< Birák 17 >
1 Volt egy ember Efraim hegységéből, neve Míkhájehú.
Nígbà náà ni ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika láti agbègbè òkè Efraimu
2 Mondta anyjának: Az ezer és száz ezüst, mely tőled elvétetett, te pedig átkot mondtál és szóltál is füleim hallatára, íme, az ezüst nálam van, én vettem azt el. És mondta az anyja: Áldott legyen fiam az Örökkévalótól.
sọ fún ìyá rẹ̀ pé, “Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà èyí tí wọ́n jí mọ́ ọ lọ́wọ́, àti nípa èyí tí mo gbọ́ tí ìwọ ń ṣẹ́ èpè. Kíyèsi fàdákà náà wà ní ọ̀dọ̀ mi, èmi ni mo kó o.” Nígbà náà ni ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Kí Olúwa bùkún ọ ọmọ mi!”
3 Visszaadta anyjának az ezer és száz ezüstöt; és mondta az anyja: Megszentelem kezemből az ezüstöt fiam számára, faragott és öntött kép készítésére; most tehát visszaadom neked.
Nígbà tí ó da ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Èmi ti fi òtítọ́ inú ya sílífà náà sọ́tọ̀ sí Olúwa fún ọmọ mi láti fi dá ère dídá àti ère gbígbẹ́. Èmi yóò dá a padà fún ọ.”
4 Visszaadta az ezüstöt anyjának; és vett az anyja kétszáz ezüstöt és odaadta az ötvösnek, az földolgozta faragott. és öntött képpé, és ott volt Míkhájehú házában.
Nítorí náà òun dá sílífà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì mú igba ṣékélì fàdákà, ó sì fún alágbẹ̀dẹ fàdákà ẹni tí ó fi wọ́n rọ ère fínfín àti ère dídà. Wọ́n sì kó wọn sí ilé Mika.
5 A férfiúnak, Míkhának pedig volt egy istenháza; készített éfódot és teráfimot és megtöltötte fiai egyikének kezét, és lett neki pappá.
Ọkùnrin náà, Mika sì ní ojúbọ kan. Òun sì ra ẹ̀wù efodu kan, ó sì ṣe àwọn ère kan, ó sì fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin ṣe àlùfáà rẹ̀.
6 Azokban a napokban nem volt király Izraélben, ki-ki tette, a mi helyes volt szemeiben.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba; olúkúlùkù ṣe bí ó ti rò pé ó tọ́ ní ojú ara rẹ́.
7 Volt egy ifjú a Jehúdabeli Bét-Léchemből, Jehúda nemzetségéből; az levita volt és ott tartózkodott.
Ọ̀dọ́mọkùnrin kan sì ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda wá, tí í ṣe ìdílé Juda, ẹni tí í ṣe ẹ̀yà Lefi, òun sì ṣe àtìpó níbẹ̀,
8 Elment ez ember a városból, a Jehúdabeli Bét-Léchemből, hogy tartózkodjék, a hol helyet talál; és eljutott Efraim hegyégébe Míkha házáig, hogy útját végezze.
ọkùnrin náà sì ti ìlú Bẹtilẹhẹmu ti Juda lọ, láti ṣe àtìpó ní ibikíbi tí ó bá rí. Ní ojú ọ̀nà àjò rẹ̀, ó dé ilẹ̀ Mika nínú àwọn ilẹ̀ òkè Efraimu.
9 És mondta neki Míkha: Honnan jössz? Szólt hozzá: Levita vagyok a Jehúdabeli Bét-Léchemből, és én megyek tartózkodni, a hol helyet találok.
Mika bi í pé, “Níbo ni ó ti ń bọ̀?” Ó dáhùn pé, “Ọmọ Lefi ni mí láti Bẹtilẹhẹmu Juda, mo sì ń wá ibi tí èmi yóò máa gbé.”
10 Erre mondta neki Míkha: Maradj nálam, légy nekem atyám és papom, én meg adok neked tíz ezüstöt az évre, egy rend ruhát és élelmedet. És ráállott a lévita.
Mika sì sọ fún un wí pé, “Dúró lọ́dọ̀ mi kí ìwọ sì jẹ́ baba mi àti àlùfáà fún mi, èmi ó sì máa fún ọ ní ṣékélì mẹ́wàá fàdákà ní ọdọọdún, pẹ̀lú aṣọ àti oúnjẹ rẹ̀.”
11 Beleegyezett a levita, hogy lakjék a férfiúnál; és volt neki az ifjú mint bármelyik a fiai közül.
Ọmọ Lefi náà sì gbà láti máa bá a gbé, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
12 Míkha megtöltötte a levita kezét, így lett neki az ifjú papjává; és ott volt Míkha házában.
Nígbà náà ni Mika ya ará Lefi náà sí mímọ́, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì di àlùfáà rẹ̀, ó sì ń gbé ilé rẹ̀.
13 És mondta Míkha: Most tudom, hogy majd jót tesz velem az Örökkévaló, mert papommá lett nekem a levita.
Mika sì wí pé, “Báyìí, èmi mọ̀ pé Olúwa yóò ṣe mi ní oore nítorí pé mo ní ọmọ Lefi ní àlùfáà mi.”