< Jóel 2 >
1 Fújjátok meg a harsonát Cziónban és riadjatok szent hegyemen, reszkessenek mind az ország lakói, mert jön az Örökkévaló napja, mert közel van;
Ẹ fun ìpè ní Sioni, ẹ sì fún ìpè ìdágìrì ní òkè mímọ́ mi. Jẹ́ kí àwọn ará ilẹ̀ náà wárìrì, nítorí tí ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ wá, nítorí ó kù sí dẹ̀dẹ̀.
2 sötétség és homály napja, felhő, sűrű ködnek napja; mint hajnal terül el hegyeken: számos és hatalmas nép, ahhoz hasonló nem volt öröktől fogva, utána sem lesz többé, nemzedék meg nemzedék évein át.
Ọjọ́ òkùnkùn àti ìrọ́kẹ̀kẹ̀, ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri. Bí ọyẹ́ òwúrọ̀ ti í la bo orí àwọn òkè ńlá: àwọn ènìyàn ńlá àti alágbára; ya dé, ti kó ti ì sí irú rẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni irú rẹ̀ kì yóò sí mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, títí dé ọdún ìran dé ìran.
3 Előtte tűz emészt és utána láng lobbant, mint Éden kertje előtte az ország, és utána sivatag puszta, menekvés sem volt tőle.
Iná ń jó níwájú wọ́n; ọwọ́ iná sì ń jó lẹ́yìn wọn. Ilẹ̀ náà dàbí ọgbà Edeni níwájú wọn, àti lẹ́yìn wọn bí ahoro ijù; nítòótọ́, kò sì sí ohun tí yóò bọ́ lọ́wọ́ wọn.
4 Mint lovak látszata az ő látszata, s mint mének úgy szaladnak.
Ìrí wọn dàbí ìrí àwọn ẹṣin; wọ́n ń sáré lọ bí àwọn ẹlẹ́ṣin ogun.
5 Mint szekerek zöreje, a hegyek csúcsain ugrálnak, mint zizegése a tűz lángjának, mely tarlót emészt, mint hatalmas nép harczra sorakozva.
Bí ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ni wọn ń fo ní orí òkè bí ariwo ọ̀wọ́-iná tí ń jó koríko gbígbẹ, bí akọni ènìyàn tí a kójọ fún ogun.
6 Miatta remegnek népek, minden arcz bevonja fényét.
Ní ojú wọn, àwọn ènìyàn yóò jẹ ìrora púpọ̀: gbogbo ojú ní yóò ṣú dudu.
7 Mint vitézek szaladnak, mint harczosok fölhágnak a falra – kiki a maga útján haladnak, nem kuszálják össze pályáikat.
Wọn yóò sáré bi àwọn alágbára; wọn yóò gùn odi bí ọkùnrin ológun; olúkúlùkù wọn yóò sì rìn lọ ní ọ̀nà rẹ̀, wọn kì yóò sì yà kúrò ni ọ̀nà wọn.
8 Egyik a másikát nem szorítják, mindegyik a maga ösvényén haladnak, a fegyveren rohannak által, nem szakadnak meg.
Bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò kọlu ẹnìkejì rẹ̀; olúkúlùkù wọn yóò rìn ní ọ̀nà rẹ̀, nígbà tí wọn bá sì ṣubú lù idà wọn kì yóò gbọgbẹ́.
9 A városban futkosnak, a falon szaladnak, a házakba másznak föl, az ablakokon által jönnek be mint a tolvaj.
Wọn yóò sáré síwá sẹ́yìn ní ìlú; wọn yóò súré lórí odi, wọn yóò gùn orí ilé; wọn yóò gbà ojú fèrèsé wọ̀ inú ilé bí olè.
10 Előtte a föld megreszketett, megrendült az ég, nap és hold elsötétültek, s a csillagok behúzták ragyogásukat.
Ayé yóò mì níwájú wọn; àwọn ọ̀run yóò wárìrì; oòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn, àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn.
11 S az Örökkévaló hallatta hangját az ő serege előtt, mert igen számos az ő tábora, mert hatalmas az igéjének végrehajtója; mert nagy az Örökkévaló napja, és félelmetes nagyon, és ki bírja el!
Olúwa yóò sì bú ramúramù jáde níwájú ogun rẹ̀: nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi; nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ; nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi; ara ta ni ó lè gbà á?
