorí tí ó sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ó di ìgbà tí mo bá gba ọmú lẹ́nu ọmọ náà, nígbà náà ni èmi yóò mú un lọ, kí òun lè fi ara hàn níwájú Olúwa, kí ó sí máa gbé ibẹ̀ títí láé.”
23 És monda néki Elkána, az ő férje: Cselekedjél úgy, a mint néked tetszik, maradj itthon, míg elválasztod; csakhogy az Úr teljesítse be az ő beszédét! Otthon marada azért az asszony és szoptatta gyermekét, a míg elválasztá.
Elkana ọkọ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ. Dúró títí ìwọ yóò fi gba ọmú lẹ́nu rẹ̀; ṣùgbọ́n kí Olúwa sá à mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà sì jókòó, ó sì fi ọmú fún ọmọ rẹ̀ títí ó fi gbà á lẹ́nu rẹ̀.
24 És minekutána elválasztotta, felvivé magával; három tulokkal, egy efa liszttel és egy tömlő borral, és bevivé őt az Úrnak házába, Silóban. A gyermek pedig még igen kicsiny vala.
Nígbà tí ó sì gba ọmú lẹ́nu rẹ̀, ó sì mú un gòkè lọ pẹ̀lú ara rẹ̀. Pẹ̀lú ẹgbọrọ màlúù mẹ́ta, àti ìyẹ̀fun efa kan, àti ìgò ọtí wáìnì kan, ó sì mú un wá sí ilé Olúwa ní Ṣilo: ọmọ náà sì wà ní ọmọdé.
25 És levágták a tulkot, és a gyermeket Élihez vitték.
Wọ́n pa ẹgbọrọ màlúù, wọ́n sì mú ọmọ náà tọ Eli wá.
26 Ő pedig monda: Óh Uram! Él a te lelked, Uram, hogy én vagyok az az asszony, a ki itt állott melletted, és könyörgött az Úrnak.
Hana sì wí pé, “Olúwa mi, bí ọkàn rẹ ti wà láààyè, Olúwa mi, èmi ni obìnrin náà tí ó dúró lẹ́bàá ọ̀dọ̀ rẹ níhìn-ín tí ń tọrọ lọ́dọ̀ Olúwa.
27 Ezért a fiúért könyörögtem, és az Úr megadta kérésemet, a melyet tőle kértem.
Ọmọ yìí ni mo ń tọrọ; Olúwa sì fi ìdáhùn ìbéèrè tí mo béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ fún mi.
28 Most azért én is az Úrnak szentelem; teljes életére az Úrnak legyen szentelve! És imádkozának ott az Úrhoz.
Nítorí náà pẹ̀lú, èmi fi í fún Olúwa; ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀: nítorí tí mo ti béèrè rẹ̀ fún Olúwa.” Wọn si wólẹ̀ sin Olúwa níbẹ̀.

< 1 Sámuel 1 >