< Jób 36 >
1 És folytatta Elíhú és mondta:
Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé,
2 Várj reám egy kicsit, hadd közöljem veled, mert még van Isten mellett mondani valóm.
“Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́, nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.
3 Messzünnen hozom tudásomat és alkotómnak adok igazat.
Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá, èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.
4 Mert valóban, szavaim nem hazugság, teljes tudású van szemben veled.
Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké nítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
5 Lám, Isten hatalmas, de kit sem vet meg, észerőre hatalmas.
“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì gàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.
6 Nem hagyja életben a gonoszt, s a szegényeknek jogát megadja.
Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí, ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.
7 Nem vonja el az igaztól szemeit, sőt királyok mellé, a trónra ültette őket örökre, hogy kimagasodtak.
Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo, ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́; àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.
8 S ha bilincsekkel vannak megkötve, ha megfogatnak a nyomorúság köteleivel:
Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí a sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,
9 megmondja nekik cselekedetüket és bűntetteiket, hogy hősködtek;
nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn, wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.
10 megnyitja fülüket a feddésnek és azt mondja, hogy térjenek meg a jogtalanságtól.
Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́, ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.
11 Ha hallgatnak rá és szolgálják őt, jólétben töltik el végig napjaikat és éveiket kellemetességben;
Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín, wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn, àti ọdún wọn nínú afẹ́.
12 de ha nem hallgatnak reá, fegyver által tűnnek el s kimúlnak megismerés híján.
Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́, wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé, wọ́n á sì kú láìní òye.
13 S az istentelen szívűek haragot táplálnak, nem esedeznek, midőn megkötözte őket.
“Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ; wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.
14 Ifjúkorban kell elhalnia lelküknek és életüknek a ledérek között.
Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe, ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
15 Kiszabadítja a nyomorgót nyomorúsága által s a szorongatás által megnyitja fülüket.
Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn, a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.
16 Kicsábít téged is a szükség szájából, tág térre, melynek helyén nincs szorongás, s a mi rászáll asztalodra, tele van zsiradékkal.
“Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò, sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀, ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.
17 De ha a gonosz ítéletével vagy tele, ítélet és törvény megragadnak téged.
Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú; ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.
18 Bizony, ne csábítson el téged a harag tömérdekségével és a váltság bősége ne hajlítson el.
Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ; láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.
19 Hát szorongás nélkül rendezze-e segítségedet s az erőszak minden megfeszítése nélkül?
Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí? Tàbí ipa agbára rẹ?
20 Ne áhítsd az éjéjszakát, midőn népek tűnnek el helyükről.
Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.
21 Őrizkedjél, ne fordulj jogtalanság felé, mert ezt inkább választottad a nyomorúságnál.
Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú, nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.
22 Lám, Isten felmagasztosul erejében; ki olyan oktató, mint ő!
“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀; ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?
23 Ki kéri számon tőle útját, s ki mondja: jogtalanságot műveltél!
Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un, tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?
24 Gondolj rá, hogy magasztald művét, melyet szemléltek férfiak;
Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga, ti ènìyàn ni yín nínú orin.
25 mind az emberek néztek rá, a halandó messziről tekinti.
Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i; ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè.
26 Lám, Isten magasztos, nem ismerjük meg, éveinek száma ki nem kutatható.
Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó, bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.
27 Mert felvonja a víznek cseppjeit, hogy az ő köde számára tisztuljanak esővé,
“Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀, kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,
28 melyet folyatnak a fellegek, csurgatnak a sok emberre.
tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ènìyàn.
29 Avagy értik-e a felhő terjedelmeit, sátrának robaját?
Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀, tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?
30 Lám, magára terítette fényét s ráborította a tenger gyökereit,
Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká ó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.
31 mert velök ítél népeket, eleséget ád busásan.
Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn; ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
32 Kezeire fényt borított s kirendelte azt a támadó ellen.
Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì ó sì rán an sí ẹni olódì.
33 Hirdet róla az ő dörgése, a csorda is a keletkező viharról.
Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní; ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!