< Jób 22 >
1 Felelt a Témánbeli Elifáz és mondta:
Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
2 Istennek tesz-e hasznot az ember? Bizony önmagának tesz hasznot az eszes!
“Ènìyàn lè è ṣe rere fún Ọlọ́run? Bí ọlọ́gbọ́n ti í ṣe rere fún ara rẹ̀?
3 Érdeke van-e a Mindenhatónak abban, hogy igaz vagy, avagy nyeresége, hogy gáncstalanná teszed útaidat?
Ohun ayọ̀ ha ni fún Olódùmarè pé olódodo ni ìwọ? Tàbí èrè kí ni fún un ti ìwọ mú ọ̀nà rẹ̀ pé?
4 Vajon istenfélelmed miatt fenyít-e meg téged, száll veled ítéletedre?
“Yóò ha bá ọ wí bí, nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ? Yóò ha bá ọ lọ sínú ìdájọ́ bí?
5 Nemde nagy a te rosszaságod, s nincs vége bűneidnek!
Ìwà búburú rẹ kò ha tóbi, àti ẹ̀ṣẹ̀ rẹ láìníye?
6 Mert megzálogoltad testvéreidet ok nélkül, s a meztelenek ruháit lehúzod;
Nítòótọ́ ìwọ béèrè fún ààbò ni ọwọ́ arákùnrin rẹ láìnídìí, ìwọ sì tú oníhòhò ní aṣọ wọn.
7 nem adtál vizet inni az elbágyadtnak s az éhezőtől megvontad a kenyeret.
Ìwọ kò fi omi fún aláàárẹ̀ mu, ìwọ sì háwọ́ oúnjẹ fún ẹni tí ebi ń pa.
8 S az erős kar emberéé az ország s a nagytekintetű marad benne lakónak.
Bí ó ṣe ti alágbára nì, òun ni ó ní ilẹ̀, ọlọ́lá sì tẹ̀dó sínú rẹ̀.
9 Özvegyeket üresen bocsátottál el s az árvák karjai összezúzattak.
Ìwọ ti rán àwọn opó padà lọ ní ọwọ́ òfo, apá àwọn ọmọ aláìní baba ti di ṣiṣẹ́.
10 Azért vannak körülötted tőrök, s rettegés rémít meg téged hirtelen.
Nítorí náà ni ìdẹ̀kùn ṣe yí ọ káàkiri, àti ìbẹ̀rù òjijì ń yọ ọ́ lẹ́nu.
11 Vagy nem látod-e a sötétséget, a vízáradatot, mely téged elborít?
Èéṣe tí òkùnkùn fi pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè ríran. Èéṣe tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi sì bò ọ́ mọ́lẹ̀.
12 Nemde Isten az ég magasságában van, s nézd a csillagok tetejét, mily magasak!
“Ọlọ́run kò ha jẹ́ ẹni gíga ọ̀run? Sá wo orí àwọn ìràwọ̀ bí wọ́n ti ga tó!
13 S te azt mondod: Mit tudhat Isten, vajon sűrű ködön keresztül ítélhet-e?
Ìwọ sì wí pé, Ọlọ́run ti ṣe mọ̀? Òun ha lè ṣe ìdájọ́ láti inú òkùnkùn wá bí?
14 Felhő az ő rejteke s nem lát s az egek körén járkál.
Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ tí ó nípọn jẹ ìbora fún un, tí kò fi lè ríran; ó sì ń rìn nínú àyíká ọ̀run.
15 Vajon az őskor ösvényét követed-e, melyet tapostak a jogtalanság emberei?
Ǹjẹ́ ìwọ fẹ́ rin ipa ọ̀nà ìgbàanì tí àwọn ènìyàn búburú tí rìn?
16 Kik megragadtattak idő előtt, folyammá omlott szét alapjuk;
A ké wọn lulẹ̀ kúrò nínú ayé láìpé ọjọ́ wọn, ìpìlẹ̀ wọn ti da bí odò ṣíṣàn.
