< 1 Mózes 9 >
1 És megáldotta Isten Nóét és fiait, és mondta nekik: Szaporodjatok, sokasodjatok és töltsétek be a földet.
Ọlọ́run sì súre fún Noa àti àwọn ọmọ rẹ̀ wí pé, “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì pọ̀ ní iye, kí ẹ sì kún ayé.
2 A tőletek való félelem és rettegés legyen a föld minden állatján és az ég minden madarán, mindenen ami mozog a földön, meg a tenger minden halain. Kezetekbe adattak.
Ẹ̀rù yín yóò mú ojo wà lára gbogbo ẹranko àti gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹ̀dá tí ń rìn nílẹ̀; àti gbogbo ẹja òkun; a fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
3 Minden mozgó lény, amely él, a tietek legyen eledelül; mint a zöld füvet, úgy adtam nektek mindet.
Gbogbo ohun tó wà láààyè tí ó sì ń rìn, ni yóò jẹ́ oúnjẹ fún un yín, bí mo ṣe fi ewéko fún un yín náà ni mo fi ohun gbogbo fún un yín.
4 De húst lelkével: vérével ne egyetek!
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ ẹran tòun-tẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
5 És bizony véreteket lelketek szerint számon kérem, minden élőlény kezéből számon kérem azt; és az ember kezéből, mindenki testvérének kezéből számon kérem az ember lelkét.
Nítòótọ́ ẹ̀jẹ̀ yín, àní ẹ̀mí yín, ni èmi yóò sì béèrè; lọ́wọ́ gbogbo ẹranko ni èmí yóò béèrè rẹ̀, àti lọ́wọ́ ènìyàn, lọ́wọ́ arákùnrin olúkúlùkù ènìyàn ni èmi yóò béèrè ẹ̀mí ènìyàn.
6 Aki ember vérét ontja, ember által ontassék annak vére, mert Isten képmására alkotta az embert.
“Ẹnikẹ́ni tí ó bá ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀, láti ọwọ́ ènìyàn ni a ó gbà ta ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀. Nítorí ní àwòrán Ọlọ́run ni Ọlọ́run dá ènìyàn.
7 Ti pedig szaporodjatok és sokasodjatok, nyüzsögjetek a földön és sokasodjatok rajta.
Ṣùgbọ́n ní tiyín, ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa pọ̀ sí i, ẹ máa gbá yìn lórí ilẹ̀, kí ẹ sì pọ̀ sí i lórí rẹ̀.”
8 És szólt Isten Nóéhoz, meg fiaihoz, mondván:
Ọlọ́run sì wí fún Noa àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé,
9 Íme, én megkötöm szövetségemet veletek és magzatotokkal utánatok;
“Mo dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín àti pẹ̀lú àwọn ìran yín tí ń bọ̀ lẹ́yìn.
10 és minden élőlénnyel, mely veletek van, madárból, baromból és a föld minden vadjából, mely veletek van, mindazokkal, melyek kijöttek a bárkából, a föld minden vadja szerint.
Àti pẹ̀lú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú yín, ìbá à ṣe ẹyẹ, ẹja, ẹran ọ̀sìn, ẹranko igbó, gbogbo ohun tí ó jáde kúrò nínú ọkọ̀ pẹ̀lú yín, àní gbogbo ẹ̀dá alààyè ní ayé.
11 És én megkötöm szövetségemet veletek, hogy ne irtassék ki többé semmi test sem özönvíz által és ne legyen többé özönvíz, hogy megrontsa a földet.
Mo dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín láéláé, Èmi kì yóò fi ìkún omi pa ayé run kúrò mọ láéláé, a kì yóò fi omi pa ayé run.”
12 És mondta Isten: Ez a jele a szövetségnek, melyet én helyezek közém és közétek és minden élőlény közé, mely veletek van, örök nemzedékekre.
Ọlọ́run sì wí pé, “Èyí ni àmì májẹ̀mú tí mo ń dá yìí láàrín èmi àti ẹ̀yin àti ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú yín, májẹ̀mú àtìrandíran tó ń bọ̀:
13 Ivemet helyeztem, a felhőbe, hogy legyen jeléül a szövetségnek közöttem és a föld között.
Mo ti fi òṣùmàrè sí àwọsánmọ̀, yóò sì jẹ́ àmì májẹ̀mú láàrín èmi àti ayé.
14 És lesz, midőn sűrű felhőt borítok a földre és meglátszik az ív a felhőben,
Nígbàkígbà tí mo bá mú kí òjò ṣú, tí òṣùmàrè bá farahàn ní àwọsánmọ̀.
