< Példabeszédek 31 >
1 Lemúel királynak szavai. Beszéd, mellyel oktatta őt az anyja.
Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba, ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ,
2 Mit, én fiam, mit én méhem fia és mit én fogadalmim fia?
“Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi! Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.
3 Ne add az asszonyoknak erődet, sem útjaidat a királyrontóknak.
Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin, okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.
4 Ne a királyoknak, Lemúel, ne a királyoknak borivás, ne a fejedelmeknek részegítő ital!
“Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli, kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì, kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle,
5 Nehogy igyék és elfelejtené a szabott törvényt és elváltoztatná a nyomorúság minden fiának jogát.
kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí, kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n.
6 Adjatok részegítő italt a bujdosónak és bort az elkeseredett lelkűeknek;
Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora.
7 igyék és felejtse el szegénységét és szenvedésére ne emlékezzék többé.
Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.
8 Nyisd meg szájadat a némának, a mulandóság minden fiának jogáért.
“Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnra wọn fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun.
9 Nyisd meg szájadat, ítélj igazsággal és szerezd jogát a szegénynek és szűkölködőnek.
Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”
10 Derék asszonyt ki talál, a korálokat felülmúlja értéke.
Ta ni ó le rí aya oníwà rere? Ó níye lórí ju iyùn lọ.
11 Bízott benne férjének szíve és nyereség sem hiányzott.
Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀ kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.
12 Jót tett vele s nem rosszat éltének minden napjaiban.
Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
13 Gondja volt gyapjúra és lenre, és dolgozott kezei kedvével.
Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀ Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.
14 Úgy volt, mint a kalmár hajói, meszszünnen hozta kenyerét.
Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò; ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn.
15 Fölkelt, midőn még éjszaka, s kiadta, az eledelt házának, s a kiszabott kenyeret szolgálóinak.
Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn; ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀ àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.
16 Gondolt mezőre és megvette, kezének gyümölcséből ültetett szőlőt.
Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á; nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀.
17 Erővel övezte föl derekát és szilárdította karjait.
Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́.
18 Megérezte, hogy jó a keresete nem alszik el éjjel mécsese.
Ó rí i pé òwò òun pé fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru.
19 Kezeit kinyújtotta a guzsalyra és ujjai tartották az orsót.
Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú.
20 Tenyerét megnyitotta a szegénynek és kezeit kinyújtotta a szűkölködőnek.
O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.
21 Nem féltette házát a hótól, mert egész háza karmazsinba van öltözve.
Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀ nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.
22 Takarókat készített magának, bysszus és bíbor az öltözete.
Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀; ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀.
23 Ismeretes a kapukban férje, midőn együtt ül az ország véneivel.
A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú.
24 Gyolcsot készített és eladta és övet, melyet adott a kanaáninak.
Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò.
25 Erő és dísz az öltözete és nevetett a jövendő nap elé.
Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.
26 Száját fölnyitotta bölcsességgel, s szeretetnek tana a nyelvén.
A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀
27 Szemléli házának menetét, és a restség kenyerét nem eszi.
Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀ kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́.
28 Előálltak fiai és boldognak mondták, férje és megdicsérte.
Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un.
29 Sok a nő, kik derekasat végeztek, de te föléje jutottál mindnyájának.
“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ.”
30 Hazugság a kellem, és hiábavalóság a szépség; asszony, ki istenfélő, az dicsértessék.
Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù Olúwa yẹ kí ó gba oríyìn.
31 Adjatok neki kezei gyümölcséből és dicsérjék őt a kapukban tettei!
Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.