17 kik azt mondták Istennek: távozz tőlünk, s hogy mit tehet nekik a Mindenható
Àwọn ẹni tí ó wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa! Kí ni Olódùmarè yóò ṣe fún wọn?’
18 holott ő megtöltötte házaikat jóval: de távol legyen tőlem a gonoszok tanácsa!
Síbẹ̀ ó fi ohun rere kún ilé wọn! Ṣùgbọ́n ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi!
19 Látják az igazak s örülnek s az ártatlan gúnyolódik rajtuk:
Àwọn olódodo rí ìparun wọn, wọ́n sì yọ̀, àwọn aláìlẹ́ṣẹ̀ sì fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà pé,
20 bizony megsemmisült a mi támadónk, s a mi maradt tőlük, tűz emésztette meg!
‘Lóòtítọ́ àwọn ọ̀tá wa ni a ké kúrò, iná yóò sì jó oró wọn run.’
21 Szegődjél csak hozzá s békéd lesz, az által jön reád a jó;
“Fa ara rẹ súnmọ́ Ọlọ́run, ìwọ ó sì rí àlàáfíà; nípa èyí ni rere yóò wá bá ọ.
22 fogadj csak el szájából tant és vedd mondásait szívedbe.
Èmi bẹ̀ ọ́, gba òfin láti ẹnu rẹ̀ wá, kí o sì to ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí àyà rẹ.
23 Ha megtérsz a Mindenhatóhoz, fölépülsz, ha eltávolítsz jogtalanságot sátradból;
Bí ìwọ bá yípadà sọ́dọ̀ Olódùmarè, a sì gbé ọ ró. Bí ìwọ bá sì mú ẹ̀ṣẹ̀ jìnnà réré kúrò nínú àgọ́ rẹ,
24 s porba helyezd az érczet s patakok kavicsába az Ófir-aranyat,
tí ìwọ bá tẹ́ wúrà dáradára sílẹ̀, lórí erùpẹ̀ àti wúrà Ofiri lábẹ́ òkúta odò,
25 s legyen a Mindenható a te érczed s ragyogó ezüstöd neked:
nígbà náà ní Olódùmarè yóò jẹ́ wúrà rẹ, àní yóò sì jẹ́ fàdákà fún ọ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
26 akkor bizony a Mindenhatóban fogsz gyönyörködni s felemelheted Istenhez arczodat.
Lóòtítọ́ nígbà náà ní ìwọ ó ní inú dídùn nínú Olódùmarè, ìwọ ó sì gbé ojú rẹ sókè sọ́dọ̀ Ọlọ́run.
27 Fohászkodol hozzá s ő hallgat rád a fogadalmaidat megfizetheted.
Bí ìwọ bá gbàdúrà rẹ sọ́dọ̀ rẹ̀, yóò sì gbọ́ tìrẹ, ìwọ ó sì san ẹ̀jẹ́ rẹ.
28 A mely szóval határozol, az beteljesül neked, és útaid fölött világosság derült föl.
Ìwọ ó sì gbìmọ̀ ohun kan pẹ̀lú, yóò sì fi ìdí múlẹ̀ fún ọ; ìmọ́lẹ̀ yóò sì mọ́ sípa ọ̀nà rẹ.
29 Ha kit megaláztak s azt mondod: emelkedés! a lecsüggedt szeműt megsegíti ő;
Nígbà tí ipa ọ̀nà rẹ bá lọ sísàlẹ̀, nígbà náà ni ìwọ o wí pé, ‘Ìgbésókè ń bẹ!’ Ọlọ́run yóò sì gba onírẹ̀lẹ̀ là!
30 megmenti a nem ártatlant s megmenekül kezeid tisztasága által.
Yóò gba ẹni tí kì í ṣe aláìjẹ̀bi là, a ó sì gbà á nípa mímọ́ ọwọ́ rẹ̀.”