12 De most is, úgymond az Örökkévaló, térjetek meg hozzám, egész szívetekkel, meg böjttel és sírással s gyászolással.
“Ǹjẹ́ nítorí náà nísinsin yìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ fi gbogbo ọkàn yín yípadà sí mi, àti pẹ̀lú àwẹ̀, àti pẹ̀lú ẹkún, àti pẹ̀lú ọ̀fọ̀.”
13 Szaggassátok meg szíveteket és ne ruháitokat, és térjetek meg az Örökkévalóhoz, a ti Istentekhez – mert kegyelmes és irgalmas ő, hosszantűrő és bőséges a szeretetben és a ki meggondolja a veszedelmet.
Ẹ sì fa ọkàn yín ya, kì í sì í ṣe aṣọ yín, ẹ sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí tí o pọ̀ ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì kún fun àánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì ṣeun púpọ̀, ó sì ronúpìwàdà láti ṣe búburú.
14 Ki tudja, hátha fordul és meggondolja; akkor hátrahagy maga után áldást, lisztáldozatot és öntőáldozatot az Örökkévaló, a ti Istenetek számára.
Ta ni ó mọ̀ bí òun yóò yípadà, kí o sì ronúpìwàdà, kí ó sì fi ìbùkún sílẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀— àní ọrẹ-jíjẹ àti ọrẹ mímu fún Olúwa Ọlọ́run yín?
15 Fújjátok meg a harsonát Cziónban, szenteljetek böjtöt, hirdessetek gyülekezést;
Ẹ fún ìpè ní Sioni, ẹ ya àwẹ̀ kan sí mímọ́, ẹ pe àjọ tí ó ni ìrònú.
16 gyűjtsétek egybe a népet, szenteljetek gyülekezetet, gyűjtsétek össze a véneket, gyűjtsétek egybe a kisdedeket és csecsszopókat, menjen ki a vőlegény kamarájából s a menyasszony mennyezetéből.
Ẹ kó àwọn ènìyàn jọ, ẹ ya ìjọ sí mímọ́; ẹ pe àwọn àgbàgbà jọ, ẹ kó àwọn ọmọdé jọ, àti àwọn tí ń mú ọmú, jẹ kí ọkọ ìyàwó kúrò nínú ìyẹ̀wù rẹ̀. Kí ìyàwó sì kúrò nínú iyàrá rẹ̀.
17 A csarnok és az oltár között sírjanak a papok, az Örökkévalónak szolgálattevői; és mondják: sajnáld meg, oh Örökkévaló, népedet, s ne tedd birtokodat gyalázattá, hogy nemzetek uralkodjanak rajtuk; miért mondhassák a népek között: hol az Istenük?
Jẹ́ kí àwọn àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ Olúwa, sọkún láàrín ìloro àti pẹpẹ. Sí jẹ́ kí wọn wí pé, “Dá àwọn ènìyàn rẹ sí, Olúwa. Má sì ṣe fi ìní rẹ fun ẹ̀gàn, tí yóò sì di òwe ní àárín àwọn kèfèrí. Èéṣe tí wọn yóò fi wí láàrín àwọn ènìyàn pé, ‘Ọlọ́run wọn ha da?’”
18 És buzgólkodott az Örökkévaló az ő országáért, és megszánta népét.
Nígbà náà ní Olúwa yóò jowú fún ilẹ̀ rẹ̀, yóò sì káàánú fún ènìyàn rẹ̀.
19 És felelt az Örökkévaló és mondta népének: Íme én küldöm nektek a gabonát, a mustot és az olajat, hogy jól lakjatok vele; és nem teszlek benneteket többé gyalázattá a nemzetek között.
Nítòótọ́, Olúwa yóò dá wọn lóhùn, yóò sì wí fun àwọn ènìyàn rẹ̀ pé: “Wò ó èmi yóò rán ọkà, àti ọtí wáìnì tuntun, àti òróró sí i yín, a ó sì fi wọn tẹ́ yín lọ́rùn; Èmi kì yóò sì fi yín ṣe ẹ̀gàn mọ́ láàrín àwọn aláìkọlà.
20 Amaz északit pedig eltávolítom tőletek, és eltaszítom szárazság és pusztaság földjére: elejét a keleti tengerbe és végét a nyugati tengerbe; s majd száll a bűze, felszáll a dögszaga – mert nagyokat mívelt.
“Ṣùgbọ́n èmi yóò lé ogun àríwá jìnnà réré kúrò lọ́dọ̀ yín, èmi yóò sì lé e lọ sí ilẹ̀ tí ó ṣá, tí ó sì di ahoro, pẹ̀lú ojú rẹ̀ sí Òkun ìlà-oòrùn, àti ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìwọ̀-oòrùn Òkun. Òórùn rẹ̀ yóò sì gòkè, òórùn búburú rẹ̀ yóò sì gòkè.” Nítòótọ́ ó ti ṣe ohun ńlá.
