< Jeremiás 32 >
1 Az ige, mely Jirmejáhúhoz lett az Örökkévalótól Czidkijáhú, Jehúda királyának tizedik évében, az Nebúkanecczárnak tizennyolcadik éve.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọdún kẹwàá Sedekiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kejìdínlógún ti Nebukadnessari.
2 Akkor pedig Bábel királyának hadserege ostromolta Jeruzsálemet és Jirmejáhú próféta be volt zárva az őrség udvarában, mely Jehúda királyának házában volt,
Àwọn ogun ọba Babeli ìgbà náà há Jerusalẹmu mọ́. A sì sé wòlíì Jeremiah mọ́ inú túbú tí wọ́n ń ṣọ́ ní àgbàlá ilé ọba Juda.
3 ahová bezáratta őt Czidkijáhú, Jehúda királya, mondván: miért prófétálsz te, azt mondván: így szól az Örökkévaló, íme én ezt, a várost Bábel királyának kezébe adom, hogy elfoglalja;
Nítorí Sedekiah ọba Juda ti há a mọ́lé síbẹ̀; pé, “Kí ló dé tí ìwọ fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀? Tí o sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Èmi ń bọ̀ wá fi ìlú yìí fún ọba Babeli, tí yóò sì gbà á.
4 és Czidkijáhú, Jehúda királya nem menekül meg a kaldeusok kezéből, hanem adatni fog Bábel királyának kezébe és szája beszélni fog az ő szájával és szemei látni fogják az ő szemeit:
Sedekiah ọba Juda kò lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn Kaldea, ṣùgbọ́n à ó mú fún ọba Babeli, yóò sì bá sọ̀rọ̀ ní ojúkojú; yóò sì rí pẹ̀lú ojú rẹ̀.
5 és Bábelbe viszi majd Czidkijáhút és ott lesz, míg nem gondolok rá, úgymond az Örökkévaló: ha harcolni fogtok a kaldeusokkal, nem fogtok boldogulni.
Yóò mú Sedekiah lọ sí Babeli tí yóò wà títí èmi yóò fi bẹ̀ ọ́ wò ni Olúwa wí. Tí ẹ̀yin bá bá àwọn ará Kaldea jà, ẹ̀yin kì yóò borí wọn.’”
6 És szólt Jirmejáhú: Lett hozzám az Örökkévaló igéje, mondván:
Jeremiah wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
7 íme Chanámél, Sallúm nagybátyádnak fia, jön hozzád, mondván: vedd meg mezőmet, mely Anátótban van, mert tied a kiváltás joga, hogy megvegyed.
Hanameli ọmọkùnrin Ṣallumu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ yóò tọ̀ ọ́ wá pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti; nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹni tó súnmọ́ wọn, ẹ̀tọ́ àti ìṣe rẹ ní láti rà á.’
8 És jött hozzám Chanánél, nagybátyám fia, az Örökkévaló igéje szerint, az őrség udvarába és szólt hozzám: Vedd meg, kérlek, mezőmet, mely Anátótban, Benjámin országában van, mert tied az öröklés joga és tied a kiváltás, vedd meg magadnak. És megtudtam, hogy az Örökkévaló igéje az.
“Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ, Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi tọ̀ mí wá ní àgbàlá túbú wí pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti tí ó wà ní ilẹ̀ Benjamini, èyí tí ó jẹ́ pé ẹ̀tọ́ rẹ ni láti gbà á àti láti ni, rà á fún ara rẹ.’ “Nígbà náà ni èmi mọ̀ wí pé ọ̀rọ̀ Olúwa ni èyí.
9 Megvettem tehát Chanáméltől nagybátyám fiától a mezőt, mely Anátótban van és lemértem neki az ezüstöt, hét sékelt és tíz ezüstöt.
Bẹ́ẹ̀ ni; èmi ra pápá náà ní Anatoti láti ọwọ́ Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi. Mo sì wọn ìwọ̀n ṣékélì àti fàdákà mẹ́tàdínlógún fún un.
10 És fölírtam levélbe és lepecsételtem és állítottam tanukat és mérlegen lemértem az ezüstöt.
Mo fọwọ́ sínú ìwé, mo sì dì í pa. Mo pe ẹlẹ́rìí sí i, mo sì wọn fàdákà náà lórí òsùwọ̀n.
11 Erre vettem a vétellevelet, a lepecsételtet – a parancsolat és törvények szerint – és a nyitottat;
Mo mú ìwé tí mo fi rà á, èyí tí a di pa nípa àṣẹ àti òfin wa, àti èyí tí a kò lẹ̀.
