< Jeremiás 33 >
1 És lett az Örökkévaló igéje Jirmejáhúhoz másodszor, és ő még elzárva volt az őrség udvarába, mondván:
Nígbà tí Jeremiah wà nínú àgbàlá túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá lẹ́ẹ̀kejì:
2 Így szól az Örökkévaló; a megtevője: az Örökkévaló megalkotja, hogy megszilárdítsa, Örökkévaló az ő neve.
“Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹni tí ó dá ayé, Olúwa tí ó mọ ayé tí ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, Olúwa ni orúkọ rẹ̀:
3 Szólj hozzám és felelni fogok neked; hadd tudatok veled nagyokat és hozzáférhetetleneket, amiket nem tudsz.
‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’
4 Mert így szól az Örökkévaló, Izrael Istene, a város házairól és Jehúda királyainak házairól, melyek lebontattak a töltések ellenében és a kard ellenében:
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ nípa àwọn ilẹ̀ ìlú yìí àti ààfin àwọn ọba Juda tí ó ti wó lulẹ̀ nítorí àwọn ìdọ̀tí àti idà
5 Jönnek harcolni a kaldeusokkal és hogy megtöltsék azokat azon emberek hulláival, akiket megöltem haragomban és felindulásomban és akiknek minden gonoszsága miatt elrejtettem arcomat e várostól.
nínú ìjà pẹ̀lú Kaldea: ‘Wọn yóò kún fún ọ̀pọ̀ òkú ọmọkùnrin tí èmi yóò pa nínú ìbínú àti nínú ìrunú mi. Èmi ó pa ojú mi mọ́ kúrò ní ìlú yìí nítorí gbogbo búburú wọn.
6 Íme én engedek neki behegedést és meggyógyulást és meggyógyítom őket; föltárom nekik békének és igazságnak bőséget.
“‘Wò ó, èmi ó mú ọ̀já àti oògùn ìmúláradá dì í; èmi ó wo àwọn ènìyàn mi sàn. Èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó jẹ ìgbádùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́.
7 Visszahozom Jehúda foglyait és Izrael foglyait és fölépítem őket mint annak előtte.
Èmi ó mú Juda àti Israẹli kúrò nínú ìgbèkùn, èmi ó sì tún wọn kọ́ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe wà tẹ́lẹ̀.
8 És megtisztítom őket minden bűnüktől, amellyel ellenem vétkeztek és megbocsátom minden bűneiket, amelyekkel ellenem vétkeztek és melyekkel elpártoltak tőlem.
Èmi ó wẹ̀ wọ́n nù kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti ṣẹ sí mi. Èmi ó sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àìṣedéédéé wọn sí mi jì wọ́n.
9 És lesz nekem hírnévül, örvendezésül, dicséretül és dicsőségül mind a föld nemzeteinél, akik hallani fogják mindazt a jót, amit velük teszek, és majd remegnek és reszketnek mindazon jó miatt és mindazon béke miatt, amelyet vele cselekszem.
Nígbà náà ni ìlú yìí ó fún mi ní òkìkí, ayọ̀, ìyìn àti ọlá níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé; tí wọ́n gbọ́ gbogbo rere tí èmi ṣe fún wọn. Wọn ó sì bẹ̀rù, wọn ó wárìrì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore àti àlàáfíà tí èmi pèsè fún wọn.’
10 Így szól az Örökkévaló: Még hallatszik e helyen, amelyről azt mondjátok: rommá lett, ember nélkül és állat nélkül, Jehúda városaiban és Jeruzsálem utcáin, amelyek pusztasággá lettek ember nélkül lakó nélkül és állat nélkül,
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ẹ̀yin yóò wí nípa ibí yìí pé, “Ó dahoro, láìsí ènìyàn tàbí ẹran.” Síbẹ̀ ní ìlú Juda àti ní òpópónà Jerusalẹmu tí ó dahoro, láìsí ẹni tó gbé ibẹ̀; ìbá à se ènìyàn tàbí ẹran, tí yóò gbọ́ lẹ́ẹ̀kan sí.
11 vígság hangja és öröm hangja, vőlegény hangja és menyasszony hangja, azoknak hangja, akik mondják: Magasztaljátok az Örökkévalót, a seregek urát; mert jóságos az Örökkévaló, mert örökké tart a kegyelme! – akik hálaáldozatot hoznak az Örökkévaló házába; mert vissza fogom hozni az ország foglyait mint annak előtte, mondja az Örökkévaló.
Ariwo ayọ̀ àti inú dídùn, ohùn ìyàwó àti ti ọkọ ìyàwó àti ohùn àwọn tí ó ru ẹbọ ọpẹ́ wọn nílé Olúwa wí pé: “‘“Yin Olúwa àwọn ọmọ-ogun, nítorí Olúwa dára, ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé.” Nítorí èmi ó dá ìkólọ ilẹ̀ náà padà sí bí o ṣe wà tẹ́lẹ̀,’ ni Olúwa wí.
12 Így szól az Örökkévaló, a seregek ura: Még lesz ezen a helyen, amely rommá lett ember és állat nélkül, és mind a városaiban pásztorok tanyája, kik juhokat heverésztetnek.
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ní ilẹ̀ yìí tí ó ti dahoro láìsí ọkùnrin àti àwọn ẹran nínú gbogbo ìlú, kò ní sí pápá oko fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sinmi.
