< 1 Mózes 30 >
1 Midőn Ráchel látta, hogy ő nem szült Jákobnak, irigykedett Ráchel az ő nővérére és mondta Jákobnak: Adj nekem gyermekeket, mert ha nem, meghalok én.
Nígbà tí Rakeli rí i pe òun kò bímọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìlara sí Lea, arábìnrin rẹ̀, ó sì wí fún Jakọbu pé, “Fún mi lọ́mọ, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó kú!”
2 És fölgerjedt Jákob haragja Ráchel ellen és mondta: Vajon Isten helyében vagyok-e én, aki megvonta tőled a méhnek gyümölcsét?
Inú sì bí Jakọbu sí i, ó sì wí pé, “Èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run, ẹni tí ó mú ọ yàgàn bí?”
3 És az mondta: Íme szolgálóm Bilhó, menj be hozzá és szüljön az én térdeimen, hogy felépüljek én is általa.
Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Biliha ìránṣẹ́bìnrin mi nìyìí, bá a lòpọ̀, kí ó ba à le bí ọmọ fún mi, kí èmi si le è tipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.”
4 És odaadta neki Bilhót, az ő szolgálóját feleségül; és Jákob bement hozzá.
Báyìí ni Rakeli fi Biliha fún Jakọbu ní aya, ó sì bá a lòpọ̀.
5 És fogant Bilhó és fiat szült Jákobnak.
Biliha sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
6 És mondta Ráchel: Ítélt fölöttem Isten, meg is hallgatta szavamat és fiat adott nekem; azért nevezte el Dánnak.
Rakeli sì wí pé, “Ọlọ́run ti ṣe ìdájọ́ mi; ó sì ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi, ó sì fún mi ni ọmọkùnrin kan.” Nítorí ìdí èyí ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Dani.
7 Újra fogant és szült Bilhó, Ráchel szolgálója második fiút Jákobnak.
Biliha, ọmọ ọ̀dọ̀ Rakeli sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
8 És mondta Ráchel: Isteni küzdelmeket kűzdtem nővéremmel, győztem is; azért nevezte el Náftálinak.
Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Mo ti bá ẹ̀gbọ́n mi ja ìjàkadì ńlá, èmi sì ti borí.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Naftali.
9 És látta Léa, hogy nem szül többet, vette Zilpót, az ő szolgálóját és odaadta őt Jákobnak feleségül.
Nígbà tí Lea sì ri pé òun ko tún lóyún mọ́, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, Silipa fún Jakọbu bí aya.
10 És szült Zilpó, Léa szolgálója, Jákobnak fiat.
Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
11 És mondta Léa: Megjött a szerencse; és elnevezte Gádnak.
Nígbà náà ni Lea wí pé, “Orí rere ni èyí!” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Gadi.
12 És szült Zilpó, Léa szolgálója, második fiút Jákobnak.
Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì tún bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
13 És mondta Léa: Boldogságom ez, mert boldognak mondanak engem a leányok: és elnevezte Ásérnek.
Nígbà náà ni Lea wí pé, “Mo ní ayọ̀ gidigidi! Àwọn ọmọbìnrin yóò sì máa pe mí ní Alábùkún fún.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Aṣeri.
14 És elment Rúbén a búzaaratás napjaiban és talált nadragulyákat a mezőn, elvitte azokat anyjának, Léának; és mondta Ráchel Léának: Adj csak nekem fiad nadragulyáiból.
Ní ọjọ́ kan, ní àkókò ìkórè ọkà jéró, Reubeni jáde lọ sí oko, ó sì rí èso mándrákì, ó sì mú un tọ Lea ìyá rẹ̀ wá. Rakeli sì wí fún Lea pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ara èso mándrákì tí ọmọ rẹ mú wá.”
15 De ő mondta neki: Vajon kevés-e, hogy elveszed férjemet, még elvennéd fiam nadragulyáit is? És mondta Ráchel: Azért maradjon veled az éjjel fiad nadragulyáiért.
Ṣùgbọ́n Lea dalóhùn pé, “Ọkọ mi tí o gbà kò tó kọ́? Ṣe ìwọ yóò tún gba èso mándrákì ọmọ mi pẹ̀lú?” Rakeli sì dáhùn pé, “Ó dára, yóò sùn tì ọ́ lálẹ́ yìí nítorí èso mándrákì ọmọ rẹ.”
16 Midőn Jákob jött a mezőről este, kiment elébe Léa és mondta: Hozzám jöjj be, mert bérbe vettelek fiam nadragulyáiért. És vele maradt az éjjel.
Nítorí náà, nígbà tí Jakọbu ti oko dé ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ náà, Lea jáde lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí pé, “O ní láti sun ọ̀dọ̀ mi ní alẹ́ yìí nítorí mo ti fi èso mándrákì tí ọmọ mi wá bẹ̀ ọ́ lọ́wẹ̀.” Nítorí náà ni Jakọbu sùn tì í ní alẹ́ ọjọ́ náà.
17 És meghallgatta Isten Leát, ez fogant és szült. Jákobnak ötödik fiút.
