< 2 Mózes 1 >

1 És ezek a nevei Izrael fiainak, akik Egyiptomba jöttek; Jákobbal, kiki az ő házával, jöttek ők.
Ìwọ̀nyí ni àwọn orúkọ ọmọ Israẹli tí wọ́n bá Jakọbu lọ sí Ejibiti, ẹnìkọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ìdílé rẹ̀:
2 Rúben, Simon, Lévi és Júda;
Reubeni, Simeoni, Lefi àti Juda;
3 Isszáchár, Zebúlun és Benjámin;
Isakari, Sebuluni àti Benjamini;
4 Dán, Náftáli, Gád és Ásér.
Dani àti Naftali; Gadi àti Aṣeri.
5 És volt összes lélekszáma a Jákob ágyékából származóknak: hetven lélek; József pedig Egyiptomban volt.
Àwọn ìran Jakọbu sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Josẹfu sì ti wà ní Ejibiti.
6 És meghalt József, meg mind a testvérei és az az egész nemzedék.
Wàyí o, Josẹfu àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú,
7 Izrael fiai pedig szaporodtak és nyüzsögtek, megsokasodtak és elhatalmasodtak igen nagyon, és megtelt az ország velük.
ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà.
8 És új király támadt Egyiptom fölött, aki nem ismerte Józsefet.
Nígbà náà ni ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
9 és mondta az ő népének: Íme, Izrael fiainak népe több és hatalmasabb nálunknál.
Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, “Ẹ wò ó, àwọn ará Israẹli ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa.
10 Nosza, legyünk okosak vele szemben, hogy el ne sokasodjék, mert lesz, ha háború támadna, ő is csatlakoznék ellenségeinkhez, harcolna ellenünk és felmenne az országból.
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lo ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí láti dá wọn lẹ́kun, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ wọn yóò túbọ̀ máa pọ̀ sí i. Bí ogun bá sì bẹ́ sílẹ̀, wọn yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ọ̀tá wa, wọn yóò sì da ojú ìjà kọ wá, wọn yóò sì sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ yìí.”
11 És rendeltek feléje robotfelügyelőket, hogy sanyargassák őt rabmunkáikkal; és épített (Izrael) eleséggyűjtő városokat Fáraónak: Pítómot és Raámszészt.
Nítorí náà, wọ́n yan àwọn ọ̀gá akóniṣiṣẹ́ lé wọn lórí láti máa ni wọ́n lára pẹ̀lú iṣẹ́ àṣekára. Wọ́n sì kọ́ Pitomi àti Ramesesi gẹ́gẹ́ bí ìlú ìṣúra pamọ́ sí fún Farao.
12 De amint sanyargatták őt, úgy sokasodott és terjeszkedett; úgy, hogy irtóztak Izrael fiaitól.
Ṣùgbọ́n bí a ti ń ni wọ́n lára tó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń pọ̀ sí i, tí wọ́n sì ń tànkálẹ̀. Nítorí náà, àwọn ará Ejibiti bẹ̀rù nítorí àwọn ará Israẹli.
13 És az egyiptomiak dolgoztattak Izrael fiaival szigorúsággal.
Àwọn ará Ejibiti sì mú àwọn ọmọ Israẹli sìn ní àsìnpa.
14 Megkeserítették az életüket kemény munkával agyagkeveréssel és téglavetéssel és minden munkával a mezőn; minden munkájukat, amelyet velük dolgoztattak, szigorúsággal (végeztették).
Wọ́n mú wọn gbé ìgbé ayé kíkorò nípa iṣẹ́ bíríkì àti àwọn onírúurú iṣẹ́ oko; àwọn ará Ejibiti ń lò wọ́n ní ìlòkulò.
15 És mondta Egyiptom királya a héber szülésznőknek, akik közül az egyiknek neve Sifró és a másiknak neve Púó,
Ọba Ejibiti sọ fún àwọn agbẹ̀bí Heberu ti orúkọ wọn ń jẹ́ Ṣifura àti Pua pé,
16 és mondta: Midőn szülésnél segédkeztek a héber nőknek, tekintsetek a szülőszékre: ha fiú az, öljétek meg őt, ha pedig leány, maradjon életben.
“Nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbẹ̀bí àwọn obìnrin Heberu, tí ẹ sì kíyèsi wọn lórí ìkúnlẹ̀ ìrọbí wọn, bí ó bá jẹ́ ọkùnrin ni ọmọ náà, ẹ pa á; ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ obìnrin, ẹ jẹ́ kí ó wà láààyè.”
17 De a szülésznők félték Istent és nem tettek úgy, amint szólt hozzájuk Egyiptom királya, és életben hagyták a fiúgyermekeket.
Ṣùgbọ́n àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọba Ejibiti ti wí fún wọn; wọ́n jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wà láààyè.
18 És hivatta Egyiptom királya a szülésznőket és mondta nekik: Miért tettétek ezt a dolgot, hogy életben hagytátok a fiúgyermekeket?
Ọba Ejibiti pe àwọn agbẹ̀bí ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí? Èéṣe tí ẹ̀yin fi dá àwọn ọmọkùnrin si?”
19 És mondták a szülésznők Fáraónak: Mert nem olyanok a héber nők, mint az egyiptomi nők, hanem életrevalók; mielőtt jön hozzájuk a szülésznő, már szültek.
Àwọn agbẹ̀bí náà sì dá Farao lóhùn pé, “Àwọn obìnrin Heberu kò rí bí àwọn obìnrin Ejibiti, wọ́n ní agbára, wọ́n sì ti máa ń bí ọmọ kí àwọn agbẹ̀bí tó dé ọ̀dọ̀ wọn.”
20 És jót tett Isten a szülésznőkkel; a nép pedig sokasodott és nagyon elhatalmasodott.
Nítorí náà Ọlọ́run ṣàánú fún àwọn agbẹ̀bí náà, àwọn ọmọ Israẹli sì ń le sí i, wọ́n sì ń pọ̀ sí i jọjọ.
21 És volt, minthogy félték a szülésznők Istent, szerzett nekik házakat.
Nítorí pé àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, Ọlọ́run sì fún wọn ni ìdílé tiwọn.
22 Fáraó pedig megparancsolta egész népének, mondván: Minden fiút, aki születik, a folyamba vessetek és minden leányt hagyjátok életben.
Nígbà náà ni Farao pàṣẹ yìí fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ pé, “Gbogbo ọmọkùnrin tí a bí ni kí ẹ gbé jù sínú odò Naili, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọbìnrin ni kí ẹ jẹ́ kí wọn ó wà láààyè.”

< 2 Mózes 1 >