< Ezékiel 28 >
1 És lett hozzám az Örökkévaló igéje, mondván:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
2 Ember fia, mondd Czór fejedelmének: Így szól az Úr, az Örökkévaló: Mivel büszke volt a szíved és azt mondtad isten vagyok, isteneknek székhelyét lakom a tengerek szívében, holott ember vagy és nem isten, de olyannak tartod szívedet, mint istenek szíve;
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún ọmọ-aládé Tire pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí tí ọkàn rẹ gbé sókè sí mi, ìwọ wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run; Èmi jókòó sí orí ìtẹ́ òrìṣà, ní àárín gbùngbùn Òkun.” Ṣùgbọ́n ènìyàn ni ọ́, kì i ṣe òrìṣà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ rò pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
3 íme bölcsebb vagy Dánielnél, semmi rejtelmes nem volt homályos előtted.
Ìwọ gbọ́n ju Daniẹli lọ bí? Ṣé kò sí àṣírí kan tí ó pamọ́ fún ọ?
4 Bölcsességeddel és értelmeddel szereztél magadnak: gazdagságot és szereztél aranyat és ezüstöt kincstáraidban;
Pẹ̀lú ọgbọ́n àti ìmọ̀ rẹ, ìwọ tí jèrè ọrọ̀ fún ara rẹ, àti àkójọpọ̀ wúrà àti fàdákà, nínú àwọn ilé ìṣúra rẹ.
5 bölcsességed sokaságával kereskedelmed által gyarapítottad gazdagságodat: és büszke lett a szíved gazdagságod által.
Nípa ọgbọ́n rẹ ńlá àti nípa òwò rẹ, ìwọ ti sọ ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, àti nítorí ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, ọkàn rẹ gbé sókè, nítorí ọrọ̀ rẹ.
6 Azért így szól az Úr, az Örökkévaló: Mivelhogy olyannak tartod szívedet, mint istene szíve,
“‘Nítorí náà èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí pé ìwọ rò pé o gbọ́n, pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
7 azért íme én hozok reád idegeneket, a, nemzetek legerőszakosabbjait, és kirántják kardjaikat bölcsességed szépsége ellen és megszentségtelenítik tündöklésedet.
Èmi yóò mú kí àwọn àjèjì dìde sí ọ, ẹlẹ́rù nínú àwọn orílẹ̀-èdè; wọn yóò yọ idà wọn sí ọ, ẹwà rẹ àti ọgbọ́n rẹ, wọn yóò sì ba dídán rẹ̀ jẹ́.
8 A verembe; szállítanak téged és meg fogsz halni, a mint elesettek; meghalnak a tenger szívében.
Wọn yóò mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá sínú ihò, ìwọ yóò sì kú ikú gbígbóná, àwọn tí a pa ní àárín Òkun.
9 Vajon fogod-e mondani megölőd előtt: isten vagyok, holott ember vagy és nem Isten a gyilkosod kezében.
Ṣé ìwọ yóò wá wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run,” ní ojú àwọn tí ó pa ọ́? Ìwọ yóò jẹ́ ènìyàn, kì í ṣe Ọlọ́run, ní ọwọ́ àwọn ti yóò pa ọ́.
10 Amint körülmetéletlenek halnak meg, úgy fogsz meghalni idegenek keze által: mert én beszéltem, úgymond az Úr, az Örökkévaló.
Ìwọ yóò kú ikú aláìkọlà, ní ọwọ́ àwọn àjèjì. Èmi ni ó ti sọ ọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
11 És lett hozzám az Örökkévaló igéje, mondván:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
12 Ember fia, hangoztass gyászdalt Czór királyáról és mondjad neki: Így szól az Úr, az Örökkévaló: Te megpecsételője a tökéletességnek, teli bölcsességgel és teljes szépségű,
“Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún sórí ọba Tire kí ó sì sọ fún un pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ìwọ jẹ́ àpẹẹrẹ ìjẹ́pípé náà, o kún fún ọgbọ́n, o sì pé ní ẹwà.
13 Édenben, Isten kertjében voltál, mindenféle drágakő volt mennyezeted: ódem, piteda és jáhalóm, tarsís, sóham és jásfé, zafír, nófekh és bárkat, meg arany; domborodásaid és nyílásaid műve rajtad volt, a mely napon teremtettél, készíttettek.
Ìwọ ti wà ní Edeni, ọgbà Ọlọ́run; onírúurú òkúta oníyebíye ni ìbora rẹ; sardiu, topasi àti diamọndi, berili, óníkìsì, àti jasperi, safire, emeradi, turikuose, àti karbunkili, àti wúrà, ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ àti àwọn òkè rẹ ní a dà, láti ara wúrà, ní ọjọ́ tí á dá ọ ní a pèsè wọn.
14 Te kérub voltál, terjeszkedő szárnyú, azzá tettelek, Isten szent hegyén voltál, tüzes kövek között jártál.
A fi àmì òróró yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí olùtọ́jú kérúbù, torí èyí ni mo fi yàn ọ́. Ìwọ wà lórí òkè mímọ́ Ọlọ́run; ìwọ rìn ni àárín òkúta a mú bí iná.
15 Gáncstalan voltál utaidon teremtésed napjától fogva, míg nem jogtalanság találtatott rajtad.
Ìwọ pé ní ọ̀nà rẹ, láti ọjọ́ tí a ti dá ọ, títí a fi rí àìṣedéédéé ní inú rẹ.
