< Ezékiel 39 >
1 Te pedig, ember fia, prófétálj Gógról és mondjad: így szól az Úr, az Örökkévaló: Íme én ellened fordulok Góg, Mésekh és Túbál legfőbb fejedelme.
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí Gogu, kí ó sì wí pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, Ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé ti Meṣeki àti Tubali.
2 Eltérítlek és csalogatlak és felhozlak észak hátuljáról és beviszlek Izraél hegyeire.
Èmi yóò dá ọ padà, èmi yóò sì darí rẹ. Èmi yóò mú ọ wá láti jìnnàjìnnà ìhà àríwá, Èmi yóò rán ọ lòdì sí orí àwọn òkè gíga Israẹli.
3 És kiütöm íjadat bal kezedből és nyilaidat jobb kezedből ejtem ki.
Nígbà náà èmi yóò lu ọrùn awọ rẹ ní ọwọ́ òsì rẹ, èmi yóò sì mú kí àwọn ọfà rẹ jábọ́ ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
4 Izraél hegyein fogsz elesni, te és mind a csapatjaid és a veled levő népek; ragadozó madárnak, minden szárnyasnak és a mező vadjainak adlak eledelül.
Ìwọ yóò sì ṣubú ní orí àwọn òkè Israẹli, ìwọ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn onírúurú ẹyẹ àti fún àwọn ẹranko igbó.
5 A mező színén fogsz elesni, mert én beszéltem, úgymond az Úr, az Örökkévaló.
Ìwọ yóò ṣubú ní gbangba pápá, nítorí tì mo ti sọ̀rọ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
6 És tüzet bocsátok Mágógra és a szigeteken biztonságban lakókra; és megtudják, hogy én vagyok az Örökkévaló.
Èmi yóò fi iná sí Magogu àti sí àwọn tí ń gbé ní agbègbè ilẹ̀ ibẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
7 Szent nevemet pedig megismertetem Izraél népem közepében és nem szentségtelenítettem meg többé szent nevemet, és megtudják a nemzetek, hogy én vagyok az Örökkévaló, a ki szent Izraélben.
“‘Èmi yóò sọ orúkọ mímọ́ mí di mí mọ̀ láàrín àwọn ènìyàn mì Israẹli. Èmi ki yóò jẹ́ kí orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́ àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, Èmi ni ẹni mímọ́ ní Israẹli.
8 Íme bekövetkezik és megtörténik, úgymond az Úr, az Örökkévaló; az a nap az, melyről beszéltem.
Ó ń bọ̀! Ó dájú pé yóò ṣẹlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè. Èyí yìí ni ọjọ́ tí mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.
9 És majd mennek Izraél városainak lakosai és tüzelnek és fűtenek fegyverrel, paizszsal és vérttel, íjjal, és nyilakkal, kézi bottal és lándzsával és tüzet gyújtanak velük hét évig.
“‘Nígbà náà, àwọn ti ó ń gbé nì àárín àwọn ìlú tí ó wà ni Israẹli yóò jáde, wọn yóò sì lo àwọn ohun ìjà bi epo ìdáná yóò sì jó wọ́n kanlẹ̀—àpáta kéékèèké àti àpáta ńlá, àwọn ọfà, àwọn kùmọ̀ ogun àti ọ̀kọ̀ fún ọdún méje wọn yóò lò wọ́n bi epo ìdáná.
10 És nem fognak fát hordani a mezőről és nem fogják vágni az erdőből, hanem a fegyverrel fognak tüzet gyújtani; zsákmányolják az ő zsákmányolóikat és prédálják az ő prédálóikat, úgymond az Úr, az Örökkévaló.
Wọn kò ní nílò láti kó igi jọ láti inú pápá, tàbí gé e láti inú igbó, nítorí pé wọ́n yóò lo òhun ìjà ogun bi epo ìdáná. Wọn yóò sì kógun àwọn tí ó ṣe ìgárá sí wọn, wọn yóò sì bo ilé àwọn tí ó bo ilé wọn, ni Olúwa Olódùmarè.
