< 1 Mózes 45 >

1 Ekkor nem bírta József magát tartóztatni mindazok előtt, akik mellette álltak és kiáltott: Vezessetek ki mindenkit tőlem! És nem állt senki nála, midőn megismertette magát József az ő testvéreivel.
Josẹfu kò sì le è pa á mọ́ra mọ́ níwájú gbogbo àwọn tí ó dúró tì í. Ó sì sọkún sókè tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn tí ó wà ní àyíká gbọ́ ohun ẹkún rẹ̀. “Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.” Kò sì sí ẹnikẹ́ni lọ́dọ̀ rẹ̀ nígbà tí ó fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
2 És hangos sírásra fakadt, hogy meghallották az egyiptomiak és meghallotta Fáraó háza.
Ó sì sọkún sókè kíkankíkan tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn Ejibiti gbọ́ ohùn ẹkún rẹ̀, àwọn ilé Farao pẹ̀lú sì gbọ́ nípa rẹ̀.
3 És mondta József az ő testvéreinek: Én vagyok József! Él-e még atyám? De testvérei nem bírtak felelni neki, mert megrémültek tőle.
Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Èmi ni Josẹfu! Ṣe baba mi sì wà láààyè?” Ṣùgbọ́n àwọn arákùnrin rẹ̀ kò le è dá a lóhùn nítorí ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi, ẹnu sì yà wọ́n níwájú rẹ̀.
4 József pedig mondta az ő testvéreinek: Lépjetek csak ide hozzám! És odaléptek, ő pedig mondta: Én vagyok József, a ti testvéretek, akit eladtatok Egyiptomba.
Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Ẹ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe bẹ́ẹ̀, ó wí pé, “Èmi ni Josẹfu arákùnrin yín tí ẹ tà sí ilẹ̀ Ejibiti!
5 Most pedig ne bánkódjatok és ne keltsen haragot szemeitekben, hogy eladtatok engem ide, mert életfenntartásra küldött engem Isten előttetek.
Ṣùgbọ́n báyìí, ẹ má ṣe banújẹ́, ẹ má sì ṣe bínú sí ara yín ní títà tí ẹ tà mí sí ìhín, nítorí, ọ̀nà àti gba ẹ̀mí yín là ni Ọlọ́run ṣe rán mi sí ìhín ṣáájú yín.
6 Mert immár két éve van az éhség az országban a még öt év, amelyekben nem lesz szántás és aratás
Ìyàn tí ó ti mú láti ọdún méjì sẹ́yìn yìí yóò tẹ̀síwájú fún ọdún márùn-ún sí i nínú èyí tí ẹnikẹ́ni kò ní gbìn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ni kórè.
7 Azért küldött engem Isten előttetek, hogy megtartsak-nektek maradékot a földön és hogy életben tartalak benneteket nagy megmenekülésre.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run rán mi ṣáájú yín sí ìhín láti da irú-ọmọ yín sí fún un yín lórí ilẹ̀ ayé àti láti fi ìgbàlà ńlá gba ẹ̀mí yín là.
8 Most tehát, nem ti küldtetek engem ide, hanem Isten; ő tett engem atyjává Fáraónak, urává az ő egész házának és uralkodóvá Egyiptom egész országában.
“Nítorí náà, kì í ṣe ẹ̀yin ni ó rán mi wá sí ibí yìí, bí kò ṣe Ọlọ́run. Ó fi mí ṣe baba, Olùdámọ̀ràn fún Farao, olúwa fún gbogbo ilé Farao àti alákòóso gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
9 Siessetek, menjetek föl atyámhoz és mondjátok neki: Így szól a te fiad József, Isten tett engem egész Egyiptom urává; jöjj le hozzám, ne vesztegelj.
Nísinsin yìí, ẹ yára padà sọ́dọ̀ baba mi kí ẹ sì wí fun un pé, èyí ni ohun tí Josẹfu ọmọ rẹ wí, Ọlọ́run ti fi mí ṣe olúwa fún gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, ẹ sọ̀kalẹ̀ wá láì jáfara.
10 És lakjál Gósen földjén, hogy közel légy hozzám, te, fiaid és fiaid fiai, juhod, marhád és mindened, amid van.
Ìwọ yóò gbé ní agbègbè Goṣeni, ìwọ kì yóò jìnnà sí mi, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ, àwọn agbo ẹran rẹ àti agbo màlúù rẹ àti gbogbo ohun tí ìwọ ní.
11 Én pedig eltartalak téged ott, mert még öt évig lesz éhség; hogy el ne szegényedj te, házad és mindened, amid van.
Èmi yóò pèsè fún yín níbẹ̀. Nítorí ó ṣì ku ọdún márùn-ún gbáko ti ìyàn yóò fi mú. Kí ìwọ àti ilé rẹ àti ohun tí í ṣe tìrẹ má ba à di aláìní.
12 És íme, szemeitek látják és testvérem, Benjámin szemei, hogy az én szám az, amely szól hozzátok.
“Ẹ̀yin fúnra yín àti Benjamini arákùnrin mi pẹ̀lú rí i pé, lóòótọ́ lóòótọ́, èmi Josẹfu ni mo ń bá a yín sọ̀rọ̀.
13 Adjátok tudtára atyámnak minden dicsőségemet Egyiptomban és mindent, amit láttatok; siessetek és hozzátok le atyámat ide.
Ẹ sọ fún baba mi nípa gbogbo ọlá tí a fún mi ní ilẹ̀ Ejibiti àti ohun gbogbo tí ẹ̀yin ti rí, kí ẹ sì mú baba mi tọ̀ mí wá sí ìhín yìí kíákíá.”
