< 1 Királyok 16 >

1 Lőn azonban az Úrnak beszéde Jéhuhoz, a Hanáni fiához, Baása ellen, mondván:
Ó sì ṣe, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jehu ọmọ Hanani wá sí Baaṣa pé,
2 Mivelhogy téged felemeltelek a porból, és fejedelemmé tettelek téged az én népemen, az Izráelen, te pedig a Jeroboám útján jársz, és bűnbe ejted az én népemet, az Izráelt, hogy engem haragra indítsanak az ő vétkeikkel:
“Èmi ti gbé ọ ga láti inú erùpẹ̀ wá, mo sì fi ọ́ ṣe olórí Israẹli ènìyàn mi, ṣùgbọ́n ìwọ sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu, ó sì mú kí Israẹli ènìyàn mi dẹ́ṣẹ̀, láti mú mi bínú nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
3 Íme én elvetem Baása maradékait, és az ő háza maradékait, és olyanná teszem a te házadat, mint Jeroboámnak, a Nébát fiának házát.
Nítorí náà, èmi yóò mú Baaṣa àti ilé rẹ̀ kúrò, èmi yóò sì ṣe ilé rẹ̀ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati.
4 A ki Baása maradékai közül a városban hal meg, azt az ebek eszik meg; a ki pedig a mezőn halánd meg, azt az égi madarak eszik meg.
Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Baaṣa tí ó bá kú ní ìlú, ẹyẹ ojú ọ̀run yóò sì jẹ àwọn tí ó kú ní oko.”
5 Baása több dolgai pedig, és a mit cselekedett, és az ő uralkodása vajjon nincsenek-é megírva az Izráel királyainak krónika-könyvében?
Àti ìyókù ìṣe Baaṣa, ohun tí ó ṣe àti agbára rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
6 És elaluvék Baása az ő atyáival, és eltemetteték Thirsában, és az ő fia, Ela uralkodék ő utána.
Baaṣa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní Tirsa. Ela ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
7 És nemcsak azért lőn az Úrnak beszéde Jéhu próféta, a Hanáni fia által Baása és az ő háza ellen és minden ő gonoszsága ellen, a melyet cselekedett volt az Úr szemei előtt, őt haragra indítván az ő kezeinek cselekedetei által, hogy olyan lesz mint a Jeroboám háza, hanem azért is, mert azt megölte.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì wá nípa ọwọ́ Jehu wòlíì ọmọ Hanani pẹ̀lú sí Baaṣa àti ilé rẹ̀, nítorí gbogbo búburú tí ó ti ṣe níwájú Olúwa, ní mímú un bínú nípa ohun tó ti ṣe àti wíwà bí ilé Jeroboamu, àti nítorí tí ó pa á run pẹ̀lú.
8 És Asának, a Júda királyának huszonhatodik esztendejében lett királylyá Ela, a Baása fia, az Izráelen Thirsában, két esztendeig.
Ní ọdún kẹrìndínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Ela ọmọ Baaṣa bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ní Israẹli, ó sì jẹ ọba ní Tirsa ní ọdún méjì.
9 Azonban az ő szolgája Zimri, a szekerek fél részének feje, pártot ütött ellene. És Ela Thirsában volt, és az ital miatt igen megrészegedett az Arsa házában, a ki az ő házának Thirsában gondviselője volt;
Simri, ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, olórí ìdajì kẹ̀kẹ́ rẹ̀, dìtẹ̀ sí i. Ela sì wà ní Tirsa nígbà náà, ó sì mu àmupara ní ilé Arsa, ìríjú ilé rẹ̀ ni Tirsa.
10 És eljövén Zimri, megveré és megölé őt, Asának, a Júdabeli királynak huszonhetedik esztendejében, és ő uralkodék helyette.
Simri sì wọlé, ó sì kọlù ú, ó sì pa á ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa, ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
11 Mikor pedig királylyá lett és trónját elfoglalta, kiirtá Baása egész házát minden rokonságával és barátaival együtt és nem hagyott belőle még csak egy ebet sem.
Bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, bí ó sì ti jókòó lórí ìtẹ́, ó lu gbogbo ilé Baaṣa pa, kò ku ọkùnrin kan sílẹ̀, bóyá ìbátan tàbí ọ̀rẹ́.