Ọlọ́run sì gbọ́ ti Lea, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin karùn-ún fún Jakọbu.
18 És mondta Léa: Isten megadta jutalmamat, hogy odaadtam szolgálómat férjemnek; és elnevezte Isszáchárnak.
Nígbà náà ni Lea wí pé, “Ọlọ́run ti sẹ̀san ọmọ ọ̀dọ̀ mi ti mo fi fún ọkọ mi fún mi,” ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Isakari.
19 Léa újra fogant és szült Jákobnak hatodik fiút.
Lea sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kẹfà fún Jakọbu.
20 És mondta Léa: Megajándékozott engem Isten ajándékkal, immár nálam fog lakni férjem, mert szültem neki hat fiút; és elnevezte Zebulúnnak.
Nígbà náà ni Lea tún wí pé “Ọlọ́run ti fún mi ní ẹ̀bùn iyebíye, nígbà yìí ni ọkọ mi yóò máa bu ọlá fún mi.” Nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ni Sebuluni.
21 Azután szült egy leányt és elnevezte Dinának.
Lẹ́yìn èyí, ó sì bí ọmọbìnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dina.
22 És megemlékezett Isten Ráchelről, meghallgatta őt Isten és megnyitotta méhét;
Nígbà náà ni Ọlọ́run rántí Rakeli, Ọlọ́run sì gbọ́ tirẹ̀, ó sì ṣí i ní inú.
23 fogant és fiat szült és mondta: Elhárította Isten az én gyalázatomat.
Ó lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan ó sì wí pé, “Ọlọ́run ti mú ẹ̀gàn mi kúrò.”
24 És elnevezte Józsefnek, mondván: Adjon még az Örökkévaló nekem másik fiút.
Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ni Josẹfu, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ kí Olúwa kí ó fi ọmọkùnrin mìíràn kún un fún mi.”
25 És volt, amint szülte Ráchel Józsefet, mondta Jákob Lábánnak: Bocsáss el engem, hadd menjek el helységembe és országomba.
Lẹ́yìn tí Rakeli ti bí Josẹfu, Jakọbu wí fún Labani pé, “Jẹ́ kí èmi máa lọ sí ilẹ̀ mi tí mo ti wá.
26 Add ide feleségeimet és gyermekeimet, akikért téged szolgáltalak, hadd menjek el; mert te ismered szolgálatomat, amellyel szolgáltalak.
Kó àwọn ọmọ àti ìyàwó mi fún mi, àwọn ẹni tí mo ti torí wọn sìn ọ́. Ki èmi lè máa bá ọ̀nà mi lọ. O sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ tó.”
27 És mondta neki Lábán: Ha ugyan kegyet találtam szemeidben – sejtem, hogy az Örökkévaló megáldott engem miattad.
Ṣùgbọ́n Labani wí fún un pé, “Bí o bá ṣe pé mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ dúró, nítorí, mo ti ṣe àyẹ̀wò rẹ, mo sì rí i pé Olúwa bùkún mi nítorí rẹ.
28 És mondta: Szabd ki béredet rám és megadom.
Sọ ohun tí o fẹ́ gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ, èmi yóò sì san án.”
29 És mondta neki: Te tudod, miként szolgáltalak és mivé lett a te nyájad nálam.
Jakọbu sì wí fún un pé, “Ìwọ sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ àti bí ẹran ọ̀sìn rẹ ti pọ̀ si lábẹ́ ìtọ́jú mi.
30 Mert kevés az, amid volt énelőttem és elterjedt sokasággá, az Örökkévaló megáldott téged nyomomban; és most, mikor tegyek valamit én is az én házamért?
Ìwọ̀nba díẹ̀ sá à ni o ní kí èmi tó dé, ó sì ti pọ̀ sí i gidigidi, Olúwa sì ti bùkún ọ nínú gbogbo èyí tí mo ṣe. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nígbà wo ní èmi yóò pèsè fún ìdílé tèmi.”
31 És ő mondta: Mit adjak neked? És mondta Jákob: Ne adj nekem semmit; ha megteszed nekem ezt a dolgot, ismét legeltetem juhaidat és őrzöm.
Ó sì tún béèrè wí pé, “Kín ni kí èmi ó fi fún ọ?” Jakọbu dáhùn pé, “Má fun mi ni ohunkóhun, ṣùgbọ́n bí ìwọ yóò bá ṣe ohun tí mo fẹ́ sọ yìí, èmi yóò sì máa bá ọ tọ́jú àwọn agbo ẹran rẹ, èmi yóò sì máa bọ́ wọn.
32 Bejárom ma összes juhaidat, eltávolítván onnan minden bárányt, mely pöttyös és foltos és minden sötétszínű bárányt a juhok közül, meg a foltost és pöttyöst a kecskék közül; ez legyen a bérem.
Jẹ́ kí èmi kí ó la agbo ẹran kọjá ní òní, èmi yóò sì mú gbogbo àgùntàn onílà àti èyí tí ó ní àmì, àti gbogbo àgbò dúdú pẹ̀lú ewúrẹ́ onílà tàbí tí ó ní àmì. Àwọn wọ̀nyí ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ mi.
