< Ezékiel 18 >
1 És lett hozzám az Örökkévaló igéje, mondván:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
2 Mit akartok ti, midőn ezzel a példabeszéddel éltek Izrael földjén, mondván: az apák egrest esznek és a fiúk fogai vásnak belé?
“Kín ni ẹ̀yin rò tí ẹ̀yin fi ń pa òwe nípa Israẹli wí pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà kíkan, eyín àwọn ọmọ sì kan.’
3 Ahogy élek, úgymond az Úr, az Örökkévaló, nem lesz többé helye annak, hogy ezzel a példabeszéddel éljetek Izraelben.
“Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, ẹ̀yin kí yóò pa òwe yìí mọ́ ni Israẹli.
4 Lám mind a lelkek az enyéim, úgy az atyának lelke mint a fiúnak lelke az enyéim; a vétkező lélek, az hal meg.
Nítorí pé èmi ló ní gbogbo ọkàn, ọkàn baba tèmi bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ọmọ pàápàá jẹ tèmi, ọkàn tó bá ṣẹ̀ ní yóò kú.
5 És ha valaki igaz lesz és jogot és igazságot művel:
“Bí ọkùnrin olódodo kan bá wà, tó ń ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ
6 a hegyeken nem evett és szemét nem emelte föl Izrael házának bálványaihoz, felebarátjának feleségét nem fertőztette meg és nőhöz tisztulása alatt nem közeledik;
tí kò bá wọn jẹun lórí òkè gíga, tí kò gbójú rẹ̀ sókè sí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Israẹli, ti kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́ tàbí kí ó sùn ti obìnrin ni àsìkò èérí rẹ̀.
7 senkit nem szorongat, az adósságért vett zálogot visszaadja, rablást nem követ el, kenyerét adja az éhezőnek és a mezítelent ruhával takarja be;
Kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, ó sì sanwó fún onígbèsè rẹ̀ gẹ́gẹ́ bó ṣe ṣe ìlérí fún un, kò fi ipá jalè ṣùgbọ́n ó fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ, tí ó sì fi ẹ̀wù wọ àwọn tí ó wà ní ìhòhò.
8 kamatra nem ad és többletet nem vesz, jogtalanságtól visszavonja kezét, igaz ítéletet hoz ember és ember között;
Ẹni tí kò fi fún ni láti gba ẹ̀dá, tàbí kò gba èlé tó pọ̀jù. Ó yọ ọwọ́ rẹ̀ kúrò nínú ìwà ẹ̀ṣẹ̀, ó sì ń ṣe ìdájọ́ òtítọ́ láàrín ọkùnrin kan àti èkejì rẹ̀.
9 törvényeim szerint jár és rendeleteimet megőrizte, hogy igazságot műveljen: igaz ő, élni fog, úgymond az Úr, az Örökkévaló.
Tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ mi, tí ó sì ń pa òfin mi mọ́ lóòtítọ́ àti lódodo. Ó jẹ́ olódodo, yóò yè nítòótọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.
10 De ha nemzett erőszakos fiút, vérontót és aki csak egyet is tett ezek közül,
“Bí ó bá bi ọmọkùnrin, oníwà ipá, tó ń jalè, tó tún ń pànìyàn, tó sì ń ṣe gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí sí arákùnrin rẹ̀
11 amaz pedig mindezeket nem tette, hanem a hegyeken is evett és felebarátjának feleségét megfertőztette;
(tí kò sì ṣe ọ̀kan nínú gbogbo iṣẹ́ wọ̀n-ọn-nì): “Ó ń jẹun lójúbọ lórí òkè gíga, tí ó sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́.
12 szegényt és szűkölködőt szorongatott, rablásokat követett el, zálogot nem ad vissza, a bálványokhoz emelte fel szemeit, utálatosságot cselekedett;
Ó ni àwọn tálákà àti aláìní lára, ó ń fipá jalè, kì í dá padà gẹ́gẹ́ bí ìlérí, o gbójú sókè sí òrìṣà, ó sì ń ṣe ohun ìríra.
13 kamatra adott és többletet vett – éljen-e? Nem fog élni, mind ez utálatosságokat cselekedte, meg fog halni, vére lesz rajta!