12 Így veszté ki Zimri a Baása egész házát, az Úrnak beszéde szerint, a melyet Baása ellen szólott Jéhu próféta által:
Bẹ́ẹ̀ ni Simri pa gbogbo ilé Baaṣa run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ sí Baaṣa nípa ọwọ́ Jehu wòlíì:
13 Baása minden vétkeiért, és Elának, az ő fiának vétkeiért, a kik vétkeztek és vétekbe ejtették az Izráelt, haragra indítván az Urat, Izráelnek Istenét az ő bálványozásukkal.
nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí Baaṣa àti Ela ọmọ rẹ̀ ti ṣẹ̀ àti tí wọ́n ti mú Israẹli ṣẹ̀, tí wọ́n fi mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú, wọ́n mú u bínú nípa òrìṣà asán wọn.
14 Elának egyéb dolgai pedig és minden cselekedetei, vajjon nincsenek-é megírva az Izráel királyainak krónika-könyvében?
Ìyókù ìṣe Ela àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
15 Asának, a Júdabeli királynak huszonhetedik esztendejében, uralkodék Zimri hét napig Thirsában; a nép pedig Gibbethon előtt táborozott, a mely a Filiszteusoké.
Ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, ni Simri jẹ ọba ọjọ́ méje ní Tirsa. Àwọn ọmọ-ogun sì dó ti Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini.
16 Mikor pedig hallotta a nép a táborban beszélni, hogy pártot ütött Zimri és a királyt meg is ölte: az egész Izráel azon a napon Omrit, az Izráel seregeinek fővezérét választá királylyá a táborban.
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli tí ó dó tì gbọ́ wí pé Simri ti dìtẹ̀ sí ọba, ó sì ti pa á, wọ́n kéde Omri, olórí ogun, bí ọba lórí Israẹli ní ọjọ́ náà ní ibùdó.
17 És felvonult Omri és az egész Izráel ő vele Gibbethonból, és megszállák Thirsát.
Nígbà náà ni Omri àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ kúrò ní Gibetoni, wọ́n sì dó ti Tirsa.
18 De Zimri, a mikor látta, hogy a várost bevették, bemenvén a királyi ház palotájába, tűzzel magára gyújtá a királyi házat, és meghala.
Nígbà tí Simri sì ri pé a ti gba ìlú, ó sì wọ inú ààfin ilé ọba lọ, ó sì tẹ iná bọ ilé ọba lórí ara rẹ̀, ó sì kú,
19 Az ő bűneiért, a melyekkel vétkezék, gonoszul cselekedvén az Úr szemei előtt; járván a Jeroboám útjában és az ő bűnében, a melyet cselekedett volt, vétekbe ejtvén az Izráelt.
nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀, ní ṣíṣe búburú níwájú Olúwa àti ní rírìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣe àti tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
20 Zimrinek egyéb dolgai pedig és az ő pártütése, a melyet cselekedett, vajjon nincsenek-é megírva az Izráelbeli királyok krónika-könyvében?
Ní ti ìyókù ìṣe Simri, àti ọ̀tẹ̀ rẹ̀ tí ó dì, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
21 Akkor kétfelé hasonlék az Izráel népe: a nép egyik része Tibnit, a Ginát fiát követte és azt tette királylyá, a másik része pedig Omrihoz ragaszkodott.
Nígbà náà ní àwọn ènìyàn Israẹli dá sí méjì; apá kan wọn ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn, láti fi í jẹ ọba, apá kan tókù sì ń tọ Omri lẹ́yìn.
22 De a népnek az a része, a mely Omrihoz ragaszkodott, erősebb volt, mint az a nép, a mely Tibnit, a Ginát fiát követte, és meghalván Tibni, uralkodék Omri.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tí ń tọ Omri lẹ́yìn borí àwọn tí ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn. Bẹ́ẹ̀ ni Tibni kú, Omri sì jẹ ọba.
23 Asának, a Júdabeli királynak harminczegyedik esztendejében uralkodék Omri Izráelben tizenkét esztendeig; Thirsában uralkodék hat esztendeig.
