< Jeremiás 44 >
1 Az ige, mely Jirmejáhúhoz lett, mind a Jehúdabeliek felől, akik Egyiptom országában laktak, akik laktak Migdólban, Tachpanchészben, Nófban és Patrósz országában, mondván:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá nípa àwọn Júù tí ń gbé ní ìsàlẹ̀ Ejibiti ní Migdoli, Tafanesi àti Memfisi àti ní apá òkè Ejibiti:
2 Így szól az Örökkévaló, a seregek ura, Izrael Istene; Ti láttátok mindazt a veszedelmet, amelyet hoztam Jeruzsálembe és mind a Jehúda városaira és íme azok romok e mai napon és nincs bennük lakó,
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Wo ibi tí mo mú bá Jerusalẹmu àti gbogbo ìlú Juda. Lónìí, wọ́n wà ní ìyapa àti ìparun.
3 gonoszságuk miatt, amelyet elkövettél, hogy engem bosszantsanak, menvén füstölögtetni és szolgálni más isteneknek, amelyeket nem ismertek ők, ti és atyáitok.
Nítorí pé ibi tí wọ́n ti ṣe. Wọ́n mú mi bínú nípa tùràrí fínfín àti nípa bíbọ àwọn òrìṣà, yálà èyí tí ìwọ tàbí àwọn baba rẹ kò mọ̀.
4 És küldtem hozzátok mind az én szolgáimat, a prófétákat, reggelenként küldve, mondván: ne tegyétek, kérlek, ezt az utálatos dolgot, amelyet gyűlölök.
Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní mo rán wòlíì mi, èyí tí ó wí báyìí pé, ‘Má ṣe àwọn ohun ìríra yìí tí èmi kórìíra.’
5 De nem hallgattak rá és nem hajlították fülüket, hogy megtérjenek gonoszságuktól, hogy más isteneknek ne füstölögtessenek.
Ṣùgbọ́n wọn kò fetísílẹ̀ láti fi ọkàn si. Wọn kò sì yípadà kúrò nínú búburú wọn tàbí dáwọ́ ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà dúró.
6 Kiömlött tehát hevem és haragom és égett Jehúda városaiban és Jeruzsálem utcáiban, és lettek rommá, pusztulássá, mint ez van e mai napon.
Fún ìdí èyí, ìbínú gbígbóná mi ni èmi yóò yọ sí àwọn ìlú Juda àti òpópó Jerusalẹmu àti sísọ wọ́n di ìparun bí ó ṣe wà lónìí yìí.
7 És most így szól az Örökkévaló, a seregek Istene, Izrael Istene miért cselekedtek ti nagy rosszat lelketek vesztére, hogy kiirtsak közületek férfit és asszonyt, kisdedet és csecsemőt Jehúdából, nem hagyva nektek maradékot,
“Báyìí tún ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí, kí ló dé tí ẹ fi ń mu ibi ńlá yìí wá sí orí ara yín nípa yíyapa kúrò lára Juda ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti èwe, tí ẹ kò sì ku ọ̀kankan?
8 azzal, hogy engem bosszantotok kezeitek műveivel, füstölögtetve más isteneknek Egyiptom országában, ahová ti jöttök, hogy ott tartózkodjatok, azért hogy kiirtsalak benneteket és azért hogy átokká és gyalázattá legyetek a föld minden nemzetei között.
Èéṣe tí ẹ fi mú mi bínú pẹ̀lú ohun tí ọwọ́ yín ṣe pẹ̀lú ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà Ejibiti, níbi tí ẹ wá láti máa gbé? Ẹ̀ ò pa ara yín run, ẹ̀ ó sì sọ ara yín di ẹni ìfiré àti ẹ̀gàn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè ayé gbogbo.
9 Elfelejtettétek-e őseitek gonoszságait és Jehúda királyainak gonoszságait és asszonyainak gonoszságait, meg a ti gonoszságaitokat és feleségeitek gonoszságait, amelyeket cselekedtek Jehúda országában és Jeruzsálem utcáiban?
Ṣé ẹ̀yin ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín àti àwọn ọba; àwọn ayaba Juda, àti àwọn ibi tí ẹ ti ṣe àti àwọn ìyàwó yín ní ilẹ̀ Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
10 Nem sújtattak le mind e mai napig és nem féltek és nem jártak tanom szerint és törvényeim szerint, melyeket elétek és őseitek elé adtam.
Láti ìgbà náà sí àkókò yìí, wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ tàbí fi ìtẹríba hàn tàbí kí wọn ó tẹ̀lé òfin àti àṣẹ tí mo pa fún un yín àti àwọn baba yín.