16 Kereskedelmed sokasága által megtelt a te belsőd erőszakkal és vétkeztél; megszentségtelenítettelek tehát, el Isten hegyéről, és elveszítettelek, szárnyas kerub, tüzes kövek közül.
Nípa ìtànkálẹ̀ òwò rẹ, ìwọ kún fún ìwà ipá; ìwọ sì dẹ́ṣẹ̀. Nítorí náà ni mo ṣe sọ ọ nù, bí ohun àìlọ́wọ̀ kúrò lórí òkè Ọlọ́run. Èmi sì pa ọ run, ìwọ kérúbù, tí ó bọ́ kúrò ní àárín òkúta a mú bí iná.
17 Büszke volt szíved szépséged által, megrontottad bölcsségedet tündöklésed miatt, földre vetettelek, királyok elé adtalak, hogy látványuk legyen rajtad.
Ọkàn rẹ gbéraga, nítorí ẹwà rẹ. Ìwọ sì ba ọgbọ́n rẹ jẹ́, nítorí dídára rẹ. Nítorí náà mo le ọ sórí ayé; mo sọ ọ di awòojú níwájú àwọn ọba.
18 Bűneid sokasága folytán, kereskedelmed jogtalansága által megszentségtelenítetted szentélyeidet, tüzet támasztottam belőled, az emésztett meg téged és hamuvá tettelek a földön, mind a nézőid szeme láttára.
Nípa ẹ̀ṣẹ̀ púpọ̀ rẹ àti òwò àìṣòótọ́ rẹ, ìwọ ti ba àwọn ibi mímọ́ rẹ jẹ́. Nítorí náà mo mú kí iná jáde wá, láti inú rẹ, yóò sì jó ọ run, èmi yóò sì sọ ọ́ di eérú lórí ilẹ̀, lójú gbogbo àwọn tí ó ń wò ọ́.
19 Mind a kik ismernek a népek közt, eliszonyodtak rajtad, rémületté lettél és nem vagy többé, örökre!
Gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó mọ̀ ọ́n, ní ẹnu ń yà sí ọ; ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’”
20 És lett hozzám az Örökkévaló igéje, mondván:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
21 Ember fia, fordítsd arczodat Czídon felé és prófétálj felőle.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú sí Sidoni; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ sí i,
22 És mondjad: Így szól az Úr, az Örökkévaló, íme én ellened fordulok, Czidón, hogy dicsőnek bizonyuljak benned; és megtudják, hogy én vagyok az Örökkévaló, midőn büntetést végzek rajta és megszenteltetem benne.
kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Sidoni, a ó sì ṣe mí lógo láàrín rẹ. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú ìdájọ́ mi ṣẹ nínú rẹ, tí a sì yá mí sí mímọ́ nínú rẹ.
23 És bocsátok reá dögvészt és vért az utczáiban és elesnek közepében megöltek, az ellene köröskörül támadó kard által; és megtudják, hogy én vagyok az Örökkévaló.
Èmi yóò sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn sínú rẹ, èmi yóò sì mú kí ẹ̀jẹ̀ sàn ní ìgboro rẹ, ẹni ti á pa yóò ṣubú ní àárín rẹ, pẹ̀lú idà lára rẹ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, nígbà náà wọn yóò mọ̀ wí pé èmi ni Olúwa.
24 És nem lesz többé szúró tüske és fájdító tövis Izraél háza számára mind a körülöttük levőktől, a kik megvetik őket; és megtudják, hogy én vagyok az Úr, az Örökkévaló.
“‘Kì yóò sì ṣí ẹ̀gún tí ń gun ni ní ilẹ̀ Israẹli mọ́, tàbí ẹ̀gún bíbani nínú jẹ́ ti gbogbo àwọn tí wọn wà ní àyíká wọn, tí wọ́n sì ń fi ojú yẹpẹrẹ wò wọ́n, nígbà náà ni wọn yóò mọ́ wí pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.
25 Így szól az Úr, az Örökkévaló: Midőn összegyűjtöm Izraél házát a népek közül, a melyek közt elszéledtek, meg fogok szenteltetni általuk a nemzetek szemeláttára; és lakni fognak földjükön, a melyet adtam szolgámnak, Jákóbnak.
“‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí èmi yóò bá sa àwọn ènìyàn Israẹli jọ kúrò ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti fọ́nká sí, tí a ó sì yà mí sí mímọ́ láàrín wọn lójú àwọn aláìkọlà. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ní ilẹ̀ àwọn tìkálára wọn, èyí tí mo fún ìránṣẹ́ mi Jakọbu.
26 És laknak rajta biztonságban, építenek házakat és ültetnek szőlőket és biztonságban laknak, midőn büntetést végzek mindazokon, kik őket megvetik a körülöttük levőktől. És megtudják, hogy én vagyok az Örökkévaló, az ő Istenük.
Wọn yóò sì máa gbé ní inú rẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì kọ́lé, wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà; nítòótọ́ wọn yóò wà ní ìbàlẹ̀ àyà, nígbà tí èmi bá ti mú ìdájọ́ mi ṣẹ̀ sí ara àwọn tí ń ṣátá wọn ní gbogbo àyíká wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.’”