< Zakariás 5 >
1 Újra fölemeltem szemeimet és láttam, s íme egy repülő tekercs.
Nígbà náà ni mo yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ìwé kíká ti ń fò.
2 És szólt hozzám: Mit látsz? – Mondtam: Látok egy repülő tekercset, hossza húsz könyöknyi, és szélessége tíz könyöknyi.
Ó sì wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ rí?” Èmi sì dáhùn pé, “Mo rí ìwé kíká tí ń fò; gígùn rẹ̀ jẹ́ ogún ìgbọ̀nwọ́, ìbú rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá.”
3 Erre szólt hozzám: Ez az átok, mely kihat az egész ország színére; mert mindenki, aki lop, innen, ahhoz képest, kipusztul és mindenki, aki esküszik, innen, ahhoz képest, kipusztul.
Ó sì wí fún mi pé, “Èyí ni ègún tí ó jáde lọ sí gbogbo ilẹ̀ ayé, nítorí gbogbo àwọn tí ó bá jalè ni a ó ké kúrò láti ìhín lọ nípa rẹ̀; gbogbo àwọn tí ó bá sì búra èké ni a ó ké kúrò láti ìhín lọ nípa rẹ̀.
4 Kibocsátottam azt, úgymond az Örökkévaló, a seregek ura, hogy bemenjen a tolvajnak házába, meg annak házába, ki nevemre hazugul esküszik és háljon a háza közepette és enyésztesse el azt, meg fáit és köveit.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò mú un jáde, Èmi yóò si wọ inú ilé olè lọ, àti inú ilé ẹni ti o bá fi orúkọ mi búra èké, yóò si wà ni àárín ilé rẹ̀, yóò si rún pẹ̀lú igi àti òkúta inú rẹ̀.’”
5 Ekkor kiment az angyal, ki velem beszélt és szólt hozzám: Emeld csak fel szemeidet és lásd, mi az, ami itt kijön.
Angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ sì jáde lọ, ó sì wí fún mi pé, “Gbé ojú rẹ sókè nísinsin yìí, kí o sì wo nǹkan tí yóò jáde lọ.”
6 Mondtam: Mi az? És mondta: Az éfa az, a mi kijön. És mondta: Ez az ő formájuk az egész országban.
Mo sì wí pé, “Kí ni nǹkan náà?” Ó sì wí pé, “Èyí ni òsùwọ̀n tí ó jáde lọ.” Ó sì wí pé, “Èyí ni àwòrán ní gbogbo ilẹ̀ ayé.”
7 S íme, egy kikkár ólom emelkedik és itt egy asszony ülve az éfában.
Sì kíyèsi i, a gbé tálẹ́ǹtì òjé sókè, obìnrin kan sì nìyìí tí ó jókòó sí àárín àpẹẹrẹ òsùwọ̀n.
8 Erre mondta: A gonoszság az! És belé dobta őt az éfába és reádobta az ólomkövet annak szájára.
Ó sì wí pé, “Èyí ni ìwà búburú.” Ó sì ti sí àárín òsùwọ̀n, ó sì ju ìdérí òjé sí ẹnu rẹ̀.
9 És fölemeltem szemeimet és láttam s íme, két asszony jön ki és szél van a szárnyaikban s olyan szárnyaik vannak, mint a gólya szárnyai; és fölemelték az éfát, föld és ég között.
Mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, obìnrin méjì jáde wá, ẹ̀fúùfù sì wá nínú ìyẹ́ wọn; nítorí wọ́n ní ìyẹ́ bí ìyẹ́ àkọ̀, wọ́n sì gbé àpẹẹrẹ òsùwọ̀n náà dé àárín méjì ayé àti ọ̀run.
10 És szóltam az angyalhoz, ki velem beszélt: Hová viszik az éfát?
Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Níbo ni àwọn wọ̀nyí ń gbé òsùwọ̀n náà lọ.”
11 Szólt hozzám: Házat építeni számára Sineár országában; s elkészíttetik, az pedig ott letétetik az ő helyén.
Ó si wí fún mi pé, “Sí orílẹ̀-èdè Babeli láti kọ ilé fún un. Tí ó bá ṣetán, a ó sì fi ìdí rẹ̀ mulẹ̀, a o sì fi ka orí ìpìlẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.”