12 És adtam a vétellevelet Bárúkhnak, Nérija Machszéja fia fiának Chanámél rokonom szeme láttára, és a tanuk szeme láttára, kik aláírták a vétellevelet, mind a Jehúdabeliek szeme láttára, akik az őrség udvarában ültek.
Èmi sì fi èyí fún Baruku, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, ní ojú Hanameli, ọmọ ẹ̀gbọ́n mi àti níwájú àwọn ẹlẹ́rìí tí ó ti fi ọwọ́ sí ìwé àti ní ojú àwọn Júù gbogbo tí wọ́n jókòó ní àgbàlá ilé túbú.
13 És megparancsoltam Bárúkhnak szemeik láttára, mondván:
“Ní ojú wọn ni èmi ti pàṣẹ fún Baruku pé,
14 Így szól az Örökkévaló, a seregek ura. Izrael Istene, vedd a leveleket, ezt a vétellevelet: mind a lepecsételtet, mind a nyitott levelet és tedd azokat cserépedénybe, hogy sok ideig elálljanak.
èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; mú àwọn ìwé tí a fi rà á wọ̀nyí, àti èyí tí a lẹ̀ àti èyí tí a kò lẹ̀, kí o wá gbé wọn sínú ìkòkò amọ̀, kí wọn ó lè wà ní ọjọ́ púpọ̀.
15 Mert így szól az Örökkévaló, a seregek ura, Izrael Istene: Még fognak venni házakat és mezőket és szőlőket ebben az országban.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; àwọn ilẹ̀, pápá àti ọgbà àjàrà ni à ó tún rà padà nílẹ̀ yìí.
16 És imádkoztam az Örökkévalóhoz, miután átadtam a vétellevelet Bárúkhnak, Neríja fiának, mondván:
“Lẹ́yìn tí mo ti fi ìwé rírà náà fún Baruku ọmọkùnrin Neriah, mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé:
17 Jaj, Uram, Örökkévaló! Íme te alkottad az eget és a földet nagy erőddel és kinyújtott karoddal, nem lehetetlen neked semmi sem;
“Háà! Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí o dá ọ̀run àti ayé pẹ̀lú títóbi agbára rẹ àti gbogbo ọ̀rọ̀ apá rẹ. Kò sí ohun tí ó ṣòro fún ọ láti ṣe.
18 aki kegyelmet cselekszik ezrediziglen és megfizeti az atyák bűnét, gyermekeik ölébe ő utánuk, a nagy és hatalmas Isten, Örökkévaló, seregek ura az ő neve;
O fi ìfẹ́ hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n o gbé ìyà ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba lé àwọn ọmọ lẹ́yìn wọn. Ọlọ́run títóbi àti alágbára, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ.
19 nagy tanácsú és hatalmas cselekvésű, te akinek szemei nyitvák az ember fiainak mind az útjaira, hogy adják kikinek útjai szerint és cselekedeteinek gyümölcse szerint.
Títóbi ni ìgbìmọ̀, àti alágbára ní í ṣe, ojú rẹ̀ ṣì sí gbogbo ọ̀nà àwọn ọmọ ènìyàn; láti fi fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ ọ̀nà rẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí èso iṣẹ́ rẹ̀.
20 Aki tettél jeleket és csodákat Egyiptom országában mind a mai napig, Izraelen is, az embereken is és szereztél magadnak nevet, mint ez van e mai napon;
O ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá ní Ejibiti. O sì ń ṣe é títí di òní ní Israẹli àti lára ọmọ ènìyàn tí ó sì ti gba òkìkí tí ó jẹ́ tìrẹ.
21 és kivezetted népedet Izraelt Egyiptom országából, jelekkel és csodákkal meg erős kézzel és kinyújtott karral és nagy félelmetességgel;
O kó àwọn Israẹli ènìyàn rẹ jáde láti Ejibiti pẹ̀lú iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu nínú ọwọ́ agbára àti nína apá rẹ pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá.
22 és adtad nekik ez országot, melyről megesküdtél őseiknek, hogy nekik adod, tejjel és mézzel folyó országot;
Ìwọ fún wọn nílẹ̀ yìí, èyí tí o ti ṣèlérí fún àwọn baba ńlá wọn; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
23 és jöttek és elfoglalták, de nem hallgattak szavadra és tanod szerint nem jártak, mind azt amit parancsoltál nekik, hogy megtegyék, nem tették és megtörténtetted velük ezt az egész veszedelmet:
Wọ́n wá, wọ́n sì gba ilẹ̀ náà ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ tàbí tẹ̀lé òfin rẹ. Wọn kò ṣe ohun tí o pàṣẹ fún wọn, nítorí náà ìwọ mú àwọn ibi yìí wá sórí wọn.