14 És borult Bénjáminnak, az ő testvérének a nyakába és sírt; Benjámin meg sírt az ő nyakán.
Nígbà náà ni ó dì mọ́ Benjamini arákùnrin rẹ̀, ó sì sọkún, Benjamini náà sì dì mọ́ ọn, pẹ̀lú omijé lójú.
15 Megcsókolta összes testvéreit és sírt rajtuk; azután pedig beszéltek vele testvérei.
Ó sì tún fẹnu ko gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ lẹ́nu, ó sì sọkún sí wọn lára. Lẹ́yìn èyí, Josẹfu àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sọ̀rọ̀ pọ̀.
16 És a hír hallatszott Fáraó házában, mondván: Eljöttek József testvérei. És jónak tetszett Fáraó szemeiben és szolgái szemeiben.
Nígbà tí ìròyìn náà dé ààfin Farao pé àwọn arákùnrin Josẹfu dé, inú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ dùn.
17 És mondta Fáraó Józsefnek: Mondd testvéreidnek, ezt tegyétek, rakjátok meg barmaitokat és eredjetek, menjetek Kánaán országába;
Farao wí fún Josẹfu pé, “Wí fún àwọn arákùnrin rẹ pé, ‘Èyí ni kí ẹ ṣe, ẹ di ẹrù lé ẹranko yín kí ẹ sì padà sí ilẹ̀ Kenaani,
18 és vegyétek atyátokat, meg házatok népét és jöjjetek el hozzám; én pedig hadd adjam nektek Egyiptom országának legjavát, hogy egyétek a föld zsírját.
kí ẹ sì mú baba yín àti ìdílé yín tọ̀ mí wá. Èmi yóò fún un yín ní ibi tí ó dára jùlọ ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sì le è gbádùn ilẹ̀ yìí.’
19 Neked pedig meg van parancsolva: Ezt tegyétek, vegyetek magatoknak Egyiptom országából szekereket gyermekeitek és feleségeitek számára, és vegyétek föl atyátokat és jöjjetek el.
“A pàṣẹ fún ọ láti sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe èyí. ẹ mú kẹ̀kẹ́ ẹrù láti ilẹ̀ Ejibiti fún àwọn ọmọ yín àti àwọn aya yín. Kí ẹ sì mú baba yín tọ mí wá.
20 Szemetek pedig ne sajnálja holmitokat, mert Egyiptom országának legjava a tietek.
Ẹ má ṣe àníyàn nípa ohun ìní yín nítorí èyí tí ó dára jù nínú ilẹ̀ Ejibiti yóò jẹ́ tiyín.’”
21 És így cselekedtek Izrael fiai; József pedig adott nekik szekereket Fáraó parancsára, és adott nekik élelmet az útra.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe èyí. Josẹfu fún wọn ni kẹ̀kẹ́ ẹrù bí Farao ti pàṣẹ, ó sì fún wọn ní oúnjẹ fún ìrìnàjò wọn pẹ̀lú.
22 Mindnyájuknak adott, mindegyiknek két váltó ruhát, Benjáminnak pedig adott háromszáz ezüstöt és öt váltó ruhát.
Ó fún ẹni kọ̀ọ̀kan wọn ní aṣọ tuntun. Ṣùgbọ́n Benjamini ni ó fún ní ọ̀ọ́dúnrún ẹyọ owó idẹ fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ márùn-ún.
23 Atyjának pedig küldött ilyeténképpen: Tíz szamarat, mely vitt Egyiptom legjavából és tíz nőstény szamarat, mely vitt gabonát és kenyeret, és eledelt atyjának az útra.
Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó kó ránṣẹ́ sí baba rẹ̀: kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá tí ó ru àwọn ohun mèremère ilẹ̀ Ejibiti àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá tí ó ru ọkà àti oríṣìíríṣìí oúnjẹ.
24 És elbocsátott testvéreit és elmentek; és mondta nekik: Ne vesszetek össze az úton!
Nígbà náà ni ó rán àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, bí wọ́n ṣe ń pínyà, ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe jà ní ọ̀nà o!”
25 Fölmentek Egyiptomból és elérkeztek Kánaán országába Jákobhoz, az ő atyjukhoz.
Báyìí ni wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti wá sí ọ̀dọ̀ Jakọbu baba wọn ní ilẹ̀ Kenaani.
26 És tudtára adták neki, mondván: József még él, és hogy ő uralkodik Egyiptom egész országán; de megdermedt szíve, mert nem hitt nekik.
Wọn wí fún un pé, “Josẹfu ṣì wà láààyè! Kódà òun ni alákòóso ilẹ̀ Ejibiti.” Ẹnu ya Jakọbu, kò sì gbà wọ́n gbọ́.
27 És elbeszélték neki József minden szavát, amit szólt hozzájuk, és látta a szekereket, melyeket József küldött, hogy őt vigyék; akkor föléledt Jákobnak, az ő atyjuknak lelke.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n sọ ohun gbogbo tí Josẹfu ti sọ fún wọn fún un tí ó sì rí kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Josẹfu fi ránṣẹ́ láti gbé e padà wá, iyè Jakọbu, baba wọn sọ.
28 És mondta Izrael: Sok ez! József fiam még él! Hadd megyek, hogy lássam őt, mielőtt meghalok.
Israẹli sì wí pé, “Mo gbà dájúdájú wí pé, Josẹfu ọmọ mi wà láààyè. Èmi ó lọ rí i kí n tó kú.”

< 1 Mózes 45 >