11 És lészen azon napon, adok Gógnak helyet, a hol sírja lesz, Izraélben; a vándorok völgyét, a tengertől keletre, és az elzárja a vándorokat; és ott eltemetik Gógot és egész sokaságát és így nevezik Góg sokaságának völgye.
“‘Ní ọjọ́ náà èmi yóò sì fi ibi ìsìnkú fún Gogu ní Israẹli, ni àfonífojì àwọn ti ó rìn ìrìnàjò lọ sí agbègbè ilà oòrùn Òkun. Yóò di ojú ọ̀nà àwọn arìnrìn-àjò, nítorí Gogu àti gbogbo ìjọ rẹ̀ ni àwa yóò sin síbẹ̀. Nítorí náà, a yóò pè é ní àfonífojì tí Ammoni Gogu.
12 És eltemetik őket az Izraél házabeliek, hogy megtisztítsák az országot, hét hónapig.
“‘Fún oṣù méje ní ilé Israẹli yóò fi máa sìn wọ́n láti ṣe àfọ̀mọ́ ilẹ̀ náà.
13 Temetni fog az ország egész népe és lesz nekik hirnévül, a mely napon dicsőnek bizonyulok, úgymond az Úr, az Örökkévaló.
Gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà yóò sìn wọ́n, ọjọ́ tí a yìn mi lógo yóò jẹ́ ọjọ́ ìrántí, ní Olúwa Olódùmarè wí.
14 És állandó embereket különítenek el, a kik bejárják az országot, eltemetve a vándorokat, az ország fölszínén megmaradtakat, hogy azt megtisztítsák; hét hónap végén fognak kutatni.
“‘Wọn yóò gbà àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ lóòrèkóòrè láti ṣe àfọ̀mọ́ náà. Ọ̀pọ̀ yóò lọ káàkiri ilẹ̀ náà, ní àfikún pẹ̀lú wọn, àwọn tókù yóò sìn àwọn tí ó kú lórí ilẹ̀. Ní ìparí oṣù keje wọn yóò bẹ̀rẹ̀ wíwá kiri wọn.
15 És körüljárnak, a kik bejárják az országot; s a ki embercsontot lát, épít mellette jelzőt, míg nem eltemették azt a temetők a Góg sokaságának völgyében.
Bí wọ́n n lọ káàkiri ilẹ̀ náà ọ̀kan nínú wọn rí egungun ènìyàn, òun yóò gbé àmì ńlá kalẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ rẹ títí àwọn asìnkú yóò fi sìn ín ní àfonífojì Hamoni Gogu.
16 A város neve is: Sokaság. Így megtisztítják az országot.
Bákan náà ìlú kan tí a ń pè ni Hamona yóò wà níbẹ̀. Nítorí náà wọn yóò wẹ ilẹ̀ náà.’
17 Te pedig, ember fia, így szól az Úr, az Örökkévaló, mondd minden szárnyas madárnak és a mező minden vadjának: gyülekezzetek és jőjjetek, gyűljetek össze köröskörül áldozásomra, melyet vágok számatokra, nagy áldozást, Izraél hegyein; majd esztek húst és isztok vért.
“Ọmọ ènìyàn èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí pé, pe gbogbo oríṣìíríṣìí ẹyẹ àti gbogbo àwọn ẹranko igbó jáde, ‘Kí wọn péjọpọ̀ láti gbogbo agbègbè sí ìrúbọ tí mó ń múra rẹ̀ fún ọ, ìrúbọ ńlá náà ní orí òkè gíga tí Israẹli. Níbẹ̀ ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀.
18 Vitézek húsát fogjátok enni és a föld fejedelmeinek vérét fogjátok inni; kosok, bárányok, bakok, tulkok, Básán hizlalt állatai valamennyien.
Ẹ̀yin yóò jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn ńlá, ẹ o sì mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ-aládé ayé bí ẹni pé wọn jẹ́ àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, ewúrẹ́ àti akọ màlúù gbogbo wọn jẹ́ ẹran ọlọ́ràá láti Baṣani.