Ó ń fi owó ya ni pẹ̀lú èlé, ó sì tún ń gba èlé tó pọ̀jù. Ǹjẹ́ irú ọkùnrin yìí wa le è yè bí? Òun kì yóò wá láààyè! Nítorí pé òun ti ṣe àwọn ohun ìríra yìí, kíkú ni yóò kú, ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wá lórí rẹ̀.
14 De íme nemzett egy fiat, és az látta atyjának minden vétkeit, amelyeket elkövetett; látta, és nem cselekszik azok szerint:
“Bí ọkùnrin yìí bá bímọ ọkùnrin, tó sì rí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti baba rẹ ń ṣẹ̀ yìí, tó sì bẹ̀rù, ti kò ṣe irú rẹ̀:
15 a hegyeken nem evett, szemeit nem emelte fel Izrael házának bálványaihoz, felebarátjának feleségét nem fertőztette meg;
“Tí kò jẹun lójúbọ lórí òkè gíga tàbí kò gbójú sókè sí àwọn òrìṣà ilé Israẹli, tí kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́
16 senkit nem szorongatott, zálogot nem vett el és rablást nem követett el, kenyerét az éhezőnek adta és a mezítelent betakarta ruhával;
tí kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, tí kò dá ohun ògo dúró tí kò gba èlé tàbí kò fipá jalè ṣùgbọ́n tí ó ń fún ẹni tébi ń pa lóúnjẹ, tó sì fi aṣọ bo àwọn oníhòhò.
17 a szegénytől visszatartotta a kezét, kamatot és többletet nem vett, rendeleteimet megtette, törvényeim szerint járt; az nem hal meg atyjának bűnéért, élni fog.
Ó ń yọ ọwọ́ rẹ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀, kò sì gba èlé tàbí èlé tó pọ̀jù, tí ó ń pa òfin mi mọ́, tí ó sì ń tẹ̀lé àwọn àṣẹ mi. Kò ní kú fún ẹ̀ṣẹ̀ baba rẹ̀, nítòótọ́ ní yóò yè!
18 Atyja, mivel fosztogatást követett el és rablást követett el testvérén és azt, ami nem jó, cselekedte népe között, íme meghalt bűnéért.
Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀, nítorí pé ó jẹ́ arẹ́nijẹ, ó jalè arákùnrin rẹ, ó ṣe ohun tí kò dára láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
19 És ti mondjátok, miért nem viselte a fiú is az atyjának bűnét? Hiszen a fiú jogot és igazságot művelt, mind a törvényeimet megőrizte és megcselekedte azokat: élni fog.
“Síbẹ̀, ẹ tún ń béèrè pé, ‘Kí ló dé ti ọmọ kò fi ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀?’ Níwọ́n ìgbà tí ọmọ ti ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ, tó sì ti kíyèsi ara láti pa gbogbo àṣẹ mi mọ́, nítòótọ́ ni pé yóò yè.
20 A vétkező lélek, az hal meg, a fiú nem viseli az atya bűnét és az atya nem viseli fia bűnét, az igaznak igazsága rajta magán lesz és a gonosznak gonoszsága rajta magán lesz.
Ọkàn tí ó bá ṣẹ̀ ní yóò kú. Ọmọ kò ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni baba náà kò ní ru ẹ̀bi ọmọ rẹ̀. Ìwà rere ènìyàn rere yóò wà lórí rẹ̀, ìwà búburú ti ènìyàn búburú náà la ó kà sí i lọ́rùn.
21 De a gonosz, midőn elfordul mind a vétkeitől, amelyeket elkövetett és megőrzi mind a törvényeimet és művel jogot és igazságot, élni fog, nem hal meg.
“Ṣùgbọ́n bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tó ti dá, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa àṣẹ mi mọ́, tó sì ń ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, nítòótọ́ ni yóò yè, kò sì ní kú.
22 Mind a bűntettei, melyeket elkövetett nem tartatnak neki emlékezetben; igazságért, amelyet művelt, élni fog.
A kò sì ní rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tó ti dá tẹ́lẹ̀ láti kà á sí lọ́rùn nítorí tí ìwà òdodo rẹ tó fihàn, yóò yè.
23 Vajon kívánva kívánom-e a gonosznak halálát, úgymond az Úr, az Örökkévaló, nemde azt, hogy megtérjen útjairól és éljen.
