< Jeremiás 35 >

1 Az ige, mely Jirmejáhúhoz lett az Örökkévalótól, Jehójákim, Jósíjáhú fiának, Jehúda királyának napjaiban, mondván:
Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọjọ́ Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda wí pé:
2 Menj a Rékhábfiak házába, beszélj velük és vidd el őket az Örökkévaló házába, a csarnokok egyikébe és adj nekik bort inni.
“Lọ sí ilé àwọn ọmọ Rekabu, kí o sì bá wọn sọ̀rọ̀, kí o sì mú wọn wá sí ilé Olúwa, sí ọ̀kan nínú iyàrá wọ̀n-ọn-nì, kí o sì fún wọn ní ọtí wáìnì mu.”
3 Erre vettem Jáazanját. Jirmejáhú, Chábaczinja fiának fiát, meg testvéreit s mind a fiait és a Rékhábfiak egész házát:
Nígbà náà ni mo mu Jaaṣaniah ọmọ Jeremiah, ọmọ Habasiniah àti àwọn arákùnrin rẹ̀; àti gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀, àti gbogbo ilé àwọn ọmọ Rekabu.
4 és elvittem őket az Örökkévaló házába, a Chánán, az Isten embere, Jigdalja fia, fiainak csarnokába, mely a nagyok csarnoka mellett van, amely Máaszéjáhú Sallúm fia, a küszöb őrének csarnoka felett van.
Mo sì mú wọn wá sí ilé Olúwa sínú iyàrá Hanani ọmọ Igdaliah, ènìyàn Ọlọ́run, tí ó wà lẹ́bàá yàrá àwọn ìjòyè, tí ó wà ní òkè yàrá Maaseiah, ọmọ Ṣallumu olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
5 És tettem a Rékhábfiak házának fiai elé borral telt serlegeket, meg poharakat; és szóltam hozzájuk: Igyatok bort.
Mo sì gbé ìkòkò tí ó kún fún ọtí wáìnì pẹ̀lú ago ka iwájú àwọn ọmọ Rekabu. Mo sì wí fún wọn pé, “Mu ọtí wáìnì.”
6 Mondták: Nem iszunk bort, mert Jónádáb, Rékháb fia, a mi ősünk megparancsolta nekünk, mondván: ne igyatok bort, ti és fiaitok örökké;
Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kì yóò mu ọtí wáìnì nítorí Jonadabu ọmọ Rekabu, baba wa pàṣẹ fún wa pé: ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín láéláé.
7 és házat ne építsetek és vetőmagot ne vessetek és szőlőt ne ültessetek, sem effélétek ne legyen, hanem sátrakban lakjatok mindennapjaitokban, hogy sok ideig éljetek azon föld színén, ahol tartózkodtok.
Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin kò gbọdọ̀ kọ́ ilé tàbí kí ẹ fúnrúgbìn, tàbí kí ẹ gbin ọgbà àjàrà. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ní ọ̀kankan nínú àwọn ohun wọ̀nyí, ṣùgbọ́n ní gbogbo ọjọ́ yín ni ẹ̀yin ó máa gbé inú àgọ́; kí ẹ̀yin kí ó lè wá ní ọjọ́ púpọ̀ ní ilẹ̀ náà; níbi tí ẹ̀yin ti ń ṣe àtìpó.’
8 És hallgattunk Jehónádáb, Rékháb fiának, ősünknek szavára, mindabban, amit megparancsolt nekünk: hogy nem iszunk bort mindennapjainkban, mi, feleségeink, fiaink és leányaink,
Báyìí ni àwa gba ohùn Jehonadabu ọmọ Rekabu baba wa gbọ́ nínú gbogbo èyí tí ó pàṣẹ fún wa, kí a má mu ọtí wáìnì ní gbogbo ọjọ́ ayé wa; àwa, àwọn aya wa, àwọn ọmọkùnrin wa, àti àwọn ọmọbìnrin wa.
9 és hogy nem építünk házakat lakásunkra, és szőlőnk, mezőnk és vetőmagunk nincs.
Àti kí a má kọ́ ilé láti gbé; bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ní ọgbà àjàrà tàbí oko, tàbí ohun ọ̀gbìn.
10 Hanem sátrakban laktunk; így hallgattunk rá és cselekedtünk egészen aszerint, mint megparancsolta nekünk Jónádáb ősünk.
Ṣùgbọ́n àwa ń gbé inú àgọ́, a sì gbọ́rọ̀, a sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Jonadabu baba wa pàṣẹ fún wa.
