< Birák 7 >

1 És korán fölkelt Jerubbáal, az Gideón, meg az egész nép, mely vele volt és táboroztak Charód forrásánál; Midján tábora pedig északra volt tőle, a Móré halmától fogva a Völgyben.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Jerubbaali (èyí ni Gideoni) pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kó ogun jọ lẹ́bàá a orísun Harodi. Àwọn ogun Midiani sì wà ní apá àríwá tí wọ́n ní àfonífojì tí ó wà ní ẹ̀bá òkè More.
2 És szólt az Örökkévaló Gideónhoz: Több a nép, mely veled van, hogy sem kezükbe adnám Midjánt: nehogy dicsekedjék rajtam Izraél, mondván: önkezem segített nekem.
Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọmọ-ogun tí o kójọ sọ́dọ̀ ti pọ̀jù fún mi láti fi àwọn ogun Midiani lé wọn lọ́wọ́, kí Israẹli má ba à gbé ara rẹ̀ ga sí mi wí pé agbára òun ni ó gbà á là,
3 Most tehát hirdesd csak a nép fülei hallatára, mondván: a ki fél és remeg, térjen vissza és forduljon meg Gileád hegyéről. És visszatért a nép közül huszonkétezer, tízezeren pedig maradtak.
sì kéde sí àwọn ènìyàn nísinsin yìí pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbọ̀n, tí ó sì ń bẹ̀rù lè padà sẹ́yìn, kí ó sì kúrò lórí òkè Gileadi.’” Báyìí ni Gideoni ṣe ya àwọn ènìyàn náà. Ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ọkùnrin sì padà sẹ́yìn àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì dúró.
4 És szólt az Örökkévaló Gideónhoz: Még ez a nép is sok, vezesd le őket a vízhez, majd megválogatom ott neked: és lészen, a kiről azt mondom neked, ez menjen veled, az megy veled; mind a kiről pedig azt mondom neked, ez ne menjen veled, az nem megy.
Olúwa sì tún sọ fún Gideoni pé, “Àwọn ènìyàn yìí sì tún pọ̀jù. Kó wọn lọ sí ibi tí omi wà, èmi yóò sì yọ̀rọ̀ wọn níbẹ̀ fún ọ. Bí mo bá wí pé eléyìí yóò bá ọ lọ yóò lọ, ṣùgbọ́n tí mo bá sọ pé, ‘Eléyìí kò ní bá ọ lọ,’ òun kò gbọdọ̀ lọ.”
5 Levezette tehát a népet a vízhez, és szólt az Örökkévaló Gideónhoz: Mind az, a ki nyaldos nyelvével a vízből, a mint nyaldos az eb – állítsd azt külön és mind azt is, a ki térdeire esik, hogy igyék.
Gideoni sì kó àwọn ọkùnrin náà lọ sí ibi ìsun omi. Níbẹ̀ ni Olúwa ti wí fún un pé, “Kí ó pín àwọn ènìyàn náà sí ọ̀nà méjì. Ya àwọn tí ó fi ahọ́n wọn lá omi bí ajá kúrò lára àwọn tí ó kúnlẹ̀ láti mu omi pẹ̀lú ọwọ́ wọn.”
6 És volt a száma azoknak, kik nyaldostak, kezüket véve szájukhoz, háromszáz ember; mind a többi nép pedig térdeire esett vizet inni.
Ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin ni ó lá omi pẹ̀lú ahọ́n wọn. Gbogbo àwọn ìyókù ni ó kúnlẹ̀ láti mu mi.
7 Ekkor szólt az Örökkévaló Gideónhoz: A háromszáz emberrel, a kik nyaldostak, segítlek meg titeket és kezedbe adom Midjánt; az egész nép pedig menjen kiki az ő helyére.
Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó lá omi ni èmi yóò lò láti gbà yín là àti láti fi ogun Midiani lé yín lọ́wọ́. Jẹ́ kí àwọn tókù padà sí ilé wọn.”
8 És kezükbe vették a nép eleségét és harsonáit, Izraél minden emberét pedig elbocsátotta kit-kit sátraihoz s a háromszáz embert megtartotta; Midján tábora pedig tőle alant volt a völgyben.
Báyìí ni Gideoni ṣe dá àwọn Israẹli tí ó kù padà sí àgọ́ wọn, ṣùgbọ́n ó dá àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin náà dúró. Àwọn wọ̀nyí sì gba gbogbo ohun èlò àti fèrè àwọn tí ó ti padà. Ibùdó ogun àwọn Midiani wà ní àfonífojì ní ìsàlẹ̀. Ibi tí ó wà.
