< Ézsaiás 3 >
1 Mert íme az Úr, az Örökkévaló, a seregek ura eltávolít Jeruzsálemből és Jehúdából támaszt és támasztékot, a kenyér minden támaszát és a víz minden támaszát;
Kíyèsi i, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, fẹ́ mú ìpèsè àti ìrànlọ́wọ́ kúrò ní Jerusalẹmu àti Juda gbogbo ìpèsè oúnjẹ àti ìpèsè omi.
2 hőst és harcost, bírót és prófétát, jóst és vénet;
Àwọn akíkanjú àti jagunjagun, adájọ́ àti wòlíì, aláfọ̀ṣẹ àti alàgbà,
3 ötvenes tisztet és tekintélyben állót, tanácsost, bölcs mestert és az igézéshez értőt.
balógun àádọ́ta àti àwọn ènìyàn, onípò gíga; olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́ àti ògbójú oníṣègùn.
4 És fiatalokat teszek fejedelmeikül és gyermekek fognak uralkodni rajtuk.
“Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn, ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sì máa jẹ ọba lórí i wọn.”
5 És tolakodik a nép, ember emberre, kiki felebarátjára; felzúdul a fiatal a vén ellen, a nemtelen a nemes ellen.
Àwọn ènìyàn yóò sì máa pọ́n ọmọnìkejì, wọn lójú ẹnìkan sí ẹnìkejì rẹ̀, aládùúgbò sí aládùúgbò rẹ̀. Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbógun ti àwọn àgbàgbà, àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí ọlọ́lá.
6 Ha aki megragadja testvérét atyja házában: neked van ruhád, te leszel a vezérünk és legyen ez az omladék a te kezed alatt –
Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin rẹ̀ mú, nínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé, “Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa, sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”
7 megszólal ama napon, mondván: nem leszek orvos; és házamban nincs kenyér és nincs ruha, ne tegyetek engem a nép vezérévé.
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé, “Èmi kò ní àtúnṣe kan. Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ó ní aṣọ nílé, ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”
8 Mert összeomlott Gyereuzsálem és Jehúda ledőlt, mert nyelvük és cselekedeteik az Örökkévaló ellen vannak, dicsőséges szemeinek bosszantására.
Jerusalẹmu ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n Juda ń ṣubú lọ, ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa, láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.
9 Arcuk kifejezése tanúskodott ellenük; vétküket mint Szodoma mondják el, nem titkolták: jaj lelküknek, mert rosszat tettek önmagukkal!
Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn, wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sodomu; wọn ò fi pamọ́! Ègbé ni fún wọn! Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.
10 Mondjátok az igazról, hogy jól jár, mert cselekedeteik gyümölcsét fogják enni;
Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn, nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èso iṣẹ́ ẹ wọn.
11 jaj a gonosznak, rosszul jár, mert kezeinek tette szerint történik vele.
Ègbé ni fún ènìyàn búburú! Ìparun wà lórí i wọn, a ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.
12 Népem – zsarnokai gyermekek és asszonyok uralkodnak rajta; népem, vezetőid tévesztők és ösvényeid útját elrontották.
Àwọn ọ̀dọ́mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójú àwọn obìnrin ń jẹ ọba lé wọn lórí. Háà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti ṣì yín lọ́nà, wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.
13 Előáll perelni az Örökkévaló, és odaáll, ítélni népeket.
Olúwa bọ sí ipò rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́ Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.
14 Az Örökkévaló törvénybe száll népének véneivel és nagyjaival: Hiszen ti lelegeltétek a szőlőt, a szegénytől rablott jószág van házaitokban.
Olúwa dojú ẹjọ́ kọ àwọn àgbàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀. “Ẹ̀yin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi, ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.
15 Mi lelt, hogy összezúzzátok népemet és a szegények arcát megőrlitek, úgymond az Úr, az Örökkévaló, a seregek ura.
Kín ni èrò yín láti máa run àwọn ènìyàn mi túútúú tí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ̀?” ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
16 És szólt az Örökkévaló: Mivelhogy büszkélkedtek Czión leányai, jártak kinyújtva torkukat és kacsintva szemeikkel, tipegve járton-járnak és lábaik láncaival csörgetnek –
Olúwa wí pé, “Àwọn obìnrin Sioni jẹ́ agbéraga, wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn, tí wọn ń fojú pe ọkùnrin, tí wọn ń sọ̀dí bí wọ́n ti ń yan lọ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjanwọnjan lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn.
17 varassá teszi tehát az Úr Czión leányainak feje tetejét és az Örökkévaló megmezteleníti hajzatukat.
Nítorí náà Olúwa yóò mú egbò wá sórí àwọn obìnrin Sioni, Olúwa yóò sì pá wọn ní agbárí.”
18 Azon a napon eltávolítja az Úr a pompás lábláncokat, a napocskákat és holdacskákat;
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò já ọ̀ṣọ́ wọn gbà kúrò ti ọwọ́ àti gèlè àti ẹ̀gbà ọrùn tí ó dàbí òṣùpá
19 a függőket, a láncokat és a fátyolokat;
gbogbo yẹtí, ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú,
20 a fejdíszeket, a bokaláncokat, a díszöveket, az illatszelencéket és bűvös ékszereket;
gbogbo gèlè, ẹ̀gbà ọrùn, ẹsẹ̀ àti àyà, àwọn ìgò tùràrí àti òògùn,
21 a gyűrűket és az orrkarikákat;
òrùka ọwọ́ àti ti imú,
22 a díszruhákat és köpenyeket, a palástokat és a zacskókat;
àwọn àtàtà aṣọ, àwọ̀lékè, agbádá àti àpamọ́wọ́,
23 a tükröket és gyolcskendőket, a fejkötőket és az általvetőket.
dígí wọn, aṣọ funfun nigínnigín ìbòrí àti ìbòjú.
24 És lesz illatszer helyett rothadság, öv helyett kötél, fodros hajmű helyett kopaszság, díszköntös helyett zsákövezet, égési seb szépség helyett.
Dípò òórùn dídùn, òórùn búburú ni yóò wá, okùn ni yóò wà dípò àmùrè, orí pípá ni yóò dípò irun ti a ṣe ní ọ̀ṣọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ ni yóò dípò aṣọ ẹ̀yẹ ìjóná dípò ẹwà.
25 Férfiaid kard által esnek el, vitézséged harcban.
Àwọn ọkùnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú, àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lójú ogun.
26 Keseregnek és gyászolnak kapui és ő kifosztva a földre ül.
Àwọn bodè Sioni yóò sọkún kíkorò, wọn ó ṣọ̀fọ̀, nítorí ó dahoro, yóò jókòó ní orí ilẹ̀.