24 íme a töltések a városig értek, annak elfoglalására és a város az ellene harcoló kaldeusok kezébe adatik kard, éhség és dögvész által, és amit kimondtál, megtörtént, íme te látod;
“Wò ó, bí àwọn ìdọ̀tí ṣe kórajọ láti gba ìlú. Nítorí idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, sì fi ìlú lé ọwọ́ àwọn ará Kaldea tí ń gbóguntì wọ́n. Ohun tí ìwọ sọ ṣẹ gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i.
25 pedig te azt mondtad nekem, oh Uram, Örökkévaló: vedd meg a mezőt ezüstön és állíts tanukat, holott a város a kaldeusok kezébe adatik!
Síbẹ̀ a ó fi ìlú náà fún àwọn ará Babeli, ìwọ Olúwa Olódùmarè sọ fún mi pé, ‘Ra pápá náà pẹ̀lú owó fàdákà, kí o sì pe ẹlẹ́rìí.’”
26 És lett az Örökkévaló igéje Jirmejáhúhoz, mondván:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá pé:
27 Íme én vagyok az Örökkévaló, minden halandónak Istene, vajon nekem lehetetlen-e bármi is?
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run gbogbo ẹran-ara. Ǹjẹ́ ohun kan ha a ṣòro fún mi bí?
28 Azért így szól az Örökkévaló: Íme én a várost a kaldeusok kezébe adom és Nebúkadnecczár, Bábel királyának kezébe, hogy elfoglalja.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí, Èmi ṣetán láti fi ìlú yìí fún àwọn ará Kaldea àti fún Nebukadnessari ọba Babeli ẹni tí yóò kó o.
29 És jönnek majd a kaldeusok, kik e város ellen harcolnak és tűzzel gyújtják fel e várost és elégetik, meg a házakat, amelyeknek tetőin füstölögtettek a Báalnak és öntőáldozatokat öntöttek más isteneknek, azért hogy bosszantsanak engem.
Àwọn ará Kaldea tí ó ń gbógun tí ìlú yóò wọ ìlú. Wọn ó sì fi iná sí ìlú; wọn ó jó o palẹ̀ pẹ̀lú ilé tí àwọn ènìyàn ti ń mú mi bínú, tí wọ́n ń rú ẹbọ tùràrí lórí pẹpẹ fún Baali tiwọn sì ń da ẹbọ ohun mímu fún àwọn ọlọ́run mìíràn.
30 Mert Izrael fiai és Jehúda fiai csakis azt szokták tenni, ami rossz szemeimben, ifjúkoruktól fogva, mert Izrael fiai csak bosszantanak engem kezeik művével, úgymond az Örökkévaló.
“Àwọn ènìyàn Israẹli àti Juda kò ṣe ohun kankan bí kò ṣe ibi lójú mi láti ìgbà èwe wọn. Nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti fi kìkì iṣẹ́ ọwọ́ wọ́n mú mi bínú ni Olúwa wí.
31 Mert haragomra és felindulásomra volt nekem e város azon naptól fogva, amelyen építették, egészen e mai napig, úgy, hogy eltávolítom színem elől,
Láti ọjọ́ tí wọ́n ti kọ́ ọ, títí di àkókò yìí ni ìlú yìí ti jẹ́ ohun ìbínú àti ìyọnu fún mi tó bẹ́ẹ̀ tí èmi yóò fà á tu kúrò níwájú mi.
32 Izrael fiainak és Jehúda fiainak minden rosszasága miatt, amit tettek bosszantásomra, ők, királyaik, nagyjaik, papjaik és prófétáik, meg Jehúda emberei és Jeruzsálem lakói.
Àwọn ènìyàn Israẹli àti àwọn ènìyàn Juda ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ìbàjẹ́ tí wọ́n ṣe. Àwọn Israẹli, ọba wọn àti gbogbo ìjòyè, àlùfáà àti wòlíì, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu.
33 Háttal fordultak felém és nem arccal, pedig tanítottam őket, reggelenként tanítva, de ők nem hallgattak rá, hogy elfogadtak volna oktatást.
Wọ́n kọ ẹ̀yìn sí mi, wọ́n sì yí ojú wọn padà. Èmi kọ wọ́n, síbẹ̀ wọn kò fetísílẹ̀ láti gbọ́ ẹ̀kọ́ tàbí kọbi ara sí ìwà ìbàjẹ́.
34 Elhelyezték undokságaikat azon házban, amely az én nevemről neveztetik, hogy azt megtisztátalanítsák.
Wọ́n kó òrìṣà ìríra wọn jọ sí inú ilé tí wọ́n fi orúkọ mi pè, wọ́n sì ṣọ́ di àìmọ́.