33 És tanuskodjék mellettem igazságom a holnapi napon, ha majd eljössz béremhez, mely előtted van; minden, ami nem pöttyös és foltos a kecskék között és sötétszínű a juhok között, lopott az nálam.
Òtítọ́ inú mi yóò sì jẹ́rìí fún mi ní ọjọ́ iwájú nígbà tí ìwọ bá wo owó iṣẹ́ mi tí ìwọ san fún mi, yóò sì ṣe pé gbogbo èyí tí kì í bá ṣe onílà tàbí alámì nínú ewúrẹ́ tàbí tí kì í ṣe dúdú nínú àgùntàn, tí o bá rí ni ọ̀dọ̀ mi ni kí o kà sí mi lọ́rùn pé jíjí ni mo jí gbé.”
34 És Lábán mondta: Igen, vajha lenne szavad szerint.
Labani sì dáhùn pé, “Mo fi ara mọ́ ọn, ṣe bí ìwọ ti wí.”
35 És eltávolította aznap a bakokat, a tarka lábúakat és foltosakat és mind a kecskéket, a pöttyöseket meg a foltosakat, mindazt, amelyen valami fehér volt és minden sötétszínűt a juhok közül; és adta fiai kezére.
Ní ọjọ́ náà gan an ni Labani kó gbogbo ewúrẹ́ tí ó ní àmì tàbí ilà (àti òbúkọ àti abo, tí ó ní funfun díẹ̀ lára), pẹ̀lú gbogbo àgùntàn dúdú, ó sì fi wọ́n sí ìtọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
36 És hagyott három napi utat maga között és Jákob között; Jákob pedig legeltette Lábánnak többi juhait.
Ibi tí Labani àti Jakọbu sì wà sí ara wọn, sì tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Jakọbu sì ń tọ́jú agbo ẹran Labani tí ó kù.
37 És vett magának Jákob friss nyárfapálcát és mogyoró- meg gesztenyefát és héjazott rajtuk fehér csíkokat, megmeztelenítvén a fehéret, mely a pálcákon volt.
Nígbà náà ni Jakọbu gé ọ̀pá tẹ́ẹ́rẹ́ tútù kan lára igi Poplari, àti igi almondi àti igi Pileeni. Ó sì bó èèpo kúrò ní ibi kọ̀ọ̀kan lára igi náà láti fún igi náà ní àwọ̀ ju ẹyọ kan lọ.
38 És odaállította a pálcákat, melyeket lehéjazott, a vályúkba, a vízitatókba, ahova mennek a juhok, hogy igyanak, szemközt a juhokkal és felhevültek, midőn eljöttek inni.
Ó sì mú àwọn ọ̀pá wọ̀nyí tì sí ọ̀ọ́kán agbada omi níbi tí àwọn ẹran ti lè rí i nígbà tí wọ́n bá wá mu omi.
39 És felhevültek a juhok a pálcáknál; és ellettek a juhok tarkalábúakat, pöttyöseket és foltosakat.
Tí àwọn ẹran bá sì ń gùn, níwájú àwọn ọ̀pá náà, wọn sì bí àwọn ẹran onílà àti alámì, àwọn tí ó ní tótòtó lára.
40 A bárányokat elkülönítette Jákob és fordította a juhok arcát a tarkalábúak felé és minden sötétszínű felé Lábán juhai között; és külön helyezett el magának nyájakat és nem helyezte azokat Lábán juhaihoz.
Nígbà náà ni ó ya àwọn abo ẹran kúrò nínú agbo ẹran Labani, ó sì yà wọ́n sọ́tọ̀ kúrò lára àgbò, ó sì mú kí wọn máa gùn pẹ̀lú àwọn àgbò Jakọbu dúdú nìkan, bẹ́ẹ̀ ni ó kó agbo ẹran jọ fún ara rẹ̀ láti ara agbo ẹran Labani.
41 És volt, valahányszor felhevültek a korai juhok, akkor odatette Jákob a pálcákat a juhok szemei elé a vályúkba, hogy felhevüljenek a pálcáknál.
Nígbàkígbà tí àwọn ẹran tí ó lera bá ń gùn, Jakọbu yóò fi àwọn ọ̀pá wọ̀nyí lélẹ̀ níwájú wọn, ní ibi tí wọn ti ń mu omi.
42 Midőn pedig későn ellettek a juhok, nem tette oda; és lettek a későn ellők Lábáné, a koraiak Jákobé.
Ṣùgbọ́n tí ó bá jẹ́ wí pé wọn kò lera, kò ní fi àwọn ọ̀pá náà lélẹ̀. Nítorí náà, àwọn tí kò lera ń jẹ́ ti Labani, nígbà tí àwọn tí ó lera ń jẹ́ ti Jakọbu.
43 És kiterjeszkedett a férfiú igen nagyon és volt neki sok juha, szolgálója, szolgája, tevéje és szamara.
Nítorí ìdí èyí, Jakọbu di ọlọ́rọ̀ gidigidi, agbo ẹran rẹ̀ pọ̀ àti àwọn ìránṣẹ́kùnrin, ìránṣẹ́bìnrin pẹ̀lú ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.