11 És volt, mikor Nebúkadnecczár, Bábel királya, feljött az országba, azt mondtuk: gyertek, menjünk be Jeruzsálembe a kaldeusok hadserege elől és Arám hadserege elől. Tehát letelepedtünk Jeruzsálemben.
Ó sì ṣe, nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli gòkè wá sí ilẹ̀ náà; àwa wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lọ sí Jerusalẹmu, nítorí ìbẹ̀rù ogun àwọn ara Siria.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwa sì ń gbé Jerusalẹmu.”
12 És lett az Örökkévaló igéje Jirmejáhúhoz, mondván:
Nígbà yìí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
13 Így szól az Örökkévaló, a seregek ura, Izrael Istene; menj és mondd meg Jehúda embereinek és Jeruzsálem lakóinak: Nem fogadtok-e el oktatást, hogy szavaimra hallgassatok, úgymond az Örökkévaló?
“Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé, lọ, kí o sì sọ fún àwọn ọkùnrin Juda, àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò ha gba ẹ̀kọ́ láti fetí sí ọ̀rọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
14 Megtartották Jehónádáb, Rékháb fiának szavait, aki azt parancsolta fiainak, hogy ne igyanak bort, és nem ittak mind e mai napig, mert hallgattak ősük parancsára; én pedig beszéltem hozzátok, reggelenként beszélve, de nem hallgattatok rám.
‘Ọ̀rọ̀ Jehonadabu ọmọ Rekabu tí ó pàṣẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì, ni a mú ṣẹ, wọn kò sì mu ọtí wáìnì títí di òní yìí, nítorí tí wọ́n gba òfin baba wọn. Èmi sì ti ń sọ̀rọ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
15 Küldtem hozzátok mind a szolgáimat a profétákat reggelenként küldve, mondván: térjetek csak meg kiki gonosz útjáról és javítsátok cselekedeteiteket és ne járjatok más istenek után, azokat szolgálva, hogy lakhassatok a földön, melyet adtam nektek és őseiteknek; de nem hajlítottátok fületeket és nem hallgattatok rám.
Èmi rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ àti àwọn wòlíì mí sí yín pẹ̀lú wí pé, “Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín, kí ẹ sì tún ìṣe yín ṣe sí rere. Kí ẹ ma sì ṣe bọ òrìṣà tàbí sìn wọ́n; ẹ̀yin ó sì máa gbé ní ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín àti fún àwọn baba ńlá yín.” Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
16 Igenis megtartották Jehónádáb, Rékháb fiának fiai ősüknek parancsát, melyet parancsolt nekik, de ez a nép nem hallgatott rám.
Nítòótọ́, àwọn ọmọ Jehonadabu ọmọ Rekabu pa òfin baba wọn mọ́ tí ó pàṣẹ fún wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wọ̀nyí kò pa òfin mi mọ́.’
17 Azért így szólt az Örökkévaló, a seregek Istene, Izrael Istene: Íme, én elhozom Jehúdára és Jeruzsálem minden lakóira mindazt a rosszat, amit kimondtam felőlük, mivel beszéltem hozzájuk, de nem hallgattak rá, szólítottam őket, de nem feleltek.
“Nítorí náà, báyìí ni, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Fetísílẹ̀! Èmi ó mú gbogbo ohun búburú tí èmi ti sọ wá sórí Juda, àti sórí gbogbo olùgbé Jerusalẹmu nítorí èmi ti bá wọn sọ̀rọ̀: Ṣùgbọ́n wọn kò sì dáhùn.’”
18 A Rékhábfiak házának pedig mondta Jirmejáhú: Így szól az Örökkévaló, a seregek ura, Izrael Istene; mivelhogy hallgattatok Jehónádáb ősetek parancsára és megőriztétek mind a parancsait és cselekedtetek mind aszerint, amint megparancsolta nektek:
Nígbà náà ni Jeremiah wí fún ìdílé Rekabu pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé: ‘Nítorí tí ẹ̀yin gba òfin Jehonadabu baba yín, tí ẹ sì pa gbogbo rẹ̀ mọ́, tí ẹ sì ṣe gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó pàṣẹ fún un yín.’
19 azért így szól az Örökkévaló, a seregek ura, Izrael Istene: nem fogy el Jónádábtól, Rékháb fiától férfi, aki áll előttem minden időben.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Jonadabu ọmọ Rekabu kì yóò fẹ́ ọkùnrin kan kù láti sìn mí.’”

< Jeremiás 35 >