15 akkor megemlékezem az én szövetségemről, mely van közöttem és köztetek és minden élőlény között minden testből; és nem lesz többé a víz özönné, hogy megrontson minden testet.
Èmi yóò rántí májẹ̀mú mi, tí ó wà láàrín èmi àti ẹ̀yin àti gbogbo ẹ̀dá alààyè, kì yóò sì tún sí ìkún omi mọ́ láti pa gbogbo ẹ̀dá run.
16 És lesz az ív a felhőben és én meglátom azt, hogy megemlékezzem az örök szövetségről, mely van Isten között és minden élőlény között, minden testből, mely a földön van.
Nígbàkígbà tí òṣùmàrè bá yọ ní àwọsánmọ̀, èmi yóò rí i, èmi yóò sì rántí májẹ̀mú ayérayé tí ń bẹ láàrín Ọlọ́run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń bẹ ní ayé.”
17 És mondta Isten Nóénak: Ez a jele a szövetségnek, melyet szereztem közöttem és minden test között, mely a földön van.
Ọlọ́run sì wí fún Noa pé, “Èyí ni àmì májẹ̀mú tí mo ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ láàrín èmi àti gbogbo alààyè ní ayé.”
18 És voltak Nóé fiai, akik kimentek a bárkából, Sém, Chom és Jefesz; Chom pedig, ő Kánaán atyja.
Àwọn ọmọ Noa tí ó jáde nínú ọkọ̀ ni Ṣemu, Hamu àti Jafeti. (Hamu ni baba Kenaani.)
19 Ezek hárman Nóé fiai és ezektől népesült be az egész föld.
Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Noa mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ni gbogbo ènìyàn ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ ayé.
20 És Nóé kezdte, a földműves, hogy szőlőt ültetett.
Noa bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ àgbẹ̀, ó sì gbin ọgbà àjàrà.
21 És ivott a borból és megrészegedett és feltakaródzott sátorában.
Ó mu àmupara nínú ọtí wáìnì àjàrà rẹ̀, ó sì tú ara rẹ̀ sí ìhòhò, ó sì sùn nínú àgọ́ rẹ̀.
22 Midőn meglátta Chom, Kánaán atyja, az ő atyjának meztelenségét, tudtára adta két fivérének, kinn.
Hamu tí í ṣe baba Kenaani sì rí baba rẹ̀ ní ìhòhò bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀ méjèèjì ní ìta.
23 És vették Sém és Jefesz a ruhát, rátették kettőjük vállára és mentek háttal fordulva és befödték atyjuk meztelenségét; arcuk pedig hátra fordulva volt és atyjuk meztelenségét nem láttak.
Ṣùgbọ́n Ṣemu àti Jafeti mú aṣọ lé èjìká wọn, wọ́n sì fi ẹ̀yìn rìn, wọ́n sì bo ìhòhò baba wọn. Wọ́n kọjú sẹ́yìn kí wọn kí ó má ba à rí ìhòhò baba wọn.
24 Midőn Nóé fölébredt borosságából, megtudta, mit tett vele kisebbik fia.
Nígbà tí Noa kúrò ní ojú ọtí, tí ó sì mọ ohun tí ọmọ rẹ̀ kékeré ṣe sí i.
25 És mondta: Átkozott Kánaán, rabszolgája legyen testvéreinek.
Ó wí pé, “Ègún ni fún Kenaani. Ìránṣẹ́ àwọn ìránṣẹ́ ni yóò máa ṣe fún àwọn arákùnrin rẹ̀.”
26 És mondta: Áldott legyen az Örökkévaló, Sém Istene és Kánaán legyen az ő szolgájuk.
Ó sì tún wí pé, “Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Ṣemu Kenaani yóò máa ṣe ẹrú fún Ṣemu.
27 Terjessze ki Isten Jefeszt és lakjék Sém sátraiban; Kánaán pedig legyen az ő szolgájuk.
Ọlọ́run yóò mú Jafeti gbilẹ̀, Jafeti yóò máa gbé ní àgọ́ Ṣemu Kenaani yóò sì jẹ́ ẹrú fún un.”
28 És élt Nóé az özönvíz után háromszáz és ötven évig.
Noa wà láààyè fún irinwó ọdún dín àádọ́ta lẹ́yìn ìkún omi.
29 Voltak pedig Nóé összes napjai: kilencszázötven év, azután meghalt.
Àpapọ̀ ọjọ́ ayé Noa jẹ́ ẹgbẹ̀rún ọdún dín làádọ́ta, ó sì kú.