< Nehemiás 1 >

1 Nechemjának, Chakhalja fiának, szavai. Történt Kiszlév havában, a huszadik évben, én pedig Súsán fővárosban voltam.
Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
2 Eljött Chanáni, egy a testvéreim közül, ő és férfiak Jehúdából; és megkérdeztem őket a zsidók felől, a menekültek felől, a kik megmaradtak a fogságból, és Jeruzsálem felől.
Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
3 És mondták nekem: A megmaradottak, a kik a fogságból ott a tartományban megmaradtak, nagy bajban és gyalázatban vannak; Jeruzsálem fala pedig át van törve s kapui tűzben vannak elégetve.
Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
4 És volt, midőn hallottam e szavakat, leültem és sírtam s gyászoltam napokon át; böjtöltem és imádkoztam az ég Istene előtt.
Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
5 És mondtam: Oh Örökkévaló, az égnek Istene, nagy és félelmetes Isten, a ki megőrzi a szövetséget és szeretetet azoknak, kik őt szeretik s parancsolatait megőrzik.
Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
6 Legyen, kérlek, a te füled figyelő, a szemeid nyitvák, hogy hallgass szolgád imádságára, a mellyel én ma imádkozom teelőtted nappal és éjjel Izraél fiai, a te szolgáidért és vallomást teszek Izraél fiai vétkeiről, melyekkel vétettünk ellened, én is, meg atyám háza vétkeztünk.
Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
7 Vétve vétettünk ellened s meg nem őriztük a parancsolatokat, a törvényeket s a rendeleteket, a melyeket parancsoltál szolgádnak, Mózesnek.
Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
8 Emlékezzél, kérlek, az igéről, melyet parancsoltál szolgádnak, Mózesnek, mondván: ti hűtlenkedni fogtok, én pedig szétszórlak titeket a népek között.
“Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
9 De majd visszatértek hozzám s megőrzitek parancsolataimat s megteszitek azokat; ha lesznek eltaszítottjaitok az ég végén, onnan is összegyűjtöm őket s elviszem őket arra a helyre, melyet kiválasztottam, hogy ott lakoztassam a nevemet.
Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
10 Hisz ők a te szolgáid s a te néped, a kiket megváltottál nagy erőddel és erős kezeddel.
“Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
11 Oh Uram, legyen, kérlek, a te füled figyelő a te szolgád imádságára és a te szolgáid imádságára, a kik kívánják félni a te nevedet; s adj, kérlek, szerencsét a te szolgádnak ma s add őt irgalomra eme férfiú előtt! Én ugyanis pohárnoka voltam a királynak.
Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.

< Nehemiás 1 >