< Jeremiás 16 >

1 És lett hozzám az Örökkévaló igéje, mondván:
Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Ne vegyél magadnak feleséget és ne legyenek fiaid és leányaid ezen a helyen.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
3 Mert így szól az Örökkévaló a fiakról és leányokról, akik a helyen születtek és anyáikról, akik szülték őket és atyáikról, akik nemzették őket ebben az országban:
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
4 Sokféle kínos halállal fognak meghalni, nem siratják őket és nem temetik el, trágyává lesznek a föld színén, a kard és az éhség által pusztulnak el, és hullájuk eledelül lesz az ég madarának és a föld vadjának.
“Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
5 Mert így szól az Örökkévaló: Ne menj be siralomnak házába, ne menj siratni és ne szánakozz rajtuk; mert elvettem békémet a néptől, úgymond az Örökkévaló, a szeretetet és az irgalmat.
Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
6 És meg fognak halni nagyok és kicsinyek ez országban, nem temetik el: se nem siratják őket, se nem vagdalják magukat, se nem kopasztják magukat miattuk.
“Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
7 És nem szegnek nekik kenyeret gyászban, hogy megvigasztalják a halottért és nem itatják velük a vigasztalás poharát, kit-kit atyjáért és anyjáért.
Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
8 De lakodalomnak házába se menj be, hogy leülj velük enni és inni.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
9 Mert így szól az Örökkévaló, a seregek ura, Izrael Istene: Íme megszüntetem ezen a helyen szemeitek előtt és napjaitokban a vígság hangját és az öröm hangját, a vőlegény hangját és a menyasszony hangját.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
10 És lesz, midőn megmondod a népnek mind e szavakat, ők meg szólnak hozzád: miért mondta ki felőlünk az Örökkévaló ezt az egész nagy veszedelmet és mi a bűnünk és mi a vétkünk, mellyel vétettünk az Örökkévaló, a mi Istenünk ellen?
“Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
11 akkor szólj hozzájuk: Mivelhogy elhagytak engem őseitek, úgymond az Örökkévaló, jártak más istenek után és szolgálták őket és leborultak előttük, engem pedig elhagytak és tanomat nem őrizték meg;
Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
12 de ti rosszabbul cselekedtetek őseiteknél, és íme jártok kiki rossz szívének makacssága után, rám nem hallgatva.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
13 Elhajítalak tehát benneteket ez országból oly országba, amelyet nem ismertek, sem ti, sem őseitek; és szolgálni fogtok más isteneket nappal és éjjel, mivel nem adok nektek könyörületet.
Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
14 Azért íme napok jönnek, úgymond az Örökkévaló, és nem mondják többé: él az Örökkévaló aki fölhozta Izrael fiait Egyiptom országából,
“Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
15 hanem: él az Örökkévaló, aki fölhozta Izrael fiait az észak országából és mindazon országokból, ahová eltaszította őket; ugyanis visszahozom őket földjükre, melyet adtam őseiknek.
Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
16 Íme én küldök sok halászért, úgymond az Örökkévaló, hogy halásszák őket és azután küldök sok vadászért, hogy vadászszák őket minden hegyről és minden dombról és a sziklák hasadékaiból.
“Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
17 Mert szemeim mind az ő utjaikon vannak, nincsenek rejtve előttem, és nincsen eltitkolva az ő bűnük szemeim előtt.
Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
18 És megfizetem legelőbb kétszeresét bűnüknek és vétküknek, amiért megszentségtelenítették országomat: undokságaik és utálatosságaik dögével megtöltötték birtokomat.
Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
19 Oh Örökkévaló, erőm és erősségem és menedékem a szorongatás napján; hozzád jönnek majd nemzetek a föld végeiről és azt mondják: csak hazugságot örököltek őseink, hiábavalóságot és nincs azok közt aki használna.
Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
20 Vajon csinálhat-e magának ember istent? és azok nem is istenek.
Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
21 Azért íme én megismertetem velük ez ízben, meg fogom ismertetni velük kezemet és hatalmamat; és megismerik, hogy nevem Örökkévaló.
“Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.

< Jeremiás 16 >