Ní ọdún kọkànlélọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Omri bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjìlá, ọdún mẹ́fà ní Tirsa.
24 És megvevé áron a Samaria hegyét Sémertől két tálentom ezüstön; és építe a hegyre, és nevezé a várost, a melyet építe, Sémernek, a hegy urának nevéről, Samariának.
Ó sì ra òkè Samaria lọ́wọ́ Ṣemeri ní tálẹ́ǹtì méjì fàdákà, ó sì kọ́ ìlú sórí rẹ̀, ó sì pe ìlú náà ní Samaria, nípa orúkọ Ṣemeri, orúkọ ẹni tí ó kọ́kọ́ ni òkè náà.
25 És gonoszul cselekedék Omri az Úr szemei előtt, és gonoszságával meghaladá mind az ő előtte valókat.
Ṣùgbọ́n Omri sì ṣe búburú níwájú Olúwa, Ó sì ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
26 És jára Jeroboámnak, a Nébát fiának minden útján és az ő bűnében, a melylyel vétekbe ejté az Izráelt, haragra indítván az Urat, Izráel Istenét az ő bálványozásai által.
Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀, láti fi ohun asán wọn mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú.
27 Omrinak egyéb dolgai pedig és minden cselekedetei és az ő erőssége, a melylyel cselekedett, vajjon nincsenek-é megírva az Izráelbeli királyok krónika-könyvében?
Ìyókù ìṣe àti ohun tí Omri ṣe, àti agbára rẹ tí ó fihàn, a kò ha kọ, wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
28 És elaluvék Omri az ő atyáival, és eltemetteték Samariában, és uralkodék ő utána az ő fia, Akháb.
Omri sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní Samaria. Ahabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
29 Akháb pedig, az Omri fia uralkodni kezde Izráelen, Asának, a Júdabeli királynak harmincznyolczadik esztendejében; és uralkodék Akháb, az Omri fia, Izráelen Samariában huszonkét esztendeig.
Ní ọdún kejìdínlógójì Asa ọba Juda, Ahabu ọmọ Omri jẹ ọba ní Israẹli, o si jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún méjìlélógún.
30 És gonoszabbul cselekedék Akháb, az Omri fia az Úr szemei előtt mindazoknál, a kik ő előtte voltak.
Ahabu ọmọ Omri sì ṣe búburú ní ojú Olúwa ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
31 Mert nem elégedék meg azzal, hogy Jeroboámnak, a Nébát fiának bűneiben járjon, hanem elméne és feleségül vevé magának Jézabelt, Ethbaálnak, a Sídonbeli királynak leányát, és elmenvén, a Baálnak szolgála, és meghajtá magát annak.
Ó sì ṣe bí ẹni pé ó ṣe ohun kékeré fún un láti máa rìn nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, ó sì mú Jesebeli, ọmọbìnrin Etibaali, ọba àwọn ará Sidoni ní aya, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ń sin Baali, ó sì bọ ọ́.
32 És oltárt emele a Baálnak a Baál házában, a melyet Samariában épített.
Ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Baali nínú ilé Baali tí ó kọ́ sí Samaria.
33 És csinált Akháb Aserát is, és jobban haragra indítá Akháb az Urat, Izráel Istenét, mint az Izráel valamennyi királya, a kik ő előtte voltak.
Ahabu sì túnṣe ère òrìṣà Aṣerah, ó sì ṣe púpọ̀ láti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú ju èyí tí gbogbo ọba Israẹli tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ ti ṣe lọ.
34 Ennek idejében építé meg a Béthelbeli Hiel Jérikhót. Az ő elsőszülött fiának, Abirámnak élete árán veté meg annak fundamentomát, és az ő kisebbik fiának, Ségubnak élete árán állítá fel annak kapuit, az Úr beszéde szerint, a melyet szólott volt Józsué, a Nún fia által.
Ní ìgbà ayé Ahabu, Hieli ará Beteli kọ́ Jeriko. Ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀ ní Abiramu, àkọ́bí rẹ, ó sì gbé àwọn ìlẹ̀kùn ibodè rẹ̀ kọ́ ní Segubu àbíkẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Joṣua ọmọ Nuni sọ.

< 1 Királyok 16 >