< 3 Mózes 17 >

1 És szólt az Örökkévaló Mózeshez, mondván:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Szólj Áronhoz és fiaihoz, meg Izrael minden fiaihoz és mondd nekik: Ez az, amit az Örökkévaló parancsolt, mondván:
“Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli: ‘Ohun tí Olúwa pàṣẹ nìyí,
3 Bárki Izrael házából, aki levág ökröt vagy juhot vagy kecskét a táborban, vagy aki levágja a táboron kívül,
bí ẹnikẹ́ni nínú ìdílé Israẹli bá pa màlúù tàbí ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí àgbò nínú ibùdó tàbí bí ó bá pa á lẹ́yìn ibùdó
4 és a gyülekezés sátorának bejáratához nem vitte el, hogy áldozza áldozatul az Örökkévalónak, az Örökkévaló hajléka előtt, vérontásul számíttatik be annak a férfiúnak; vért ontott, irtassék ki az a férfiú az ő népe köréből.
tí kò sì mú un wá sí ibi àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa níwájú àgọ́ ìpàdé, ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni kí ẹ kà sí ẹni náà lọ́rùn: torí pé ó ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹni náà ni a ó sì gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
5 Azért, hogy elvigyék Izrael fiai vágóáldozataikat, melyeket áldoznak a mezőn, vigyék el azokat az Örökkévalónak, a gyülekezés sátorának bejáratához, a paphoz és áldozzák azokat békeáldozatok gyanánt az Örökkévalónak.
Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí àwọn ọmọ Israẹli le è máa mú ẹbọ wọn tí wọn ti rú ní ìta gbangba wá sí iwájú Olúwa: wọ́n gbọdọ̀ mú un wá síwájú àlùfáà àní sí Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n sì rú wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa.
6 És a pap hintse a vért az Örökkévaló oltárára, a gyülekezés sátorának bejáratánál, és füstölögtesse el a zsiradékot, kellemes illatul az Örökkévalónak.
Àlùfáà náà yóò sì fi ẹ̀jẹ̀ náà wọ́n ibi pẹpẹ Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, yóò sì sun ọ̀rá rẹ̀ ní òórùn dídùn sí Olúwa.
7 Hogy ne áldozzák többé áldozataikat a bakoknak, melyek után paráználkodva járnak; örök törvény legyen ez nekik, nemzedékeiken át.
Nítorí náà, kí wọn má ṣe rú ẹbọ wọn sí ère ẹranko mọ́, nínú èyí tí wọ́n ti ṣe àgbèrè tọ̀ lọ. Èyí yóò sì jẹ́ ìlànà títí láé láti ìran dé ìran wọn tí ń bọ̀.’
8 És mondd nekik: Bárki Izrael házából és az idegen közül; aki tartózkodik közöttük, aki áldoz égőáldozatot, vagy vágóáldozatot,
“Kí ó sọ fún wọn pé, ‘Ọkùnrin yówù kí ó jẹ́ ní ìdílé Israẹli tàbí ti àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn tí ó bá rú ẹbọ sísun tàbí ṣe ẹbọ
9 és a gyülekezés sátorának bejáratához nem viszi el, hogy elkészítse azt az Örökkévalónak, irtassék ki az a férfiú az ő népéből.
tí kò sì mú un wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
10 És bárki Izrael házából és az idegen közül, aki tartózkodik közöttük, aki eszik bármi vért – haragomat fordítom a személy ellen, aki eszi a vért és kiirtom azt az ő népe köréből.
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ ẹ̀jẹ̀ yálà nínú ìdílé Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni náà tí ó jẹ ẹ̀jẹ̀, èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
11 Mert a test lelke a vérben van és én az oltárra rendeltem azt nektek, hogy engesztelést szerezzen lelkeitekért, mert a vér az, mely a lélekért engesztelést szerez.
Nítorí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí ẹ̀dá wà, èmi sì ti fi fún yín lórí pẹpẹ fún ètùtù ọkàn yín: nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni a fi ń ṣe ètùtù fún ẹ̀mí ènìyàn.
12 Azért mondtam Izrael fiainak: Bármely személy közületek ne egyék vért; az idegen, aki tartózkodik közöttetek, se egyék vért.
Ìdí nìyí tí mo fi sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ọ̀kankan nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àlejò kan tí ń ṣe àtìpó nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀.
13 Bárki Izrael fiai közül és az idegen közül, aki tartózkodik közöttük, aki vadász vadat vagy madarat, melyet enni szabad, ontsa ki a vérét és födje be azt porral.
“‘Ẹnikẹ́ni yálà nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé láàrín wọn, tí ó bá pa ẹranko tàbí ẹyẹ tí ó yẹ fún jíjẹ gbọdọ̀ ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀ kí ó sì bò ó mọ́lẹ̀.
14 Mert minden testnek lelke a vére; a lelkével együtt, azért mondtam Izrael fiainak, semmi húsnak vérét ne egyétek, mert minden testnek lelke a vére; bárki azt eszi, irtassék ki.
Torí pé ẹ̀mí gbogbo ẹ̀dá ni ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, torí náà ni mo fi kìlọ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí kankan, torí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí wọ̀nyí ni ẹ̀mí wọn wà, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹ́ ni a ó gé kúrò.
15 És minden személy, aki eszik elhullott és szétszaggatott állatot, akár bennszülött, akár idegen, mossa meg a ruháit, fürödjék meg vízben és tisztátalan legyen estig, azután tiszta lesz.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó kú sílẹ̀ fúnra rẹ̀, tàbí èyí tí ẹranko búburú pa kálẹ̀ yálà onílé tàbí àlejò, ó ní láti fọ aṣọ rẹ̀. Kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di àṣálẹ́ lẹ́yìn èyí ni yóò tó di mímọ́.
16 De ha nem mossa meg a ruháit és testét nem füröszti meg, akkor viseli bűnét.
Ṣùgbọ́n bí ó bá kọ̀ láti wẹ ara rẹ̀ tí kò sì fọ aṣọ rẹ̀ náà: ẹ̀bi rẹ̀ yóò wà lórí ara rẹ̀.’”

< 3 Mózes 17 >