< 4 Mózes 30 >

1 És szólt Mózes Izrael fiai törzseinek fejeihez, mondván: Ez az, amit parancsolt az Örökkévaló:
Mose sì sọ fún olórí àwọn ẹ̀yà ọmọ Israẹli pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ,
2 Ha valaki fogadalmat tesz az Örökkévalónak, vagy esküt tesz, hogy megkösse magát megszorítással, meg ne szegje szavát; mind aszerint amint kijön szájából, cselekedjék.
nígbà tí ọkùnrin kan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ sí Olúwa tàbí búra láti fi de ara rẹ̀ ní ìdè kí òun má bà ba ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ́ kí ó ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sọ.
3 És ha nő tesz fogadalmat az Örökkévalónak vagy megköti magát megszorítással az atyja házában, hajadon korában,
“Nígbà tí ọmọbìnrin kan bá sì wà ní ilé baba rẹ̀ tó bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa tàbí búra láti fi de ara rẹ̀
4 és meghallja az atyja az ő fogadalmát vagy megszorítását, amellyel megkötötte magát, és hallgat az atyja, akkor fönnállnak minden fogadalmai, és minden megszorítás, amellyel megkötötte magát fenn fog állni.
tí baba rẹ̀ bá sì gbọ́ ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tàbí ìdè rẹ̀ tí kò sì sọ nǹkan kan sí i, kí gbogbo ẹ̀jẹ́ rẹ̀ kí ó dúró àti gbogbo ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ yóò sì dúró.
5 Ha azonban megtiltja az atyja neki, amely napon meghallja, minden fogadalmai és megszorításai, melyekkel megkötötte magát, nem állnak fenn; az Örökkévaló pedig megbocsát neki, mert az atyja megtiltotta neki.
Ṣùgbọ́n tí baba rẹ̀ bá kọ̀ fun un ní ọjọ́ tí ó gbọ́, kò sí ọ̀kan nínú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tàbí nínú ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ tí yóò dúró; Olúwa yóò sì tú u sílẹ̀ nítorí baba rẹ̀ kọ̀ fún un.
6 Ha pedig férjhez megy és fogadalmai rajta vannak, vagy ajkainak kijelentése, amellyel megkötötte magát,
“Tí ó bá sì ní ọkọ lẹ́yìn ìgbà tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́ tàbí lẹ́yìn ìgbà tí ó sọ ọ̀rọ̀ kan láti ẹnu rẹ̀ jáde nínú èyí tí ó fi de ara rẹ̀ ní ìdè,
7 és meghallja a férje, amely napon meghallja és hallgat, akkor fennállnak fogadalmai, és megszorításai, melyekkel megkötötte magát, fönn fognak állni.
tí ọkọ rẹ̀ sì gbọ́ nípa èyí ṣùgbọ́n tí kò sọ nǹkan kan, nígbà náà ni ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ tó dúró.
8 Ha azonban, amely napon meghallja a férje, megtiltja neki, akkor megsemmisíti fogadalmát, mely rajta van, vagy ajkai kijelentését, mellyel megkötötte magát, az Örökkévaló pedig megbocsát neki.
Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ bá kọ̀ nígbà tí ó gbọ́, ǹjẹ́ òun yóò mú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tí ó jẹ́ àti ohun tí ó ti ti ẹnu rẹ̀ jáde, èyí tí ó fi de ara rẹ̀ dasán, Olúwa yóò sì dáríjì í.
9 Az özvegy és elvált asszony fogadalma, mindaz, amivel megkötötte magát, fönnáll ránézve.
“Ṣùgbọ́n ẹ̀jẹ́ kí ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè kí ìdè tí opó tàbí obìnrin tí a kọ̀sílẹ̀ bá ṣe yóò wà lórí rẹ̀.
10 Ha pedig férje házában tett fogadalmat, vagy kötötte meg magát megszorítással eskü által,
“Bí obìnrin tí ó ń gbé pẹ̀lú ọkọ rẹ̀ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ tàbí de ara rẹ̀ ní ìdè lábẹ́ ìbúra,
11 és meghallja a férje, de hallgat, nem tiltja meg neki, akkor fennállnak minden fogadalmai, és minden megszorítás, amellyel megkötötte magát, fenn fog állni.
tí ọkọ rẹ̀ bá sì gbọ́, ṣùgbọ́n tí kò sọ̀rọ̀, tí kò sì kọ̀, nígbà náà ni ẹ̀jẹ́ rẹ̀ yóò dúró.
12 Ha azonban megsemmisíti azokat férje, amely napon meghallja, minden kijelentése ajkainak, akár fogadalmai, akár önmagának megszorításai, nem fog fennállni; férje megsemmisítette azokat és az Örökkévaló megbocsát neki.
Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ bá sọ wọ́n dasán, nígbà tí ó gbọ́, nígbà náà kò sí ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde tí yóò dúró, ọkọ rẹ̀ ti sọ wọ́n dasán, Olúwa yóò tú u sílẹ̀.
13 Minden fogadalmat és minden megszorító esküt, mely önmaga sanyargatására való, férje erősít meg és férje semmisít meg.
Ọkọ rẹ̀ lè ṣe ìwádìí tàbí sọ ọ́ dasán ẹ̀jẹ́ tàbí ìbúra ìdè tí ó ti ṣe láti fi de ara rẹ̀.
14 Ha pedig hallgat a férje napról-napra, akkor megerősítette minden fogadalmait, vagy minden megszorításait, melyek rajta vannak; megerősítette azokat, mert hallgatott, amely napon meghallotta.
Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ kò bá sọ nǹkan kan sí í nípa rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́, nígbà náà ni ó ṣe ìwádìí nípa ẹ̀jẹ́ àti ìbúra ìdè tí ó dè é. Kí ọkùnrin náà ṣe ìwádìí lórí rẹ̀ láìsọ nípa rẹ̀ si nígbà tí ó gbọ́ nípa rẹ̀.
15 Ha pedig megsemmisíti azokat, miután hallotta, akkor viselje annak bűnét.
Bí ó ti wù kí ó rí, bí ọkùnrin náà bá sọ ọ́ dasán, ní àkókò kan lẹ́yìn tí ó ti gbọ́ wọn, nígbà náà ó jẹ̀bi ọ̀rọ̀ náà.”
16 Ezek a törvények, melyeket az Örökkévaló parancsolt Mózesnek férj és felesége között, atya és leánya között, hajadon korában, atyjának házában.
Èyí ni ìlànà tí Olúwa fún Mose nípa ìbátan láàrín ọkùnrin àti obìnrin àti láàrín baba àti ọ̀dọ́mọbìnrin rẹ̀ tí ó sì ń gbé ní ilé rẹ̀.

< 4 Mózes 30 >