21 Ne félj, föld, ujjongj és örvendj, mert nagyokat mívelt az Örökkévaló!
Má bẹ̀rù, ìwọ ilẹ̀; jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn kí o sì yọ̀, nítorí Olúwa ti ṣe ohun ńlá.
22 Ne féljetek, mező vadjai, mert megzöldültek a puszta tanyái, mert a fa megtermette gyümölcsét, fügefa és szőlőtő adták erejüket.
Ẹ má bẹ̀rù, ẹranko igbó, nítorí pápá oko aginjù ń rú. Nítorí igi ń so èso rẹ̀, igi ọ̀pọ̀tọ́ àti àjàrà ń so èso ọ̀rọ̀ wọn.
23 És ti Czión fiai, ujjongjatok és örvendjetek az Örökkévalóban, a ti Istentekben, mert adta nektek az igazságra tanítót, és hullatott nektek esőt, meg őszi esőt és tavaszi esőt az első hónapban.
Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, ẹ̀yin ọmọ Sioni, ẹ sì yọ̀ nínú Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ó ti fi àkọ́rọ̀ òjò fún yín bí ó ti tọ́, Òun ti mú kí òjò rọ̀ sílẹ̀ fún un yín, àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní oṣù kìn-ín-ní.
24 És megtelnek a szérűk gabonával és áradoznak a présházak musttól meg olajtól.
Àwọn ilẹ̀ ìpakà yóò kún fún ọkà; àti ọpọ́n wọn nì yóò sàn jáde pẹ̀lú ọtí wáìnì tuntun àti òróró.
25 És pótolom nektek azon éveket, melyeket megevett a sáska, a nyaló, a faló és a szöcske, az én nagy seregem, melyet bocsátottam rátok.
“Èmi yóò sì mú ọdún wọ̀nyí ti eṣú jẹ run padà fún un yín. Èyí tí eṣú agénijẹ àti eṣú jewéjewé ọwọ́ eṣú agénijẹ àti kòkòrò ajẹnirun mìíràn ti fi jẹ àwọn ogun ńlá mi tí mo rán sí àárín yín.
26 És enni fogtok, enni és jóllakni és dicséritek az Örökkévalónak, a ti Istenteknek nevét, ki csodálatosan cselekedett veletek; s nem fog megszégyenülni népem örökre.
Ẹ̀yin yóò ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti jẹ, títí ẹ̀yin yóò fi yó ẹ ó sì yín orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó fi ìyanu bá yín lò; ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mi láéláé.
27 S majd megtudjátok, hogy Izraél közepette vagyok én, s én vagyok az Örökkévaló, a ti Istenetek és senki más; s nem fog megszégyenülni népem örökre.
Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, èmi wà láàrín Israẹli, àti pé; Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, àti pé kò sí ẹlòmíràn, ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mí láéláé.
28 Lészen pedig ez után: kiöntöm szellememet minden halandóra, és majd prófétálnak a fiaitok és leányaitok; véneitek álmokat álmodnak – ifjaitok látomásokat látnak.
“Yóò sì ṣe níkẹyìn ọjọ́, èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí sí ara ènìyàn gbogbo; àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀, àwọn arúgbó yín yóò máa lá àlá, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò máa ríran.
29 Még a szolgákra és szolgálókra is ama napokban kiöntöm szellememet.
Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin, àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin, ní èmi yóò tú ẹ̀mí mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.
30 És adok csodajeleket az égen és a földön: vért, tüzet és füstoszlopokat.
Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrun àti ní ayé, ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.
31 A nap átváltozik sötétséggé, s a hold vérré, mielőtt eljönne az Örökkévaló napja, a nagy és félelmetes.
A á sọ oòrùn di òkùnkùn, àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa tó dé.
32 És lészen, mind az a ki szólítja az Örökkévaló nevét, megmenekül; mert Czión hegyén és Jeruzsálemben menekvés lesz, a mint mondta az Örökkévaló, s azon megmaradottak közt, a kiket szólít az Örökkévaló!
Yóò sí ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pè orúkọ Olúwa ní a ó gbàlà, nítorí ní òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu ní ìgbàlà yóò gbé wà, bí Olúwa ti wí, àti nínú àwọn ìyókù tí Olúwa yóò pè.