11 Azért így szól az Örökkévaló, a seregek ura, Izrael Istene: Íme én ellenetek fordítom arcomat a rosszra és hogy kiirtsam egész Jehúdát.
“Fún ìdí èyí, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: Mo ti pinnu láti mú ibi wá sí orí yín àti láti pa Juda run.
12 És veszem Jehúda maradékát, azokat, akik arra fordították arcukat, hogy Egyiptom országába menjenek, hogy ott tartózkodjanak, és kivesznek mindnyájan, Egyiptom országában fognak elhullani, fegyver, éhség által fognak kiveszni, aprajától nagyjáig, kard és éhség által fognak meghalni, és lesznek esküvé, iszonyattá, átokká és gyalázattá.
Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Juda, tí wọ́n ṣetán láti lọ Ejibiti. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.
13 És megbüntetem azokat, akik Egyiptom országában laknak, amint megbüntettem Jeruzsálemet, kard, éhség és dögvész által.
Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jerusalẹmu.
14 És nem lesz megmenekülő és megmaradó Jehúda maradékának, azoknak, akik, jöttek, hogy ott tartózkodjanak Egyiptom országában és majd visszatérjenek Jehúda országába, ahova visszatérni vágyódik a lelkük, hogy ott lakjanak, mert nem fognak visszatérni, hanem csak menekülők.
Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Juda tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Ejibiti tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Juda, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mélòó kan.”
15 És feleltek Jirmejáhúnak mindazon férfiak, akik tudták, hogy feleségeik füstölögtetnek más isteneknek és mind az ott álló asszonyok, nagy gyülekezet és az egész nép, amely Egyiptom országában lakott, Patrószban, mondván:
Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremiah.
16 Azon szó, melyet szóltál hozzánk az Örökkévaló nevében – abban nem hallgatunk rád,
“Wọn sì wí pé, àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ní orúkọ Olúwa.
17 hanem meg fogunk tenni minden szót, amely szánkból eredt, hogy füstölögtetünk az ég királynőjének és öntünk neki öntőáldozatokat, amint tettük mi és őseink, királyaink és nagyjaink, Jehúda városaiban és Jeruzsálem utcáin, akkor jóllaktunk kenyérrel és jó dolgunk volt és rosszat nem láttunk.
Dájúdájú, à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe. A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run, à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ni àwọn ìgboro Jerusalẹmu. Nígbà náà àwa ní oúnjẹ púpọ̀, a sì ṣe rere a kò sì rí ibi.
18 De mióta megszűntünk füstölögtetni az ég királynőjének és neki öntőáldozatokat önteni, hiányunk volt mindenben és kard és éhség által vesztünk el.
Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí Ayaba Ọ̀run àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”
19 És hogyha füstölögtetünk az ég királynőjének és neki öntőáldozatokat öntünk, vajon férjeink tudta nélkül készítettünk-e neki kalácsokat, őt ábrázolva és öntöttünk neki öntőáldozatokat?
Àwọn obìnrin náà fi kún un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rú ẹbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”
20 És szólt Jirmejáhú az egész néphez, a férfiakhoz és az asszonyokhoz és az egész néphez, akik szóval feleltek neki, mondván:
Wàyí o, Jeremiah sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,
21 Nemde arról a füstölögtetésről, melyet végeztetek Jehúda városaiban és Jeruzsálem utcáin, ti és őseitek, királyaitok és nagyjaitok és az ország népe arról emlékezett meg az Örökkévaló és az jutott eszébe;
“Ṣe Olúwa kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Juda àti àwọn ìgboro Jerusalẹmu láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn baba rẹ, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.
22 és az Örökkévaló nem bírta többé elviselni cselekedeteitek gonoszsága miatt, azon utálatosságok miatt, amelyeket cselekedtetek, úgy hogy országotok rommá, iszonyattá és átokká lett, lakó nélkül, mint az van e mai napon.
Nígbà tí Olúwa kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìríra gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.
23 Amiatt, hogy füstölögtettetek és hogy vétkeztetek az Örökkévaló ellen és nem hallgattatok az Örökkévaló szavára, és tana és törvényei és bizonyságai szerint nem jártatok, ezért ért benneteket ez a veszedelem, mint az van e mai napon.
Nítorí pé ẹ ti sun ẹbọ, tí ẹ sì ti ṣẹ̀ sí Olúwa àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, àti pé ẹ kò sì tẹ̀lé òfin rẹ̀ àti àwọn àṣẹ. Ibi náà yóò wá sórí rẹ àti bí o ṣe rí i.”