Ǹjẹ́ èmi ha ni inú dídùn si ikú ènìyàn búburú bí í? Ní Olúwa Olódùmarè wí pé, dípò èyí inú mi kò ha ni i dùn nígbà tó ba yípadà kúrò ni àwọn ọ̀nà búburú rẹ̀ kí ó sì yè?
24 De ha az igaz elfordul igazságától és jogtalanságot követ el, mindazon utálatosságok szerint cselekszik, amelyeket a gonosz cselekedett, éljen-e? Mind az igazságai, amelyeket cselekedett, nem tartatnak emlékezetben, hűtlenségéért, amellyel hűtlenkedett, és vétkéért, amellyel vétkezett, azokért hal meg.
“Ṣùgbọ́n bí ènìyàn rere bá yípadà kúrò ni ọ̀nà òdodo rẹ̀ tó sì ń dẹ́ṣẹ̀, tí ó sì tún ń ṣe àwọn ohun ìríra tí ènìyàn búburú ń ṣe, yóò wa yè bí? A kì yóò rántí ọ̀kankan nínú ìwà rere rẹ̀ mọ́, nítorí ó ti jẹ̀bi ìwà àrékérekè àti ẹ̀ṣẹ̀ tó dá, yóò sì kú.
25 És ti azt mondjátok, nem megfelelő az Úrnak útja! Halljátok csak, Izrael háza, vajon az én utam nem megfelelő-e; hiszen a ti útjaitok nem megfelelők!
“Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin tún wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ ilé Israẹli. Ọ̀nà mi ni kò ha gún? Kì í wa ṣé pé ọ̀nà tiyín gan an ni kò gún?
26 Mikor az igazságos elfordul az igazságától és jogtalanságot követ el és ennek folytán meghal, azon jogtalanságáért, amelyet elkövetett, hal meg.
Bí olódodo ba yípadà kúrò nínú olódodo rẹ̀, tó sì dẹ́ṣẹ̀, yóò ku fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá.
27 És mikor a gonosz elfordul gonoszságától, melyet művelt, és jogot s igazságot művelt, ő életben tartja lelkét:
Ṣùgbọ́n bi ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú tó ti ṣe, tó sì ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, yóò gba ẹ̀mí rẹ̀ là.
28 látta ugyanis és elfordult mind a bűntetteitől, melyeket cselekedett; élni fog, nem hal meg.
Nítorí pé ó ronú lórí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá, ó sì yípadà kúrò nínú wọn, nítòótọ́ ni yóò yè; kì yóò sí kú.
29 És Izrael háza azt mondja: nem megfelelő az Úrnak útja; vajon az én útjaim nem megfelelők-e, Izrael háza, hiszen a ti útjaitok nem megfelelők!
Síbẹ̀, ilé Israẹli wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Ọ̀nà mi kò ha tọ́ bí ilé Israẹli? Kì í wa ṣe pè ọ̀nà tiyín gan an ni ko gún?
30 Azért kit-kit útjai szerint foglak megítélni benneteket, Izrael háza, úgymond az Úr, az Örökkévaló; forduljatok el és térjetek meg mind a bűntetteitektől, hogy ne legyen nektek bűnre való botlásul.
“Nítorí náà, ilé Israẹli, èmi yóò da yín lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ẹnìkọ̀ọ̀kan yín bá ṣe rí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ẹ yípadà! Kí ẹ si yí kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni ìrékọjá kì yóò jẹ́ ọ̀nà ìṣubú yín.
31 Dobjátok el magatoktól mind a bűntetteiteket, melyekkel vétkeztettek és szerezzetek magatoknak új szívet és új szellemet, hisz miért halnátok meg, Izrael háza!
Ẹ kọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti ẹ ti dá sílẹ̀, kí ẹ sì gba ọkàn àti ẹ̀mí tuntun. Nítorí kí ló fi máa kú, ilé Israẹli?
32 Mert nem kívánom annak, aki meghal, a halálát, úgymond az Úr, az Örökkévaló, térjetek meg tehát és éljetek!
Nítorí pé inú mi kò dùn sí ikú ẹnikẹ́ni ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí náà, ẹ yípadà kí ẹ sì yè!