13 A hegység városaiban, az alföld városaiban, a délvidék városaiban, Benjámin földjén és Jeruzsálem környékein meg Jehúda városaiban, át fognak még menni a juhok a számlálónak kezén, mondja az Örökkévaló.
Ní ìlú òkè wọ̀n-ọn-nì, nínú ìlú àfonífojì, àti nínú ìlú ìhà gúúsù, àti ní ilẹ̀ ti Benjamini, ní ibi wọ̀n-ọn-nì tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda ni agbo àgùntàn yóò tún máa kọjá ní ọwọ́ ẹni tí ń kà wọ́n,’ ni Olúwa wí.
14 Íme napok jönnek, úgymond az Örökkévaló, teljesíteni fogom azt a jó igét, melyet kimondtam Izrael háza és Jehúda, háza felől.
“‘Àwọn ọjọ́ náà ń bọ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí èmi ó mú ìlérí rere tí mo ṣe fún ilé Israẹli àti ilé Juda ṣẹ.
15 Ama napokban és amaz időben sarjasztok Dávidnak igaz sarjadékot, és tenni fog jogot és igazságot az országban.
“‘Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ní àkókò náà, Èmi ó gbé olódodo dìde láti ẹ̀ka Dafidi. Yóò ṣe ìdájọ́ àti ohun tí ó tọ́ ní ilẹ̀ náà.
16 Ama napokban meg fog segítetni Jehúda és Jeruzsálem biztonságban fog lakni, és ez az ahogy nevezni fogják: az Örökkévaló a mi igazságunk!
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Juda yóò di ẹni ìgbàlà. Jerusalẹmu yóò sì máa gbé láìséwu. Orúkọ yìí ni a ó máa pè é Olúwa wa olódodo.’
17 Mert így szól az Örökkévaló: nem fogy el Dávidtól férfi, aki ül Izrael házának trónján.
Nítorí báyìí ni Olúwa wí: ‘Dafidi kò ní kùnà láti rí ọkùnrin tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ ní ilé Israẹli.
18 És a levita papoktól sem fog elfogyni férfi előttem, aki bemutat égőáldozatot és füstölögtet lisztáldozatot és készít vágóáldozatot minden időben.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà tí ó jẹ́ ọmọ Lefi kò ní kùnà láti ní ọkùnrin kan tí ó dúró níwájú mi ní gbogbo ìgbà láti rú ẹbọ sísun; ẹbọ jíjẹ àti láti pèsè ìrúbọ.’”
19 És lett az Örökkévaló igéje Jirmejáhúhoz, mondván:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá wí pé:
20 Így szól az Örökkévaló: Ha felbonthatjátok szövetségemet a nappal és szövetségemet az éjszakával, úgy hogy ne legyenek a nap és az éjszaka a maguk idejében,
“Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Tí ìwọ bá lè dá májẹ̀mú mi ní òru tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀sán àti òru kò lè sí ní àkókò wọn mọ́.
21 fölbontható Dávid szolgámmal való szövetségem is, úgy hogy nem volna neki fia, aki mint király ül a trónján, meg a levita papokkal, szolgálattevőimmel.
Nígbà náà ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú Dafidi ìránṣẹ́ mi àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi tí ó jẹ́ àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ níwájú mi lè bàjẹ́, tí Dafidi kò sì rí ẹni láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
22 Ahogy nem számlálható meg az ég serege és nem mérhető meg a tenger fövénye, úgy fogom megsokasítani Dávid szolgám magzatját és a levitákat, akik szolgálatomat végzik.
Èmi ó mú àwọn ọmọ lẹ́yìn Dafidi ìránṣẹ́ mi àti Lefi tí ó jẹ́ oníwàásù níwájú mi di bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, tí kò ṣe é kà àti bí iyẹ̀pẹ̀ ojú Òkun tí kò ṣe é wọ́n.’”
23 És lett az Örökkévaló igéje Jirmejáhúhoz, mondván:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
24 Nemde láttad, mit beszél ez a nép, mondván: azon két család, amelyet az Örökkévaló kiválasztott – megvetette azokat; népemet pedig azzal káromolják, hogy többé nem lesz nemzet azok előtt.
“Ǹjẹ́ ìwọ kò kíyèsi pé àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń sọ pé: ‘Olúwa ti kọ àwọn ọba méjèèjì tí ó yàn sílẹ̀’? Nítorí náà, ni wọ́n ti ṣe kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi. Wọn kò sì mọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè kan.
25 Így szól az Örökkévaló: ha nincs meg szövetségem a nappal és az éjszakával, ha ég és föld törvényeit nem szabtam,
Báyìí ni Olúwa wí: ‘Bí èmi kò bá ti da májẹ̀mú mi pẹ̀lú ọ̀sán àti òru àti pẹ̀lú òfin ọ̀run àti ayé tí kò lè yẹ̀.
26 Jákobnak és Dávid szolgámnak magzatját is meg fogom vetni, úgy, hogy ne vegyek magzatjából uralkodókat Ábrahám, Izsák és Jákob magzatja fölött; mert visszahozom foglyaikat és irgalmazok nekik.
Nígbà náà ni èmi ó kọ ọmọ lẹ́yìn Jakọbu àti Dafidi ìránṣẹ́ mi tí èmi kò sì ní yan ọ̀kan nínú ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ́ alákòóso lórí àwọn ọmọ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu; nítorí èmi ó mú ìkólọ wọn padà; èmi ó sì ṣàánú fún wọn.’”