9 Volt pedig azon éjjel, szólt hozzá az Örökkévaló: Kelj föl, menj le a táborba, mert kezedbe adtam.
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa sọ fún Gideoni pé, “Dìde, dojú ogun kọ ibùdó ogun àwọn ará Midiani nítorí èmi yóò fi lé ọ lọ́wọ́.
10 De ha félsz lemenni, menj le te és legényed Púra a táborhoz;
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀rù àti kọlù wọ́n bá ń bà ọ́, yọ́ wọ ibùdó wọn lọ kí o mú Pura ìránṣẹ́ rẹ lọ́wọ́
11 majd meghallod mit beszélgetnek s azután megerősödnek kezeid – menj hát le a táborba. És lement, ő és legénye Púra, a táborban levő fegyveresek közelébe.
kí o sì fi ara balẹ̀ gbọ́ ohun tí wọ́n ń sọ nínú ibùdó náà. Lẹ́yìn èyí ọkàn rẹ̀ yóò le láti kọlù ibùdó náà.” Báyìí ni òun àti Pura ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ ẹnu-ọ̀nà ibùdó yìí.
12 Midján pedig és Amálék meg mind a Kelet fiai elterültek a völgyben, mint a sáska sokaságra; s tevéiknek nem volt száma, mint a föveny a tenger partján sokaságra.
Àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti gbogbo ènìyàn ìlà-oòrùn tó lọ ní àfonífojì bí eṣú ni wọ́n rí nítorí púpọ̀ wọn. Àwọn ìbákasẹ wọn kò sì lóǹkà, wọ́n sì pọ̀ bí yanrìn inú Òkun.
13 Odament Gideón, s íme valaki elbeszél egy álmot a társának; mondta: Íme, álmot álmodtam, s íme egy czipó árpakenyér forog Midján táborában, eljutott a sátorig s meglökte, hogy összedőlt, majd fölfelé fordította, hogy összedőlt a sátor.
Gideoni dé sí àsìkò tí ọkùnrin kan bẹ̀rẹ̀ sí í rọ́ àlá tí ó lá sí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀. Ó ní, “Mo lá àlá kan, nínú àlá náà mo rí àkàrà kan tó ṣe róbótó tí a fi barle ṣe ń yí wọ inú ibùdó àwọn ará Midiani, ó sì kọlu àgọ́ pẹ̀lú agbára ńlá dé bi wí pé àgọ́ náà dojúdé, ó sì ṣubú.”
14 Erre felelt a társa és mondta: Nem más az, mint Gideónnak, Jóás fiának, az izraelita férfiúnak kardja; kezébe adta Isten Midjánt és az egész tábort.
Ọ̀rẹ́ rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Èyí kò le túmọ̀ sí ohun mìíràn ju idà Gideoni ọmọ Joaṣi ará Israẹli lọ: Ọlọ́run ti fi àwọn ará Midiani àti gbogbo ogun ibùdó lé e lọ́wọ́.”
15 És volt, mihelyt meghallotta Gideón az álom elbeszélését és megfejtését, leborult; visszatért Izraél táborához s mondta: Keljetek föl, mert kezetekbe adta az Örökkévaló Midján táborát.
Nígbà tí Gideoni gbọ́ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀, ó wólẹ̀ sin Ọlọ́run: lẹ́yìn náà ni ó padà sí ibùdó àwọn ọmọ Israẹli ó sì pè wọ́n pé, “Ẹ dìde! Nítorí pé Olúwa yóò lò yín láti ṣẹ́gun gbogbo ogun Midiani.”
16 S elosztotta a háromszáz embert három csapatra; adott harsonákat mindnyájuk kezébe; meg üres korsókat és fáklyákat a korsókban.
Nígbà tí ó ti pín àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì sí ọ̀nà mẹ́ta, ó fi fèrè, pẹ̀lú àwọn òfìfo ìkòkò lé ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn lọ́wọ́, iná sì wà nínú àwọn ìkòkò náà.
17 És szólt hozzájuk: Tőlem látjátok majd s akképpen cselekedjetek; íme, midőn odaérek a tábor szélére, akkor lészen, a mint én cselekszem, úgy cselekedjetek ti.
Ó sọ fún wọn pé, “Ẹ máa wò mí, kí ẹ sì máa ṣe ohun tí mo bá ṣe. Nígbà tí mo bá dé igun ibùdó wọn ẹ ṣe ohun tí mo bá ṣe.
18 Megfúvom a harsonát, én és mind a velem levők, akkor fújjátok ti is a harsonákat az egész tábor körül és mondjátok: Az Örökkévalóért és Gideónért!