19 Enni fogtok zsiradékot jóllakásra és inni fogtok vért részegségre, áldozásomból, melyet vágok nektek.
Níbi ìrúbọ tí mo ń múra kalẹ̀ fún yín, ẹ̀yin yóò jẹ ọ̀rá títí ẹ̀yin yóò fi jẹ àjẹkì, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ títí ẹ̀yin yóò fi yó.
20 És jóllaktok az én asztalomnál lóval és szekérhaddal, vitézzel és minden harczossal, úgy mond az Úr, az Örökkévaló.
Ní orí tábìlì mi ni àwa yóò ti fi ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin bọ yín yó, pẹ̀lú àwọn alágbára ńlá àti oríṣìíríṣìí jagunjagun,’ ni Olúwa Olódùmarè wí.
21 És oda teszem dicsőségemet a nemzetek közé és látni fogják mind a nemzetek ítéletemet, melyet míveltem és kezemet, melyet rájuk tettem.
“Èmi yóò ṣe àfihàn ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì rí ìyà tí mo fi jẹ wọ́n.
22 És megtudja Izraél háza, hogy én vagyok az Örökkévaló, az ő Istenök azon napon túl.
Láti ọjọ́ náà lọ, ilé Israẹli yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
23 És megtudják a nemzetek, hogy bűne miatt számkivetésbe ment Izraél háza, azért hogy hűtelenkedtek ellenem és én elrejtettem tőlük arczomat és adtam őket szorongatóik kezébe és elestek a kard által mindnyájan.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì mọ̀ pé àwọn ènìyàn Israẹli lọ sí ìgbèkùn nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí pé wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi. Nítorí náà mo mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, mo sì fi wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, gbogbo wọn sì ṣubú nípasẹ̀ idà.
24 Tisztátalanságuk szerint és bűntetteik szerint cselekedtem velök és elrejtettem tőlük arczomat.
Mo ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí àìmọ́ àti àìṣedéédéé wọn, mo sì mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
25 Azért így szól az Úr, az Örökkévaló: Most visszahozom Jákób foglyait és irgalmazok Izraél egész házának és buzgólkodom szent nevemért.
“Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Jakọbu padà kúrò ní oko ẹrú, èmi yóò ní ìyọ́nú si gbogbo ènìyàn Israẹli, èmi yóò sì ní ìtara fún orúkọ mímọ́ mi.
26 És viselik majd gyalázatukat és egész hűtlenségüket, mellyel hűtlenkedtek ellenem, midőn biztonságban laktak földjükön és nem volt, ki ijesztett.
Wọn yóò gbàgbé ìtìjú wọn àti gbogbo àìṣòdodo tí wọ́n fihàn sí mi nígbà tí wọn ń gbé ni àìléwu ni ilẹ̀ wọn níbi tí kò ti sí ẹnikẹ́ni láti dẹ́rùbà wọ́n.
27 Midőn visszahozom őket a népek közül és összegyűjtöm őket ellenségeik országaiból, akkor megszenteltetem általuk a sok nemzet szemeláttára.
Nígbà tí mo ti mú wọn padà kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì kó wọn jọ pọ̀ kúrò ni ìlú àwọn ọ̀tá wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ wọn ní ojú àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀.
28 És megtudják, hogy én vagyok az Örökkévaló, az ő Istenük, midőn számkivetem őket a nemzetekhez, de összegyűjtöm őket földjükre és nem hagyok meg ott többé közülük.
Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn nítorí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo rán wọn lọ sí ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò kó wọn jọ sí orí ilẹ̀ wọn, láìfi nǹkan kan sẹ́yìn.
29 És nem rejtem el többé arczomat tőlük, mivel kiöntöttem szellememet Izraél házára, úgymond az Úr, az Örökkévaló.
Èmi kì yóò sì fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn mọ nítorí èmi yóò tú èémí mi jáde sí ilé Israẹli, ní Olúwa Olódùmarè wí.”