24 És szólt Jirmejáhú az egész néphez és mind az asszonyokhoz: Halljátok az Örökkévaló igéjét, egész Jehúda, mely Egyiptom országában van.
Nígbà náà ni Jeremiah dáhùn pẹ̀lú obìnrin náà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ọmọ Juda tí ó wà ní Ejibiti.
25 Így szól az Örökkévaló, a seregek ura, Izrael Istene, mondván: Ti és feleségeitek, kimondtátok szájatokkal, kezeitekkel pedig teljesítettétek, mondván: végbe fogjuk vinni fogadásainkat, amelyeket fogadtunk, hogy füstölögtetünk az ég királynőjének és öntünk neki öntőáldozatokat – ám tartsátok meg fogadásaitokat és vigyetek végbe fogadásaitokat.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí. Ìwọ àti àwọn ìyàwó rẹ fihàn pẹ̀lú àwọn ìhùwà rẹ àti àwọn ohun tí ó ṣèlérí nígbà tí o wí pé, ‘Àwa yóò mú ẹ̀jẹ́ tí a jẹ́ ṣẹ lórí sísun tùràrí àti dída ẹbọ ohun mímu sí orí ère Ayaba Ọ̀run.’ “Tẹ̀síwájú nígbà náà, ṣe ohun tí o sọ, kí o sì mú ẹ̀jẹ́ rẹ ṣẹ.
26 Azért halljátok az Örökkévaló igéjét, mind a Jehúdabeliek, akik Egyiptom országában laknak: Íme én esküszöm az én nagy nevemre, mondja az Örökkévaló, nem lesz többé az én nevem szólítva Jehúda valamely emberének szájában, aki mondaná: él az Úr, az Örökkévaló, Egyiptom egész országában.
Ṣùgbọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, gbogbo ẹ̀yin Júù tí ń gbé ilẹ̀ Ejibiti, mo gégùn ún: ‘Mo búra pẹ̀lú títóbi orúkọ mi,’ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí, ‘pé kò sí ẹnikẹ́ni láti Juda tí ń gbé ibikíbi ní Ejibiti tí ó gbọdọ̀ ké pe orúkọ mi tàbí búra, “Gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó dá wa ti wà láààyè.”
27 Íme én őrködöm fölöttük rosszra és nem jóra, és kivesznek mind a Jehúda emberei, akik Egyiptom országában vannak, kard és éhség által, mígnem végük lesz.
Nítorí náà, èmi ó ṣọ wọ́n fún ibi, kì í ṣe fún rere. Àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni a ó parun pẹ̀lú idà àti ìyàn títí tí gbogbo wọn yóò fi tán.
28 És kardtól menekülők csekély számban fognak visszatérni Egyiptom országából Jehúda országába és megtudja Jehúda egész maradéka, azok, akik Egyiptom országába jöttek, hogy ott tartózkodjanak, kinek szava fog megállni, az enyém-e vagy az övék.
Àwọn tí ó bá sá àsálà kúrò lọ́wọ́ ìparun idà àti pípadà sí ilẹ̀ Juda láti Ejibiti yóò kéré níye. Gbogbo àwọn tí ó bá kú ní ilẹ̀ Juda, tí ó wá gbé ilẹ̀ Ejibiti yóò mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóò dúró yálà tèmi tàbí tiyín.
29 És ez nektek a jel, úgymond az Örökkévaló, hogy megbüntetlek benneteket e helyen, azért, hogy megtudjátok, hogy meg fognak állni szavaim ellenetek rosszra.
“‘Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún un yín pé èmi yóò fi ìyà jẹ yín níbi tí Olúwa ti sọ láti lè jẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ìjìyà mi tí mo sọ pé ẹ̀ ó jẹ yóò ṣẹ.’
30 Így szól az Örökkévaló: Íme én adom Fáraó Chofrát, Egyiptom királyát, ellenségeinek kezébe és azoknak kezébe, kik életére törnek, amint adtam Czidkijáhút, Jehúda királyát, kezébe Nebúkadnecczárnak, Bábel királyának, az ő ellenségének és az életére törőnek.
Báyìí ni Olúwa wí: ‘Èmi yóò fi Farao Hofira ọba Ejibiti lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́, èyí tí ó lè pa ayé rẹ́; gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekiah ọba Juda lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́ ọ̀tá tó ń lépa ẹ̀mí rẹ̀.’”