Nígbà tí èmi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi bá fun fèrè wa, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin náà ni gbogbo igun ibùdó tí ẹ̀ bá wà kí ẹ fun àwọn fèrè yín kí ẹ sì hó pé, ‘Fún Olúwa àti fún Gideoni.’”
19 S oda ért Gideón meg a száz ember, ki vele volt, a tábor szélére a középső őrszak kezdetén – éppen fölállították az őröket – akkor megfújták a harsonákat és szétzúzták a kezükben levő korsókat.
Gideoni àti àwọn ọgọ́rùn-ún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ dé òpin ibùdó àwọn ará Midiani ní nǹkan bí agogo méjìlá padà. Wọ́n fun fèrè wọn, wọ́n sì tún fọ́ àwọn ìkòkò tí ó wà ní ọwọ́ mọ́lẹ̀.
20 Erre megfújta a három csapat a harsonákat, összetörték a korsókat s megragadták bal kezükkel a fáklyákat, jobb kezükkel pedig a harsonákat, hogy fújjanak; így kiáltottak: Kard az Örökkévalóért és Gideónért!
Àwọn ẹgbẹ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta fun fèrè wọn, wọ́n tún fọ́ àwọn ìkòkò wọn mọ́lẹ̀. Wọ́n mú àwọn fìtílà iná wọn ní ọwọ́ òsì wọn àti fèrè tí wọ́n ń fun ní ọwọ́ ọ̀tún wọn. Wọ́n pariwo hé è pé, “Idà kan fún Olúwa àti fún Gideoni!”
21 És álltak kiki a maga helyén a tábor körül; szerteszaladt az egész a tábor, riadoztak és megfutamodtak.
Nígbà tí ọkùnrin kọ̀ọ̀kan dúró ní ipò rẹ̀ yí ibùdó àwọn Midiani ká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun Midiani ń sá káàkiri, wọ́n ń pariwo bí wọ́n ṣe ń sálọ.
22 És megfújták a háromszáz harsonát, ekkor fordította az Örökkévaló egyiknek kardját a másika ellen és pedig az egész táborban; és megfutamodott a tábor Bét-Sittáig, Czeréra felé, Ábél Mechóla partjáig Tabbát mellett.
Nígbà tí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì fun fèrè wọn, Olúwa sì yí ojú idà ọkùnrin kọ̀ọ̀kan padà sí ẹnìkejì rẹ̀ àti sí gbogbo ogun wọn. Àwọn ọmọ-ogun sì sá títí dé Beti-Sitta ní ọ̀nà Serera títí lọ dé ìpínlẹ̀ Abeli-Mehola ní ẹ̀bá Tabbati.
23 És összegyülekezett Izraél embere Naftáliból, Ásérból és egész Menasséból és üldözték Midjánt.
Gbogbo àwọn ọmọ-ogun Israẹli láti ẹ̀yà Naftali, Aṣeri àti gbogbo Manase ni Gideoni ránṣẹ́ si, wọ́n wá wọ́n sì lé àwọn ará Midiani.
24 S követeket küldött Gideón Efraim egész hegységébe, mondván: Menjetek le Midján ellenébe és foglaljátok el tőlük a vizeket Bét-Báráig, meg a Jordánt. És összegyülekezett Efraim minden embere, s elfoglalták a vizeket Bét-Báráig, meg a Jordánt.
Gideoni tún ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè Efraimu wí pé, “Ẹ jáde wá bá àwọn ará Midiani jà, kí ẹ tètè gba àwọn omi Jordani títí dé Beti-Bara kí wọ́n tó dé bẹ̀.” Báyìí ni a ṣe pe gbogbo ọkùnrin ológun Efraimu jáde tí wọ́n sì gba gbogbo àwọn à bá wọ odò Jordani títí dé Beti-Bara.
25 Elfogták Midján két vezérét: Órébet és Zeébet; és megölték Órébet az Óréb-sziklán, Zeébet pedig megölték a Zeéb-présházban, és üldözték Midjánt; Óréb és Zeéb fejét pedig Gideónhoz vitték túl a Jordánon.
Wọ́n mú méjì nínú àwọn olórí àwọn ará Midiani, àwọn náà ni Orebu àti Seebu. Wọ́n pa Horebu nínú àpáta Orebu, wọ́n sì pa Seebu níbi tí àwọn ènìyàn ti mọ̀ fún wáìnì tí a ń pè ní ìfúntí Seebu. Wọ́n lé àwọn ará Midiani, nígbà tí wọ́n gbé orí Orebu àti Seebu tọ Gideoni wá ẹni tí ó wà ní apá kejì Jordani.

< Birák 7 >