35 És építették a Báal magaslatait a Ben-Hinnóm völgyében, hogy átvezessék fiaikat és leányaikat a Molokhnak, amit nem parancsoltam nekik és nem jutott eszembe, hogy ez utálatosságot cselekedjék, azért hogy vétekre indítsák Jehúdát.
Wọ́n kọ́ ibi gíga fún Baali ní àfonífojì Hinnomu láti fi ọmọ wọn ọkùnrin àti obìnrin rú ẹbọ sí Moleki. Èmi kò pàṣẹ, fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò wá sí ọkàn mi pé kí wọ́n ṣe ohun ìríra wọ̀nyí tí ó sì mú Juda dẹ́ṣẹ̀.
36 Most tehát azért így szól az Örökkévaló, Izrael Istene, a városról, melyről azt mondjátok: Bábel királyának kezébe adatott kard, éhség és dögvész által:
“Ìwọ ń sọ̀rọ̀ nípa ti ìlú yìí pé, ‘Pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn ni à ó fi wọ́n fún ọba Babeli,’ ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ nìyìí,
37 Íme én összegyűjtöm őket mindazon országokból, ahová eltaszítottam őket haragomban, felindulásomban és nagy haragvásban; és visszahozom őket e helyre és lakoztatom őket biztonságban.
Èmi ó kó wọn jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo ti lé wọn kúrò ní ìgbà ìbínú àti ìkáàánú ńlá mi. Èmi yóò mú wọn padà wá sí ilẹ̀ yìí; èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó máa gbé láìléwu.
38 És lesznek nekem népül, én pedig leszek nekik istenül.
Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
39 Adok nekik egy szívet és egy utat, hogy féljenek engem minden időben, hogy jó dolguk legyen nekik és gyermekeiknek utánuk.
Èmi ó fún wọn ní ọkàn kan àti ìṣe kí wọn kí ó lè máa bẹ̀rù mi fún rere wọn àti fún rere àwọn ọmọ wọn tí ó tẹ̀lé wọn.
40 És kötök velük örök szövetséget, mely szerint nem fordulok el tőlük, hogy velük jót tegyek, félelmemet pedig szívükbe adom, hogy ne térjenek el tőlem.
Èmi ò bá wọn dá májẹ̀mú ayérayé, èmi kò ní dúró láti ṣe rere fún wọn, Èmi ó sì jẹ́ kí wọ́n bẹ̀rù mi, wọn kì yóò sì padà lẹ́yìn mi.
41 És majd örvendek rajtuk, hogy jót tegyek velük, és elplántálom őket ez országban igazán, egész szívemmel és egész lelkemmel.
Lóòtítọ́, èmi ó yọ̀ nípa ṣíṣe wọ́n ní rere, èmi ó sì fi dá wọn lójú nípa gbígbìn wọ́n sí ilẹ̀ yìí tọkàntọkàn mi.
42 Mert így szól az Örökkévaló: Valamint ráhoztam e népre mind e nagy veszedelmet, úgy rájuk hozom mind a jót, amit kimondok felőlük.
“Nítorí báyìí ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú gbogbo ibi ńlá yìí wá sórí àwọn ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó mú gbogbo rere tí èmi ti sọ nípa tiwọn wá sórí wọn.
43 És mező vétetik ebben az országban, amelyről azt mondjátok: pusztaság az, ember és állat nélkül, a kaldeusok kezébe adatott.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, pápá yóò di rírà ní ilẹ̀ yìí tí ìwọ ti sọ pé, ‘Ohun òfò ni tí kò bá sí ọkùnrin tàbí àwọn ẹran, nítorí tí a ti fi fún àwọn ará Babeli.’
44 Mezőket pénzen fognak venni, levélbe írva, megpecsételve és tanukat állítva Benjámin földjén és Jeruzsálem környékein, meg Jehúda városaiban, a hegység varosaiban, az alföld városaiban és a Délvidék városaiban, mert vissza fogom hozni foglyaikat, úgymond az Örökkévaló.
Wọn ó fi owó fàdákà ra oko, wọn yóò fi ọwọ́ sí ìwé, wọn ó dí pa pẹ̀lú ẹlẹ́rìí láti ilẹ̀ Benjamini àti ní ìlú kéékèèké tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda àti ní ìlú àwọn ìlú orí òkè, àti ni àwọn ẹsẹ̀ òkè, àti ní gúúsù, èmi ó mú ìgbèkùn wọn padà wá, ni Olúwa wí.”